Jump to content

Balaraba Ramat Yakubu

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́
Balaraba Ramat Yakubu
Balaraba Ramat Yakubu
Ado Ahmad Gidan Dabino MON with Balaraba Ramat Yakubu at Abuja during the premiere of the film Juyin Sarauta
Ọjọ́ìbí1959 (ọmọ ọdún 6667)
Kano, Northern Region, British Nigeria (now in Kano State, Nigeria)
Iṣẹ́Writer

Balaraba Ramat Yakubu (tí a bí ní ọdún 1959) jẹ́ òǹkọ̀wé ọmọ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà tí ó ń kọ̀wé ní èdè Hausa . Ó jẹ́ olórí nínú oríṣi ìwé orin soyaya littattafan tàbí "ìwé ìfẹ́", ó sì jẹ́ ọ̀kan lára àwọn òǹkọ̀wé èdè Hausa díẹ̀ tí a ti túmọ̀ iṣẹ́ wọn sí èdè Gẹ̀ẹ́sì. Ó tún ti ṣiṣẹ́ gẹ́gẹ́ bí òǹkọ̀wé lórí fíìmù, olùgbéréjáde, àti olùdarí àwọn fíìmù Kannywood . Àwọn ìtàn rẹ̀ dá lórí àwọn ọ̀ràn bí ìgbéyàwó ìfipámúni àti ẹ̀kọ́ àwọn obìnrin. [1]

Ìgbésí ayé ìbẹ̀rẹ̀

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Balaraba Ramat Yakubu ni àbúrò General Murtala Ramat Muhammed, [2] tó ṣiṣẹ́ gẹ́gẹ́ bí olórí ológun ní Nàìjíríà fún ìgbà díẹ̀ láti ọdún 1975 títí di ìgbà tí wọ́n pa á ní ọdún 1976.

Nígbà tí ó pé ọmọ ọdún mẹ́tàlá, wọ́n mú un kúrò nílé ìwé, wọ́n sì fipá mú un láti ṣe ìgbéyàwó ní ìgbà èwe. [3] Ó ti sọ pé ìdí nìyí tí òun fi ń kọ̀wé ní èdè Hausa dípò èdè Gẹ̀ẹ́sì. [4]

Balaraba Ramat bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí obìnrin kan ṣoṣo tó wà nínú ẹgbẹ́ òǹkọ̀wé tó ní ipa lórí ìlú Kano, Raina Kama. [5] Ìwé ìtàn rẹ̀ àkọ́kọ́, Budurwar Zuciya ("Young at Heart"), ni wọ́n tẹ̀ jáde ní ọdún 1987. Àwọn ìwé ìtàn rẹ̀ kejì àti kẹta, Alhaki Kwikwiyo Ne... ("Ẹ̀ṣẹ̀ jẹ́ ọmọ aja tí ó ń tẹ̀lé ọ sílé") àti Wa zai auri jahila? ("Ta ló máa fẹ́ obìnrin aláìmọ̀kan?"), lẹ́yìn náà ní ọdún 1990. Abdulkareem Muhammed ṣe àtúnṣe Alhaki Kwikwiyo Ne... sí fíìmù kan. [6]

A ṣe ìtúmọ̀ èdè Gẹ̀ẹ́sì sí ìwé Alhaki Kuykuyo Ne..., Ẹ̀ṣẹ̀ jẹ́ ọmọ aja tí ó ń tẹ̀lé ọ sílé", ní ọdún 2012 láti ọwọ́ awọn Ìtẹ̀jáde Blaft, ilé ìtẹ̀wé Íńdíà kan, pẹ̀lú àwọn àtúnyẹ̀wò rere. [7] [8]

Ẹ̀bùn ìwé kan wà tí wọ́n pè ní orúkọ rẹ̀, èyí ni ebùn Ìwé fún eré Hausa fún eré orí ìtàgé ti Balaraba Ramat Yakubu [9]

Balaraba Ramat bẹ̀rẹ̀ sí í ṣe fíìmù ní ọdún 1990 pẹ̀lú Wata Shari'ar, láìpẹ́ yìí ló kọ ìwé àti ṣe àgbékalẹ̀ Juyin Sarauta, [10] fíìmù kan tó gba àmì-ẹ̀yẹ mẹ́wàá, tó sì gba àtúnyẹ̀wò rere láti ọ̀dọ̀ àwọn ọ̀mọ̀wé àti àwọn ògbógi fíìmù [11]

  • Kabir, Hajara Muhammad,. Northern obinrin idagbasoke. [Nigeria]. ISBN 978-978-906-469-4. OCLC 890820657.

Àwọn ìtọ́kasí

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]
  1. Zeijl, Femke van. "From illiterate child bride to famous Nigerian novelist". www.aljazeera.com (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). Retrieved 2022-05-27.
  2. terrific (2020-02-18). "THE ROLE MODEL SERIES - HOW BALARABA RAMAT YAKUBU, - GEN. MURTALA MUHAMMED’S JUNIOR SISTER PERSEVERED TO EMERGE A SUCCESS AFTER FORCED MARRIAGE AT AGE 13 YEARS". Terrific Headlines (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). Archived from the original on 2020-08-15. Retrieved 2020-05-30. Unknown parameter |url-status= ignored (help)
  3. Malumfashi, Sada (2019-12-13). "A History of Hausa Feminist Writings". The Republic (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). Retrieved 2020-05-30.
  4. "I write in Hausa ‘cos I didn’t get Western education - Says Murtala Muhammed’s sister". NigeriaFilms.com. Archived from the original on 23 April 2016. Retrieved 11 January 2013. Unknown parameter |url-status= ignored (help)
  5. Graham Furniss. "Hausa popular literature and video film: the rapid rise of cultural production in times of economic decline" (PDF). Archived from the original (PDF) on 16 July 2016. Retrieved 11 January 2013. Unknown parameter |url-status= ignored (help)
  6. Carmen Mccain (22 October 2012). "Hajiya Balaraba Ramat Yakubu’s novel Alhaki Kuykuyo Ne/Sin is a Puppy Published in translation by Blaft". Retrieved 11 January 2013.
  7. Subashini Navaratnam (6 December 2012). "'Sin is a Puppy That Follows You Home', a Popular Hausa Novel, Is a Fast-Paced, Riveting Read". Retrieved 11 January 2013.
  8. Deepa Dharmadhikari. "Book Review: Full Hausa". Retrieved 11 January 2013.
  9. Awaal Gaata. "CATCHING THEM YOUNG: School gives prizes to students in Kano". Archived from the original on 2013-02-15. Retrieved 11 January 2013. Unknown parameter |url-status= ignored (help)
  10. "Juyin Sarauta – Ramat Productions Ltd". ramatproductions.com (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). Retrieved 2018-10-16.[Ìjápọ̀ tí kò ṣiṣẹ́ mọ́]
  11. Juyin Sarauta

    Kíkà síwájú síi

    [àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]
    • "Balaraba Yakubu: Awọn onkọwe abo ti Nigeria". Deutsche Welle. Ti gba pada 12 Oṣu Kini 2018.