Jump to content

Adéníyì Akíntọ́lá

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́
Chief Adeniyi Michael Akintola (SAN)
Deputy Speaker, Oyo State House of Assembly
In office
1992–1993
Àwọn àlàyé onítòhún
Ọjọ́ìbí21 Oṣù Kínní 1960 (1960-01-21) (ọmọ ọdún 65)
Ido, Oyo State, Nigeria
EducationUniversity of Ibadan (LL.B, M.Sc)

Adéníyì Michael Akíntọ́lá tí a bí ní ọjọ́ kọkànlélógún oṣù kìíní ọdún 1960 jẹ́ agbẹjọ́rò àti olóṣèlú ọmọ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà. Ó jẹ́ agbẹjọ́rò àgbà fún Nàìjíríà (SAN), ó sì jẹ́ alábáṣiṣẹpọ̀ àgbà ti ilé iṣẹ́ òfin Niyì Akíntọ́lá & Co àti Igbákejì Abẹnugan ti Ilé Ìgbìmọ̀ Aṣòfin Ìpínlẹ̀ Oyo nígbà ìjọba olómìnira kẹta.

,

Ìgbésí ayé àti ẹ̀kọ́ rẹ̀

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

A bí Akíntọ́lá ní ọjọ́ kọkànlélógún oṣù kìíní ọdún 1960 ní Ìdó, Ìpínlẹ̀ Oyo. Ó ti ṣiṣẹ́ gẹ́gẹ́ bí ọmọ ìkọ́ṣẹ́ atún'kọ̀ṣe, ọmọ iṣẹ́ tó ń tẹ̀lé ọkọ̀ àti ọmọ iṣẹ́ ayàwòrán ní Ìpínlẹ̀ Kaduna ní ìbẹ̀rẹ̀ ìgbésí ayé rẹ̀.

Ó kẹ́kọ̀ọ́ nípa ìmọ̀ òfin ní Yunifásítì ti Ibadan, ó sì gba ìwé ẹ̀rí LL.B. ní ọdún 1984. Wọ́n pè é sí ilé ẹjọ́ agbẹjọ́rò ní Nàìjíríà ní ọdún 1986. Ó tún ní ìwé ẹ̀rí ìmọ̀ ìjìnlẹ̀ kejì nínú ìmọ̀ ìṣèlú láti Yunifásítì ti Ibadan.

Akíntọ́lá bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ òfin ní ọdún 1986, ó sì ti fara hàn nínú ẹjọ́ òfin àti ẹjọ́ ìdìbò. Ní ọdún 2001, wọ́n fún un ní ipò Agbẹjọ́rò Àgbà ti Nàìjíríà .

Àwọn ẹjọ́ pàtàkì tó ti ṣiṣẹ́ lé lórí

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]
  • Akíntọ́lá ṣiṣẹ́ gẹ́gẹ́ bí ọ̀gá àwọn agbẹjọ́rò fún Ràṣídì Ládọjà nínú ìgbẹ́jọ́ Inakoju àti Adeleke ní ọdún 2007, níbi tí Ilé Ẹjọ́ Gíga ti fagilé ìgbẹ́jọ́ Ladoja, tí ó sì tún dá a padà gẹ́gẹ́ bí gómìnà.
  • Ní ọdún 2023, ó jẹ́ ara ẹgbẹ́ àwọn agbẹjọ́rò tó ń gbèjà ìdìbò tó gbé Bola Tinubu wọlé gẹ́gẹ́ bí ààrẹ ní Ilé ẹjọ́ tó ń rísí àwọn awuyewuye tó wáyé nínú ètò ìdìbo Ààrẹ.

Gẹ́gẹ́bí Olòṣèlú

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Gẹ́gẹ́ bí Aṣòfin

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Ní ọdún 1992, wọ́n yan Akintola gẹ́gẹ́ bí aṣojú fún Ilé Ìgbìmọ̀ Aṣòfin Ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́, tí ó ń ṣojú fún Ìpínlẹ̀ Ìdó. Ó ṣiṣẹ́ gẹ́gẹ́ bí Igbákejì Abẹnugan títí tí wọ́n fi tú ilé ìgbìmọ̀ aṣòfin náà ká lẹ́yìn ìdìtẹ̀gbàjọba ológun tó wáyé ní oṣù kọkànlá ọdún 1993.

Ìpinnu láti di Gómìnà

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Akíntọ́lá díje fún ipò gómìnà ní abẹ́ àsìá ẹgbẹ́ òṣèlú ti All Progressives Congress (APC) ní Ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́ ní ọdún 2019 àti ọdún 2023. Ní ọdún 2023, ó yọ ara rẹ̀ kúrò nínú ìbò abẹ́lẹ́ ti ẹgbẹ́ náà , o sì fi ẹ̀sùn kàn pé mọ̀kàrúrù wà nínú àkójọ orùkọ àwọn aṣojú ẹgbẹ́ náà.

Iṣẹ́ orílẹ̀-èdè

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Akintola jẹ́ aṣojú tí ó ṣojú fún Ìpínlẹ̀ Oyo ní Àpérò Orílẹ̀-èdè ti ọdún 2014. Ó tún ṣiṣẹ́ gẹ́gẹ́ bí ọ̀kan lára Ìgbìmọ̀ Ààrẹ lórí Àtúnyẹ̀wò Òfin ti ọdún 1999.

Ìgbésí ayé rẹ̀ ní Àgbà

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Akintola fẹ́ Adájọ́ Bóyèdé Racheal Akíntọ́lá, adájọ́ Ilé ẹjọ́ gíga ti Ìpínlẹ̀ Oyo.

Àwọn ìtọ́kasí

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]