Jump to content

Abimbola Amusu

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́
Abimbola Amusu
Birth nameAbimbola Olatilewa Amusu
Allegiance Nigeria
Service/branch Adigun Nàìjíríà
RankMajor General
Commands heldNigerian Army Medical Corps

Ọ̀gágun Abimbola Olatilewa Amusu jẹ́ ọmọ ilẹ̀ iṣẹ́ ológun orílè-èdè Nàìjíríà kan tó ń ṣàkóso ẹgbẹ́ ìṣègùn ọmọ ogun Nàìjíríà láti ọdún 2015 sí ọdún 2018. Òun ni ọ̀gágun obìnrin kejì nínú ìwé ìtàn ẹgbẹ́ ìṣègùn ọmọ ogún orílè-èdè Nàìjíríà tó ti ṣe olórí àwùjọ náà. Wọ́n yàn án lẹ́yìn ìfẹ̀yìntì ọ̀gágun Obashina Ayodele.[1]

Amusu ní ìwé-ẹ̀rí Master nípa ètò ìṣàkóso ọrọ̀ ajé (MBA) (Health Management) láti ilẹ̀ ẹ̀kọ́ gíga Yunifásítì ti Ìpínlẹ̀ Èkó, ó tún jẹ́ ọ̀kan lára àwọn olùkọ́ni tí ń ṣe idanwo fún akẹ́kọ̀ọ́ ní National Postgraduate Medical College ní orílè-èdè Nàìjíríà àti ọmọ ẹgbẹ́ ìgbìmọ̀ àwọn olùkọ́ni; Faculty of Pathology, ní kọ́lẹ́ẹ̀jì kan náà. Amusu ni aláṣẹ ẹgbẹ́ ìṣègùn ọmọ ogun Nàìjíríà lọ́wọ́lọ́wọ́. Ó dara pọ̀ mọ́ ẹgbẹ́ ọmọ ogun Nàìjíríà gẹ́gẹ́ bí ọmọ ogun kejì ní oṣù kẹfà ọdún 1982, ó jẹ́ Olùdarí àti Olórí Onímọ̀ nípa Ẹjẹ̀, 44 Nigerian Army Reference Hospital ní ìjọba ìpínlẹ̀ Kaduna láti oṣù kẹsàn-án ọdún 2014 sí oṣù kejìlá kí wọ́n tó fi í ṣe Olórí Ẹgbẹ́ Ìlera, ọ́fíìsì kan tí ó wà títí di ìgbà tí ó fẹ̀yìntì ní ọdún 2018. Ó fẹ̀yìntì kúrò nínú ẹgbẹ́ ọmọ ogun Nàìjíríà ní oṣù Kejìlá ọdún 2018. Ó wà lára àwọn ọ̀gágun méjì àti Brigadier Generals mẹ́ta tí wọ́n yọ kúrò ní iṣẹ́ ní ẹgbẹ́ ìlera ọmọ ogun Nàìjíríà ní Èkó ní ọdún 2018.[2][3][4][5]

Àwọn Ìtọ́kasí

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]
  1. "Army Appoint A Female General As Medical Corps Commander". Nigerian Army (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). Archived from the original on 2021-01-19. Retrieved 2020-05-07. Unknown parameter |url-status= ignored (help)
  2. "Army pulls five generals out of service". Punch Newspapers (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). Retrieved 2020-05-07.
  3. "Army pulls 5 generals out of service". Vanguard News (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). 2018-12-18. Retrieved 2020-05-07.
  4. Nwezeh, Kingsley (2019-09-13). "Nigeria: Aisha Buhari Calls for Eradication of Gender Bias in Military". All Africa News (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). Retrieved 2020-05-07.
  5. Odunsi, Wale (2018-12-18). "Five Generals exit Nigerian Army" (in en-US). Daily Post (Lagos, Nigeria). https://dailypost.ng/2018/12/18/five-generals-exit-nigerian-army/.