Jump to content

Ẹgbẹ́ Ẹlẹ́mu

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́

 

Ẹgbẹ́ àwọn akẹ́kọ̀ọ́ nípa àwùjọ àti àṣà ìbílẹ̀ tì a mọ̀ ní (Kegite Club International) jẹ́ ẹgbẹ́ àwọn akẹ́kọ̀ọ́ nípa àwùjọ àti àṣà ìbílẹ̀. Wọ́n dá a sílẹ̀ ní ọdún 1962 ní Yunifásítì Ọbáfẹ́mi Awólọ́wọ̀, tó wà ní Ilé-ifẹ̀, ní Ìpínlẹ̀ Ọ̀sun, orílẹ̀ èdèNàìjíríà . Ó ti dá ẹka oríṣiríṣi tó lé ní ọgọ́rùn-ún sílẹ̀, pàápàá jùlọ ní Nàìjíríà, àti ní ilẹ̀ Íńdíà, United Kingdom, àti Amẹ́ríkà pẹ̀lú. Ẹgbẹ́ náà ní àwọn ìrísí kan sí àwọn ẹgbẹ́ ní Nàìjíríà, ṣùgbọ́n ọ̀pọ̀ àwọn ọmọ Nàìjíríà kà á sí àjọ àṣà ìbílẹ̀ tí kò ní oun ìkọ̀kọ̀ kankan.

Àwọn akẹ́kọ̀ọ́ méje tí wọ́n jẹ Ọ̀mu Ẹmu ló dá Ẹgbẹ́ Ẹlẹ́mu yìí sílẹ̀ ní oṣù kẹwàá ọdún 1962 gẹ́gẹ́ bí ẹgbẹ́ àwùjọ àti àṣà ní Yunifásítì ti Ilé-Ife (tó jẹ́ Yunifásítì Ọbáfẹ́mi Awólọ́wọ̀ báyìí) ní Ifẹ̀, Ìpínlẹ̀ Ọ̀ṣun, ní orílẹ̀ èdè Nàìjíríà . [1] [2] Ẹgbẹ́ náà lo omi ọ̀pẹ (Ẹmu ọ̀pẹ) láti wọ inú àti láti gbé àṣà Áfíríkà lárugẹ. Olórí àkọ́kọ́ fún ẹgbẹ́ náà ni Olúṣẹ́gun Adéṣínà, tó wá di ọ̀jọ̀gbọ́n ní yunifásítì náà lẹ́yìn náà. [1] Obìnrin àkọ́kọ́ tí ó jẹ́ ọmọ ẹgbẹ́ rẹ̀ dara pọ̀ mọ́ wọn ní ọdún 1968. Síbẹ̀síbẹ̀, ẹgbẹ́ náà kógbáwọlé fún ìgbà díẹ̀ ní ìparí ọdún 1960. [2]

Ní ọdún 1972, ẹgbẹ́ tó fara pẹ́ ẹgbẹ́ náà, Ẹgbẹ́ Ẹlẹ́mu (Kegites Confraternity), ni a dá sílẹ̀ ní Yunifásítì ti Ìbàdàn . [2] [1] Ète àti èróńgbà rẹ̀ ni “láti lo àwọn orin Áfíríkà, ìtàn àròsọ àti àwọn ohun mìíràn ti ilẹ̀ Áfíríkà láti fún àwọn ọmọ ilé-ẹ̀kọ́ gíga ní ìgbà náà níyànjú láti máa ṣe ìtọ́jú àṣà àti ìṣe ilẹ̀ Áfíríkà wọn”. [3]

Àwọn ẹgbẹ́ méjèèjì para pọ̀ gẹ́gẹ́ bí Ẹgbẹ́ (Kegites) Ẹlẹ́mu ní ọdún 1973, tí wọ́n sì ṣe ayẹyẹ ní Ilé Ifẹ̀. [1] [2] Ẹgbẹ́ náà tàn dé Ilé Ẹ̀kọ́ gbogbonìṣe ti ilẹ̀ Ibadan ní ọdún 1973. [1] Ní ọdún 1974, ẹgbẹ́ náà bẹ̀rẹ̀ sí í tàn kálẹ̀ sí àwọn ilé ìwé mìíràn ní orílẹ̀ èdè Nàìjíríà, nígbẹ̀yìn-gbẹ́yín wọ́n dá a sílẹ̀ ní gbogbo àwọn ilé ẹ̀kọ́ gíga ní orílẹ̀-èdè náà. [1]

Wọ́n yí orúkọ rẹ̀ padà sí Ẹgbẹ́ Ẹlẹ́mu Àgbáyé (Kegite Club International) ní oṣù kẹwàá ọdún 1986. Wọ́n ṣí àwọn ẹ̀ka mìíràn ní Brazil, Ghana, India, Liberia, àti United Kingdom. [1] Àjọ náà ń gbé àṣà Áfíríkà lárugẹ, ó sì ń mú kí àwọn èyan gbàá mọ́ra, ó ń ṣe ìwúri òun ìgbega fún àwọn àṣà àti lílo àwọn ohun tí ó wá láti Áfíríkà, ó sì ń ṣe àwọn ìtàkurọ̀sọ tí ó jẹ mọ́ ìlù-lílu àti orin kíkọ níbi ìpéjọpọ̀ wọn. [2] [1] Ní ọdún 1996, wọ̀n ti ní ẹka tí ó jẹ́ oókandínláàádọ́rùn-ún. [1]

Ní ọdún 2024, ó ní ẹka tó ju ọgọ́rùn-ún lọ, títí kan ẹ̀ka àwọn akẹ́kọ̀ọ́ ní Íńdíà, United Kingdom, àti Chicago, Illinois. Yunifásítì Ọbáfẹ́mi Awólọ́wọ̀ ni olú ilé-iṣẹ́ rẹ̀ ní àgbáyé. [2] [1] Yunifásítì ti Ibadan ni olú ilé-iṣẹ́ orílẹ̀-èdè rẹ̀ (Nigeria). [2] [1]

Àwọn àmì àti àṣà

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Orúkọ wọn jẹ́ jáde láti ara "kèrègbè" ( Akèrègbè tí a ń lò fún ìtọ́jú Ẹmu Ògùrọ̀), "omi funfun" tí ó wá láti inú "igi ọ̀pẹ". [2] Àmì rẹ̀ ni igi ọ̀pẹ tí ó ń mú ẹmu ọ̀pẹ jáde tí ó sì máa ń wà ní gbogbo ìgbà, ó dúró fún àìkú láéláé. [4] Àwọn àwọ̀ rẹ̀ jẹ́ ewéko, àwọ̀ funfun, àti Àwọ̀ ilẹ̀. [1] Àwọ̀ ewéko ni àwọ̀ ewé ọ̀pẹ àti ìyè. [1] [5] Funfun ni àwọ̀ omi igi ọ̀pẹ ó sì dúró fún àlàáfíà. [5] [1] Àwọ̀ ilẹ̀ wá láti àwọ̀ igi ọ̀pẹ ó sì dúró fún ilẹ̀ àti erùpẹ̀. [5] [1]

Àkọlé Ẹgbẹ́ Àwọn Ẹlẹ́mu ni “Àṣà wa ni ogún wa; ran wa lọ́wọ́ láti gbé e ró”. [1] Àkọlé Ẹgbẹ́ Ẹlẹ́mu ni “Ìpìlẹ̀ ìṣọ̀kan Áfíríkà àti àlàáfíà àgbáyé nínú ẹmu ọ̀pẹ.” [2] [1] Àkọlé rẹ̀ di “Ìṣọ̀kan nínú onírúurú” pẹ̀lú ìyípadà orúkọ sí Ẹgbẹ́ ẹlẹ́mu Àgbáyé ní ọdún 1986. [2]

Àwọn ọmọ ẹgbẹ́ máa ń kọ orin ní èdè Yorùbá nípa ẹmu ọ̀pẹ, tí a gbé ka orí orin Kristẹni. [2] Nínú àwọn orin kan, a ti fi “ẹmu ọ̀pẹ” rọ́pò ọ̀rọ̀ náà “Jésù” àti “Olúwa mi”. [2] Nínú àwọn orin mìíràn, a ti fi “Akọ̀pẹ” rọ́pò ọ̀rọ̀ náà “Ọlọ́run”, orúkọ ẹgbẹ́ náà fún ẹni tí ó ń gun ọ̀pẹ láti lọ dá ẹmu náà. [2]

Ilé ìsìn tàbí ibi ìpàdé ẹgbẹ́ náà jẹ́ ilé kékeré kan tí ó ní àyè gbígbòòrò níwájú fún orin,ìlù àti ijó. [1] [2] Àwọn oun èlò orin ìbílẹ̀ tí a fi ọwọ́ ṣe ni ó máa ń wà ní ibi ìsìn wọn, wọn a sì fi igi oparun yí gbogbo ibẹ̀ ká, èyí tí ó jọ ti àwọn àbẹ́tẹ̀ tí wọn ti ń ta ẹmu ọ̀pẹ ní ìgbèríko Nàìjíríà. [1] Níbi àwọn ayẹyẹ apéjọpọ̀ wọn niwọn ti maa ń kọ orin, ijó, àti mímu. [1] [2] Ẹmu ọ̀pẹ tí wọ́n máa n mu níbi àpèjọ wọn ni a ń pè ní "omi mímọ́". [2]

Ààrẹ Ẹgbẹ́ Ẹlẹ́mu ní wọ́n máa ń pè ní Olóyè . [2] Àwọn olórí mìíràn ní àgbà tí ó ń fún olóyè nímọ̀ràn, fẹ́dà tàbí akọ̀wé gbogbogbò, ayékòótọ̀ tàbí alukoro ẹgbẹ́, olóyè tí ó ń ṣe àbójútó ààbò àti ìbáwí, àti àpò owó tàbí akápò. [1] [2] Orúkọ náà fẹ́dà dá lórí ọ̀rọ̀ Gẹ̀ẹ́sì tí á ń pè ní "ìyẹ́", èyí tí ó ń rántí ìgbà tí wọ́n lo ìyẹ́ àti tàdáwà láti kọ ǹkọ. [2] [1] Àwọn olórí mìíràn ní olùkọ orin, kọmíṣọ́nà ijó, "HOD" tàbí Olórí Onílù tí ó ń darí àwọn onílù, akọ̀pẹ tí ó ń pèsè ẹmu ògùrọ̀, àti olùdà tí ó ń da tàbí pín ẹmu fún àwọn ọmọ ẹgbẹ́. [2] [1] Ẹgbẹ́ náà tún ní olùtọ́jú tí ó ń ṣe ojúṣe fún àwọn dúkìá wọn. [2]

Àwọn àríyànjiyàn

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Bó tilẹ̀ jẹ́ pé wọ́n sábà máa ń wo Ẹgbẹ́ Kegite gẹ́gẹ́ bí ẹgbẹ́ àwùjọ, àwọn ọmọ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà kan kà á sí ẹgbẹ́ òkùnkùn nítorí ipa tí wọ́n kó nínú ìgbòkègbodò àṣà àwùjọ. [4] Síbẹ̀síbẹ̀, Ẹgbẹ́ ẹlẹ́mu ní gbogbo àwọn ẹ̀yà nínú, ó sì ń gbé èrò tí kò ní “àbájáde búburú” lárugẹ, èyí tí ó yà á sọ́tọ̀ kúrò lára àwọn ẹgbẹ́ mìíràn ní orílẹ̀ èdè Nàìjíríà tí a mọ̀. [4]

Wo Eléyìí pẹ̀lú

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]
  • Àwọn ẹgbẹ́ ní Nàìjíríà
  • Àkójọ àwọn ẹgbẹ́ ní Nàìjíríà

Àwọn ìtọ́kasí

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Kíkà síwájú síi

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]
  • Tochukwu, Okeke; Monday, Mbah Boniface; Onyebuchi, Okeke Chukwuma (2018). [free "Sociolinguistic Analysis of the Language of Palm Wine Drinkers’ Club (Kegite)"]. Journal of Language Teaching and Research 9 (4): 856–868. doi:10.17507/jltr.0904.25. ISSN 1798-4769. free.