Akanni Wright
Akanbi Wright tí a tún mọ̀ sí Akanbi Ègé jẹ́ olórin ọmọ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà láti ìlú Èkó, tí ó sì tún jẹ́ ọ̀kan pàtàkì nínú ìtàn ìbẹ̀rẹ̀ pẹ̀pẹ̀ orin juju, ó jẹ́ gbajú gbajà tí ó máa ń lo ìlù gangan nínú oríṣìí orin kíkọ yìí.[1] Orin rẹ̀ di ìlú mọ̀-ọ́n-ká ní ọ̀wọ́ ọdún 1930, nígbà tí ó ṣeré pẹ̀lú àwọn ẹgbẹ́ olórin kan tó ti di ògbóǹtarìgì nínú orin Juju, ẹni tí orúkọ adarí wọ́n ń jẹ́ Julius Araba. Àwọn àkóónú orin Wright máa ń dá lé ọ̀rọ̀ òṣèlú ní tílé toko, onígbọ̀wọ́ NNDP Herbert Macaulay ni, àwo rẹ̀ tó sì gbẹ̀yìn ni Demo lo L'eko, ìfọ́nu nípa ìgbọ̀wọ́ tí NNDP tàn ká ní ìlú Èkó ni.[2] Nígbà ogun, ó kọ orin láti ṣe ìgbọ̀wọ́ fún ogun ilẹ̀ Bírítìṣì àti ìlàkàkà àwọn ọmọ ogun ilẹ̀ Nàìjíríà ní Burma,tí orin náà sì di ìlú mọ̀-ọ́n-ká, àwọn ọmọ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà márùn-ún tí wọ́n jẹ́ R.A.F[2] àwọn bí márùn-ún tí wọ́n jẹ́ ọmọ ogun orílẹ̀-èdè Nàìjíríà ni wọ́n wọlé gẹ́gẹ́ bi ológun orí Òfurufú.
Wright dàgbà ní àdúgbò Olówógbowó, nígbà yẹn tí àwọn ará ìlú Saro tẹ̀dó. Ó yí orúkọ Bàbá rẹ̀ kúrò ní Wright sí Ege, láti ṣe àtìlẹ̀yìn fún ìlàkàkà orílẹ̀-èdè Nàìjíríà.[2]
Àwọn àwo
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]- Everybody likes saturday night
- The five Nigeran RAF
- Ẹ̀mí mi lọ́wọ́ rẹ
- Ọ̀rẹ́ mi Ọ̀rẹ́ mi
- Ọ̀rẹ́ aláìda
- Hitler tó ń da ayé rú
- Ìyàwó tí mo kọ́kọ́ fẹ́
Àwọn ìtọ́kasí
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]- ↑ Waterman, Christopher Alan (1990). Jùjú : a social history and ethnography of an African popular music. Chicago: University of Chicago Press. pp. 66,82. ISBN 0226874648. OCLC 20594122. https://archive.org/details/jjsocialhistorye0000wate/page/66.
- 1 2 3 Ajayi., Thomas, T. (1992). History of juju music : a history of an African popular music from Nigeria ([1st ed.] ed.). [Jamaica, NY]: The Organization. pp. 126-128. ISBN 0963326104. OCLC 27409755. https://archive.org/details/historyofjujumus00thom/page/126.
- ↑ (in en-US) West Africa, His Master’s Voice JL 1-39 – afrodisc.com. http://afrodisc.com/west-africa/emi-west-african-labels/west-africa-his-masters-voice-jl-1-39/.