M. K. O. Abíọ́lá

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́
Moshood Abiola
Ọjọ́ìbí(1937-08-24)24 Oṣù Kẹjọ 1937
Abeokuta
Aláìsí7 July 1998(1998-07-07) (ọmọ ọdún 60)
Abuja
Orílẹ̀-èdèNàìjíríà
Orúkọ mírànM.K.O Ab́iọ́lạ́
Iṣẹ́Okowo, Oloselu, Oluranilowo.
Gbajúmọ̀ fúnBeing arrested following a Presidential election in Nigeria which he won/Philanthropy
Olólùfẹ́Simbiat Atinuke Shoaga
Kudirat Olayinka Adeyemi
Adebisi Olawunmi Oshin
Doyinsola Abiola Aboaba
Modupe Onitiri-Abiola [1]
Remi Abiola
(+other women)
Àwọn ọmọAbdulateef Kola Abiola
Dupsy Abiola
Hafsat Abiola
Rinsola Abiola
Khafila Abiola
(+other children)

Moshood Káṣìmawòó Ọláwálé Abíọ́lá (August 24, 1937 - July 7, 1998) tí ó túmọ̀ sí M.K.O Abíọ́lá jẹ́ ọmọ orílẹ̀ èdè Nàìjíríà. A bi ní ìlú Abẹ́òkútaÌpínlẹ̀ Ògùn. Ó jẹ́ oníṣòẁò,òǹtẹ̀wé, olóṣèlú àti olóyè ilẹ̀ Yorùbá Ẹ̀gbá pàtàpátá.[2] Ó díje sípò Ààrẹ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà ní ọdún 1993, òun náà sì ni gbogbo ènìyàn gbàgbọ́ tí wọ́n sì fẹnukò sí jákè-jádò orílẹ-èdè Nàìjíríà wípé ó jáwé olúborí nígbà tí olóri ìjọba ológun ìgbà náà Ibrahim Babangida kò kéde rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí olúborí ètò ìdìbò náà tí ó sì fi ẹ̀sùn àìṣòtítọ́ àti àìṣòdodo ètò ìdìbò yàn náà. M.K.O kú ní ọdún 1998. [3][4]

Igbesi Aye re[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Moshood Abíọ́lá ni àkọ́bí  bàbá àti ìyá rẹ̀ lẹ́yìn ìkúnlẹ̀ ọmọ kẹtàlélógún, ìdí èyí ní ó fàá tí wọ́n fi dúró títí di ẹ̀yìn ọdún mẹ́ẹ̀dógún (15 years) kí àwọn òbí rẹ̀ tó fún lórúkọ rẹ̀ “Kasimawo”[5] . Moshood fakọyọ nínú ìmọ̀ ìdágbálé (entrepreneur) láti ìgb̀a èwe rẹ̀, ó bẹ̀rè iṣẹ́ igi-ṣíṣẹ́ tà láti ọmọ ọdún mẹ́sàán. Ó ma ń jí ní ìdájí lọ sóko igi láti wági tí yóò tà ṣáájú kí ó tó lọ sị́ ilé-ìwé kí òun àti bàbá rẹ̀ tó ti rúgbo pẹ̀lú àwọn àbúrò rẹ̀ kó lè rówó ná. Nígb̀a tí ó t́o ọmọ ọdún mẹ́ẹ̀dógún (15 years), ó dá ẹgbẹ́ eré kan kalẹ̀ tí wọ́n ma ń kọrin kiri láti lè rí óúnjẹ jẹ níbi ìnáwo èyíkéyìí tí wọ́n bá lọ. Láìpẹ́, ó di gbajú-gbajà níbi orin rẹ̀ tó ń kó kiri, ó sì di ẹni tí ó ń bèrè fún owó iṣẹ́ kí wọ́n tó kọrin lóde ìnáwó kòkan. Àwọn owó tí ó ń rí níbi eré rẹ̀ yìí nị́ ó fi ń ran ẹbí rẹ̀ lọ́wọ́ tí ó sì ń san owó ilé-ẹ̀kọ́ gíga tí ìjọ Onítẹ̀bọmi tí ó wà ní Abéòkúta . Abíọ́́lá jẹ́ Olóòtú ìwé ìròyìn ọ̀sọ̀ọ̀sẹ̀ ilé-ìwé wọn tí ó ń jẹ́ The TrumpeterOlúṣẹ́gun Ọbásanjọ́ sì jẹ́ igbákejì rẹ. Ó dára pọ̀ mọ́ ẹgbẹ́ National Council of Nigeria and the Cameroons ní ìgbà tí ó di ọmọ ọdún mọ́kàndínlógún nítorí ìfẹ́ tí ó ní sí ètò òṣèlú àwa arawa lábẹ́ àsíá Ọbáfẹ́mi Awólọ́wọ̀ olùdásílẹ̀ ẹgbẹ́ òṣèlú Action Group.[6]

Ni odun 1960, Moshood gba sikolashipu ijọba lati ka iwe ni University ti Glasgow ni ilu Scotland ni bii ti o gba oye ni isiro sebe sebe o o je oye oniṣiro iwiregbe. Moshood di Ẹlẹgbẹ ti Institute of Chartered Accountants of Nigeria (ICAN) (ICAN).

Àwọn ìtọ́kasí[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

  1. "REMEMBERING ABIOLA, 15 YEARS AFTER". National Mirror. July 6, 2013. Archived from the original on March 27, 2017. https://web.archive.org/web/20170327080631/http://nationalmirroronline.net/new/remembering-abiola-15-years-after/. Retrieved March 26, 2017. 
  2. "Moshood Kashimawo Olawale Abiola | Nigerian entrepreneur and politician". Encyclopedia Britannica (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). Retrieved 2020-05-25. 
  3. "‘MKO Was The Winner’ - Buhari Apologises To Abiola Family Over Annulment Of June 12 ’93 Election". Sahara Reporters. 2018-06-12. Retrieved 2018-06-13. 
  4. Aribisala, Femi (2018-06-12). "What June 12 reveals about Nigerian democracy". Vanguard News. Retrieved 2018-06-13. 
  5. Odumakin, Yinka (2018). "June 12 dissemblers". Vanguard News. 
  6. Inyang, Ifreke (2018-06-12). "MKO Abiola: What Falana told Buhari about results of June 12 elections". Daily Post Nigeria. Retrieved 2018-06-13.