Òjó Arówóṣafẹ́
Ìrísí
Òjó Arówóṣafẹ́ tí gbogbo ènìyàn mọ̀ sí Fádèyí Olóró (ni wọ́n bí ní Ọjọ́ kẹẹ̀ẹ́dógún oṣù kẹsàn-án ọdún 1957) jẹ́ ọmọ bíbí Ìgbàrà odò ní ìpínlẹ̀ Èkìtì lórílẹ̀-èdè Nàìjíríà.[1]
Ìgbà èwe àti aáyan ìkẹ́kọ̀ọ́
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Fádèyí Olóró bẹ̀rẹ̀ ìkẹ́kọ̀ọ́ rẹ̀ ni St. Pauls Catholic Primary School, Ìgbàrà Odò, ní ìpínlẹ̀ Èkìtì. Ó tẹ̀ síwájú ní Timmy Agbale Grammar School, ní ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́ ayéjọ́un ṣùgbọ́n tí ó wà ní ìpínlẹ̀ Ọ̀ṣun báyìí. Ó bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ tíátà ṣíṣe ní ọdún 1977. Ìràwọ̀ rẹ̀ tàn nígbà tí ó kópa gẹ́gẹ́ bí Fádèyí Olóró nínú eré orí tẹlifíṣàn kan ní 1986 tí wọ́n pé àkọ́lé rẹ̀ ní Àrélù. Nínú eré yìí ni orúkọ ìnagijẹ rẹ̀ Fádèyí Olóró tí jẹ jáde.[2]
Àtòjọ díẹ̀ nínú àwọn sinimá-àgbéléwò tí ó ti kópa
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]- Adánilóró
- Fitu fona
- Bola ele o’ ku
- Adédogun
- Rúkèrúdò
Àwọn Ìtọ́kasí
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]- ↑ Akinyoade, Akinwale (2019-05-12). "Ailing Fadeyi Oloro Cries Out For Help To Nigerians". The Guardian Nigeria News - Nigeria and World News. Archived from the original on 2019-12-12. Retrieved 2019-12-16.
- ↑ "OLORO FADEYI". Modern Ghana. 2006-12-03. Retrieved 2019-12-16.