Jump to content

Ayélóyún

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́
Qamardeen Odunlami
Orúkọ àbísọQamardeen Yusuf Odunlami
Ọjọ́ìbí27 Oṣù Kẹjọ 1973 (1973-08-27) (ọmọ ọdún 52)
Lagos state, Nigeria
Ìbẹ̀rẹ̀Ilorin, Kwara state
Irú orin
Occupation(s)
  • Singer
  • songwriter
  • musician
  • composer
Years active1992–present

Qamardeen Yusuf Odunlami ( tí a bí ní ọjọ́ kẹtàdínlọ́gbọ̀n oṣù kẹjọ ọdún 1973) [1] tí gbogbo ènìyàn mọn sí orúkọ orí ìtàgé rẹ̀ tín ṣe Ayéloyun, ẹni tí a mọ̀ sí olórin àti olùṣeorin ẹ̀sìn Islam ní Nàìjíríà. Ó gbé àwo orin àkọ́kọ́ rẹ̀ jáde Taqwallah ní ọdún 1994, àwo orin rẹ̀ Igbeyawo sì jáde ní ọdún 2003, èyí tí ó jẹ́ àwo orin kẹsàn-án rẹ̀, ó sì mú kí ó gbajúmọ̀, kí o sì lókìkí.

Ìbẹ̀rẹ̀ Ìgbésí ayé àti ẹ̀kọ́

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

A bí Ayeloyun ní Agege, Èkó, Nàìjíríà sì ìdílé ọlọ́mọ méje. Ní ọdún 2006, wọn gbàá wọlé sí Yunifásítì Ilorin, Ìpínlẹ̀ Kwara láti kẹ́kọ̀ọ́ nípa Sharia àti Òfin Àpapọ̀ ṣùgbọ́n ó fi ilé ìwé náà sílẹ̀ láti gbájú mọ́ iṣẹ́ orin. [2] [3]

Nígbà tí Ayeloyun wà ní kékeré, ó bẹ̀rẹ̀ sí í ṣe àwárí ìfẹ́ rẹ̀ sí orin nígbà tí ó wà ní kíláàsì èdè Lárúbáwá ní Marcaz, Agege, níbi tí ó ti kọrin nígbà Laylat al-Qadr àwẹ̀ Ramadan nítorí pé àwọn asíwájú rẹ̀ kò sí níbẹ̀ nígbà náà[4]. Ó bẹ̀rẹ̀ orin gẹ́gẹ́bí iṣẹ́ ní ọdún 1992 láti kojú ìbàjẹ́ ẹ̀sìn nínú Islam, ó sì gbé àwo orin àkọ́kọ́ rẹ̀ jáde ní ọdún 1994, ó sì ti gbé àwo orin mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n jáde tí ó sì gba ìyìn rẹ̀. [5]

Àwọn ìtọ́kasí

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]
  1. https://www.vanguardngr.com/2011/06/i-spent-18-months-in-my-mother%E2%80%99s-womb-aiyeloyun-2/
  2. https://thenationonlineng.net/day-a-fan-kissed-me-in-the-public-aiyeloyun/
  3. https://ayeloyungloballink.wordpress.com/2016/05/26/first-blog-post/
  4. https://www.nigeriafilms.com/celebrity-gossips/80-interviews/14740-i-still-want-to-be-a-lawyer-islamic-singer-ayeloyun[Ìjápọ̀ tí kò ṣiṣẹ́ mọ́]
  5. https://thenationonlineng.net/day-a-fan-kissed-me-in-the-public-aiyeloyun/