Àwọn Ará Ẹ̀gbá
Àwọn ará Ẹ̀gba jẹ́ ẹ̀yà kan nílẹ̀ Yorùbá, ẹ̀yà kan ní ìwọ̀ oòrùn Nàìjíríà, ọ̀pọ̀lọpọ̀ wọn sì wá láti àárín gbùngbùn Ìpínlẹ̀ Ogun, ìyẹn ẹkùn tó ń ṣojú Àárín Gbùngbùn ìpinlẹ̀ Ogun ní ilé ìgbìmọ̀ aṣòfin àgbà.
Àárín Gbùngbùn ìpinlẹ̀ Ogun ní ilé ìgbìmọ̀ aṣòfin àgbà ni ó ní àpapọ̀ ìjọba ìbílẹ̀ mẹfà tí àwọn mẹ́fẹ̀fà sì lọ báyìí: Àríwa Abẹ́òkúta, Gúsù Abẹ́òkúta, Ewékorò, Ifọ̀, Obáfẹ́mi Owódé àti ìjọba ìbílẹ̀ Ọdẹ́dá. Àwon Ẹ̀gbá mìíràn tí wọn ní aṣojú ní ilé ìgbìmọ̀ aṣòfin àgbà wà ní Ìwọ̀ oòrùn ìpínlẹ̀ Eko, Ìlà oòrùn ìpinlẹ̀ Èkó, Àríwá Ìpínlẹ Ọ̀yọ́, àti Gúsù ìpínlẹ Ọ̀yọ́.

Kí wọ́n tó dá Gúúsù orílẹ̀ èdè Nàìjíríà sílẹ̀, agbègbè àti àwọn ènìyàn Ẹ̀gbá ni wọ́n pààlà pẹ̀lú Ketu (Benin) ní ìwọ̀ oòrùn, Ìlú Èko ní gúúsù, Ìjẹ̀bú ní ìlà-oòrùn, àti Ọ̀yọ́, Ìbàdàn àti Isoya nítòsí Ilé Ife ní àríwá. Àwọn ènìyàn náà so pọ̀ mọ́ Odò Ogun, ṣùgbọ́n wọ́n ya ara wọn sọ́tọ̀ kúrò ní etíkun ti ìlú Èko tí ó kún fún ẹrẹ̀. Nípasẹ̀ ilẹ̀ Egba, àwọn ọ̀nà tààrà wà sí àwọn ìlú Yorùbá mìíràn, bíi Ìlú Èkó, Ìbàdàn, Ìjẹ̀bú-Òde, Kétu (Benin), àti Porto Novo (Àjàṣẹ́) ní ilẹ̀ olómìnira Benin. [1] [2]
Ẹ̀kọ́ nípa Ẹ̀tọ́
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Ìpilẹ̀ṣẹ̀ ọ̀rọ̀ náà "Egba" jẹ́ àríyànjiyàn. Ìtumọ̀ àkọ́kọ́ lè wá láti inú ọ̀rọ̀ náà "Ẹgbálugbó", tí ó túmọ̀ sí àwọn arìnrìn-àjò lọ sí ijù, èyí sì wá láti inú òtítọ́ pé àwọn baba ńlá àwọn ará Egba wá láti agbègbè Ilẹ̀ Ọba Ọ̀yọ́ sí "Igbó Egba" wọ́n sì dá ohun tí a mọ̀ lóde òní sí ìlú Abeokuta sílẹ̀. Àwọn "Egbalugbo" wà ní ìsopọ̀ pẹ̀lú Ẹgbáluwé tàbí Ẹgbálodó, tí ó túmọ̀ sí àwọn arìnrìn-àjò lọ sí odò, tí wọ́n gé orúkọ náà kúrú sí " Ẹgbádo ," àwọn ẹ̀yà mìíràn ní ilẹ̀ Yorùbá. Ìtumọ̀ mìíràn tí ó ṣeé ṣe lè wá láti "Ẹsẹ̀gbá," orúkọ olóyè kan tí ó darí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹgbẹ́ ti Ẹ̀gbá sí ibi tí wọ́n wà nísinsìnyí. [3]
Ìtàn
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Ẹgbẹ́ Egba, tí ó wà lábẹ́ ìjọba Ọ̀yọ́ ní àkọ́kọ́, gba òmìnira lẹ́yìn ìparun ńlá tó débá Ọ̀yọ́ ní abala àkọ́kọ́ ọ̀rúndún kọkàndínlógún. Àwọn ogun pẹ̀lú Dahomey, nínú èyí tí àwọn Ẹ̀gba ṣe àṣeyọrí látara ààbò tí wọ́n fún wọn láti ọwọ́ Òkúta Olumo, ló mú kí wọ́n dá ìlú Abeokuta sílẹ̀, èyí tí ó túmọ̀ sí “lábẹ́ àpáta”.
Ilẹ̀ Ẹ̀gba ni ó pín sí àwọn ẹka wọ̀nyí: Aké, Òwú, Òkè Ọnà àti Gbágùrá, ọ̀kọ̀ọ̀kan ló ní ọba tirẹ̀. (Nínú ìtàn, orílẹ̀-èdè Egba jẹ́ ti àwọn ìpín mẹ́rin wọ̀nyí; Ìbarà, bó tilẹ̀ jẹ́ pé ilẹ̀ Abeokuta wà ní àgbègbè rẹ̀ pẹ̀lú, jẹ́ ara ilẹ̀ Yewa.) Nígbà ìjọba amúnisìn ti àwọn ará ìlú ọba gba Alake (tàbí Ọba Ake) gẹ́gẹ́ bí olórí pàtàkì fún gbogbo ẹ̀yà àti agbègbè wọn, nítorí náà, a ń pe ẹni tí ó tẹ̀lé e ní Aláké ti Ìlú Ẹ̀gba báyìí. Nítorí náà, àwọn oyè ọba àwọn ìpín tí a mẹ́nu ṣáájú yìí ni Aláke ti ìlú Ẹ̀gba, Oshile ti Òkè Ọnà, Àgùrá ti Gbágùra, àti Olówu ti ilẹ̀ Òwu, ní ìtòlẹ́sẹẹsẹ ìtẹ̀dó àti ipò àgbà ní orílẹ̀-èdè Ẹ̀gba.
Ó yẹ kí a ṣe àkíyèsí pé ìlú ìbílẹ̀ àti ibi ìtẹ̀dó orílẹ̀-èdè Ẹ̀gba ní Ìlú Ẹ̀gba ni o wà lábẹ́ àti ní àyíká Òkúta Olumo, èyí tí ó wà ní agbègbè Ìkijà/Ìkèrèkú ti Ẹ̀gbá Òkè Onà, Jagunnà ti Ìtokò, olóyè Òkè Ọnà, ni Olúwo Olúmọ̀. Òkúta Olúmo wà ní agbègbè àti lábẹ́ ìṣàkóso àwọn Ìtokò.
Orúkọ mìíràn tí àwọn tí ó pìlẹ̀ ìlú Abẹ́òkúta ń pe àwọn ènìyàn ibẹ̀ ni Oko Adagba ní ìtọ́kasí ọdẹ tó ṣàwárí Àpáta Olumo. Adagba lọ ṣọdẹ láti wá àwọn ẹranko ìgbẹ́ láti ìlú Ọbańtokò níbi tí àwọn ọmọ ìlú Itoko ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ dúró sí nígbà tí wọ́n ń rìn kiri láti lọ sí ibi ìsádi kan. Lẹ́yìn náà, ni ó ṣàwárí òkè náà.
Ílẹ̀ Ẹ̀gbá ni ibi tí Henry Townsend ń gbé, ó sì tún jẹ́ ilé ìwé ìròyìn àkọ́kọ́ ní Nàìjíríà ( Iwe Iroyin ). Àwọn ènìyàn ibẹ̀ ńi àkọ́kọ́ nínú ọ̀pọ̀lọpọ̀ìlú ní orílẹ̀-èdè Nàìjíríà (títí di àìpẹ́ yìí, ọ̀kan ṣoṣo nínú wọn) láti ní orin ìyìn.
Orin Ẹ̀gbá
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]- Lórí òkè ò'un pẹ̀tẹ́lẹ̀
- Ibẹ̀ l'agbé bí mi ò
- Ibẹ̀ l'agbé tọ́ mi d'àgbà oo
- Ilẹ̀ òmìnira
- Chorus : Maa yọ̀, maa yọ̀, maa yọ̀ o; l'Órí Olúmọ; Maa yọ̀, maa yọ̀, máà yọ̀ o; l'Órí Olúmọ
- Abẹ́òkúta ìlu Ẹ̀gbá
- N kó ní gbagbé è rẹ
- Kò gbé ọ l'ẹ́kè ọkàn mi
- Bí ìlú odò ọya
- Èmí ó f'Abẹ́òkútà ṣògo
- Kò dúró ní orí Olúmọ
- Maayọ̀ l'orúkọ Ẹ̀gbá ooo
- Èmi ọmọọ Líṣàbi
- E e
- Chorus : aa yọ̀, maa yọ̀, maa yọ̀ o; l'Órí Olúmọ; Maa yọ̀, maa yọ̀, máà yọ̀ o; l'Órí Olúmọ
- Èmí ó maayọ̀ l'órí Olúmọ̀
- Èmí ó s'ògoò yí l'ọ́kàn mi
- Wípé ìlú olókìkí o
- L'àwa Ẹ̀gbá ń gbé
- Chorus : maa yọ̀, maa yọ̀, maa yọ̀ o; l'Órí Olúmọ; Maa yọ̀, maa yọ̀, máà yọ̀ o; l'Órí Olúmọ
Aṣọ Àṣà Àtijọ́
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]- Àwọn ọkùnrin:
- Ṣòkòtò péńpe, Kẹ̀mbẹ̀/ Sòkòtò
- Buba àti Agbada
- Fila (abẹti aja)
- Àwọn obìnrin:
- Iro
- Buba
- Àwọn ìbòrí /ìbòrí /Gele
- Òmíràn: Ipele – Aṣọ tí a gbé sí èjìká tàbí tí a fi wé ìbàdí
Díẹ̀ lára Àwọn ọ̀tọ̀nkùlú tó jẹ́ ọmọ bíbí ilẹ̀ Ẹ̀gbá
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]- Ọba Ládàpọ̀ Samuel Adémọ́lá, Aláké ti ìlu Abeokuta, Adémọ́lá kejì 1920 sí ọdún 1962
- Ọ̀gbẹ́ni Adegboyega Edun, àlùfáà, olùkọ́, olórí àti olùṣàkóso ìjọba; Akọ̀wé ìjọba àpapọ̀ Ẹ̀gbá
- Olóyè Moshood Kashimawo Olawale Abiola, onísòwò àti olóṣèlú
- Amb. Akin Fayomi, diplomat, aṣoju sí ìlú France, Monaco, Liberia
- Olóyè Olusegun Obasanjo, Ààrẹ Nàìjíríà láti ọdún 1999 sí 2007
- Olóyè Ebenezer Olasupo Obey-Fabiyi, olórin àyi ajíhìnrere
- Ọgbẹ́ni Olufela Olusegun Oludotun Ransome-Kuti,olórin àti ajìjàgbara
- Oloyè Olufunmilayo Ransome-Kuti, ajìjàgbara ẹ̀tọ́ ọmọnìyàn àti "Ìyá Orílẹ̀-èdè"
- Ẹni Ọ̀wọ̀ Oludotun Israel Ransome-Kuti, Àlùfáà, olùkọ́ àti ọ̀gá àgbà (April 30, 1891 – April 6, 1955)
- Ọ̀jọ̀gbọ́n Olikoye Ransome-Kuti, onímọ̀ nípa ọmọdé, ajìjàgbara, àti mínísítà ìlera (Ọgbọ̀njọ́ Oṣù Kejìlá 1927 sí Ọjọ́ kínní Oṣù Kẹfà ọdún 2003)
- Olóyè Ernest Shónẹ́kàn, Ààrẹ fìdí ẹ́ ti orílẹ èdè Nàìjíríà, ọjọ́ kẹrìndínlọ́gbọ̀n Oṣù Kẹjọ Ọdún 1993 sí ọjọ́ kẹtàdínlógún Oṣù Kọkànlá 1993
- Ọ̀jọ̀gbọ́n Wole Soyinka, òǹkọ̀wé, ajìjàgbara àti ẹni tó gba ẹ̀bùn Nobel
- Olórí FRA Williams SAN, agbẹjọ́rò.
- Olóyè Bọ́lá Tinubu, olóṣèlú tó jẹ́ ààrẹ kẹrìndínlógún ní Nàìjíríà (láti ọdún 2023), gómìnà ìpínlẹ̀ Èkó tẹ́lẹ̀ (1999 sí 2007), àti Aṣòfin fún ìwọ̀ oòrùn Èkó ní ìjọba olómìnira kẹta ti Orílẹ̀-èdè Nàìjíríà
- Ogbeni Adewale Oke Adekola, onimọ-ẹrọ ilu, ọmọwe, onkọwe, ati oluṣakoso
- Olùṣọ́ Àgùntàn Tunde Bakare, amòfin ati Olùṣọ́ Àgùntàn
- Ọ̀gbẹ́ni Tunde Kelani, olùyàwòrán sinimá àti olùdarí
- Ọ̀gbẹ́ni Segun Odegbami, agbábọ́ọ̀lù
- Rt. Hon. Dimeji Bankole, Olórí ilé ìgbìmọ̀ aṣojù ṣòfin ní Nàìjíríà
- Arábìnrin Bukola Elemide, tí a tún mọ̀ ní Àṣá, akọrin,
- Ògbẹ́ni Olu Jacobs, òṣèré
- Sir Shina Peters, akọrin
- Alhaji Waheed Ayinla Yusuf (Omowura), olórin àpàlà
- Ọmọ-Ọba Bola Ajibola, adájọ́ ilé ẹjọ́ àgbáyé tó ti fẹ̀yìntì
- Olóyè Simeon Adebo, agbẹjọ́rò àti aṣojú
- Olóyè Fẹ́lá Sowande, olùkọ orin
- Olóyè JF Ọdunjo, ògbóǹtarìgì litireso Yoruba, Olùkọ ìwé Alawiye
- Ogbeni Tunde Lemo, Igbákejì Gómìnà Banki àpapọ̀ ilẹ̀ Nàìjíríà
- Ògbẹ́ni John Fashanu, agbábọ́ọ̀
- Ògbẹ́ni Femi Kuti, olórin
- Ògbẹ́ni Seun Kuti, olórin
- Ogbeni Made Kuti, akọrin
- Ọ̀gbẹ́ni Clarence Peters, olùdarí fídíò orin
- Ògbẹ́ni Ebun Oloyede, òṣèré
- Aṣòfin Ibikunle Amosun, gómìnà ìpínlẹ̀ Ogun láti ọdún 2011 sí 2019
- Olóyè Olusegun Osoba, oníròyìn àti olóṣèlú, gómìnà ìpínlẹ̀ Ogun láti ọdún 1999 sí 2003
- Arabinrin Zainab Balogun, òṣèré àti awoṣe
- Ọ̀jọ̀gbọ́n Adeoye Lambo, ọ̀jọ̀gbọ́n ìṣègùn, ìgbà kan rí tí ó ti jẹ́ Igbákejì Ààrẹ fún Àjọ Ìlera Àgbáyé (WHO)
- Ọ̀jọ̀gbọ́n Saburi Biobaku, igbákejì olórí ilé-ẹ̀kọ́ gíga ti Yunifásítì ti Èkó
- Olóyè Alaba Lawson, oníṣòwò àti ọ̀mọ̀wé
Wóò sìwájú si
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]- Egba United Government
Àwọn ìtọ́kasí
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Kíkà síwájú síi
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]- SO Biobaku: Àwọn Egba àti àwọn aládùúgbò wọn; 1842 - 1914. Oxford 1957.