Jump to content

Ajomuzu Collette Bekaku

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́
Ajomuzu Collette Bekaku
Ọjọ́ìbí23 Oṣù Kẹ̀sán 1975 (1975-09-23) (ọmọ ọdún 50)
Mambanda Village, Cameroon
Ọmọ orílẹ̀-èdèCameroonian
Iléẹ̀kọ́ gígaUniversity of Yaounde II
Iṣẹ́Activist
Gbajúmọ̀ fúnFounder of Cameroon Association for the Protection and Education of the Child (CAPEC)

Ajomuzu Collette Bekaku (tí a bí ní ọjọ́ kẹtàlélógún oṣù ọwéwé ọdún 1975) jẹ́ ajìjàǹgbara fún ẹ̀tọ́ ọmọnìyàn, olórí àgbà àti olùdásílẹ̀ Ẹgbẹ́ Cameroon Association for the Protection and Education of the Child (CAPEC) tí ó ń ṣàkóso onírúurú iṣẹ́ àdúgbò títí bí ilé ìwé alákọ̀ọ́bẹ̀rẹ̀ àti ilé ìwé gírámà.

Ìgbésí ayé ìbéèrè

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

A bí i ní abúlé Mambanda, ní agbègbè gúúsù Ìwọ̀ Oòrùn orílè-èdè Cameroon, ìyá kan ṣoṣo ló tọ́ ọ dàgbà, ìyá rẹ̀ jẹ́ olùkọ́ ilé-ẹ̀kọ́ alákọ̀ọ́bẹ̀rẹ̀. Òun àti àwọn ọmọ akẹ́kọ̀ọ́ kíláàsì rẹ̀ ní láti ṣiṣẹ́ nínú okò ọ̀gẹ̀dẹ̀ àti rọ́bà láti ran àwọn òbí wọn lọ́wọ́. Iṣẹ́ tó léwu ní iṣẹ́ náà, èyí sì mú kí ó di ajìjàgbara fún àwùjọ.[1]

A.C. Bekaku (ọtun) pẹ̀lú àwọn olùkọ́ni ní ese kúkú àti àgbáyé ni oṣù kẹrin ọdún 2014

Ní ọdún 2003, ó jáde ní ilé-ẹ̀kọ́ gíga Yunifásítì Yaoundé Kejì gẹ́gẹ́ bí olú-ẹ̀kọ́ nípa òfin àti ìṣàkóso ìṣòwò.[2]

Nígbà tí ó ń kẹ́kọ̀ọ́ ní yunifásítì Yaoundé, ó ṣiṣẹ́ fún British Council tí orílè-èdè Cameroon.[3] Ní ọdún 2003 lẹ́yìn tí ó parí ẹ̀kọ́ rẹ̀, ó dá àwùjọ CAPEC sílẹ̀ àti àwọn ilé-ẹ̀kọ́ méjì lẹ́yìn náà.[2] Fún iṣẹ́ àkójọpọ̀ owó láti bójútó àwọn iṣẹ́ àkànṣe rẹ̀, ó lo itakun GlobalGiving, àti Indiegogo, àti àwọn ojú ọ̀nà ìkànnì ayélujára mìíràn.[4]

Ẹgbẹ́ Cameroon fún Ààbò àti Ẹ̀kọ́ Àwọn Ọmọdé (CAPEC)

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

CAPEC jẹ́ àjọ tí kìí ṣe fún èrè àti ti ìjọba tí ó wà ní ìlù Yaoundé. Láti ọdún 2003, ó ti ń ṣiṣẹ́ lórí ọ̀pọ̀lọpọ̀ iṣẹ́ àkànṣe láwùjọ, lọ́wọ́lọ́wọ́, ó ti ní àwọn ọ́fíìsì káàkiri ní Yaoundé àti Kumba ti o sì ní àwọn òṣìṣẹ́ tó lé ní ọgbọ̀n. Àwọn iṣẹ́ pàtàkì àwùjọ náà ni:

  • ìpín dogbá àti ikùn ní lápá
  • ìwòsàn àrùn / àrùn ìbálòpọ̀ / OVC (àwọn òpó àti ọmọ aláìní)
  • àkànṣe ètò ẹ̀kọ́.

Ètò rẹ̀ fún àwọn olùyọ̀ǹda ara-ẹni fún iṣẹ́ ìlú kárí ayé.[5] [6] A kà àwùjọ CAPEC sí ọ̀kan lára àwọn àjọ tí òun ṣe ìrànlọ́wọ́ fún ọmọdé tó dára jùlọ ní orílè-èdè Cameroon.[7]

Àwọn Ìtọ́kasí

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]