Cyril Stober
Cyril Stober
Cyril Stober jẹ́ akọ̀ròyìn Nàìjíríà àti akàròyìn. Wọ́n bí i ní ìpínlẹ̀ Niger. Ó lọ sí ilé ẹ̀kọ́ sẹ́kọ́ńdírí ti Fatima Secondary Secondary tí a mọ̀ sí Father O'Connell Science College, Minna báyìí.
Iṣẹ́
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Ó lé ní ọgbọ́n ọdún tí Stober lò gẹ́gẹ́ bí akọ́sẹ́mọsẹ́ gẹ́gẹ́ bí akàròyìn àti akọ̀ròyìn. Iṣẹ́ rẹ̀ gangan ní láti mójútó ìròyìn ní 9 pm lórí NTA network àti NTA prime time news. Ọ̀nà ìmúra rẹ̀ ni wíwọ aṣọ ìbílẹ̀, fìlà àti awò rẹ̀. Ní ọdún 2015, awuyewuye kan wà pé ó ti fẹ̀yìntì, ó ya àwọn òǹwòran rẹ̀ lẹ́nu bí wọ́n ṣe rí i tí ó ń tukọ̀ ètò padà. Ní ọjọ́ 21 oṣù kẹrin ọdún 2019, Stober fẹ̀yìntì ní Nigerian Broadcasting Authority. Cyril Stober sì tún ń tukọ̀ ètò dáadáa lórí NTA network programming lẹ́yìn ìfẹ̀yìntì rẹ̀ ó dà gẹ́gẹ́ bí akọni Nàìjíríà.
Ìgbé Ayé Àdáni
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Stober fẹ́ Efun Merriman-Johnson, akàròyìn tẹ́lẹ̀ ẹni tí òun náà ṣiṣẹ́ ní Nigerian Television Authority títí di àkókò tí wọ́n fi kọ ara wọn sílẹ̀. Ní ọjọ́ 13 oṣù kìíní ọdún 2019, Stober fẹ́ Elizabeth Banu ní ìlú abínibí rẹ̀ ní Garkida, ìpínlẹ̀ Adamawa, Nigeria. Ó ní ọmọ mẹ́ta (obìnrin méjì àti ọkùnrin kan) láti ibi ìgbéyàwó rẹ̀ pẹ̀lú Efun Merriman-Johnson. Ìyàwó rẹ̀ tuntun náà jẹ́ akàròyìn ní NTA.