Ajomuzu Collette Bekaku
| Ajomuzu Collette Bekaku | |
|---|---|
| Ọjọ́ìbí | 23 Oṣù Kẹ̀sán 1975 Mambanda Village, Cameroon |
| Ọmọ orílẹ̀-èdè | Cameroonian |
| Iléẹ̀kọ́ gíga | University of Yaounde II |
| Iṣẹ́ | Activist |
| Gbajúmọ̀ fún | Founder of Cameroon Association for the Protection and Education of the Child (CAPEC) |
Ajomuzu Collette Bekaku (tí a bí ní ọjọ́ kẹtàlélógún oṣù ọwéwé ọdún 1975) jẹ́ ajìjàǹgbara fún ẹ̀tọ́ ọmọnìyàn, olórí àgbà àti olùdásílẹ̀ Ẹgbẹ́ Cameroon Association for the Protection and Education of the Child (CAPEC) tí ó ń ṣàkóso onírúurú iṣẹ́ àdúgbò títí bí ilé ìwé alákọ̀ọ́bẹ̀rẹ̀ àti ilé ìwé gírámà.
Ìgbésí ayé ìbéèrè
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]A bí i ní abúlé Mambanda, ní agbègbè gúúsù Ìwọ̀ Oòrùn orílè-èdè Cameroon, ìyá kan ṣoṣo ló tọ́ ọ dàgbà, ìyá rẹ̀ jẹ́ olùkọ́ ilé-ẹ̀kọ́ alákọ̀ọ́bẹ̀rẹ̀. Òun àti àwọn ọmọ akẹ́kọ̀ọ́ kíláàsì rẹ̀ ní láti ṣiṣẹ́ nínú okò ọ̀gẹ̀dẹ̀ àti rọ́bà láti ran àwọn òbí wọn lọ́wọ́. Iṣẹ́ tó léwu ní iṣẹ́ náà, èyí sì mú kí ó di ajìjàgbara fún àwùjọ.[1]
Ẹ̀kọ́
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]
Ní ọdún 2003, ó jáde ní ilé-ẹ̀kọ́ gíga Yunifásítì Yaoundé Kejì gẹ́gẹ́ bí olú-ẹ̀kọ́ nípa òfin àti ìṣàkóso ìṣòwò.[2]
Ìṣẹ́
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Nígbà tí ó ń kẹ́kọ̀ọ́ ní yunifásítì Yaoundé, ó ṣiṣẹ́ fún British Council tí orílè-èdè Cameroon.[3] Ní ọdún 2003 lẹ́yìn tí ó parí ẹ̀kọ́ rẹ̀, ó dá àwùjọ CAPEC sílẹ̀ àti àwọn ilé-ẹ̀kọ́ méjì lẹ́yìn náà.[2] Fún iṣẹ́ àkójọpọ̀ owó láti bójútó àwọn iṣẹ́ àkànṣe rẹ̀, ó lo itakun GlobalGiving, àti Indiegogo, àti àwọn ojú ọ̀nà ìkànnì ayélujára mìíràn.[4]
Ẹgbẹ́ Cameroon fún Ààbò àti Ẹ̀kọ́ Àwọn Ọmọdé (CAPEC)
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]CAPEC jẹ́ àjọ tí kìí ṣe fún èrè àti ti ìjọba tí ó wà ní ìlù Yaoundé. Láti ọdún 2003, ó ti ń ṣiṣẹ́ lórí ọ̀pọ̀lọpọ̀ iṣẹ́ àkànṣe láwùjọ, lọ́wọ́lọ́wọ́, ó ti ní àwọn ọ́fíìsì káàkiri ní Yaoundé àti Kumba ti o sì ní àwọn òṣìṣẹ́ tó lé ní ọgbọ̀n. Àwọn iṣẹ́ pàtàkì àwùjọ náà ni:
- ìpín dogbá àti ikùn ní lápá
- ìwòsàn àrùn / àrùn ìbálòpọ̀ / OVC (àwọn òpó àti ọmọ aláìní)
- àkànṣe ètò ẹ̀kọ́.
Ètò rẹ̀ fún àwọn olùyọ̀ǹda ara-ẹni fún iṣẹ́ ìlú kárí ayé.[5] [6] A kà àwùjọ CAPEC sí ọ̀kan lára àwọn àjọ tí òun ṣe ìrànlọ́wọ́ fún ọmọdé tó dára jùlọ ní orílè-èdè Cameroon.[7]
Àwọn Ìtọ́kasí
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]- ↑ "Ajomuzu Collette Bekaku - Bitame Lucia Nursery and Primary School in Nkolfoulou, Cameroon". blis.cam. Retrieved 2019-01-10.
- 1 2 "Interview with Ajomuzu Collette Bekaku - founder and executive director of CAPEC". Develop Africa.org. Retrieved 22 March 2026.
- ↑ "Ajomuzu Collette Bekaku". LinkedIn.
- ↑ "Building School in Cameroon - part 2.". Indiegogo (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). Retrieved 2019-01-10.[Ìjápọ̀ tí kò ṣiṣẹ́ mọ́]
- ↑ "Cameroon Association for the Protection and Education of the Child (CAPEC) |" (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). Retrieved 2019-01-10.
- ↑ "Legal References". www.capecam.org. Retrieved 2019-01-10.[Ìjápọ̀ tí kò ṣiṣẹ́ mọ́]
- ↑ "Help make a difference with the gift of education - busuu blog" (in en-US). busuu blog. 2012-12-03. https://blog.busuu.com/charity.
- CS1 Èdè Gẹ̀ẹ́sì-language sources (en)
- All articles with dead external links
- Articles with dead external links from March 2026
- Articles with invalid date parameter in template
- Articles with permanently dead external links
- Articles with dead external links from April 2026
- Pages containing cite templates with deprecated parameters