Jump to content

Adéníji Àdèlé

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́
Oba Sir Adeniji Adele II, KBE
Ọba ìlú Èkó

Adéníji Àdèlé II
Oba of Lagos
Reign 1949–1964
Coronation 1949
Predecessor Fálolú Dòsùmú
Successor Adéyínká Oyèkàn
House Àdèlé Ajosun, Ológun Kútere
Father Bùráímọ̀ Àdèlé
Mother Moriamo Lalugbi
Born (1893-11-13)13 Oṣù Kọkànlá 1893
(N.S.: 13 November 1893)
Lagos, Nigeria
Died 12 July 1964(1964-07-12) (ọmọ ọdún 70)
Èkó, Nàìjíríà
Burial Ìgà Ìdúnganran
Religion Lahore Ahmadiyya Movement

Ọba Sir Musendiku Buraimoh Adéníji Àdèlé II, tí ó tún jẹ́ KBE (tí a bí ní ọjọ kẹtàlá oṣù kọkànlá ọdún 1893 – tí o sì kú ní ọjọ kejìlá oṣù keje ọdún 1964) ni ó jẹ́ Ọba ìlú Èkó láàrín ọjọ́ kínní oṣù Kẹwàá ọdún 1949 sí ọjọ́ kejìlá oṣù keje ọdún 1964.[1][2]

Ìgbésí ayé rẹ̀

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Wọ́ bí Àdèlé ní inú ọdún 1893 sínú ìdílé alàgbà Buraimoh Àdèlé tí ìyá rẹ̀ sì jẹ́ Mọ̀ríyámọ̀ Lálúgbi ní ìlú Èkó. Bàbá bàbá rẹ̀ ni Ọba Àdèlé Ajósùn. Àdèlé lọ sí ilé-ẹ̀kọ́ alákọ̀ọ́bẹ̀rẹ̀ ti Holy Trinity Primary School, tí ó wà ní agbègbè Èbúté-Èrò, tí ó sì lọ sí ilé-ẹ̀kọ́ girama ti CMS Grammar School, Lagos bákan náà. Lẹ́yìn tí ó kẹ́kọ̀ọ́ jáde nílé ẹ̀kọ́ girama ni ó dara pọ̀ mọ́ àwọn agbẹ̀kọ́ lábẹ́ ilé-ẹ̀kọ́ Àwọnẹ̀ tí àwọn gẹ̀ẹ́sì àmúnisìn ń ṣakóso rẹ̀. Lẹ́yìn tí ó pari ikẹ́kọ́ ilẹ̀ wíwọ̀n ni wọ́n gbé lọ sí ìlú kano gẹ́gẹ́ bí wọnlẹ̀-wọnlẹ̀. Ó ṣíṣeẹ́ pẹ̀lú Cameroon Expeditionary Force gẹ́gẹ́ bí awọnlẹ̀ nígbà ogun agbáyé ẹlẹ́kejì.

Ní ọdún 1920, Adéníji Àdèlé sin olóyè Amodu Tijani Oluwa lọ sí ìlú London láti lọ farahàn níwájú ìgbìmọ̀ privy council ti ilẹ̀ Gẹ̀ẹ́sì lórí rògbòdìyàn ilẹ̀ Olùwá tí Àmọ́dù sì borí ẹjọ́ náà. Adéniji Àdèlé tún ṣiṣẹ́ gẹ́gẹ́ bí akápò owó tí ó sì padà di kíláákì àgbà ní ọdún 1937. Wọ́n fi oyè Commander of the Order of the British Empire (1956) and Knight of the Order of the British Empire (1962) tí olorì orílẹ̀-èdè United Kingdom (the Queen of the United Kingdom) fi dáa lọ́lá.[3][4]

Ipa rẹ̀ nínú òṣèlú

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Ọba Àdèlé nígbà ayé rẹ̀ jẹ́ alátìlẹ́yìn Ẹgbẹ́ Nigerian Youth Movement o sì tún jẹ́ ọmọ ẹgbẹ́ Egbe Omo Oduduwa ti alàgbà Ọbáfẹ́mi Awólọ́wọ̀ n darí. Nítorí náà, ìfarahàn ìṣèlú rẹ̀ wà ní ìdíje pẹ̀lú ẹgbẹ́ olóṣèlú tó ń ṣàkóso nígbà yẹn, NCNC/NNDP (èyí tí ìpìlẹ̀ agbára ìṣèlú rẹ̀ jẹ́ Ilé Docemo) tí Herbert Macaulay dá sílẹ̀, tí Nnamdi Azikiwe sì di olórí rẹ̀ nígbà tó yá. NNDP tako ìgòkè Ọba Adele sí itẹ́ ọba, nítorí pé kò jẹ́ ọmọ ìran Dosunmu, wọ́n sì gbé ẹjọ́ lọ sí ilé-ẹjọ́ láti dá ìkórónéṣọ̀ọ̀n rẹ̀ dúró. Ìdájọ́ ilé-ẹjọ́ Judicial Committee of the Privy Council tí ó kalẹ̀ sí ìlú London ni ó sọọ́ di Ọba ní ọdún 1957.[5]

Àwọn ìtọ́kasí

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]
  1. "LAGOS (Yoruba State)". Archived from the original on 17 May 2017. Retrieved 19 September 2015. Unknown parameter |url-status= ignored (help)
  2. "Oba of Lagos". Retrieved 19 September 2015.
  3. Moshood Ademola Fayemiwo, PhD; Margie Neal-Fayemiwo, Ed.D (6 July 2017). ASIWAJU: The Biography of Bolanle Ahmed Adekunle Tinubu. Strategic Book Publishing & Rights Agency, 2017. pp. 288. ISBN 9781946539434.
  4. Toyin Falola; Ann Genova (July 2009). Historical Dictionary of Nigeria. Scarecrow Press, 2009. pp. 16. ISBN 9780810863163. https://books.google.com/books?id=QWTd1ftuCbwC&q=adeniji+adele+knight&pg=PA16.
  5. Robert L. Sklar (8 December 2015). Nigerian Political Parties: Power in an Emergent African Nation. Princeton University Press, 2015. pp. 71. ISBN 9781400878239. https://books.google.com/books?id=xD7WCgAAQBAJ&q=adeniji+adele&pg=PA71.