Damilola Adebonojo

Dámilọ́lá Adébọ̀nọ̀jọ̀ tí ọ̀pọ̀ ènìyàn mọ̀ sí ìyá Yorùbá jẹ́ olùkọ́ èdè Yorùbá ní University of Georgia. Damilola jẹ́ ọmọ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà, tó farajìn fún ìpolongo èdè Yorùbá, tó sì ń ṣiṣẹ́ ribiribi láti ṣe ìgbélárugẹ èdè náà ní ayé òde-òní, nípa kíkọ́ àwọn ọmọdé àti àgbàlagbà ní èdè Yorùbá. [1] Òun ni olùdásílẹ̀ ilé-iṣẹ́ Alámọ̀jà, tó ń rí sí kíkọ́ àwọn ọmọdé ní èdè Yorùbá àti ìpèsè iṣẹ́ ògbufọ̀ fún àwọn fíìmù àgbéléwò Yorùbá.[2]
Ètò ẹ̀kọ́ rẹ̀
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Dámilọ́lá gboyè ẹ̀kọ́ B.A nínú ìmọ̀ Yorùbá and Communication Arts, láti Lagos State University, ní ọdún 2016. Ó tẹ̀ síwájú láti gboyè M.A nínú ìmọ̀ Yorùbá Literature and Culture, láti Lagos State University bákan náà, ní ọdún 2021. Lọ́lọ́lọ́wọ́, ó ń kẹ́kọ̀ọ́ láti gboyè Ph.D nínú ìmọ̀ Comparative Literature and Intercultural Studies, ní University of Georgia.[3]
Iṣẹ́ tó yàn láàyò
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Dámilọ́lá jẹ́ olùkọ́ èdè Yorùbá. Láti ọdún 2016 ni ó ti ń ṣiṣẹ́ kíkọ́ èdè Yorùbá gẹ́g bí èdè àkọ́kúntẹni, tó sì ti ṣiṣẹ́ pẹ̀lú ọ̀pọ̀lọpọ̀ akẹ́kọ̀ọ́ káàkiri àgbáyé. Òun ni olùdásílẹ̀ Alámọ̀já, èyí tó jẹ́ ilé-iṣẹ́ tó ń ṣe ìpèsè àwọn ohun tó jẹ mọ́ èdè Yorùbá, bí i iṣẹ́ ògbufọ̀ fún àwọn fíìmù àgbéléwò Yorùbá, bẹ́ẹ̀ sì ni ó ti ṣètò MENYO-20k, èyí tó jẹ́ ẹ̀rọ maṣíìnì tí ń tú èdè Yorùbá sí èdè Gẹ́ẹ̀sì, àti èdè Gẹ̀ẹ́sì sí èdẹ̀ Yorùbá.[4] Ní ọdún 2017, ó gba ètò Fulbright Scholarship Program, láti máa lọ kọ́ èdè Yorùbá ní òkè-òkun.[5] Lọ́lọ́lọ́wọ́ báyìí, ó jẹ́ olùkọ́ èdè Yorùbá ní University of Georgia.
Àwọn àmì-ẹ̀yẹ rẹ̀
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Ní oṣù Kẹjọ ọdún 2021, Damilola gba àmì-ẹ̀yẹ Fulbright Foreign Language Teaching Assistant Ní ọjọ́ kẹtàlá oṣù kẹrin ọdún 2024, African Language Teacher's Association fún un ní àmì-ẹ̀yẹ,[6] bẹ́ẹ̀ sì ni UGA's Office of Instruction fi àmì-ẹ̀yẹ dá a lọ́lá fún iṣẹ́ takuntakun rẹ̀ lórí ètò ẹ̀kọ́ èdè Yorùbá ní ọjọ́ kẹta oṣù Kẹrin ọdún 2024.[7]
Àwọn ìtọ́kasí
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]- ↑ "Meet Dámilọ́lá Adébọ́nọ̀jọ, Yorùbá language activist". Rising Voices. 2019-05-07. Retrieved 2025-05-10.
- ↑ "Yorùbá Reading School". Alamoja Yoruba Online School. 2021-04-14. Retrieved 2025-05-10.
- ↑ "Damilola Adebonojo". Google Scholar. Retrieved 2025-05-10.
- ↑ Telegraph, New (2025-05-03). "Alamoja Yoruba Revolutionises Yoruba Language Education With Innovative Edtech Solutions". New Telegraph. Retrieved 2025-05-10.
- ↑ Osagie, Evelyn (2025-04-16). "‘Women are cultural custodians, unstoppable forces’". The Nation Newspaper. Retrieved 2025-05-10.
- ↑ Uba, Josfyn (2025-05-06). "Yoruba women, living archives of cultural heritage…". The Sun Nigeria. Retrieved 2025-05-10.
- ↑ "Damilola Adebonojo". Comparative Literature. Retrieved 2025-05-10.