Ọdún Eyibi
| Ipò | Ó ń lọ lọ́wọ́ |
|---|---|
| Ọjọ́ | Oṣù Kẹwàá 15 |
| Ibùdó | Òkè Ẹlẹ́tu, Ìjẹ̀dẹ LCDA |
| Ìlú | Ìkòròdú |
| Orílẹ̀-èdè | Nàìjíríà |
Ọdún Eyibi jẹ́ ayẹyẹ àṣà ọdọọdún tí wọ́n máa ń ṣe ní Òkè Ẹlẹ́tu, lábẹ́ ìjọba ìbílẹ̀ Ìjẹ̀dẹ (Ijede LCDA) ní Ìkòròdú, Ìpínlẹ̀ Èkó, ní apá Ìwọ̀-oòrùn Gúúsù orílẹ̀-èdè Nàìjíríà.[1] Nígbà mìíràn, wọ́n máa ń pe ọdún yìí ní Ọdún Eyibi/Ẹlúkú. Ayẹyẹ yìí máa ń ṣàfihàn àṣà àti ìṣẹ̀ṣe àwọn Yorùbá, ó sì máa ń tẹnu mọ́ ìṣọ̀kan, àlàáfíà, àti ìwẹ̀nùmọ́ ẹ̀mí. Ọdún yìí fẹsẹ̀ múlẹ̀ nínú àṣà àwọn baba ńlá wa, ó sì jẹ́ àkókò fún ìtọ́jú àṣà àti kíkó àwọn ènìyàn pọ̀ gẹ́gẹ́ bí ọ̀kan. Ọdún Ẹlúkú àti ọdún Agẹmọ jẹ́ ẹ̀ka ọdún lábẹ́ Ọdún Eyibi, èyí tí wọ́n sábà máa ń ṣe láàrin àwọn ẹ̀yà Ìjẹ̀bú.[2]
Ayẹyẹ Ọdún Eyibi ti 2024
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Ọdún Eyibi ti ọdún 2024 bẹ̀rẹ̀ ní ọjọ́ kẹẹ̀dógún (15) Oṣù Kẹwàá pẹ̀lú ayẹyẹ Ìtúwòrò. Ayẹyẹ yìí gba pé kí wọ́n kó àwọn ewé pàtàkì jọ fún ètùtù láti tọrọ ìbùkún, àlàáfíà, ìṣọ̀kan, àti ìdàgbàsókè ọrọ̀ ajé fún ìlú. Ẹlẹ́tu ti Òkè Ẹlẹ́tu, Ẹlẹ́tu Adéníyì Ọmọ́táyọ̀ Àjàyí, tí í ṣe olórí ìlú Òkè Ẹlẹ́tu, tẹnu mọ́ bí ìṣọ̀kan àti àlàáfíà ṣe ṣe pàtàkì tó. Wọ́n fi oríṣiríṣi ijó àṣà, ayẹyẹ ńlá, àti ètùtù ìbílẹ̀ ṣàfihàn èyí.[3][4]
Àwọn Ìtọ́kasì
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]- ↑ "Present Day". www.ikoroduoga.net. Retrieved 2024-11-28.
- ↑ "Ikorodu Yearly Festivals". INN-HOUSE☆ (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). 2020-02-18. Retrieved 2024-11-28.
- ↑ Newspaper, Impact (2024-10-17). "Oke Eletu Celebrates Eyibi Festival As Traditional Head Calls For Unity, Peace -" (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). Retrieved 2024-11-28.
- ↑ Newspaper, Impact (2024-10-14). "2024 Eyibi Festival In Oke Eletu Kicks Off Tuesday, October 15 -" (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). Retrieved 2024-11-28.