Jump to content

Ààrẹ Látoósà

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́

Àdàkọ:Infobox noble

Palace of Aare Latoosa in Ibadan
The Palace of Aare Latoosa in Ibadan


Ààrẹ Látòósà Ọyatóòsà (c.1820s - 1885), tí a tún ń pè ní Latoosa (tàbí Latosisa), tí orúkọ rẹ̀ padà di Mohammed Obadoke Latoosa,[1] jẹ́ jagunjagun, Iba àti Ààrẹ Ọ̀nà Kakanfò fún ilẹ̀ Ọ̀yọ́ àti adarí fún ilẹ̀ Ìbàdàn. [2] Òun náà tún ni adarí àti aṣáájú ogun fún àwọn ikọ̀ Ìbàdàn nínú ogun Kírìjí[1][3] tí ó sì papò dá ní ọdún 1885.[4][1][5]

Nígbà tí Látòósà wọ̀lú Ìbàdàn, ó dára pọ̀ mọ́ ikọ̀ ọmọ ogun Balógun Ògúnmọ́lá tí ó sì tètè di akọgun àti ikọ̀ ọmọ ogun tí ń ṣọ́ Baṣọ̀run náà. Wọ́n fi Látòósà jẹ oyè Ààrẹ Ọ̀nà Kakanfò àti adarí ilẹ̀ Ìbàdàn ní ọjọ́ kẹta oṣù kẹwàá ọdún 1871. Látòósà jẹ́ ọmọ bíbí ìlú ÌlọráÌpínlẹ̀ Ọ̀yọ́ lónìí.[6] Ààrẹ Látòósà ni ó jẹ́ Ààrẹ Ọ̀nà Kakanfò Kejìlá fún ilẹ̀ Ọ̀yọ́. Ó jẹ Kakanfò nígbà tí púpọ̀ ilẹ̀ Yoòbá wà ní hílà-hílo ogun tí ogun Kírìjí sì jẹ́ ogun tí ó pẹ́ jùlọ ní ilẹ̀ Yorùbá tí ó tó ọdún mẹ́rìndínlógún 1877-1893. Òun náà sì ni Àarẹ Ọ̀nà Kakanfò tí ó jẹ kẹ́yìn kí alàgbà Samuel Ladoke Akintola. [6]

Àwọn ìtọ́kasí

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]
  1. 1 2 3 "Latoosa: The Kakanfo that triggered Kiriji War". Vanguard News. January 11, 2018.
  2. Ofunleye, Foluke (2004), A Male-Centric Modification of History: "Efunsetan Aniwura" Revisited, 31, pp. 300–319
  3. "The 14 Kakanfos of Yorubaland". April 4, 2017.
  4. "HISTORY OF IBADAN PART 36: THE REIGN OF LATOOSA AS THE AARE ONA KAKANFO". January 13, 2021. Archived from the original on June 10, 2023. Retrieved August 30, 2025.
  5. "The untold story of legendary Obadoke Aare Latoosa | By Arowolo-Are Jubril - MegaIcon Magazine". 5 October 2020.
  6. 1 2 "The Chiefs Who Ruled With Latoosa, the 2nd Aare Ona Kakanfo of Ibadan". Yoruba Facts (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). 2017-04-15. Retrieved 2023-02-27.