Jump to content

Adéṣẹ̀ye Ògúnléwé

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́
Adéṣẹ̀ye Ògúnléwé
ÀàrẹOlusegun Obasanjo
Àwọn àlàyé onítòhún
Ẹgbẹ́ olóṣèlúPeoples Democratic Party
All Progressives Congress

Kingsley Adéṣẹ̀yẹ Ògúnléwé jẹ́ olóṣèlú ọmọ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà tó ti ṣiṣẹ́ gẹ́gẹ́ bí Mínísítà fún ọ̀rọ̀ iṣẹ́ láti ọdún 2003 sí ọdún 2006. [1] Ó ti ṣiṣẹ́ gẹ́gẹ́ bí Aṣòfin tó ń ṣojú fún agbègbè Ìlà-oòrùn ìpínlẹ̀ Èkó láti ọdún 1999 sí 2003. Ó wá láti ìdílé ọba ní Igbógbo.

Ìgbésí ayé rẹ̀

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Ògúnléwé wá láti ìdílé ọlọ́rọ̀ ti Igbogbo, agbègbè kan ní Ìkòròdú . Ẹ̀gbọ́n rẹ̀ ọkùnrin tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Akin jẹ́ akọ̀wé àgbà ní Ilé-iṣẹ́ ìjọba àpapọ̀ tó wà fún Ìṣòwò àti Iṣẹ́, ẹni tí wọ́n yọ kúrò ní ipò rẹ̀ lẹ́yìn tí Ògúnléwé ti padà lọ sí inú ẹgbẹ́ òṣèlú ti PDP. [2]

Akẹ́kọ̀ọ́ jáde ilé-ẹ̀kọ́ gíga Yunifásítì ti Ìbàdàn ni Ògúnléwé. Nígbà tí ó wà ní Yunifásítì yìí, ó ń gbé ní Mellanby Hall ó sì kópa gidigidi nínú àwọn iṣẹ́ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí akẹ́kọ̀ọ́.

Òṣèlú. Agbẹjọ́rò ni, ó sì jẹ́ akọ̀wé àgbà ní Ìpínlẹ̀ Èkó nígbà kan rí. [2]

Ọmọ rẹ̀ Ọkùnrin Moyọ̀sọ́re jẹ́ olóṣèlú. Ọmọ rẹ̀ Ọkùnrin mìíràn, Ṣẹ̀yẹ, jẹ́ asáré.

Gẹ́gẹ́ bí Aṣòfin

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Wọ́n dìbò yàn án gẹ́gẹ́ bí Aṣòfin lábẹ́ àsìà ẹgbẹ́ òṣèlú tí Alliance for Democracy (AD) ní ọdún 1999 fún ẹkún ìdìbò Ìlà-oòrùn ìpínlẹ̀ Èkó, kí ó tó yalọ sínú ẹgbẹ́ òṣèlú ti PDP .

Ní oṣù Keje ọdún 2002, Wahab Dosunmu àti Ogunlewe fi ẹ̀sùn kan Gómìnà Ìpínlẹ̀ Èkó nígbà náà, Bola Ahmed Tinubu, pé ó ń tàpá sí ìgbẹ́kẹ̀lé owó àwọn ará ìlú nípa gbígbé àwọn àkànṣe iṣẹ́ fún àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀.

Ògúnléwé díje láti wọlé ẹlẹ́ẹ̀kejì gẹ́gẹ́ bí aṣòfin ni ọdun 2003 lábẹ́ àsìà ẹgbẹ́ òṣèlú PDP, ṣùgbọn ó fìdí rẹmi sí ọwọ́ Olorunnimbe Mamora ti ẹgbẹ́ òṣèlú ti Alliance for Democracy (AD). [2]

Gẹ́gẹ́ bíì Mínísítà fún Ọ̀rọ̀ Iṣẹ́

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Ní oṣù Keje ọdún 2003, Ògúnléwé kéde pé ìjọba àpapọ̀ yóò ná owó tó tó bílíọ̀nù méjì ó lé owó ilẹ̀ òkèèrè láti tún ṣe àtúnṣe àti láti mú kí àwọn òpópónà orílẹ̀-èdè Nàìjíríà túnbọ̀ sunwọ̀n síi, ó sì gbèrò láti jẹ́ kí gbogbo ọ̀nà ní orílẹ̀-èdè Nàìjíríà ṣeé rìn títí ìparí ọdún. Ní oṣù Kejìlá ọdún 2004, ó sọ pé ìjọba àpapọ̀ ti fọwọ́ sí àfikún owó tó tó mílíọ̀nù lọ́nà Ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rún náírà fún àtúnṣe àwọn ọ̀nà ní Gúúsù-Ìlà-Oòrùn orílẹ̀-èdè Nàìjíríà. [3]

Ní oṣù kẹrin ọdún 2004, Ògúnléwé gba ẹ̀bùn àṣeyọrí fún àwọn olórí ní ilẹ̀ Afrika ní Kwame Nkrumah ní Accra, Ghana . Ní oṣù karùn-ún ọdún 2004, ó tẹ nọ́mbà ẹ̀rọ ìbáraẹni ṣọ̀rọ̀ rẹ̀ jáde, ó sì sọ fún àwọn ará ìlú láti pe òhun tí wọ́n bá jálu kòtò tàbí tí wọ́n bá ní ìjàǹbá ọkọ̀ lójúu pópó. Ó sọ pé ẹ̀rù ò ba òún láti máa gba àwọn náà, ṣùgbọ́n ó tún sọ nípa àwọn ọ̀nà náà pé “Wọ́n ti dára gan-an báyìí.” Ó sọ pé àtúnṣe ti bá àwọn ọ̀nà tó tó kìlómítà ẹgbẹ̀rún méjìlá ó lé ní igba mẹ́ta àárín ní oṣù mẹ́fà sẹ́yìn.

Ní oṣù kẹfà ọdún 2004, ìjà wáyé ní ìpínlẹ̀ Èkó láàárín àwọn aṣojú Ilé Iṣẹ́ Ìjọba Àpapọ̀ tó ń rísí ọ̀rọ̀ iṣẹ́ àti àwọn òṣìṣẹ́ Ilé Iṣẹ́ Ìṣàkóso ìgbòkègbodò Ọkọ̀ ní Ìpínlẹ̀ Èkó. Ìjà náà jẹ́ lórí ìṣàkóso àwọn ọ̀nà ìjọba àpapọ̀, ó sì hàn gbangba pé ó ní í ṣe pẹ̀lú àríyànjiyàn tó ń lọ lọ́wọ́ láàrín Ògúnléwé àti Gómìnà ìpínlẹ̀ Èkó nígbà náà Bola Ahmed Tinubu ti Alliance for Democracy. [4]

Ní oṣù kẹjọ ọdún 2004, Ògúnléwé kéde pé Banki Àgbáyé àti Banki Ìdàgbàsókè Áfíríkà gbèrò láti bá Nàìjíríà ṣiṣẹ́ pọ̀ láti kọ́ Ọ̀nà Ìwọ̀ Oòrùn Áfíríkà láti ìlú Èkó sí olú ìlú Mauritania, Nouakchott . Ní oṣù kẹwàá ọdún 2004, ó sọ pé ọdún 2005 yóò rí ìlọsíwájú kíákíá nínú àtúnṣe àti kíkọ́ àwọn ọ̀nà tuntun. [5]

Ní oṣù kẹta ọdún 2006, lẹ́yìn tí wọ́n yọ ọ́ kúrò ní ipò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí Mínísítà fún ọ̀rọ̀ Iṣẹ́, Ògúnléwé rọ Ààrẹ Olusegun Obasanjo láti gbé àpótí fún ìgbà kẹta gẹ́gẹ́ bìi Ààrẹ.

Ìgbésí ayé rẹ̀ lẹ́yìn tí ó kúrò ní ipò Mínísítà

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Ní oṣù Keje ọdún 2006, wọ́n rí ẹni tí wọ́n pa gẹ́gẹ́ bí olùdíje fún ipò gómìnà ní ìpínlẹ̀ Èkó, Funsho Williams nílé rẹ̀. Wọ́n gbé Ògúnléwé, ẹni tí ó ti jẹ́ alátakò fún ìdìbò tí ó sọ Funsho Williams di olùdíje lábẹ́ àsìa ẹgbẹ́ òṣèlú PDP, nítorí ìpànìyàn náà. Wọ́n tú u sílẹ̀ lẹ́yìn náà, ṣùgbọ́n ní oṣù Kejì ọdún 2007, wọ́n tún padà gbe. [6]

Ní oṣù kọkànlá ọdún 2009, àwọn ìgbìmọ̀ ilé aṣòfin lórí ìrìnnà tí Heineken Lokpobiri jẹ̀ adarí wọn, fi ìròyìn kan ránṣẹ́ sí ilé ìgbìmọ̀ aṣòfin gíga tí ó ṣe àfihàn pé “mọ̀kàrúrù àti àìkó àkóyawọ́ pọ̀” nínú gbígbé àwọn iṣẹ̀ ọ̀nà fún àwọn agbaṣẹ́ṣe láàárín ọdún mẹ́wàá, wọ́n sì dámọ̀ràn pé kí wọ́n fi ẹ̀sùn kan àwọn mínísítà iṣẹ́ tẹ́lẹ̀ Anthony Anenih, Ògúnléwé, Obafemi Anibaba, Cornelius Adebayo àti àwọn mìíràn fún ìwà ìbàjẹ́. [7] Ìjíròrò ìgbìmọ̀ aṣòfin lórí náà ni wọ́n fi falẹ̀. Ó fi ipò rẹ̀ sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí Olùdarí-ẹ̀ka ti Federal University of Agriculture, Abeokuta ní ọdún 2016. Ní ọdún 2019, ó fi ẹgbẹ́ òṣèlú Peoples Democratic Party sílẹ̀ tó sì darapọ̀ mọ́ ẹgbẹ́ òṣèlú All Progressives Congress

Àwọn ìtọ́kasí

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]
  1. Empty citation (help)
  2. 1 2 3 Empty citation (help)
  3. Empty citation (help)
  4. Empty citation (help)
  5. Empty citation (help)
  6. Empty citation (help)
  7. Empty citation (help)