Jump to content

Àwọn ìdìtẹ̀gbàjọba àwọn ológun ní Nàìjíríà

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́

Láti ìgbà tí orílẹ̀ èdè Nàìjíríà ti gba òmìnira ní ọdún 1960, àwọn ìdìtẹ̀gbàjọba àwọn ológun márùn-ún ló ti wáyé. Láàárín ọdún 1966 sí 1999, ìjọba ológun ló ń ṣàkóso orílẹ̀ èdè Nàìjíríà láìsí ìdíwọ́, yàtọ̀ sí ìpadàbọ̀ sí ìjọba tiwantiwa fún ìgbà díẹ̀ lábẹ́ ìjọba Olómìnira Kejì láti ọdún 1979 sí ọdún1983. [1] Síbẹ̀síbẹ̀, ìdìtẹ̀gbàjọba tó wáyé kẹ́hìn ni eléyìí tó wáyé ní ọdún 1993, kò sì sí ìgbìyànjú pàtàkì kankan lábẹ́ Ìjọba olómìnira Kẹrin, èyí tó mú ìjọba tiwantiwa padà bọ̀ sípò ní ọdún 1999 pẹ̀lú dídá àwọn ẹgbẹ́ òṣèlú púpọ̀ sílẹ̀.

Àkójọ àwọn ìgbìyànjú ìdìtẹ̀gbàjọja àti àwọn ìdìtẹ̀gbàjọja tó wáyé

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Ìdìtẹ̀gbàjọja oṣù kìíní ọdún 1966

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Ní ọjọ́ kẹẹ̀ẹ́dógún oṣù kìíní ọdún 1966, ẹgbẹ́ àwọn ọmọ ogun tí wọ́n jẹ́ ọ̀dọ́ bi ìjọba Nàìjíríà ṣubú, èyí sì fòpin sí ìjọba Olómìnira àkọ́kọ́ tí ó wà fún ìgbà kúkúrú. ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ọmọ ogun tí wọ́n ṣe iṣẹ́ náà jẹ́ ọ̀dọ́, tí Kaduna Nzeogwu, jẹ́ olórí wọn, wọ́n sì pa ọ̀pọ̀ àwọn ará àríwá, lára wọn ni Olórí ìgbìmọ̀ ìjọba Tafawa Balewa, Alákòóso Ahmadu Bello, Alákòóso Ladoke Akintola, Mìnìsìtà fún ètò Ìṣúná Festus Okotie-Eboh, àti àwọn olórí àwọn ọmọ ogun mẹ́rin tí wọ́n ga jùlọ ní apá àríwá. Àwọn olórí ìdìtẹ̀gbàjọba náà ṣèlérí ní gbangba láti fòpin sí ìwà ìbàjẹ́, láti dín ìwà ipá kù, àti láti ṣètò ìdìbò tuntun. Ọ̀gágun Johnson Aguiyi Ironsi, tí ó tún jẹ́ ọmọ Igbo ṣùgbọ́n tí kò kópa nínú ìdìtẹ̀gbàjọba àkọ́kọ́ náà, dá sí i láti fi ìbáwí lé àwọn ológun lọ́wọ́, ó sì di olórí ìjọba. Ó gbẹ́sẹ̀ lé ìwé òfin, ó tú ilé ìgbìmọ̀ aṣòfin ká, ó fòfin de àwọn ẹgbẹ́ òṣèlú, ó sì dá ìjọba ológun fìdí fẹ ẹ́ sìlẹ̀, láìsọ ọjọ́ tí a óò dá ìjọba àwarawa padà. [1]

Àtúndìtẹ̀gbàjọba ní oṣù Keje ọdún 1966

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Ní ọjọ́ kọkàndínlọ́gbọ̀n oṣù keje ọdún 1966, àtúndìtẹ̀gbàjọba kan bẹ̀rẹ̀, a sì ti dojú ìjọba Ironsi bolẹ̀ ní ọjọ́ kìíní oṣù kẹjọ. Yakubu Gowon di olórí ìjọba. Ironsi àti gómìnà agbègbè ìwọ̀ oòrùn, Francis Adekunle Fajuyi, wà lára àwọn tí ó bá ìṣẹ̀lẹ̀ náà lọ. Muhammadu Buhari, ẹni tí a fi ṣe olórí ìjọba ní ọdún 1983, jẹ́ ọ̀kan lára àwọn ológun tí ó kópa nínú ìdìtẹ̀gbàjọja náà. Àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ méjèèjì yìí dá awuyewuye sílẹ láàrín àwọn ẹ̀yà tí ó sì dà rúkèrúdo àti ìjà ẹlẹ́yàmẹyà sílẹ̀, èyí tí ó fa ìṣẹ̀lẹ̀ tí ó yọrí sí ogun abẹ́lé ní Nàìjíríà nígbẹ̀yìn gbẹ́yín. [1] Lẹ́yìn tí ogun náà parí, ní oṣù kẹwàá ọdún 1970, Gowon tún sọ ìlérí rẹ̀ tẹ́lẹ̀ láti rí i dájú pé ìjọba ológun yóò parí ní ọjọ́ kìíní oṣù kẹwàá ọdún 1976. Ṣùgbọ́n ní ọdún 1974, ó sún ìgbà ìjọba àwarawa síwájú, ó ṣàlàyé pé àwọn ọmọ Nàìjíríà kò tí ì fi “ìwọ̀ntúnwọ̀nsì àti ìkóra-ẹni-níjàánu hàn nínú àwọn ìwà wọn”.

Ìdìtẹ̀gbàjọba ọdún 1975

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Ní ọjọ́ kọkàndínlọ́gbọ̀n oṣù keje ọdún 1975, kọ́nẹ̀lì Joseph Nanven Garba, ọ̀rẹ́ Gowon tímọ́tímọ́, kéde lórí Redio àpapọ̀ ilẹ̀ Nàìjíríà pé òun àti àwọn ológun mìíràn ti pinnu láti yọ Gowon kúrò gẹ́gẹ́ bí olórí ìjọba àti olórí àwọn ọmọ ogun. [2] [3] ìdìtẹ̀gbàjọba náà kò ní ìtàjẹ̀sílẹ̀ nínú: Gowon wà ní ìlẹ òkèèrè, ó lọ sí ìpàdé Àjọ Ìṣọ̀kan Àgbáyé ní Kampala . [4] Wọ́n fi alákòóso ọmọ ogun Murtala Muhammed rọ́pò rẹ̀, wọ́n sì fi alákòóso ọmọ ogun Olúṣẹ́gun Ọbásanjọ́ sì jẹ́ igbákejì olórí ìjọba. Ìwé ìròyìn New York Times ròyìn pé Ọ̀gágun Hassan Katsina, olórí ẹgbẹ́ ọmọ ogun tẹ́lẹ̀ tí Gowon ti àdíkù ipò rẹ̀, ni wọ́n sọ pé òun ni ó ṣe agbátẹrù “ ìdìtẹ̀gbàjọba náà.” [4] Ní ọjọ́ kìíní oṣù kẹwàá, Muhammed, bíi Gowon, ṣe ìlérí láti padà sí ìjọba alágbádá: lẹ́yìn tí wọ́n ṣe àkọsílẹ̀ òfin tuntun àti onírúurú àyípadà sí ìwé òfin, wọ́n yóò ṣètò ìdìbò, èyí tí yóò jẹ́ kí wọ́n gbé agbára sílẹ̀ ní ọjọ́ kìíní oṣù kẹwàá ọdún 1979. [5]

Ìgbìyànjú ìdìtẹ̀gbajọba ní ọdún 1976

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Ní ọjọ́ kẹtàlá oṣù kejì ọdún 1976, wọ́n pa Muhammed ní ìbẹ̀rẹ̀ ìgbìyànjú ìdìtẹ̀gbàjọba kan tí ó kùnà. Wọ́n pa awakọ̀ àti olùrànlọ́wọ́ rẹ̀; bákan náà ni Ibrahim Taiwo, gómìnà ológun ti ìpínlẹ̀ Kwara . [6] Àwọn ológun kan tí wọ́n pe ara wọn ní “àwọn ọ̀dọ́ oníjàgídíjàgan” nínú ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ lórí rédíò kan tí wọ́n ṣe; síbẹ̀síbẹ̀, wọn kò ní àtìlẹ́yìn láti ọ̀dọ̀ àwọn olóṣèlu àti ológun. [6] [7] Àwọn olórí ẹgbẹ́ àwọn ọmọ ogun àti àwọn olórí ìjọba tìkò sí ní ìlú Èkó korò ojú sí ìdìtẹ̀gbàjọba náà, wọ́n sì paná rẹ̀ kíákíá. [6] Ọbásanjọ́ di olórí ìjọba. Ìjọba Nàìjíríà ròyìn pé kọ́nẹ̀lì kejì Bukar Suka Dimka ló darí ìdìtẹ̀gbàjọba náà, wọ́n sì fẹ́ dá ìjọba Gowon padà. [8] Wọ́n mú àwọn ènìyàn tí ó tó marùndiláàádóje látàrí ípá tí wọ́n kó nínú ìdìtẹ̀gbàjọba náà, ní oṣù kẹta, wọ́n dájọ́ ikú fún ènìyàn méjìlélọ́gbọ̀n, lára wọn ni Dimka àti mínísítà fún ètò ààbò, Ọ̀gágun Illiya D. Bisalla . [9]

Ìdìtẹ̀gbàjọba ọdún 1983

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Ní ọjọ́ kọkànlélọ́gbọ̀n oṣù Kejìlá ọdún 1983, àpejọ ọ̀gá àwọn ọmọ ológun kan ṣe ìdìtẹ̀gbàjọba kan tí ó fòpin sí ìjọba olómìnira Nàìjíríà Kejì . [10] ìdìtẹ̀gbàjọba náà yọ Ààrẹ Shehu Shagari tí àwọn ará ìlú dìbò yàn gẹ́gẹ́ bí ààrẹ ìjọba tiwantiwa kúrò, nínú ìròyìn àkọ́kọ́ lẹ́yìn ìdìtẹ̀gbàjọba náà, alákòóso ọmọ ogun Sani Abacha pe ní "aláìní ọgbọ́n àti ìwà ìbàjẹ́". [11] Abacha, ẹni tí a yàn gẹ́gẹ́ bí olórí ìjọba ní ọdún mẹ́wàá lẹ́yìn náà, ni a sọ pé ó kó "ipa pàtàkì" nínú ìdìtẹ̀gbàjọba náà. [12] Ìpànìyàn kan ṣoṣo tí a ròyìn ni ó ṣẹlẹ̀ nígbà tí wọ́n pa alákòóso ọmọ ogun Ibrahim Bako nínú ìjà iná nígbà tí wọ́n mú Shagari ní Abuja . [13] Ọ̀gágun Muhammed Buhari ni wọ́n fi jẹ olórí ìjọba lẹ́yìn náà. [14] [15]

Ìdìtẹ̀gbàjọba ọdún 1985

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Ní ọjọ́ kẹtàdínlógún oṣù kẹjọ ọdún 1985, àwọn ológun tí Ọ̀gágun Ibrahim Babangida, olórí àwọn ọmọ ogun, darí ìdìtẹ̀gbàjọba kúrò lọ́wọ́ Buhari nínú ìdìtẹ̀ ààfin nígbà tí Buhari fúnra rẹ̀ kò sí ní ìlú Èkó, igbákejì tàbí olùrànlọ́wọ́ rẹ̀, Ọ̀gágun Túndé Ìdíàgbọn, sì wà ní ìrìn àjò lọ sí Saudi Arabia. [16] Ọ̀gágun Joshua Dogonyaro ló kéde ìdìtẹ̀gbàjọba náà lórí rédíò ní òwúrọ̀, Babangida sì bá àwọn ọmọ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà sọ̀rọ̀ lẹ́yìn náà, ó ní ìjọba Buhari “le koko, kò sì mọ bí a tí ń yí ẹnu padà” ó sì ti fi “àìbáramu àti àìní òye” hàn. [17] [18]

Ìgbìyànjú ìdìtẹ̀gbajọba ní ọdún 1990

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Ní ọjọ́ kejìlélógún oṣù kẹrin ọdún 1990, àwọn ọmọ ológun tí Ọ̀gágun Gideon Orkar darí ìkọlu sí Dodan Barracks nínú ìgbìyànjú láti gba ìjọba Babangida. [19] Babangida sá àsálà fún ẹ̀mí rẹ̀, ìjà sì dúró lẹ́yìn wákàtí mẹ́wàá lẹ́yìn náà, nígbà tí àwọn olórí àwọn ọmọ ológun níbòmíràn ní orílẹ̀-èdè náà kéde àtìlẹ́yìn wọn fún Babangida. Àwọn ọkùnrin méjìlélógójì tí wọ́n dá lẹ́bi pé wọ́n lọ́wọ́ nínú ìgbìyànjú ìdìtẹ̀gbàjọba ni wọ́n pa pẹlú ìbọn ní oṣù keje ọdún 1990.

Ìdìtẹ̀gbàjọba ọdún 1993

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Nígbà tí Babangida dojúkọ ìfúngun láti yípadà sí ìjọba tiwantiwa, ó fi ipò rẹ̀ sílẹ̀ ó sì yan Ernest Shonekan gẹ́gẹ́ bí ààrẹ fìdí ẹẹ́ ní ọjọ́ kẹrìndínlógún oṣù kẹjọ ọdún 1993. Ìjọba ìyípadà Sónẹ́kàn dúró fún oṣù mẹ́ta péré: ní ọjọ́ kẹtàdínlógún oṣù kọkànlá ọdún 1993, wọ́n bì ìjọba náà lulẹ̀ nínú ìdìtẹ̀gbàjọba tí ọ̀gágun Sani Abacha darí rẹ̀. [20] [21] Èyí tẹ̀lé ìfagilé ìdìbò ààrẹ tí wọ́n ti polówó gẹ́gẹ́ bí ìbẹ̀rẹ̀ ìjọba Olómìnira Kẹta ti Nàìjíríà . Ní oṣù kẹsàn-án ọdún 1994, bó tilẹ̀ jẹ́ pé ó ti ṣèlérí láti mú ìjọba tiwantiwa padà bọ̀ sípò, [22] [23] Abacha pàṣẹ kan tí ó gbé ìjọba rẹ̀ ga ju àṣẹ ilé ẹjọ́ lọ, èyí tí ó fún un ní agbára pátápátá. [24] [25]

Àwọn ìtàn ìdìtẹ̀ ìjọba

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Ní ọ̀pọ̀ ọdún sẹ́yìn, ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ènìyàn ńla lati mú látàrí àwọn ìdìtẹ̀gbàjọba tó ti wáyé:

  • Ní oṣù Kejìlá ọdún 1985, ìjọba Babangida kéde pé ó ti dẹ́kun ìgbìyànjú ìdìtẹ̀, ó sì ti mú àwọn tó ṣe é, títí kan Ọ̀gágun Mamman Vatsa . [26] Àwọn ológun mẹ́tàlá gba ìdájọ́ ikú fún ìdìtẹ̀ láti ṣe ìdìtẹ̀, àti mẹ́wàá nínú wọn, títí kan Vatsa, ni wọ́n pa nípa ìbọn ní oṣù kẹta ọdún 1986.
  • Ní oṣù Keje ọdún 1995, ìjọba Abacha dá àwọn ènìyàn ogójì lẹ́bi fún ìdìtẹ̀gbàjọba. Obasanjo, olórí orílẹ̀-èdè tẹ́lẹ̀ rí, wà lára àwọn tí wọ́n fi sẹ́wọ̀n, gẹ́gẹ́ bí Musa Yar'Adua náà ṣe wà níbẹ̀.
  • Ní oṣù Kejìlá ọdún 1997, ìjọba Abacha kéde pé ó ti dẹ́kun ìgbìyànjú ìdìtẹ̀gbàjọba tí igbákejì rẹ̀, Ọ̀gágun Oladipo Diya, gbèrò, ẹni tí ori ṣẹ̀ṣẹ̀ kóyọ nínù ìgbìyànjú ìpànìyàn. [27] [28] Àwọn ọ̀gágun mẹ́ta mìíràn, àwọn kọ́nẹ́ẹ̀lì márùn-ún, àti àwọn olórí mẹ́ta mìíràn tún wà tí wọ́n mú. Àwọn alárìíwísí fura sí pé ìdìtẹ̀ náà jẹ́ àbò fún ìwẹ̀nùmọ́ . [29]
  • Ní oṣù kẹrin ọdún 2004, ìjọba Ọbásanjọ́ tí a yàn gẹ́gẹ́ bí tiwantiwa sọ pé ó ti mú ọ̀pọ̀ àwọn ológun ní ìsopọ̀ pẹ̀lú ètò ìdìtẹ̀ kan. Wọ́n fura sí Hamza al-Mustapha, olórí ààbò ti Abacha, pé ó lọ́wọ́ nínú rẹ̀. [30]
  • Ní ìparí oṣù kẹsàn-án ọdún 2025, ìdìtẹ̀gbàjọba sí ìjọba Tinubu tí àwọn ọ̀tẹlẹ̀múyẹ́ àwọn ológun Nàìjíríà tú síta tí àwọn oníròyìn Sahara Reporters sì tú síta. Wọ́n fagilé ìtòlẹ́sẹẹsẹ ológun láti ṣàyájọ ọjọ́ òmìnira tí wọ́n ṣètò fún ọjọ́ kìíní oṣù kẹwàá ọdún 2025 , àwọn ológun mẹ́rìndínlógún ni wọ́n mú láti ọwọ́ ilé iṣẹ́ ọ̀tẹlẹ̀múyẹ́ tó ń rísí ètò ààbò . [31] Àwọn ìròyìn àkọ́kọ́ nípa ìdìtẹ̀gbàjọba náà ni àwọn ológun sẹ̀, wọ́n sì sọ pé ìdí tí wọ́n fi gbé àwọn ọmọ ológun kan tì mọ́lé ni láti báwọn wí fún ìwà àìtọ́. Wọ́n sọ pé ìdìtẹ̀ náà kan àwọn ọ̀gá ọmọ ogun láti àríwá tí Musa Abubakar Sadiq ṣe olórí pẹ̀lú ìrànlọwọ owó tí wọ́n sọ pé ó wá láti ọwọ gómìnà tẹ́lẹ̀ àti mínísítà epo rọ̀bì Timipre Slyva . [32] Àwọn ọlọ̀tẹ̀ náà gbèrò láti fi ipá gba ìjọba àpapọ̀ ní ọjọ́ kẹẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n oṣù kẹwàá nípa pípa Ààrẹ àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ọ̀gá lẹ́ka ìjọba . Tinubu rọ́pò àwọn ọ̀gá àwọn ọmọ ológun ní ọjọ́ kejìdínlógún oṣù kẹwàá, pẹ̀lú yíyan Ọ̀gágun Olúfẹ́mi Olúyẹdé tí wọ́n gbé ga sí olórí àwọn ẹ̀ṣọ́ aláàbò, ìwádìí sì ṣì ń lọ lọ́wọ́. [33]

Gẹ́gẹ́ bí òpìtàn ará Nàìjíríà Max Siollun ti sọ, “Àwọn ìdìtẹ̀gbàjọba ológun àti ìṣàkóso ológun (tí ó bẹ̀rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìyípadà pàjáwìrì) di ohun tí ó dà bí ẹni pé ó wà nínú ìṣèlú Nàìjíríà títí láé.” Ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ohun àlùmọ́nì àbáláyé ni a tún ti tọ́ka sí gẹ́gẹ́ bí ìdí fún ìdìtẹ̀ ológun tí ó wọ́pọ̀ nínú ìtàn Nàìjíríà.

Àwọn ìjà ẹlẹ́yàmẹyà ti kó ipa pàtàkì nínú bí ìdìtẹ̀gbàjọba ṣe ń wáyé jẹ́ àbájáde ìṣàkóso ìjọba amúnisìn tí ó dá ìjọba àtọwọ́dá tí ó ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹ̀yà ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀. Àwọn ẹgbẹ́ ẹ̀yà ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ wọ̀nyí ni àwọn ẹgbẹ́ ẹ̀yà ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ wà ní ipò wọn, èyí tí ó rí i dájú pé “kò sí ọ̀kan lára àwọn ẹgbẹ́ náà tí ó lè ṣàkóso Nàìjíríà fúnra rẹ̀, àti… pé ìjà náà jẹ́ ọ̀rọ̀ àkókò lásán.” Nítorí náà, kò sí àtakò tí ó wà ní àárín gbùngbùn sí ìṣàkóso ológun; nígbà tí ìdìtẹ̀gbàjọba kan bá ṣẹlẹ̀, ó jẹ́ ẹgbẹ́ mìíràn ti ìjọba ológun. [ <span title="The text near this tag may need clarification or removal of jargon. (May 2022)">ìtumọ̀ nílò</span> ]

Àwọn ipa ìjọba ológun

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Àwọn ipa ọrọ̀ ajé ti ìjọba ológun ti ní lori eto ọrọ̀ ajé Nàìjíríà ló burú jọjọ. A ti fi ọrọ̀ ajé àtọwọ́dọ́wọ́ tí ó dá lórí iṣẹ́ àgbẹ̀ sílẹ̀, ìjọba Nàìjíríà sì gbára lé títa epo rọ̀bì sí òkè òkun, èyí tí ó dá lórí ìyípadà owó epo nígbà gbogbo, ó sì fa ọrọ̀ ajé tí kò dúró dáadáa. Ìjọba Babangida ní “ni ó burú jáì, nípa fífi àwọn ohunàlùmọ́nì ṣòfò àti àìníṣàkóso, fífi ipò ìjọba àti àwọn ohun àlùmọ́nì ìjọba ṣe àdáni, àìbìkítà àwọn ẹ̀ka tí kì í ṣe ti epo rọ̀bì àti àwọn ohun pàtàkì tí a kò fi sí ipò pàtàkì”. Nítorí ìlànà ọrọ̀ ajé ológun ti àwọn ọdún 1980, ìdá márùndínláàádọ́ta owó tí wọ́n ń rí gbà láti owó tí wọ́n ń rí níbi okòwò ilẹ̀ òkèrè ni wọ́n fi ń san gbèsè, kò sì sí ìdàgbàsókè tó múnádóke. Èyí yọrí sí ìṣẹ́, ìwà ọ̀daràn, ìlòkulò ọmọdé, àrùn, ìbàjẹ́ ilé-iṣẹ́ àti ìyapa ìlú. [34] Àìdúróṣinṣin àti àìnítẹ́lọ́rùn tí àwọn ìlànà wọ̀nyí fà jẹ́ ọ̀kan lára àwọn ohun tí ó fa ìdìtẹ̀gbàjọba déédé.

  • Ìtàn Nàìjíríà
  • Ìjọba ológun ní Nàìjíríà
  • Àkójọ àwọn ìgbìyànjú ìdìtẹ̀gbàjọba nípasẹ̀ orílẹ̀-èdè

Àwọn Àkíyèsí Àkọ́kọ́

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]
  1. 1 2 3 Metz, Helen Chapin (1991). Nigeria: A Country Study. Washington: GPO for the Library of Congress. http://countrystudies.us/nigeria.
  2. .
  3. .
  4. 1 2 "Gowon Ousted in Nigeria; Coup Ends Nine‐Year Rule". https://www.nytimes.com/1975/07/30/archives/gowon-outsted-in-nigeria-coup-ends-nineyear-rule-gowon-deposed-as.html.
  5. .
  6. 1 2 3 Darnton, John (1976-02-15). "Nigeria confirms killing of leader" (in en-US). The New York Times. ISSN 0362-4331. https://www.nytimes.com/1976/02/15/archives/nigeria-confirms-killing-of-leader-military-council-gives-post-to.html.
  7. .
  8. .
  9. .
  10. .
  11. .
  12. .
  13. .
  14. .
  15. .
  16. .
  17. .
  18. .
  19. .
  20. .
  21. .
  22. .
  23. .
  24. .
  25. .
  26. .
  27. .
  28. .
  29. .
  30. .
  31. .
  32. .
  33. .
  34. Àṣìṣe ìtọ́kasí: Invalid <ref> tag; no text was provided for refs named Ihonvbere, p.196

Kíkà síwájú síi

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]