Dàpọ̀ Abíọ́dún
Dapo Abiodun | |
|---|---|
| Governor of Ogun State | |
Lọ́wọ́lọ́wọ́ | |
| Ó gun orí àga 29 May 2019 | |
| Deputy | Noimot Salako-Oyedele |
| Asíwájú | Ibikunle Amosun |
| Àwọn àlàyé onítòhún | |
| Ọjọ́ìbí | Adedapo Oluseun Abiodun 29 Oṣù Kàrún 1960 Iperu, Ogun State, Western Region, Colonial Nigeria (now in Ogun State, Nigeria) |
| Ẹgbẹ́ olóṣèlú | All Progressives Congress (APC) |
| (Àwọn) olólùfẹ́ | |
| Occupation |
|
Adédàpọ̀ Olúseun Abíọ́dún MFR CON tí a bí ní ọjọ́ kọkàndínlọ́gbọ̀n oṣù karùn-ún ọdún 1960 jẹ́ oníṣòwò àti olóṣèlú ọmọ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà, tí ó ti ń ṣiṣẹ́ gẹ́gẹ́ bí Gómìnà fún Ìpínlẹ̀ Ogun láti oṣù karùn-ún ọdún 2019. Lọ́wọ́lọ́wọ́, Abíọ́dún jẹ́ ọmọ ẹgbẹ́ òṣèlú All Progressives Congress, ó bẹ̀rẹ̀ òṣèlú nígbàtí Abacha fẹ̀ yípadà sí olóṣèlú ní ọdún 1998, ó sì ń ṣiṣẹ́ nínú òṣèlú títí di ìgbà tí a fi yàn án gẹ́gẹ́ bí gómìnà ní ọdún 2019. [1]
A bí Abíọ́dún ní Ìpẹ́ru, Ìpínlẹ̀ Ògùn ní ọdún 1960, ó sì jẹ́ oníṣirò owó fún ọ̀pọ̀ ọdún kí ó tó bẹ̀rẹ̀ okòwò ní ọdún 1990. Pẹ̀lú iṣẹ́ ìṣòwò, Abíọ́dún wọ inú òṣèlú ìdìbò, ó sì jẹ́ alága ìgbìmọ̀ ti Ilé Iṣẹ́ Àjọ tó ń rísí ìforùkọsílẹ̀ àwọn ilé iṣẹ́ sílẹ̀ ní Nàìjíríà Kí ó tó di olùdarí ìṣàkóso Heyden Petroleum àti olùdásílẹ̀ First Power Limited ní ọdún 2019. [2] Wọ́n yan Abíọ́dún sí ipò àkọ́kọ́ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí gómìnà pẹ̀lú àlà díẹ̀, lẹ́yìn náà wọ́n tún yàn án padà pẹ̀lú àlà díẹ̀ kan náà ní ọdún 2023. [3]
Ìgbésí ayé rẹ̀ ní kékeré
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Abìọ́dún ni bí ní ọjọ́ kọkàndínlọ́gbọ̀n oṣù karùn-ún ọdún 1960 Ìpẹ́ru, Ìpínlẹ̀ Ògùn, sí ilé ọba Ìpẹ́ru. [4] A bi sí ìdílé Dọ́kítà Emmanuel Abíọ́dún àti Ìyáàfin Victoria Abíọ́dún láti Ìpẹ́ru Rẹ́mọ, ní agbègbè Ìlap-oòrùn Ògùn. [4]
Abíọ́dún lọ sí ilé-ẹ̀kọ́ Kristi ní ìlú Adó Èkìtì ní ọdún 1972, ilé-ẹ̀kọ́ oníwèé mẹ́wàá Jósẹ́fù mímọ́ ní ìlú Ondo ní ọdún 1977, lẹ́yìn náà ó lọ sí ilé-ẹ̀kọ́ oníwèé mẹ́wàá ti Òǹdó ní ọdún 1978.
Abíọ́dún kẹ́kọ̀ọ́ nípa ìmọ̀ ẹ̀rọ ìkọ́lé ní Yunifásítì Ife (tí a mọ̀ sí Ọbáfẹ́mi Awólọ́wọ̀ Yunifásitì báyìí), Ilé-Ife, Ìpínlẹ̀ Osun, ó tẹ̀ síwájú pẹ̀lú ẹ̀kọ́ rẹ̀ pẹ̀lú gbígba ìwé Ẹ̀rí BBA nínú ìṣirò owó láti Yunifásítì Ìpínlẹ̀ Kennesaw ní Atlanta, Georgia ní ọdún 1986. [5]
Iṣẹ́ ṣíṣe
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Abíọ́dún bẹ̀rẹ̀ ìrìn àjò iṣẹ́ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí oníṣirò Owó ní Glock Inc. ní USA láti ọdún 1989 sí ọdún 1991. Nígbà tí ó padà sí Nàìjíríà, ó bẹ̀rẹ̀ sí í ṣe iṣẹ́ ajé, ó sì di Alága Crestar Hydrocarbons Limited, OMS-Heyden Exploration and Production Limited, Heyden Petroleum Ltd (HPL), Alarmnet, Innovative Ventures Limited, àti First Power Limited. [5] Láti ọdún 2012 sí 2019, ó jẹ́ Alága ti Depot and Petroleum Product Marketers' Association (DAPPMA).
Ẹ̀ka iṣẹ́ Òde
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Iṣẹ́ òṣèlú Abíọ́dún bẹ̀rẹ̀ ní ọdún 1998 nígbà tí ó díje fún ipò Aṣòfin tí á ṣojú ìlà oòrùn Ògùn lórí ìpele ẹgbẹ́ òṣèlú United Nigeria Congress Party, ṣùgbọ́n ìṣẹ́gun náà kò fìdí múlẹ̀ nítorí ìjọba olómìnira kẹta tí kò lè wáyé.
Lẹ́yìn náà, ó dara pọ̀ mọ́ ẹgbẹ́ òṣèlú Peoples Democratic Party ní ọdún 1999 gẹ́gẹ́ bí ọ̀kan lára àwọn olùdásílẹ̀ níbi tí ó ti díje fún ipò ìpele àkọ́kọ́ fún ipò gómìnà ní ìpínlẹ̀ Ogun ní ọdún 2002 níbi tí ó ti ṣe ipòkejì ẹni tí ó borí nínú ìdìbò abẹ́lé náà, ẹni tí ó sì wá padà jáwé olúborí ní ìdìbò gbogbogbòò.
Ó díje nínú ìdìbò gbogbogbòò ọdún 2015, ó díje làbẹ́ àsìà ẹgbẹ̀ òṣèlú All Progressive Congress (APC) fún Aṣòfin tí á ṣojú ìlà oòrùn Ògùn ṣùgbọ́n kò jáwé olúborí ní ọdún 2018, Ààrẹ Muhammadu Buhari yàn án gẹ́gẹ́ bí Alága ti Ilé-iṣẹ́ Àjọ tó ń rísí ìforúkọsílẹ̀ àwọn ilé iṣẹ́ (CAC)
Ní ọdún 2019, ó díje fún ipò gómìnà nínú ẹgbẹ́ òṣèlú APC ní ìdìbò gbogbogbòò ní ìpínlẹ̀ Ogun, ó sì di Gómìnà karùn-ún ní ìpínlẹ̀ Ògùn. Abíọ́dún borí ní ìjọba ìbílẹ̀ méjìlá nínú ìjọba ìbílẹ̀ ogún tó wà ní ìpínlẹ̀ náà. [6]
Nígbà tí wọ́n dé ipò, ó ṣe àgbékalẹ̀ ètò kíkọ́ Ọjọ́ Ọ̀la Wa, wọ́n sì gbé e ka orí àwọn òpó ìdàgbàsókè márùn-ún tí orúkọ wọn ń jẹ́ ISEYA (Ilé-iṣẹ́, Ìlera Àwùjọ àti Ìrànlọ́wọ́, Ẹ̀kọ́, Ìfún Àwọn Ọ̀dọ́ ní agbára àti ìpèsè iṣẹ́ àti Iṣẹ́ Àgbẹ̀).
Ní ọdún 2023, Abíọ́dún tú àwọn ẹlẹ́wọ̀n mẹ́rìndínlọ́gọ́ta sílẹ̀ tí wọ́n ti lo ju ogún ọdún lọ nínú ẹ̀wọ̀n tí wọ́n ti lò. Àwọn kan lára àwọn ẹlẹ́wọ̀n náà jẹ́ àgbàlagbà tàbí wọ́n ní ìṣòro pẹ̀lú ìlera wọn. Ó tún yí ìdájọ́ ikú fún àwọn ẹlẹ́wọ̀n mẹ́ta padà sí ẹ̀wọ̀n igbére. [7]
Ní ọjọ́ kẹjọ oṣù kẹta ọdún 2023, wọ́n tún yàn án gẹ́gẹ́ bí gomina lábẹ́ ẹgbẹ́ òṣèlú All Progressives Congress (APC) nínú ìdìbò gómìnà ti ìpínlẹ̀ Ogun ní ọdún 2023, ó sì borí Ládi Adébutú ti ẹgbẹ́ òṣèlú People's Democratic Party (PDP) àti Biyi Ọ̀tẹ́gbẹ̀yẹ ti ẹgbẹ́ òṣèlú African Democratic Congress (ADC) .
Àwọn àríyànjiyàn
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Ṣáájú ìdìbò gómìnà ọdún 2019, ìròyìn láti TheCable ṣàlàyé bí wọ́n ṣe fi ẹ̀sùn arúmọjẹ kan àwọn ìwé ẹ̀rí Abíọ́dún nípa ṣíṣàkíyèsí àwọn ìyàtọ̀ tó wà láàárín àwọn ìwé ẹ̀rí tí Abíọ́dún lò láti díje fún ipò Aṣòfin rẹ̀ ní ọdún 2015, àwọn ìwé ẹ̀rí tí ó lò láti díje fún ipò gómìnà, àti ojú òpó ayèlujára ilé-iṣẹ́ rẹ̀. [8] Àwọn ìyàtọ̀ náà fi ìbéèrè sí bóyá Abíọ́dún lẹ́tọ̀ọ́ láti díje tàbí kò lẹ́tọ̀ọ́, nítorí pé àríyànjiyàn nípa bóyá Abíọ́dún ṣe ìsìnrù ìlú tàbí àgùnbánirọ̀ ọlọ́dúnkan (National Youth Service Corps) ti ìjọba àpapọ̀ ṣe ní pàtàkì fún gbogbo àwọn tó kẹ́kọ̀ọ́ jáde ní ilé ẹ̀kọ́ gíga èyí sì ṣe ìpèníjà fún ìdíje rẹ̀. Nínú ìdáhùn rẹ̀, Abíọ́dún sọ pé òun kò tíì sọ pé òun parí ìwé ẹ̀rí òun ní Yunifásítì Ọbáfẹ́mi Awólówọ̀, ó sì ṣàlàyé wípé àríyànjiyàn àti awuyewuye náà jẹ́ gẹ́gẹ́ bí “ìdààmú òṣèlú.” Síbẹ̀síbẹ̀, àwọn ìpèníjà sí ìdíje Abíọ́dún tẹ̀síwájú lẹ́yìn ìdìbò náà pẹ̀lú àwọn ìgbìyànjú láti tako òótọ́ àwọn ìwé ẹ̀rí Abíọ́dún. Nínú ìdájọ́ wọn tí ó fìdí ìṣẹ́gun Abíọ́dún múlẹ̀, ilé ẹjọ́ sọ pé àwọn ẹ̀bẹ̀ náà kùnà láti fihàn pé Abíọ́dún ti ṣe jìbìtì pẹ̀lú àwọn ìwé ẹ̀rí rẹ̀.
Nítorí ìtújáde Pandora Papers, Premium Times ròyìn nípa ipa Abíọ́dún nínú àwọn ilé-iṣẹ́ méjì tí wọ́n mọ̀ sí British Virgin Islands ní etíkun tí wọ́n sì ń rí owó orí gbà. Ìròyìn náà sọ pé Abíọ́dún ni olùdarí àti ẹni tó ni Marlowes Trading Corporation àti Heyden Petroleum Limited, èyí sì hàn gbangba pé ó rú òfin àjọ tó ń rísí ìwà ọmọlúàbí (Code of Conduct Bureau) àti òfin ètò ìdìbò (Tribunal Act) nítorí pé kò sí ilé-iṣẹ́ méjì tí wọ́n kéde nígbà tí wọ́n yan Abíọ́dún gẹ́gẹ́ bí gómìnà. Abíọ́dún fúnra rẹ̀ yẹra fún ìbéèrè lórí kókó ọ̀rọ̀ náà, ṣùgbọ́n alábàáṣiṣẹpọ̀ Abíọ́dún sọ pé gómìnà náà ti fẹ́ tú àwọn ilé-iṣẹ́ náà ká, ṣùgbọ́n kò kíyèsí pé wọn kò tíì tú wọn ká.
Ní ọdún 2022, Sahara Reporters tẹ àkọsílẹ̀ ìwà ọ̀daràn ti bí wọ́n ṣe mú Abíọ́dún ní ọdún 1986 fún jìbìtì káàdì ìsanwó, fífẹ́wọ́, àti yíyí ìwé sọ̀wédowó ní àfikún sí pípa ọlọ́pàá kan lára nígbà tí wọ́n gbìyànjú mu ní Miami-Dade County ní Orílẹ̀-èdè Amẹ́ríkà lábẹ́ orúkọ àpèlé náà “Shawn Michael Davids.” [9] [10] Bó tilẹ̀ jẹ́ pé wọ́n ti tú àṣírí mímú náà síta tẹ́lẹ̀ — pẹ̀lú ìpèníjà sí ìdíje Abiodun ní ọdún 2019 — síbẹ̀síbẹ̀, wọn kò tíì tú àwọn ìwé náà jáde ní gbangba. Àwọn ọ̀rẹ́ Abiodun àti àwọn agbẹjọ́rò rẹ̀ sọ pé mímú náà kò ní ipa lórí àǹfààní rẹ̀ láti díje fún ipò.
Àwọn ẹ̀bùn
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Abíọ́dún ti gba ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn àmia-ẹẹ̀yẹ gẹ́gẹ́ bíi gómìnà, díẹ̀ nínú wọn ni:
- Gómìnà Ìpínlẹ̀ tó dára jù lọ ní ọdún 2021 pẹ̀lú Ìpínlẹ̀ tó dára jù nínú ètò ààbò láti ọwọ́ Ìwé Ìròyìn Ọjọ́ Ìṣòwò
- Gómìnà tó dára jù lọ nínú iṣẹ́-ọ̀gbìn ti ọdún 2020 nípasẹ̀ Àwọn àmì-ẹ̀rí iṣẹ́-ọ̀gbìn ti Nàìjíríà (NAA)
- Gómìnà tó dára jù lọ nínú ètò amáyédẹ̀rùn ní Gúúsù Ìwọ̀ oòrùn ní ọdún 2022 nípasẹ̀ ẹgbẹ́ àwọn oníròyìn Nàìjíríà (NUJ) agbègbè B
- Ẹ̀bùn Forbes ti ọdún 2022 gẹ́gẹ́ bí Gómìnà tó dáa jùlọ ní Áfíríkà nínú Ìyípadà àwọn Ilé Iṣẹ́
- Ẹ̀bùn Gómìnà tó dára jùlọ ní ọdún 2023 ní fífúnni ní ilé láti ọwọ́ọ tó ń rísí ọ̀rọ̀ ilé ní Nàìjíríà
Ìgbésí ayé rẹ̀
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Abíọ́dún fẹ́ olólùfẹ́ ìgbà èwe rẹ̀, Bámidélé, wọ́n sì bí ọmọ márùn-ún.
Ní ọdún 2017, wọ́n rí ọmọ wọn, Gbémiga Abíọ́dún (tí a tún mọ̀ sí DJ Olu) tí ó jẹ́ ọmọ ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n tó ti kú sínú ọkọ̀ ayọ́kẹ́lẹ́ rẹ̀ pẹ̀lú ọ̀rẹ́ rẹ̀ kan. A kò mọ ohun tó fa ikú rẹ̀. [11]
Ní oṣù kẹwàá ọdún 2023, Abíọ́dún gbé ètò ẹ̀kọ́ ọ̀fẹ́ kalẹ̀ fún àwọn akẹ́kọ̀ọ́ ẹgbẹ̀ta dín láàádọ́ta ní ìrántí ọmọ rẹ̀. [12]
Wíwò síwájú si
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Àwọn ìtọ́kasí
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]- ↑ "The new governors-elect in Southwest". 12 March 2019. https://thenationonlineng.net/the-new-governors-elect-in-southwest/.
- ↑ Empty citation (help)
- ↑ Empty citation (help)
- 1 2 Patrick, Okohue (22 May 2019). "Dapo Abiodun set to end divisive, sectional governance in Ogun". Lagos. https://dailytimes.ng/2019/05/22/dapo-abiodun-set-to-end-divisive-sectional-governance-in-ogun/.
- 1 2 Empty citation (help)
- ↑ Empty citation (help)
- ↑ Empty citation (help)
- ↑ Empty citation (help)
- ↑ . New York. Missing or empty
|title=(help); - ↑ Empty citation (help)
- ↑ Empty citation (help)
- ↑ Empty citation (help)