Jump to content

Aladura

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́

Àdàkọ:Infobox Christian denomination

Ọ̀rọ̀ yìí "Aladura" túmọ̀ sí "ẹni tí ó máa ń ṣe àdúrà" ní èdè Yoruba. Aladura jẹ́ ọ̀kan lára àwọn ìpínsọ́wọ̀ọ́ àwọn ilé ìjọsìn tí ó jẹ́ ti ìbílẹ̀ èyí tí ó bẹ̀rẹ̀ ní ilẹ̀ Yorùbá ní nǹkan bíi ìbẹ̀rẹ̀ ogún sẹ́ńtúrì sẹ́yìn. Àwọn ilé ìjọsìn yìí ní ìgbàgbọ́ kíkún àdúrà ṣíṣe àti ìtọ́nisọ́nà láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run nípasẹ̀ ẹ̀mí mímọ́ nínú gbogbo ohun tí wọ́n bá ń ṣe.

Ilé ìjọsìn àkọ́kọ́ tí a mọ̀ pé ó jẹ́ ọ̀kan lára àwọn Aladura bẹ̀rẹ̀ pẹ̀lú Abbieassalem Samuel Somoye ẹni tí wọ́n mọ̀ sí (Baba Dada) ní ọdún 1918 ní Abule Dada ní Ìpínlẹ̀ Ògùn, tí ó wà ní orílẹ̀ èdè Nàìjíríà.

Àwọn ìjọ tí a mọ̀ gẹ́gẹ́ bí ìjọ Aladura jẹ́ àwọn èyí tí a le yà sọ́tọ̀ pẹ̀lú àwọn ìwà àti ìṣe àwọn Àpọ́sítélì, àwọn tí wọ́n dá àwọn ilé ìjọsìn yìí sílẹ̀ jẹ́ àwọn tí Jésù pè fúnra rẹ̀. Jésù sọ nínú ọ̀rọ̀ rẹ̀ pé: ilé mi yóò jẹ́ èyí tí a ó máa pè ní ilé àdúrà.

Àwọn ilé ìjọsìn Aládùúrà tẹpẹlẹ mọ́ agbára àdúrà, àwọn orin tí wọ́n kún fún àdúrà, àti ọ̀rọ̀ Ọlọ́run (èyí tí ó ń bẹ nínú Bíbélì àti èyí tí ó ti ẹnu àwọn wòlíì jáde).

Wọ́n gbàgbọ́ nínú ohun mímọ́. They believe in holiness. Àwọn Yorùbá a sì máa pè wọ́n ní "ìjọ-mímọ́". Àwọn ìjọ Aladura jẹ́ ìjọ tí wọ́n ti máa jíhìnrere àti àwọn àbùdá to jọ mọ́ Pentecostalism.

Ọ̀pọ̀ nínú àwọn olùdásílẹ̀ ní sẹ́ńtúrì ogún sẹ́yìn jẹ́ Anglicans àti Methodists. Wọ́n kọ àwọn agbára ìbílẹ̀ àwọn ẹ̀sìn ilẹ̀ Áfíríkà. Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n kọ àwọn onírúurú ìwà bíi: ìwà fífẹ́ ju aya kan lọ àti ṣíṣe àwọn ògùn búburú, tí wọ́n sì gbájúmọ́ àwọn ìwà mímọ́.[1]

Ní àkókò tí a wà yí, onírúurú àwọn ilé ìjọsìn ní orílẹ̀-èdè Nàìjíríà ni a le pè ní "Aladura", ní ọ̀nà kan tàbí èkejì àwọn náà tí gba ara àwọn ìjọ yìí kọjá.

Àwọn ilé ìjọsìn Aládùúrà tí wọ́n jẹ́ ojúlówó pẹ̀lú àwọn olùdásílẹ̀ wọn:

Àwọn Aladura ṣáájú ọdún 1960

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Àwọn ilé ìjọsìn Aladura tí ó ti wà ṣáájú ọdún 1960 jẹ́ àwọn tí wọ́n máa ń pè ní "Àwọn ìjọ Alásọ funfun".

Samuel A. A. Somoye[2]

  • Ilé ìjọsìn ti Olúwa (Church of the Lord) (Aladura) 1918 ní Abule Dada, ní Ìpínlẹ̀ Ogun, ní orílẹ̀-èdè Nàìjíríà.

Moses Orimolade,

David O. Odunbanjo, Joseph Sadare, Oba Babalola Akinyele, Sophia Odunlami, àti àwọn mìíràn

Joseph A. Babalola,

SBJ Oschoffa,

Àwọn Aladura lẹ́yìn ọdún 1960

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

J.O. Akindayomi,

W.F. Kumuyi

Àwọn Aladura lẹ́yìn ọdún 2000

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Michael C. Egbo

  • Kings Apostolic Christ Evangelical Mission KACEM

Aladura ṣáájú ọdún 1960

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Eternal Sacred Order of Cherubim and Seraphim

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Moses Orimolade Tunolase, ẹni tí wọ́n padà pè ní Baba Aladura, tàbí Bàbá tí ó máa ń ṣe àdúrà, ó dá ìjọ Eternal Sacred Order of Cherubim and Seraphim sílẹ̀ ní ọdún 1925, gẹ́gẹ́ bíi ẹgbẹ́ aládùúrà láàrin ìjọ Anglican. Ọmọbìnrin tí Alàgbà Christiana Abiodun gbà tọ́ bọ́ sínú ìdè, nígbà náà ni Moses Orimolade Tunolase, ẹni tí ó ti di Ajíhìnrere àti olùkọ́ ni ó ní àǹfààní láti wò ó sàn nínú ìdè tí ó wà. Ní nǹkan bíi ọdún 1925 wọ́n ti fi ìjọ Anglican sílẹ̀ láti dá dúró. Iṣẹ́ kan gbòógì tí àwọn ìjọ yìí gbé dání ni láti tú àṣírí àwọn àjẹ́ kí wọ́n ó sì kọjú wọn ní ìta gbangba nígbà tí wọ́n bá wà ní Ìrìnàjò àti jíhìnrere káàkiri ìlú. Àwọn Ìrìnàjò ọlọ́jọ́ pípẹ́ yìí ni a mọ àwọn ìjọ Kébúrù àti Sẹ́ráfì (Cherubim and Seraphim) mọ́ gẹ́gẹ́ bí a ti mọ̀ wọ́n mọ́ Ajíhìnrere àti Arìnrìn-àjò. Ní àkókò yìí ilé ìjọsìn yìí jẹ́ ọ̀kan lára àwọn ilé ìjọsìn tí ó gbajúgbajà tí ọ̀pọ̀ ènìyàn sì máa ń lọ pẹ̀lú káàkiri gbogbo àgbáyé.

The Apostolic Church àti Christ Apostolic Church

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Ìjọ àkọ́kọ́ àwọn Aládùúrà jẹ́ èyí tí ó bẹ̀rẹ̀ láti St. Saviour's Anglican Church, ní Ijebu-Ode, ní orílẹ̀ èdè Nàìjíríà ní ọdún 1918. The Sexton, Ali, rọ́ àlá fún àwọn àgbààgbà ìjọ mẹ́rin, J.B. Sadare, E.O. Onabanjo, D.C. Oduga and E.O.W. Olukoya. Wọ́n dá àwọn àkókò ṣíṣe àdúrà sílẹ̀. Wọ́n bẹ̀rẹ̀ dá ikọ̀ àwọn aládùúrà sílẹ̀, èyí tí ọ̀pọ̀ ènìyàn mọ̀ sí "Ẹgbẹ́ Aládùúrà". Lẹ́yìn tí D.O. Odubanjo dara pọ̀ mọ́ ikọ̀ yìí ní ọdún 1919, wọ́n di gbajúmọ̀ pẹ̀lú àwọn ọ̀nà ìṣe àwọn Faith Tabernacle ti Philadelphia. Wọ́n kọ ìtẹ̀bọmi fún àwọn ọmọ ìkókó àti gbogbo ohun tí ó bá ń jẹ́ òògùn ìwòsàn, yálà tí ìbílẹ̀ ni tàbí tí àwọn ará òkè òkun. Èyí sì fa ìjà nínú ìgbàgbọ́ láàrin Anglican Church tí ó sì ṣe okùnfà bí wọ́n ṣe lé wọn kúrò nínú ilé ìjọsìn. Èyí mú kí Joseph Sadare ó fi ipò rẹ̀ sílẹ̀ nínú Synod tí wọ́n sì pa á ní dandan fún àwọn ìyókù láti kọ̀wé fi iṣẹ́ wọn sílẹ̀ àti mímú àwọn ọmọ wọn kúrò ní ilé ẹ̀kọ́ Anglican School. Ikọ̀ àwọn Aladura bẹ̀rẹ̀ Ìrìnàjò nípa ṣíṣe àwárí ẹ̀mí Ọlọ́run tí ó jẹ́ ojúlówó.[3]

Ìjọ alásọ funfun ti àwọn ọmọlẹ́yìn Kírísítì

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Ìjọ alásọ funfun ti àwọn ọmọlẹ́yìn Kírísítì (Celestial Church of Christ) èyí tí ọ̀pọ̀ àwọn ènìyàn mọ̀ sí (ìjọ Cele) jẹ́ èyí tí wọ́n dá sílẹ̀ ní ọdún 1947, ẹni tí ó jẹ́ olùdásílẹ̀ ìjọ náà ni Alàgbà Samuel OshoffaPorto Novo, ní ìlú Benin.

Àwọn Ìtọ́kasí

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]
  1. "Aladura Churches in Nigeria". rlp.hds.harvard.edu. Archived from the original on 2020-09-21. Retrieved 2025-02-08.
  2. YorubaGidiTV (2023). "FIRST WHITE GARMENT CHURCH IN NIGERIA". YouTube.
  3. Abi Olowe; Great Revivals, Great Revivalist – Joseph Ayo Babalola, Omega Publishers, 2007

Àdàkọ:Yoruba topics Àdàkọ:Religion topics