Ahmadiyya
Ahmadiyya jẹ́ ọ̀kan lára ẹ̀ka ẹ̀sìn Mùsùlùmí ní orílẹ̀-èdè Nàìjíríà lábẹ́ caliph ní orílẹ̀-èdè London.[1][2] Púpọ̀ lára àwọn ọmọ ẹgbẹ́ yìí ló wà láti apá Ìwọ̀-Òòrùn ní orílẹ̀-èdè Nàìjíríà. Gẹ́gẹ́ bí ọ̀kan lára àwọn ojúṣe ẹgbẹ́ náà sí àwùjọ, wọ́n ti kọ́ ilé-ìwé mẹ́wàá àti ilé-ìwòsàn méjì ni àgbègbè Apapa àti Ojokoro, ní Ìpínlẹ̀ Èkó.[3]
Ìdásílẹ̀ Ẹgbẹ́
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Wọ́n dá Ẹgbẹ́ [[[Ahmadiyya|Ahmadiyya]] sílẹ̀ ní British India, Mirza Ghulam Ahmad, ẹni tí ń gbìyànjú láti tún ẹ̀sìn Mùsùlùmí ṣe ni ó dá sílẹ̀; ní ọdún 1891, ó kéde pé wòlíì, mujaddid (“ẹni tí ń tún nǹkan se”), àti olùgbàlà tàbí Mahdi, èyí tí àwọn Mùsùlùmí ń retí ni òun.
Ètò Ìdarí Ẹgbẹ́
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Amir, ẹni tí wọ́n tún pè ní 'Ajíhìnrere tí ń Ṣàkóso' ni ò ń darí ẹgbẹ́ náà. Ó ní àwọn igbá-kejì mẹ́fà tí ń ràn án lọ́wọ́, ní àfikún, ìgbìmọ̀ kan tún wà ní àwọn àgbègbè tí ó yí wọn ká. Nayyar, Amir àti ajíhìnrere tí ń ṣàkóso àkọ́kọ́, ní ìgbìmọ̀ aláṣẹ ti orílẹ̀-èdè ni ọdún 1921. Ìgbìmọ̀ aláṣẹ ti orílẹ̀-èdè yìí ní Akọ̀wé-Àgbà, akọ̀wé tí ń ṣàkóso Tabligh, àbá-ni-ṣe-ṣírò, akọ̀wé owó àti àwọn aṣojú ẹ̀ka, káàkiri ẹgbẹ́ náà.[3]
Olùrànlọ́wọ́ Ẹgbẹ́ Náà Lórílẹ̀-Èdè Nàìjíríà
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]- Majlis Ansarullah
- Lajna Imaillah
- Majlis Khuddam
- Majlis Atfal
- Nasirat
- Ahmadi Muslim Students' Association
Àwọn Ìtọ́kási
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Ìtọ́kási
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]- ↑ "Achievements of Ahmadiyya Muslim Jamaat in Nigeria
- ↑ "" Ahmadiyya movement nigeria". Archived from the original on 2020-03-23. Retrieved 2020-05-09. Unknown parameter
|url-status=ignored (help) - 1 2 says, Mudathir ridwan (1989-12-18). "History of Ahmadiyyat in Nigeria". Review of Religions (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). Retrieved 2020-06-07.
Cited sources
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]- Fisher, Humphrey J. (1963) (in en). Aḥmadiyyah: a study in contemporary Islām on the West African Coast. Nigerian Institute of Social and Economic Research. https://books.google.com/books?id=2lG_xQEACAAJ.
- Hanson, John H. (2017). The Ahmadiyya in the Gold Coast : Muslim cosmopolitans in the British Empire. Bloomington, Indiana: Indiana University Press. pp. 131–138. ISBN 978-0-253-02951-5. OCLC 971020961.