Jump to content

Damilola Adebonojo

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́
Àwòrán Dámilọ́lá Adébọ̀nọ̀jọ̀

Dámilọ́lá Adébọ̀nọ̀jọ̀ tí ọ̀pọ̀ ènìyàn mọ̀ sí ìyá Yorùbá jẹ́ olùkọ́ èdè Yorùbá ní University of Georgia. Damilola jẹ́ ọmọ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà, tó farajìn fún ìpolongo èdè Yorùbá, tó sì ń ṣiṣẹ́ ribiribi láti ṣe ìgbélárugẹ èdè náà ní ayé òde-òní, nípa kíkọ́ àwọn ọmọdé àti àgbàlagbà ní èdè Yorùbá. [1] Òun ni olùdásílẹ̀ ilé-iṣẹ́ Alámọ̀jà, tó ń rí sí kíkọ́ àwọn ọmọdé ní èdè Yorùbá àti ìpèsè iṣẹ́ ògbufọ̀ fún àwọn fíìmù àgbéléwò Yorùbá.[2]

Ètò ẹ̀kọ́ rẹ̀

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Dámilọ́lá gboyè ẹ̀kọ́ B.A nínú ìmọ̀ Yorùbá and Communication Arts, láti Lagos State University, ní ọdún 2016. Ó tẹ̀ síwájú láti gboyè M.A nínú ìmọ̀ Yorùbá Literature and Culture, láti Lagos State University bákan náà, ní ọdún 2021. Lọ́lọ́lọ́wọ́, ó ń kẹ́kọ̀ọ́ láti gboyè Ph.D nínú ìmọ̀ Comparative Literature and Intercultural Studies, ní University of Georgia.[3]

Iṣẹ́ tó yàn láàyò

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Dámilọ́lá jẹ́ olùkọ́ èdè Yorùbá. Láti ọdún 2016 ni ó ti ń ṣiṣẹ́ kíkọ́ èdè Yorùbá gẹ́g bí èdè àkọ́kúntẹni, tó sì ti ṣiṣẹ́ pẹ̀lú ọ̀pọ̀lọpọ̀ akẹ́kọ̀ọ́ káàkiri àgbáyé. Òun ni olùdásílẹ̀ Alámọ̀já, èyí tó jẹ́ ilé-iṣẹ́ tó ń ṣe ìpèsè àwọn ohun tó jẹ mọ́ èdè Yorùbá, bí i iṣẹ́ ògbufọ̀ fún àwọn fíìmù àgbéléwò Yorùbá, bẹ́ẹ̀ sì ni ó ti ṣètò MENYO-20k, èyí tó jẹ́ ẹ̀rọ maṣíìnì tí ń tú èdè Yorùbá sí èdè Gẹ́ẹ̀sì, àti èdè Gẹ̀ẹ́sì sí èdẹ̀ Yorùbá.[4] Ní ọdún 2017, ó gba ètò Fulbright Scholarship Program, láti máa lọ kọ́ èdè Yorùbá ní òkè-òkun.[5] Lọ́lọ́lọ́wọ́ báyìí, ó jẹ́ olùkọ́ èdè Yorùbá ní University of Georgia.

Àwọn àmì-ẹ̀yẹ rẹ̀

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Ní oṣù Kẹjọ ọdún 2021, Damilola gba àmì-ẹ̀yẹ Fulbright Foreign Language Teaching Assistant Ní ọjọ́ kẹtàlá oṣù kẹrin ọdún 2024, African Language Teacher's Association fún un ní àmì-ẹ̀yẹ,[6] bẹ́ẹ̀ sì ni UGA's Office of Instruction fi àmì-ẹ̀yẹ dá a lọ́lá fún iṣẹ́ takuntakun rẹ̀ lórí ètò ẹ̀kọ́ èdè Yorùbá ní ọjọ́ kẹta oṣù Kẹrin ọdún 2024.[7]

Àwọn ìtọ́kasí

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]
  1. "Meet Dámilọ́lá Adébọ́nọ̀jọ, Yorùbá language activist". Rising Voices. 2019-05-07. Retrieved 2025-05-10.
  2. "Yorùbá Reading School". Alamoja Yoruba Online School. 2021-04-14. Retrieved 2025-05-10.
  3. "Damilola Adebonojo". ‪Google Scholar‬. Retrieved 2025-05-10.
  4. Telegraph, New (2025-05-03). "Alamoja Yoruba Revolutionises Yoruba Language Education With Innovative Edtech Solutions". New Telegraph. Retrieved 2025-05-10.
  5. Osagie, Evelyn (2025-04-16). "‘Women are cultural custodians, unstoppable forces’". The Nation Newspaper. Retrieved 2025-05-10.
  6. Uba, Josfyn (2025-05-06). "Yoruba women, living archives of cultural heritage…". The Sun Nigeria. Retrieved 2025-05-10.
  7. "Damilola Adebonojo". Comparative Literature. Retrieved 2025-05-10.