Jump to content

Àjàká

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́

Àjàká jẹ́ Oba Ọ̀yọ́ (tí ó wà láàrin Nàìjíríà òdẹ òní) ti oje ni igba meji lórí ìté. [1] [2] [3] Bàbá rẹ jẹ́ Oranyan tabi Òrànmíyàn ti arákùnrin rẹ, gẹ́gẹ́bí akọ̀wé Samuel Johnson, jẹ Shango . [3]

Àjàká ni àkóso Oyo ní àkókó gẹ́gẹ́ bí olóyè – àti Àrólé – baba rẹ̀. Lẹhin iku baba rẹ, arakunrin rẹ, Shango ti o jẹ akíkanjú ni ìwà gba ipò rẹ. [3] Ó gbé ní àkókò wàhálà ati rúdurùdu, ní ìbèrè ó jẹ́ ènìyàn ti o ni ìfẹ́ alaafia ti òpò ro bi àìní akíkanjú ni. Ìdí fún èyí kò jìnnà: ó dàbí pé ọba ti pinnu láti gbajúmò ìṣàkóso ààfin ti o si gba awọn ọmọ ogun rẹ ni òmìnira ju bí aṣa ṣe fi àyè sílè lọ. Èyí mú kí wọ́n ro lóyè, tí wọ́n sì kéde arákùnrin rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí olú ọba lẹ́yìn ọ̀pọ̀lọpọ̀ àtakò láti ọ̀dọ̀ àwọn ìjòyè rẹ.

Ṣùgbọ́n wọn padà pé láti wá je ọba lẹhin iku Shango, ẹniti, gẹgẹbi arosọ àtẹnudẹ́nu, di oriṣa Àrá. [3] Òpó ọdún lórí apẹrẹ, ìwà òun na padà kúrò ní tútù sì gbígbóná bí ti arákùnrin re. Basorun tabi Alakoso Agba ati Balogun nigba ijọba rẹ keji ni Salekoudi, ati pe ni akoko yii ni Ilu Yoruba, Ogidigbo, jẹ́ àfilólè ní ìlú Òyó . Ilu naa si je oun tiwọn nlo ni awon ayeye nla ti Alaafin ati Basorun bá wà .

Àjàká ni ọmọ kan, ọmọbìnrin kan, ti o ku ninu ina ni kete lẹhin igbeyawo rẹ. [2]

  1. Colonialism Within and Without: The Old Oyo Empire in West Africa
  2. 1 2 Oyewumi, Oyeronke (2016-09-27) (in en). African Gender Studies: A Reader. Springer. ISBN 978-1-137-09009-6. https://books.google.com/books?id=RlUBDgAAQBAJ&dq=Ajaka+oyo&pg=PA184.
  3. 1 2 3 4 Smith, Robert (2023-12-20) (in en). Kingdoms of the Yoruba. Taylor & Francis. ISBN 978-1-003-80417-8. https://books.google.com/books?id=RFneEAAAQBAJ&dq=Ajaka+oyo&pg=PT38.