Jump to content

Abdulkadir Ahmed

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́
Abdulkadir Ahmed
Governor of the Central Bank of Nigeria
In office
28 June 1982  30 September 1993
AsíwájúOla Vincent
Arọ́pòPaul Agbai Ogwuma
Àwọn àlàyé onítòhún
Ọjọ́ìbí(1940-10-31)31 Oṣù Kẹ̀wá 1940
Jama'are, Northern Region, British Nigeria (now in Bauchi State, Nigeria)
Aláìsí1997 (ọmọ ọdún 5657)

Abdulkadir Ahmed (tí a bí ní ọjọ́ kọkànlélọ́gbọ̀n oṣù kẹwa ọdún 1940 – ọdún 1997) jẹ́ ọkùnrin oníṣòwò àti oṣiṣẹ ìlú Nàìjíríà ti o jẹ Gómìnà Bánkì àpapọ̀ orílẹ-èdè Nàìjíríà láti ọdún 1982 sí 1993. [1]

A bi Ahmed ní ọjọ́ kọkànlélọ́gbọ̀n oṣù kẹwàá ọdún 1940 ní Jama'are ni ipinle Bauchi . Ó lọ sí Barewa College, Zaria ní ọdún 1955. Ó dara pọ̀ mọ́ New Nigerian Development Company ní oṣù kínní, ọdún 1960. Ahmed kẹ́kọ̀ọ́ ní Yunifásítì ti Ife ní ọdún 1961. Ó jáde ní ilé ẹ̀kọ́ gíga South West London College ní ọdún 1972. Ahmed di Kọmíṣọ́nà fún ìnáwó fún ìpínlẹ̀ Bauchi ní (oṣù kẹta ọdún 1976 – oṣù kẹfà ọdún 1977). Wọ́n yán an gẹgẹ bi Igbákejì Gomina Bánkì àpapọ̀ orílẹ-èdè Nàìjíríà ní ọdún 1977. [2] Ṣáájú ki o to di Kọmísánnà fún Isuna, Ahmed ni ìrírí aláṣẹ pẹlú Northern Nigeria Development Company (NNDC) o si ṣe aṣojú ilé-iṣẹ́ ní àwọn ìgbìmọ̀ ti àwọn ilé-iṣẹ́ ti o niiṣe gẹ́gẹ́bí Arewa Textiles Mills, Northern Nigeria Textiles Mills, Cement Company of Northern Nigeria ati Arewa Hotels. O darapọ̀ mọ NNDC ni ọdún 1960 àti pé ó ní àtìlẹ́yìn fún ikẹkọ ní àwọn ilé-iṣẹ́ ni Nàìjíríà àti ní òkèèrè. O ṣiṣẹ bi oníṣirò agbègbè ti ẹgbẹ́ náà ati ní ọdún 1974, o di olùdarí owó fún ẹgbẹ́ náà. [3]

Ahmed jẹ́ ẹlẹ́gbẹ́ ti Institute of Chartered and Certified Accountants ati Institute of Chartered Accountants of Nigeria .

Gómìnà ti Bánkì àpapọ̀

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Ahmed ni wọn yàn gẹgẹ bí Gómìnà Bánkì àpapọ̀ ní ọjọ́ kẹtàdínlọ́gbọ̀n oṣù kẹfà ọdún 1982 o sì fẹ̀yìntì ní ọgbọ̀njọ́ oṣù kẹ̀sán ọdún 1993. O wà ní ofìisì fún ọdún mọ́kànlá ní àkókò ìjọba tiwantiwa ti Shehu Shagari àti ìjọba adelé ti Ernest Shonekan, àti ìjọba ológun ti Ọ̀gágun Muhammadu Buhari àti Ibrahim Babangida . [4]

Òun ni alága àkọkọ ti ìgbìmọ̀ ti Ile-iṣẹ Iṣeduro Idogo Nẹtiwọọki nígbàtí wọn dáa sílẹ̀ ní ọjọ kẹẹdógún oṣù kẹfà ọdún 1988. [5]

Ni àkókò ti ìjọba rẹ̀, Shagari fun ni àwọn ìwe àdéhùn fún iṣẹ ikole Dam Kafin Zaki ní Ìpínlẹ̀ Bauchi. Ahmed ati mínísítà ọ̀rọ̀ orisun omi Abubakar Hashidu jẹ́ ọmọ bíbi ìpínlẹ̀ náà. Ìjọba arọ́pò ti Alákóso Ológun Gbogbogbò Sani Abacha fagile iṣẹ àkànṣe o si yan ìgbìmò ìdájọ́ kan ti ìwádìí. [6] Abacha tún ṣètò ìgbìmọ̀ ti ìwádìí lóri àwọn iṣẹ CBN lábẹ àwọn ti o ti ṣáájú rẹ̀. [7]

  1. http://allafrica.com/stories/199712170094.html
  2. http://www.cenbank.org/AboutCBN/RetiredExecutive.asp?Name=Alhaji+Abdulkadir+Ahmed
  3. People. Lagos.https://en.wikipedia.org/wiki/Abdulkadir_Ahmed#cite_ref-3
  4. http://allafrica.com/stories/200906030669.html
  5. https://web.archive.org/web/20090831041552/http://www.ndic-ng.com/about_ndic.htm
  6. http://pi.library.yorku.ca/ojs/index.php/refuge/article/viewFile/21922/20591
  7. http://findarticles.com/p/articles/mi_qa5327/is_n195/ai_n28652057/