Ahmad Bamba
| Sheikh Dr Ahmad Bamba | |
|---|---|
| Ọjọ́ìbí | c. 1940 Kumasi, Gold Coast |
| Aláìsí | (ọmọ ọdún 82) Kano State, Nigeria |
| Resting place | Kano State, Nigeria |
| Successor | DR UMAR IBRAHIM |
| Àwọn ọmọ | 28 |
| Parent(s) |
|
Sheikh Ahmad Muhammad Ibrahim Bamba (c. ọdún 1940 sí ọjọ́ kẹjọ oṣù Kìíní, ọdún 2022) (أحمد بن محمد Aḥmad ibn Muḥammad) jẹ́ onímọ̀ kan nípa ẹ̀sìn Ìsìláàmù láti Ghana. Ó ṣiṣẹ́ gẹ́gẹ́ bí olùkọ́ ní Yunifásítì Báyéró, Kano. Ó kọ́ ẹ̀kọ́ Hadith Sahih al-Bukhari ní Mọ́ṣáláṣí rẹ̀ (Darul Hadis (Ilé ti Hadith)) ní Tudun Yola, Kano, Nàìjíríà. Wọ́n ń pè é ní Qala Haddasana,[1] gbólóhùn kan tó sábà máa ń lò nígbà tó bá ń kọ́ni lẹ́kọ̀ọ́. [2][3][4]
Ìbẹ̀rẹ̀pẹ̀pẹ̀ ayé rẹ̀
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Sheikh Dr. Ahmad Bamba ni a bí ní ọdún 1940. Ó dàgbà ní Alabar A.E.B. tàbí Nguwan Gonjawa, ìgbèríko kan ní ìlú ńlá Kumasi ti Ghana. Bàbá rẹ̀ ni Muhammad Ibrahim Bamba tí àwọn ìyá rẹ̀ sì ni Hajia Khadijah (Mma Adizatu) àti Hajia Fatima (Mma Hajia), àwọn ọmọbìnrin ti Mma Gyamata, tí ó jẹ́ ọmọbìnrin ti ọ̀jọ̀gbọ́n àti olórí àkọ́kọ́ ti agbègbè Gonja ní Kumasi, Mallam Sani.
Ẹ̀kọ́ ẹ̀sìn Ìsìláàmù rẹ̀ àkọ́kọ́ wá ní Wataniyya lábẹ́ àbójútó Sufi, Alhaji Baba Al-Waiz (Babal-Waiz) ní Kantudu. Ó parí ìwé ẹ̀kọ́ rẹ̀ lábẹ́ ìkọnilẹ́kọ̀ọ́ ilé bàbá rẹ̀. Ó tẹ̀síwájú nínú ẹ̀kọ́ rẹ̀ nípa fiqh (Òfin Ìsìláàmù) ó sì bẹ̀rẹ̀ pẹ̀lú Al - Ishmawiy lábẹ́ ìtọ́nisọ́nà Mallam Amadu Langonto (ọmọ Baba Ibrahim/Ibrah àti Imam ti Gonja). Lẹ́yìn náà, ó kẹ́kọ̀ọ́ lọ́dọ̀ olórí ẹ̀sìn Sunni àkọ́kọ́ ní Kumasi, Sheikh Abdul Samad Habibullah. Àwọn akẹ́kọ̀ọ́ ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ ni Mallam Imrana Musah, olórí ìjọ agbègbè Ashanti tí ó ti kú, Olórí Ìjọ Watanniyya, Mallam Muntari, Olórí Ìjọ Dagomba ní báyìí, Alhaji Lawal ti Baba Abbas (tí a mọ̀ sí Alhaji Nuhu Abbas), Mallam Zakari ti Alhaji Nuhu Kotokoli, Ustaz Umar, Olórí Ìjọ Yadiga, Alhaji Siidi, Mallam Muhammad Danraz, àti Mallam Dan Azumi.
Iṣẹ́
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Ó jẹ́ olùkọ́ ní Yunifásítì Báyéró fún ẹ̀ka ẹ̀kọ́ ẹ̀sìn Ìsìláàmù níbi tí ó tún ti kọ́ni ní ẹ̀kọ́ Hadith. Èyí ló mú kí wọ́n dá ilé ìjọsìn Darul Hadith' (Ilé Hadith) sílẹ̀ níbi tí ó ti tẹ̀síwájú pẹ̀lú áwọn ẹ̀kọ́ rẹ̀ lẹ́yìn tí ó fẹ̀hìntì lẹ́nu iṣẹ́.
Ikú
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Ó kú ní Ilé-ìwòsàn 'Aminu Kano Teaching Hospital' ní Ìpínlẹ̀ Kánò ní ọjọ́ keje oṣù Kìíní ọdún 2022, ní ọjọ́ orí èjì-lé-lọ́gọ́rin.[5][6]
Àwọn Ìtọ́kasí
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]- ↑ "Sheikh Ahmad Bamba, 'Kala Haddasana, na Kano ya rasu" (in ha). BBC News Hausa. https://www.bbc.com/hausa/labarai-59907798.
- ↑ "Sheikh Ahmad Muhammad Ibrahim Bamba: A tribute". Daily Trust (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). 11 January 2022. Archived from the original on 11 January 2022. Retrieved 15 January 2022.
- ↑ "Popular Kano cleric, Ahmad Bamba, is dead | Premium Times Nigeria" (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). 7 January 2022. Retrieved 15 January 2022.
- ↑ "Dr. Bamba's death hit the state very well: Ganduje - P.M. News" (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). Retrieved 15 January 2022.
- ↑ Lawal, Nurudeen (7 January 2022). "Breaking: Prominent Islamic scholar Dr Ahmad Bamba dies". Legit.ng - Nigeria news. (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). Retrieved 15 January 2022.
- ↑ "Sheikh Ahmad Bamba, 'Kala Haddasana, na Kano ya rasu" (in ha). BBC News Hausa. https://www.bbc.com/hausa/labarai-59907798.