Jump to content

Ateke Tom

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́

Ateke Tom (ojoibi 2 osu kefa 1964) [1] jẹ olórí àgbègbè ìbílè àti Amanyanabo akọkọ ti ìlú Okochiri, ẹnì ti o je olórí tẹ́lẹ̀ ti Niger Delta Vigilante, omo-ogun ẹ̀yà Ijaw ní àgbègbè Niger Delta orílè-èdè Nàìjíríà . Ni Oṣu Kẹjọ ọdun 2007, lẹhin awọn ọjọ ti ìjà láàrin awọn ẹgbẹ ológun oríṣiríṣi ati awọn ológun ààbò ni ìlú Port Harcourt, Ateke Tom kọwe si Gómìnà ti Ìpínlẹ̀ Rivers Celestine Omehia, ti o bèèrè ìdáríjì ni ìdáhùn si itọnu àti imupadabọ ti ijọba ti fun awọn ọmọ-ogun ti o fi ará wọn silẹ.

Ni ọjọ 1 Oṣu Kẹwa Ọdun 2009, ọdun 49th ti ominira Nàìjíríà ati ọjọ mẹta ṣaaju pipade ètò ìdáríjì ijọba kan, Tom fi tinútinú jọwọsilẹ fun Alákóso Umaru Musa Yar'Adua ni Ilé Ijọba, Abuja . Won rán baalu Ààrẹ láti gbé Tom lo sì ìlú Abuja, Ààrẹ náa si so pe “Loni, Olóyè Tom Ateke o ti fun mi ni ẹ̀bùn aseye òmìnira odun kokandinlaadota, mọ si féràn re púpọ̀. Bákannáà ni Igbakeji Aare Goodluck Jonathan na wá níbè , Mínísítà fun Idaabobo Gbogbogbo Godwin Abbe, Akọwe si Ijọba àpapọ̀ Yayale Ahmed, Olóyè Agbófinró Paul Dike ati Oludamoran Ààbò orílè-èdè Abdullahi Sarki Mukhtar, láàrin awọn mìíran. [2]

Ni ọjọ 25 Oṣu kọkanla ọdun 2017, Ateke Tom jẹ ade bi Amanyanabo akọkọ ti Okochiri. Eto ayẹyẹ náa ni Ezenwo Wike, Gómìnà ipinle Rivers lo peju si. [3] [4]

  • Epo ilẹ Nigeria
  • Ogun Epo Nàìjíríà
  • Ijaw