Afonja
Àfọ̀njá ti ìlú Ìlọrin jẹ́ Ààrẹ-ọ̀nà-Kakaǹfò gbogbo ìlú tí Ọ̀yọ́ ń ṣe ìṣàkóso lé lórí ní ìgbà kan rí. Baba ńlá baba rẹ̀ ni Láderin tí ó tẹ ìlú Ìlọrin dó.[1]Pasin (jagun-jagun) tí ó jẹ́ omo Laderin jẹ́ ewu lójú Baṣọ̀run Gáà ní ìgbà náà nítorí òkìkí rẹ. Fún ìdí èyí, wọn lé Pasin lo sí ẹ̀yìn odi, wọ́n sì pa à sí ibẹ̀ pàápàá. Lẹyìn èyí, Alugbin tí ó jẹ́ omo Pasin di Baálẹ̀. Lẹ́yìn ikú Alugbin, Àfònjá gorí oyè. Laderin, Pasin, Alugbin àti Àfònjá nìkan ni baálé tí ó jẹ ní ìlú Ìlọrin.
Aólẹ̀ Arógangan
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Aólẹ̀ jẹ ọba lẹ́yìn ikú Abíọ́dún ní ọdún 1789. Ìbátan Abíọ́dún ni Aólẹ̀. Aólẹ̀ jẹ́ ọkùnrin tí ó ga, tí ó sì rẹwà ṣùgbọ́n ojo ni. Àfọ̀njá ní ìbáṣepọ̀ tí ó ṣe rẹ́gí pẹ̀lú Aólẹ̀ nítorí wí pé Ààfin Aláàfin ni wọ́n bí Àfọ̀njá sí. Aólẹ̀ àti Àfọ̀njá bẹ̀rẹ̀ sí ní fura sí ara wọn, èyí ló ṣokùnfà èdè àyedè tí ó wà láàárín Aólẹ̀ àti Àfọ̀njá. Lásìkò ìjọba Aólẹ̀, ìwà ibi àti ìwà ìkà gba ìlú Ọ̀yọ́ kan. Ètò omonìyàn àwọn ará ìlú di títẹ̀ mọ́lẹ̀, ìwà ìkà àti ọ̀tẹ̀ jẹ́ nǹkan tí ó gba òde kan. Ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ará ìlú di títà sí òwò ẹrú.
Lẹ́yìn tí Aólẹ̀ jẹ Aláàfin, gẹ́gẹ́ bí àṣà àti ìṣe fún àwọn Aláàfin tuntun, Aólẹ̀ dárúkọ agbègbè kan tí wọ́n ti ń ná ọjà gegebi ibi ti ko nife si, agbegbe nan un je Apomu. Ni aye àtijọ, ìlú Apòmù jẹ́ ibi ìnájà fún àwọn ènìyàn tí ó wá láti Òyó, Ifẹ̀, Òwu àti ilẹ̀ Ìjẹ̀ṣà. Ọjà Apòmù yìí ni Aole ti ta ọ̀rẹ́ rẹ̀ sí oko ẹrú, ní ìgbà tí Baálẹ̀ ìlú Apòmù gbọ́ sí ìṣẹ̀lẹ̀ náà, ó pàṣẹ pé kí wọ́n gbé ọ̀rẹ́ Aólẹ̀ padà wá sí inú ìlú. Nǹkan tí Baálẹ̀ Apòmù se yìí bí Aólẹ̀ nínú, èyí ló fàá tí Aólẹ̀ fẹ́ fi sígun lo sí ìlú Apòmù. Ní ìgbà tí Baálẹ̀ ìlú Apòmù gbọ́ sí èyí, ó gb'ẹ̀mí ara rẹ̀ láti fi tu Aólẹ̀ lójú. Síwájú síi, Aólẹ̀ dárúkọ Àfònjá tí ó jẹ́ Ààrẹ Ònà Kakanfò gẹ́gẹ́ bíi ọ̀tá rẹ̀. Ní ọdún 1796, wọ́n gbìmọ̀ pọ̀ láti sígun fún Àfònjá láti kógun ja ìlú Ìwéré tí ó jẹ́ èèwọ̀ ní ìgbà náà láti kógun jà. Àfònjá gbọ́ sí ìgbìmọ̀ ọ̀tẹ̀ yìí, ó sì lẹ̀dí àpò pọ̀ pẹ̀lú Baṣọ̀run Àsàmú Agbaolekan àti Owota ti ìlú Òyó láti kọ ẹ̀yìn sí Oba. Wọ́n fi igbá tí ó sófo ráńsẹ́ sí Oba, èyí tí ó túmọ̀ sí wípé ìlú Òyó ti kẹ̀yìn sí Oba Aólẹ̀ àti wípé Oba ní láti gb'ẹ̀mí ara rẹ̀.
Adebo
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Lẹ́yìn ikú Aólè tí ó jẹ́ Oba fún ọdún méje, wọ́n fi Adebo je Oba. Ìgbà Adebo ò rogbo rárá, rògbòdìyàn ń ṣẹlẹ̀ ní ìlú Òyó àti àwọn ìlú yòókù tí Òyó ń se ìsàkóso lórí won. Ìlú Òyó di nǹkan yẹpẹrẹ ní ilẹ̀ Yorùbá. Opele tí ó jẹ́ Baálé ìlú Igbogun ni ó kọ́kọ́ yapa kúrò lábẹ́ ìsàkóso ìlú Òyó Oyo. Opele dá ológun tiẹ̀ sílẹ̀, ó sì gba ìlú Igbo-owu àti Idofian. Ní ìgbà tí ó fe gba ìlú Ìgbòho ni wọ́n pa Opele. Gégé bí ogbeni S. A. Akintoye ti wí, ìkùnà àwọn Ọ̀yọ́-mèsì láti fi Àfònjá je Aláàfin ló mú kí Àfònjá lọ dá ìjọba tiẹ̀ sílẹ̀ pẹ̀lú Ìlọrin gégé bí olú-ìlú. Láti gba òmìnira kúrò lọ́wọ́ Òyó, Àfònjá pinnu láti gba agbára kúrò lọwọ ìjọba Oyo. Fún ìdí èyí, ìgbésẹ àkọkọ tí Àfònjá gbé ni wípé ó so ìlú Ìlọrin di ìlú ńlá àti olú-ìlú. Ó je gàba lórí àwọn ìlú bíi Kanla, Ganmo, Idofian, Elehinjare, Oke-Oyi, Igbon, Iresa, Ibare àti bẹ́ẹ̀-bẹ́ẹ̀ lo. Láti fi kún agbára ológun rẹ, ó ráńsẹ́ pe Álímì tí ó jẹ́ Fúlàní àti àlùfáà ẹṣin mùsùlùmí sí ìlú Ìlọrin. Álímì jẹ́ ìpè náà, ó sì kó gbogbo àwọn ẹrú rẹ̀ tí ó jẹ́ Haúsá wá sí ìlú Ìlọrin, Àfònjá sì da gbogbo wọn pọ̀ mọ́ àwọn ológun rẹ̀. Síwájú síi, Àfònjá ránṣẹ́ pe ọrẹ olówó rẹ kan tí ó ń jẹ́ Solagberu. Solagberu jẹ́ ọrẹ Àfònjá tí ó ń gbé ní ọwọ́ ìta ìlú Ìlọrin tí à ń pè ní Òkè Súnà.
Ní bíi Ọdún 1817, Àfònjá so wípé òun yóò fún àwọn ẹlẹ́sìn mùsùlùmí àti ẹrú tí ó wà ní ìlú Òyó ní òmìnira àti ààbò tí wọn bá le sá wá sí ìlú Ìlọrin. Ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ẹrú Haúsá sá wá sí ìlú Ìlọrin ní ìgbà náà. Ọ̀PỌ̀LỌPỌ̀ won ni inú UN bí látàrí nǹkan tí àwọn olówó won ti fi ojú won rí ní ìlú Òyó. Fún ìdí èyí, wọn finnú fíndọ̀ darapọ̀ mọ́ àwọn omo-ogun Àfònjá. Àwọn tí ó darapọ̀ yìí jẹ omo ilẹ̀ Haúsá, Nupe, Bariba, Aja àti Fúlàní. Solagberu náà sì kó àwon èèyàn wá láti Gbanda, Kubajo, Agoho, Kuwo àti Kobe láti wá darapọ̀ mọ́ omo-ogun Àfònjá.
Gbogbo àwọn tí ó darapọ̀ mọ́ àwọn omo-ogun Àfònjá jẹ ẹlẹ́sìn mùsùlùmí, wọ́n sì rí àwọn yòókù bíi kèfèrí. Àsìkò yìí ló bẹrẹ ìjà ẹ̀sìn (Jihad) ní ilẹ Yorùbá. Wọ́n ń pe ara won ní Jamas, wọn tún ní àmì ìdánimọ̀ tí ó ń jẹ́ Kende. Ìgbésẹ kẹta tí Àfònjá gbé ni wípé ó kó gbogbo àwọn olórí ológun yòókù sí abé rẹ gégé bí Ààrẹ wọn. Èyí tí ó se pàtàkì jùlọ ni Toyeje, Baálẹ̀ ìlú Ogbomosho tí ó jẹ́ adarí àwọn omo-ogun rẹ ní apá ọtún fún Àfònjá. Fagbohun, Baálẹ̀ ìlú Jabata ní òun pàṣẹ ní apá òsì.
Òjó Agunbambaru, ọ̀kan lára àwọn omo Baṣọ̀run Gáà tí ó sálọ sí Bariba gbọ sí nǹkan tí ìlú Òyó ti dà. Ó pinnu wípé àsìkò ti tó láti gba ẹ̀san ikú bàbá rẹ̀ àti láti gba oyè Baṣọ̀run. Ó wá sí ìlú Òyó pẹlú àwọn omo-ogun Bariba láti kógun ja ìlú Òyó, Òjó àti àwọn omo-ogun rẹ̀ pa ọpọlọpọ àwọn ìjòyè ìlú Òyó pẹlu àwọn tí ó jẹ olóòótọ́ léyìn Àfònjá. Òjó gbéra pẹlu ọpọlọpọ àwọn omo-ogun láti sígun lọ bá Àfònjá, ó ku díẹ̀ kí ó ṣẹgun Àfònjá ṣugbọn Adegun ti Oníkòyí tí ó jẹ ọrẹ ìkọ̀kọ̀ Àfònjá kọ Ojo Imaginable sílẹ ní òjìji. Èyí ló fún Àfònjá ní ìṣẹgun. Òjó àti àwọn omo-ogun rẹ sálọ padà lo sí ilẹ̀ Bariba. Òkìkí Àfònjá gbòòrò si látàrí ìṣẹgun yìí. Oba Adebo kógun ja ìlú Gbogun, bí ogun náà se ń lo lọwọ, Oba Adebo kú ní ojú oorun rẹ. Ó je oba náà fún àádọ́jọ ọjọ́, léyìn ikú rẹ ni omo-oba Maku je Oba.
Maku
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Maku g'orí ìtẹ́ Oba lẹ́yìn ikú Adebo. Àfònjá kò mọ̀ sí bí Maku se je Oba. Maku kógun ja ilẹ̀ Iworo sùgbọ́n kò sẹ́gun. Lẹ́yìn èyí, ó sálọ sí ìlú Ìwó níbi tí ó ti gb'ẹ̀mí ara rẹ̀.
Ìṣubú Àfònjá
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Àfònjá di ọ̀kan soso alágbára nlá ní ilẹ̀Yoruba. Àfònjá gba àwọn oba àti ìjòyè láyè láti se ìsàkóso ìlú won fúnra won. Àwọn Jamas tí Àfònjá kójọ bẹ̀rẹ̀ jàgídíjàgan, wọ́n bẹ̀rẹ̀ sí ní ja àwọn omo ìlú ní olè. Àwọn ará ìlú kò le sọrọ sí nǹkan tí àwọn Jamas Àfònjá ń se nítorí tí wọ́n bẹ̀rù Àfònjá àti àwọn omo-ogun rẹ̀. Àfònjá ko etí ikún sí ohun gbogbo tí ó ń ṣẹlẹ̀ ní inú ìlú ní pàápàá lẹ́yìn ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìkìlọ̀. Lẹ́yìn ìgbà díẹ̀, àwọn Jamas yìí kò gbọ́rọ̀ sí Àfònjá lẹ́nu mọ́. Àfònjá pinnu láti tú won ká sùgbọ́n ẹ̀pa kò bóró mọ́. Àwọn Jamas pẹ̀lú Álímì tí ó jẹ́ adarí won kógun ja Àfònjá àti àwọn tí ó jẹ́ olóòótọ́ rẹ̀. Gégé bí ọ̀gbẹ́ni S.A Akintoye, ó wípé Àfònjá ké sí ọ̀rẹ́ rẹ̀ Solagberu láti ràn án lọ́wọ́ sùgbọ́n tí Solagberu kọ̀ jálẹ̀ nítorí wípé ó rí ì gẹ́gẹ́ bíi ẹ̀ṣẹ̀ sí ẹ̀sìn rẹ̀ láti kẹ̀yìn sí àwọn ẹlẹ́sìn Mùsùlùmí ẹgbẹ́ rẹ̀. Ọwọ́ te Àfònjá, wọ́n gb'ẹ̀mí rẹ̀, wọ́n tún jó òkú rẹ̀ títí tí ó fi di eérú.
Álímì tí ó jẹ́ àlùfáà fún àwọn Fúlàní bẹ̀rẹ̀ ìsàkóso lórí ìlú Ìlọrin. Àfònjá ni à ń rántí gégé bí Ààrẹ Ònà Kakanfò tí ó jẹ́ kí àwọn Fúlàní gba ìlú Ìlọrin. Sùgbọ́n Ọ̀mọ̀wé Ade Ajaye so wípé ó tó ọdún 1820 kí Álímì tó wá sí ìlú Ìlọrin ní ìgbà tí ìjọba ìlú Òyó ti ń wálẹ̀.
Ìsàkóso ìlú Ìlọrin wà ní abẹ́ àwọn Fúlàní. Àwọn Fúlàní wá sí ìlú Ìlọrin gégé bí àlejò, ojúlùmò àti oníbàásepọ̀ sùgbọ́n wọ́n lo ọ̀gbọ́n àyínìke fún àwọn Yorùbá.
Ìgbìyànjú Àkọ́kọ́ Láti Gba Ìlú Ìlọrin Padà
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Ikú Àfònjá dun àwọn Yorùbá lọ́pọ̀lọpọ̀. Àwọn Yorùbá bẹ̀rẹ̀ sí ní bẹ̀rù wípé àwon Fúlàní yóó gba gbogbo ilẹ̀ Yorùbá, látàrí èyí, wọ́n pinnu láti kó àwọn jagun-jagun jọ pẹ̀lú Toyoje tí ô jẹ́ Baálé ìlú Ogbomoso àti Ààrẹ Ònà Kakanfò ní ìgbà náà gẹ́gẹ́ bí i adarí. Sùgbọ́n Álímì ti fura sí èrò ogun àwọn Yorùbá. Álímì ti wádìí ogbọ́n ogun àwọn Yorùbá àti bí ó se le borí won. Àwọn jagun-jagun ilẹ̀ Yorùbá kó ara won jọ ní Ogele ṣùgbọ́n àwọn jagun-jagun ti ilẹ̀ Fúlàní pẹ̀lú àwọn ẹṣin àti ní pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́ Olóyè Solagberu ti Òkè Súnà tí ó jẹ́ alágbára ẹlẹ́sìn mùsùlùmí omo Yorùbá sẹ́gun àwọn jagun-jagun ilẹ̀ Yorùbá.
Ìgbìyànjú elẹ́ẹ̀kejì - Ogun Mugbamugba
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Àwọn alágbára ilẹ̀ Yorùbá parapọ̀ lẹ́ẹ̀kan síi láti gba ìlú Ìlọrin. Ogun náà ni wọ́n jà nínú oṣù Erénà àti oṣù Igbe ní ìgbà tí èso ìgbá wà ní ìta. Iyàn mú ní ìgbà náà nítorí ogun yìí. Àwọn Fúlàní sẹ́gun àwọn Yorùbá àti Monija tí ó jẹ́ Oba. Ogun yìí ni ogun ìkẹyìn tí Álímì jà. Omo Álímì Ọkùnrin tí ó ń jẹ́ Abudusalami jẹ́ Oba àkọ́kọ́ tàbí Emir ti ìlú Ìlọrin. Èyí jẹ́ ibẹrẹ jeje Emir dípò Oba ní ìlú Ìlọrin.[2]
Àwọn Ìtọ́kasí
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]- ↑ (PDF) https://dn790008.ca.archive.org/0/items/historyofyorubas00john/historyofyorubas00john.pdf. Retrieved 2025-12-05. Missing or empty
|title=(help) - ↑ Martin, Maria (2022-03-22). "Aribidesi Usman and Toyin Falola. The Yoruba from Prehistory to the Present. Cambridge: Cambridge University Press, 2019. 496 pp. Photographs. Bibliography. Index. $39.99. Paper. ISBN: 978-1-107-68394-5". African Studies Review (Cambridge University Press (CUP)) 65 (2): E19–E21. doi:10.1017/asr.2022.1. ISSN 0002-0206.