Jump to content

Ère Ìkòròdú ọ̀gá

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́

Ìkòròdú ọ̀gá jẹ ère idẹ tí ó wà ní ìyípo ọ̀nà ní ìdíkọ̀ Ìkòròdú ní ìlú Èkó, Nàìjíríà, èyí tí ó ṣe àpèjúwe ọdẹ tí ó wà ní ìnàró tí ó sì ga ní ìwọ́n bàtà mẹ́ẹ̀dógún ní orí erin, tí ó sì mú ìbọn ìṣẹ̀mbáyé ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ àti àpò ìdẹ̀gbẹ́ ní èjìká àlàáfíà rẹ pẹ̀lú fìlà odẹ ní orí re. Wíwà rẹ̀ ni a ṣe ìwádìí rẹ̀ padà sí ọgọ́rùn ọdún mọ́kàndínlógún s'ẹ́yìn; a sì ṣíi l'ójú ní oṣù Kejì ọdún 1991.[1] Ère yìí nì a ti ọwọ́ olóògbé Samuel Omobowale Oduyebo ṣe. Ère náà ṣe àkàwé ìwà akin àti ìdarí Ogaremade, tí a gbàgbọ́ pé ó tẹ ilú Ìkòròdú dó, ọmọ ọba ìlu Sàgámù àti ẹni ìbẹ̀rẹ̀ pẹ̀pẹ̀ nínú ìdásílẹ̀ ìlú Ìkòròdú ní ọgọ́rùn ọdún mẹ́tàdínlógún.[2]