Jump to content

Akinwumi Ogundiran

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́
Akinwumi Ogundiran
Born1966 (ọmọ ọdún 5960)
InstitutionsNorthwestern University
Alma materBoston University

Akinwumi OgundiranAkinwumi_Ogundiran.wav listen (wọ́n bíi ní odún un 1966)tí wọ́n tún mọ̀ sí Cardiss Collins jẹ́ Ọ̀jọ̀gbọ́n níbi iṣẹ́ ọnà àti nínú ìmò ìjìnlẹ̀ sáyẹ̀ǹsì ó sì tún jẹ́ Ọ̀jọ̀gbọ́n nínú ìmò ìtàn ní Yunifásítì tó wà ní Northwestern ní orílè-èdè Nàìjíríà.[1]Ó jẹ́ olùwádìí ìmọ̀ nípa àṣà ayé ìgbà nnì (archaeologist), Òpìtàn onímọ̀ ni pẹ̀lú (anthropologist) , ó sì tún jẹ́ Akọ̀wé ìtàn àṣà, tí ìwádìí rẹ̀ dojú kọ ìgbé ayé [[Àṣà Yorùbá|Yorùbá] ní ìwọ oòrùn Áfíríkà, Áfíríkà Atlantiki, àti ìtàn ìtànkálẹ̀ àwọn ọmọ Áfíríkà káàkiri ayé (African Diaspora). Wọ́n bí i ní Ìbàdàn, ní orílè-èdè Nàìjíríà , ó sì kó lọ sí Orílẹ̀-Èdè Amẹ́ríkà ní ọdún 1993. Ó jẹ́ Ọ̀jọ̀gbọ́n-on Chancellor, àti Ọ̀jọ̀gbọ́n nínú ẹ̀ka Africana Studies, òwúlẹ̀wútàn àti onímọ̀ nínú ìtàn History ní UNC Charlotte.[2]


Akinwumi Ogundiran kẹ́kọ̀ọ́ gboyè BA pẹ̀lú ọlá ìpele àkọ́kọ́ (First Class Honors) ní ilé-ẹ̀kọ́ gíga Obafemi Awolowo Yunifásítì ní ọdún 1988. Lẹ́yìn náà, ó gba MSc ní ilé-ìwé gíga UI ní ọdún 1991. Ní ọdún 2000, ó parí PhD rẹ̀ ní Boston University.[2] Ó sọ àtẹ̀jáde ìwádìí (thesis) rẹ̀ ni àkọlé yìí: Ìyípadà ìbùgbé àti ìbáṣepọ̀ agbègbè ní àárín ilẹ̀ Yorùbá láti ọdún 1200 sí 1900: Àròkọ ìwádìí ìtàn ìlú (archaeology) àti ìtàn ní agbègbè Ìlàrè,ní orílè-èdè Nàìjíríà Settlement cycling and regional interactions in central Yorùbá-land, AD 1200-1900: Archaeology and history in Ìlàrè district, Nigeria.[3]


Iṣẹ́ Ààyò Rẹ̀

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]
Ní ọdún 1991, Ogundiran ṣiṣẹ́ gẹ́gẹ́ bí olùṣàtúnṣe ìròyìn (newsroom editor) ní ní ilé-iṣẹ́ ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ kan tó wà ní ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́ Broadcasting Corporation of Oyo State ní orílẹ̀ èdè Nàìjíríà. Ó bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ ìkọ́ni rẹ̀ ṣáájú ìkẹ́kọ̀ọ́ gboyè ìwé ẹ̀ríi dókítà ní orílè-èdè Nàìjíríà ní ilé ẹ̀kọ́ gíga ní ìpínlè Dẹ́ltà Delta State University àti Yunifásítìi Benin. Lẹ́yìn ìkẹ́kọ̀ọ́ gboyè dókítà rẹ̀, iṣẹ́ ìkọ́ni rẹ̀ bẹ̀rẹ̀ ní Ẹ̀ka Ìmọ̀ Ìtàn (Department of History) ní  Yunifásítì tó wà ní Florida (Florida International University), ní Miami.[2] Láti ọdún 2008 sí 2018, Ogundiran jẹ́ alágà fún ẹ̀ka Ìtẹ́-ẹ̀kọ́ Africana (Chair of the Africana Studies department) ní UNC Charlotte, níbi tí ó ti Ọ̀jọ̀gbọ́n Kánsẹ́lọ̀ tí ó sì tún jẹ́ Ọ̀jọ̀gbọ́n Ìtẹ́-ẹ̀kọ́ Africana, Òwúlẹ̀wútàn (Anthropology) àti ìmọ̀ Ìtàn (History).[1] Iṣẹ́ Ìwádìí rẹ̀ dá lórí àròkọ-ìtàn àwòrán ilẹ̀ (archaeology) ìdàgbàsókè àwùjọ àti ìtàn ìṣẹ̀dálẹ̀ àwọn ọmọ Yorùbá people ní apá ìwọ̀-oòrùn Áfíríkà, pàápàá jùlọ lórí àwọn ìbéèrè tó kan ìfarahàn nípa àwọn olùgbé àgbègbè náà, àti nípa ìdàgbàsókè àwùjọ, àti ìtàn àṣà láàárín ọdún 1000 sí 1800 AD. Ogundiran tún ti ṣètò àti darí àwọn iṣẹ́ ìwádìí àjọṣepọ̀ lórí àròkọ-ìtàn ilẹ̀ ti Atlantic Africa àti African Diaspora.Àwọn àgbègbè iṣẹ́ mìíràn tí ó tún ń ṣiṣẹ́ lórí ni ìrònú ọgbọ́n ọkàn àwọn aláwọ̀ dúdú (Black Intellectual Thought), ìdúróṣinṣin àwùjọ, ìwé kíkọ lórí àtúpalẹ̀ ìtàn, àti àwọn ohun àjogúnbá.[2]


Àwọn Ìtọ́kasí

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]
  1. 1 2 "Akin Ogundiran: Department of History - Northwestern University". history.northwestern.edu (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). Retrieved 2023-09-30. Àṣìṣe ìtọ́kasí: Invalid parameter "wọ́n" in <ref> tag. The supported parameters are: details, dir, follow, group, name.
  2. 1 2 3 4 "Akin Ogundiran". Akin Ogundiran (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). Retrieved 2020-06-21.
  3. "BU Library". buprimo.hosted.exlibrisgroup.com. Retrieved 2020-06-21.