Adéníyì Akíntọ́lá
Chief Adeniyi Michael Akintola (SAN) | |
|---|---|
| Deputy Speaker, Oyo State House of Assembly | |
| In office 1992–1993 | |
| Àwọn àlàyé onítòhún | |
| Ọjọ́ìbí | 21 Oṣù Kínní 1960 Ido, Oyo State, Nigeria |
| Education | University of Ibadan (LL.B, M.Sc) |
Adéníyì Michael Akíntọ́lá tí a bí ní ọjọ́ kọkànlélógún oṣù kìíní ọdún 1960 jẹ́ agbẹjọ́rò àti olóṣèlú ọmọ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà. Ó jẹ́ agbẹjọ́rò àgbà fún Nàìjíríà (SAN), ó sì jẹ́ alábáṣiṣẹpọ̀ àgbà ti ilé iṣẹ́ òfin Niyì Akíntọ́lá & Co àti Igbákejì Abẹnugan ti Ilé Ìgbìmọ̀ Aṣòfin Ìpínlẹ̀ Oyo nígbà ìjọba olómìnira kẹta.
,
Ìgbésí ayé àti ẹ̀kọ́ rẹ̀
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]A bí Akíntọ́lá ní ọjọ́ kọkànlélógún oṣù kìíní ọdún 1960 ní Ìdó, Ìpínlẹ̀ Oyo. Ó ti ṣiṣẹ́ gẹ́gẹ́ bí ọmọ ìkọ́ṣẹ́ atún'kọ̀ṣe, ọmọ iṣẹ́ tó ń tẹ̀lé ọkọ̀ àti ọmọ iṣẹ́ ayàwòrán ní Ìpínlẹ̀ Kaduna ní ìbẹ̀rẹ̀ ìgbésí ayé rẹ̀.
Ó kẹ́kọ̀ọ́ nípa ìmọ̀ òfin ní Yunifásítì ti Ibadan, ó sì gba ìwé ẹ̀rí LL.B. ní ọdún 1984. Wọ́n pè é sí ilé ẹjọ́ agbẹjọ́rò ní Nàìjíríà ní ọdún 1986. Ó tún ní ìwé ẹ̀rí ìmọ̀ ìjìnlẹ̀ kejì nínú ìmọ̀ ìṣèlú láti Yunifásítì ti Ibadan.
Iṣẹ́ Amòfin
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Akíntọ́lá bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ òfin ní ọdún 1986, ó sì ti fara hàn nínú ẹjọ́ òfin àti ẹjọ́ ìdìbò. Ní ọdún 2001, wọ́n fún un ní ipò Agbẹjọ́rò Àgbà ti Nàìjíríà .
Àwọn ẹjọ́ pàtàkì tó ti ṣiṣẹ́ lé lórí
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]- Akíntọ́lá ṣiṣẹ́ gẹ́gẹ́ bí ọ̀gá àwọn agbẹjọ́rò fún Ràṣídì Ládọjà nínú ìgbẹ́jọ́ Inakoju àti Adeleke ní ọdún 2007, níbi tí Ilé Ẹjọ́ Gíga ti fagilé ìgbẹ́jọ́ Ladoja, tí ó sì tún dá a padà gẹ́gẹ́ bí gómìnà.
- Ní ọdún 2023, ó jẹ́ ara ẹgbẹ́ àwọn agbẹjọ́rò tó ń gbèjà ìdìbò tó gbé Bola Tinubu wọlé gẹ́gẹ́ bí ààrẹ ní Ilé ẹjọ́ tó ń rísí àwọn awuyewuye tó wáyé nínú ètò ìdìbo Ààrẹ.
Gẹ́gẹ́bí Olòṣèlú
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Gẹ́gẹ́ bí Aṣòfin
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Ní ọdún 1992, wọ́n yan Akintola gẹ́gẹ́ bí aṣojú fún Ilé Ìgbìmọ̀ Aṣòfin Ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́, tí ó ń ṣojú fún Ìpínlẹ̀ Ìdó. Ó ṣiṣẹ́ gẹ́gẹ́ bí Igbákejì Abẹnugan títí tí wọ́n fi tú ilé ìgbìmọ̀ aṣòfin náà ká lẹ́yìn ìdìtẹ̀gbàjọba ológun tó wáyé ní oṣù kọkànlá ọdún 1993.
Ìpinnu láti di Gómìnà
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Akíntọ́lá díje fún ipò gómìnà ní abẹ́ àsìá ẹgbẹ́ òṣèlú ti All Progressives Congress (APC) ní Ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́ ní ọdún 2019 àti ọdún 2023. Ní ọdún 2023, ó yọ ara rẹ̀ kúrò nínú ìbò abẹ́lẹ́ ti ẹgbẹ́ náà , o sì fi ẹ̀sùn kàn pé mọ̀kàrúrù wà nínú àkójọ orùkọ àwọn aṣojú ẹgbẹ́ náà.
Iṣẹ́ orílẹ̀-èdè
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Akintola jẹ́ aṣojú tí ó ṣojú fún Ìpínlẹ̀ Oyo ní Àpérò Orílẹ̀-èdè ti ọdún 2014. Ó tún ṣiṣẹ́ gẹ́gẹ́ bí ọ̀kan lára Ìgbìmọ̀ Ààrẹ lórí Àtúnyẹ̀wò Òfin ti ọdún 1999.
Ìgbésí ayé rẹ̀ ní Àgbà
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Akintola fẹ́ Adájọ́ Bóyèdé Racheal Akíntọ́lá, adájọ́ Ilé ẹjọ́ gíga ti Ìpínlẹ̀ Oyo.