Jump to content

Ahmadiyya

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́

Ahmadiyya jẹ́ ọ̀kan lára ẹ̀ka ẹ̀sìn Mùsùlùmí ní orílẹ̀-èdè Nàìjíríà lábẹ́ caliph ní orílẹ̀-èdè London.[1][2] Púpọ̀ lára àwọn ọmọ ẹgbẹ́ yìí ló wà láti apá Ìwọ̀-Òòrùn ní orílẹ̀-èdè Nàìjíríà. Gẹ́gẹ́ bí ọ̀kan lára àwọn ojúṣe ẹgbẹ́ náà sí àwùjọ, wọ́n ti kọ́ ilé-ìwé mẹ́wàá àti ilé-ìwòsàn méjì ni àgbègbè Apapa àti Ojokoro, ní Ìpínlẹ̀ Èkó.[3]

Ìdásílẹ̀ Ẹgbẹ́

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Wọ́n dá Ẹgbẹ́ [[[Ahmadiyya|Ahmadiyya]] sílẹ̀ ní British India, Mirza Ghulam Ahmad, ẹni tí ń gbìyànjú láti tún ẹ̀sìn Mùsùlùmí ṣe ni ó dá sílẹ̀; ní ọdún 1891, ó kéde pé wòlíì, mujaddid (“ẹni tí ń tún nǹkan se”), àti olùgbàlà tàbí Mahdi, èyí tí àwọn Mùsùlùmí ń retí ni òun.

Ètò Ìdarí Ẹgbẹ́

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Amir, ẹni tí wọ́n tún pè ní 'Ajíhìnrere tí ń Ṣàkóso' ni ò ń darí ẹgbẹ́ náà. Ó ní àwọn igbá-kejì mẹ́fà tí ń ràn án lọ́wọ́, ní àfikún, ìgbìmọ̀ kan tún wà ní àwọn àgbègbè tí ó yí wọn ká. Nayyar, Amir àti ajíhìnrere tí ń ṣàkóso àkọ́kọ́, ní ìgbìmọ̀ aláṣẹ ti orílẹ̀-èdè ni ọdún 1921. Ìgbìmọ̀ aláṣẹ ti orílẹ̀-èdè yìí ní Akọ̀wé-Àgbà, akọ̀wé tí ń ṣàkóso Tabligh, àbá-ni-ṣe-ṣírò, akọ̀wé owó àti àwọn aṣojú ẹ̀ka, káàkiri ẹgbẹ́ náà.[3]

Olùrànlọ́wọ́ Ẹgbẹ́ Náà Lórílẹ̀-Èdè Nàìjíríà

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Àwọn Ìtọ́kási

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]
  1. "Achievements of Ahmadiyya Muslim Jamaat in Nigeria
  2. "" Ahmadiyya movement nigeria". Archived from the original on 2020-03-23. Retrieved 2020-05-09. Unknown parameter |url-status= ignored (help)
  3. 1 2 says, Mudathir ridwan (1989-12-18). "History of Ahmadiyyat in Nigeria". Review of Religions (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). Retrieved 2020-06-07.

Àdàkọ:Ahmadiyya topics