Jump to content

Ọba Adédọ̀tun Àrẹ̀mú Gbádébọ̀ (Kẹta)

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́
Alake

Adédọ̀tun Aremu Gbadébò lll (Okukenu lV)
Alake of Egba
Lọ́wọ́lọ́wọ́
Ó gun orí àga
2 August 2005 - present
AsíwájúOba Oyebade Lipede
Àwọn àlàyé onítòhún
Ọjọ́ìbí14 Oṣù Kẹ̀sán 1943 (1943-09-14) (ọmọ ọdún 82)
Abeokuta

Ọba Adédòtun Àrẹ̀mú Gbádébọ̀ (Kẹta) tí a bí ní ọjọ́ kẹrìnlá oṣù kẹsàn ọdún 1943) ni Aláké ti ìlú Ẹ̀gbá, ẹ̀yà kan ní ìlú Abẹ́òkúta, ní orílẹ̀ èdè Nàìjíríà . Ó ti gun orí ìtẹ̀ àwọn baba ńlá rẹ̀ láti ọjọ́ kejì Oṣù Kẹjọ ọdún 2005.

Ìgbésí ayé rẹ̀ ní Èwe

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

A bí Gbádébọ̀ ní ọjọ́ kẹrìnlá oṣù kẹsàn-án ọdún 1943, sí Ilé Ọba Laarun. Ó jẹ́ ọmọ ọmọ Aláké kẹfà ti Ìlú Ẹ̀gbá, Ọba Gbádébọ̀, ẹni tí ó jẹ láti ọdún 1898 sí 1920, ó sì jẹ́ ọmọ ẹ̀gbọ́n Oba Gbadebo Kejì. Bàbá bàbá rẹ̀ ni Òkúkẹ́nù, Aláké àkọ́kọ́ ti Ìlú Ẹ̀gbá. Láti ọwọ́ Òkúkẹ́nù, ìran Gbádébọ̀ padà sí Laarun, Aláké ti Aké tí ó jọba ní ìbẹ̀rẹ̀ ọdún 1700. Laarun ni bàbá bàbá Gbadebo láti ìran karùn-ún.

Gbádébọ̀ lọ sí ilé-ẹ̀kọ́ gíga Baptist Boys’ ní ìlú Abẹ́okúta àti Ìbàdàn Grammar School, lẹ́yìn náà ó lọ sí Yunifásítì ti Ibadan ní ọdún 1965, ó gba ìwé-ẹ̀rí àkọ́kọ́ lórí ìmọ̀ iṣẹ́ ọnà ní ọdún 1969. Ó dara pọ̀ mọ́ ẹgbẹ́ ọmọ ogun ní ọdún 1969, ó sì lọ sí ilé-ẹ̀kọ́ Ilé ẹ̀kọ́ àwọń ọmọ ológun, Jaji láti oṣù kẹsàn-án ọdún 1978 sí oṣù kẹjọ ọdún 1979. Níkẹyìn ó di olórí òṣìṣẹ́ fún Ọ̀gágun Túndé Ìdíàgbọn, olórí òṣìṣẹ́ ní ilé-iṣẹ́ àwọn ọmọ ológun tó ga jùlọ ní Dodan Barracks, láti oṣù kíní ọdún 1984 sí oṣù kẹsàn-án ọdún 1985. Ó fẹ̀yìntì kúrò nínú iṣẹ́ ológun gẹ́gẹ́ bí Colonel.

Yíyàn sí ipò Ọba

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

A yan Gbádébọ̀ gẹ́gẹ́ bí Alake ní oṣù kẹjọ ọdún 2005 èyí fòpin sí àkókò awuyewuye olóṣù mẹ́fà tó wáyé nípa ẹni tí yóò gba ipò Alake tó wàjà, Ọba Oyèbádé Lípẹ̀dé, ẹni tí ó wàjà ní ọjọ́ kẹta oṣù kejì ọdún 2005. [1] Ó gba ìbò mẹ́ẹ̀ẹ́dógún nínú mẹ́tàlélógún nínú ìdìbò tí àwọn Afọbajẹ Ẹgbá ṣe, ó sì borí àwọn olùdíje mẹ́jọ mìíràn pẹ̀lú àbúrò rẹ̀, Adélékè.

Àríyànjiyàn/Awuyewuye

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Ní oṣù kẹrin ọdún 2010, ìjà kan wáyé láàrín Ọba Gbádébọ̀ àti Olú ti Ìgbẹ̀ìn, Ọba Festus Olúwọlé Mákindé, wọ́n gbé ẹjọ́ náà lọ sí Ilé Ẹjọ́ Gíga ti Ìpínlẹ̀ Ogun, Ẹ̀ka Ìdájọ́ Abeokuta, Ìpínlẹ̀ Ogun, orílẹ̀ èdè Nàìjíríà. Olú ti Ìgbẹ̀ìn ń tako ìgbìyànjú Aláké láti yí oyè rẹ̀ padà láti Olú ti Ìgbẹ̀ìn sí Olú ti Mòwé, ìyípadà tí yóò ní ipa lórí ẹ̀tọ́ rẹ̀ láti lo àwọn àmì ìbílẹ̀ kan títí kan ìjókòó gẹ́gẹ́ bí olú ti Ìgbẹ̀ìn. [2]

Àwọn ìtọ́kasí

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]
  1. Empty citation (help)
  2. Empty citation (help)