Àbáyọ̀mí Ọlọ́nìṣakin
Abayomi Olonisakin | |
|---|---|
Olonisakin in 2018 | |
| Chief of Defence Staff | |
| In office 21 July 2015 – 29 January 2021 | |
| Asíwájú | Alex Sabundu Badeh |
| Arọ́pò | Lucky Irabor |
| Commander of TRADOC | |
| In office September 2013 – July 2015 | |
| Asíwájú | Salihu Zaway Uba |
| Arọ́pò | Mobolaji Koleoso |
| Commander of the Nigerian Army Corps of Signals | |
| In office January 2013 – September 2013 | |
| Àwọn àlàyé onítòhún | |
| Ọjọ́ìbí | 2 Oṣù Kejìlá 1961[1] Ekiti state, Nigeria |
| Alma mater | Nigeria Military School Nigerian Defence Academy Obafemi Awolowo University |
| Military service | |
| Allegiance | |
| Branch/service | |
| Years of service | 1979 – 2021 |
| Rank | |
| Commands | Chief of Defence Staff Commander of TRADOC Commander of the Army Corps of Signals |
Àbáyọ̀mí Gabriel Ọlọ́nìṣakin CFR psc(+) GSS CMH fwc (tí a bí ní ọjọ́ kejì oṣù Kejìlá ọdún 1961) jẹ́ ọ̀gágun ọmọ ogun orílẹ̀-èdè Nàìjíríà tó ti fẹ̀yìntì, olórí àwọn òṣìṣẹ́ ààbò tẹ́lẹ̀, àti aṣojú orílẹ̀-èdè Nàìjíríà sí Orílẹ̀-èdè Kamẹrúùnù lọ́wọ́lọ́wọ́. Ààrẹ Muhammadu Buhari yàn án sí ipò olórí àwọn òṣìṣẹ́ alààbò ní ọjọ́ kẹtàlá oṣù Keje ọdún 2015. Ó fi ipò sílẹ̀ ní ọjọ́ kọkàndínlọ́gbọ̀n oṣù kìíní ọdún 2021.
Ìgbésí ayé àti ẹ̀kọ́ rẹ̀
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Ọlọ́nìsakìn, tí ó wá láti Ìpínlẹ̀ Èkìtì tí ó sì kọ́ ẹ̀kọ́ alákọ̀ọ́bẹ̀rẹ̀ àti girama ní Zaria . Ọmọ kẹta nínú àwọn ọmọ márùn-ún ni, Ọlọ́nìṣakin dàgbà nínú ọgbà ilé ìjọsìn kan ní Odò Ìjẹ̀bú ní Òde Èkìtì, agbègbè ìjọba ìbílẹ̀ Gbonyin, ní Ìpínlẹ̀ Èkìtì, níbi tí àwọn òbí rẹ̀ ti jẹ́ ọmọ ìjọ CMS agbègbè náà. [2] Ó forúkọ sílẹ̀ ní Ilé-ẹ̀kọ́ Ológun Nàìjíríà, Zaria ní ọdún 1973 , lẹ́yìn náà ó dara pọ̀ mọ́ Ilé-ẹ̀kọ́ Ológun Nàìjíríà gẹ́gẹ́ bí ọmọ ẹgbẹ́ akẹ́kọ̀ọ́ karùndínlọ́gbọ̀n. Wọ́n yàn án gẹ́gẹ́ bí Lieutenant Kejì sínú Iṣẹ́ ológun gẹ́gẹ́ bìi atọ́nisọ́nà ní ọdún 1981. [3] Ọlọ́nìsakin kẹ́kọ̀ọ́ gboyè ní àkọ́kọ́ Yunifásitì pẹ̀lú àmì ẹ̀yẹ nínú ìmọ̀ àwọn oun èlò ilé tó ń loná láti Yunifásítì Ọbáfẹ́mi Awólọ́wọ̀ ní Ilé Ifẹ̀ . [3]
Àwọ́n Iṣẹ́ tí ó ṣe
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Kí wọ́n tó yàn án gẹ́gẹ́ bí Olórí aláàbò, Ọ̀gágun Olonisakin ni olórí àwọn ẹgbẹ́ wọ̀nyí.
Wọ́n gbé Ọlọ́nìṣakin ga sí ipò Ọ̀gágun ní oṣù kẹjọ ọdún 2015 láti ọwọ́ Ààrẹ Muhammadu Buhari lẹ́yìn ìfìdí rẹ̀ múlẹ̀ gẹ́gẹ́ bí Olórí ẹ̀ka Ààbò. [6]
Àwọn ẹ̀bùn àti àmì ẹ̀yẹ
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Ní oṣù kẹwàá ọdún 2022, Ààrẹ Muhammadu Buhari nígbà náà fún un ní ọlá orílẹ̀-èdè Nàìjíríà ti Commander of the Order of the Federal Republic (CFR).