Èdè Agatu
| Agatu | |
|---|---|
| North Idoma | |
| Sísọ ní | Nigeria |
| Ọjọ́ ìdásílẹ̀ | 1987 |
| Agbègbè | Benue State, Nassarawa State |
| Ìye àwọn afisọ̀rọ̀ | 70,000 |
| Èdè ìbátan | |
| Àwọn àmìọ̀rọ̀ èdè | |
| ISO 639-3 | agc |
Èdè Agatu, tàbí Èdè Ìdomà Àríwá, jẹ́ èdè Idomoid ti Nàìjíríà. Èdè yìí ni wọ́n ń pè ní èdè ìbílẹ̀ Ìdomà[1]
Orísun
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Agatu jẹ́ èdè abínibí tí ó dúró sán-ún ní Nàìjíríà. Èdè yìí jẹ́ ara èdè Niger-Congo. Gbogbo àwọn tó wà láwùjọ ẹ̀yà náà ló ń sọ èdè náà bí èdè Abínibí.[1]
Àgbéyẹ̀wò
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Èdè Agatu, tó jẹ́ apá kan ẹ̀yà Ìdomà nínú ẹ̀yà Niger-Congo, jẹ́ èdè tí nǹkan bí ọ̀kẹ́ mẹ̀ta àbọ̀ ènìyàn ń sọ ní àárín gbùngbùn Nàìjíríà, ní pàtàkì ní Ìpínlẹ̀ Benue. Ó jẹ́ èdè pàtàkì fún àwọn ènìyàn Agatu àti ìdánimọ̀ àṣà wọn.[2]
Àṣà
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Àṣà Agatu ní ọlá fún àwọn àgbààgbà àti àwùjọ, èyí tí ó hàn nínú èdè tí ó ń lo àwọn ọ̀nà ìfọ̀rọ̀wérọ̀ àti àwọn ọ̀rọ̀ ọ̀wọ̀. Àwọn ìyàtọ̀ kéékèèké wà nínú èdè ìbílẹ̀, àmọ́ wọ́n yé ara wọn dáadáa. Mímọ àwọn àṣà ìbílẹ̀ àti àwọn ohun tí wọn ò gbà gbọ́ ṣe pàtàkì fún ìjùmọ̀sọ̀rọ̀ tó gbéṣẹ́. Àwọn ayẹyẹ alágbára àti orin àtọwọ́dọ́wọ́ ti àwọn ènìyàn Agatu ń mú kí àṣà ìbílẹ̀ èdè náà pọ̀ sí i.[2]