Donald Ojogo
Donald Kimikanboh Ojogo | |
|---|---|
| Member of the House of Representatives | |
Lọ́wọ́lọ́wọ́ | |
| Ó gun orí àga 2023 | |
| Asíwájú | Kolade Victor Akinjo |
| Constituency | Ilaje/Ese-Odo |
| Àwọn àlàyé onítòhún | |
| Ọjọ́ìbí | 25 Oṣù Kẹ̀wá 1968 Arogbo, Ese-Odo, Ondo State, Nigeria |
| Ọmọorílẹ̀-èdè | Nigerian |
| Alma mater | University of Lagos |
| Occupation |
|
Donald Kimikanboh Ojogo (a bí i ní ọjọ́ karùndínlọ́gbọ̀n oṣù kẹwà á ọdún 1968) jẹ́ olóṣèlú Nàìjíríà fún àwọn All Progressives Congress tí ó ṣiṣẹ́ gẹ́gẹ́ bí ọmọ Nigerian House of Representatives tí ń ṣe aṣojú Ilaje/Ese-Odo àpapọ̀ ẹgbẹ́.[1][2]
Ìgbé ayé àti ẹ̀kọ́
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]A bí Ojogo ní ìlú rẹ̀ ní Arogbo, Ondo State. Ó bẹ̀rẹ̀ ìrìnàjò sí ilé ẹ̀kọ́ girama rẹ ní Local Authority Primary School, Arogbo, ní ibi tí ó ti parí ilé ìwé alákọ̀ọ́bẹ̀rẹ̀ láti ọdún 1974 sí 1980. Ó tèsíwájú sí Ijaw National High School, Arogbo, fún ẹ̀kọ́ sẹ́kọ́ndárì láti ọdún 1980 sí 1985. Ní 1986, wón gbàa á sí Federal School of Arts and Science, Ondo, sùgbón kò pari ní torí àì ní owó láti tèsíwájú. Ní ọdún 1990 ó Gba ìwé ìwọlé sí University of Lagos, ní ibi tí ó ti gba ìwé ẹ̀rí ti bachelor's degree ní ẹ̀kọ́ ìsàkọsílẹ̀ ìtàn àti i master's degree ní ẹ̀kọ́ ìsàkọsílẹ̀ ìtàn àti in àwọn ìlànà ìwádàíí.[3]
Iṣẹ́
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Ìrìn àjò ọ̀jọ̀gbọ́n Ojogo bẹ̀rẹ̀ ní 1988 nígbà tí ó bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ ní ìgbìmọ̀ ìjọba Ilaje/Ese-Odo gẹ́gẹ́ bí aláṣẹ. Lẹ́yìn tí Ojogo jáde ní Yunifásítì ti Èkó lọ́dún 1995, ó bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ akọròyìn. Ó ṣiṣẹ́ gẹ́gẹ́bí Energy Reporter ní Ìwé ìròyìn Guardian Guardian Newspaper[4] ní èkó láti ọdún 1996 sí ọdún 1998 kí ó tó darapọ̀ mọ́ Ìwé Ìròyìn Comet Comet Newspaper gẹ́gẹ́ bí oníròyìn ìlú Ondo.[3]
Iṣẹ́ rẹ̀ nínú iṣẹ́ ìròyìn ríi pé ó di àwọn ipò tí ojúṣe tí ń pọ̀ síi, pẹ̀lú Akọròyìn Òṣèlú àti Oníròyìn Òṣèlú àgbà ní Ìwé Ìròyìn Independent Daily èkó Daily Independent Newspaper, Ní ọdún 2007, Ojogo ni wọ́n pe láti ṣiṣẹ́ gẹ́gẹ́bí Akòwé Ìròyìn fún Gómìnà Olusegun Kokumo Agagu Olusegun Kokumo Agagu ti Ìpínlẹ̀ Ondo. Lẹyìn náà ó padà sí Nigerian Tribune Nigerian Tribune láti darapọ̀ mọ́ Daily Independent ní Abuja gẹ́gẹ́bí Olóòtú Ìṣèlú ní Leadership Newspapers Group[1][4] Ó tún ṣiṣẹ́ bí Olóòtú Ìṣèlú Ẹgbẹ́ ní Ẹgbẹ́ Àwọn ìwé ìròyìn Asíwájú àti olóòtu ní New Telegraph Newspaper.[4]
Ìṣèlú
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Ìfarabalẹ̀ Ojogo fún iṣẹ́ ìjọba ni ó mú kí ó padà sí Ìpínlè Ondo, níbití ó ti ṣiṣẹ́ gẹ́gẹ́bí igbákejì Olórí àwon òṣìṣẹ́ sí ọ́físì igbákejì Gómìnà nígbà náà Oloye Agboola Ajayi[1] àti lẹyìn náà, ṣiṣẹ́ gẹ́gẹ́bí Komísánà físánà n ilé & Housing ni 2017; Komisona fún Àlàyé àti ìṣàlàyé ní Ìpínlè Ondo.Ní ọdún 2019, ó díje nínu ìdìbò Ilé-ìgbìmọ̀ Aṣòfin gẹ́gẹ́ bí olùdíje tí Gbogbo Progressive Congress (APC) ṣùgbọ́n kò yọrísí rere. Ó tún díje lórí ipò ẹgbẹ́ APC ó sì borí lọ́dún 2023[5]
Àwọn ìtọ́kasí
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]- 1 2 Tope, Fayehun (March 27, 2023). "Ex-LEADERSHIP Staff, Ojogo, Wins Ondo Reps Seat". Leadership. https://leadership.ng/ex-leadership-staff-ojogo-wins-ondo-reps-seat/.
- ↑ "Decision 2023: Fmr Ondo information commissioner, Ojogo wins House of Reps seat". Channels TV. February 27, 2023. https://www.tvcnews.tv/2023/02/decision-2023-fmr-ondo-information-commissioner-ojogo-wins-house-of-reps-seat/.[Ìjápọ̀ tí kò ṣiṣẹ́ mọ́]
- 1 2 "Donald K. Ojogo @ A Glance". May 8, 2022. Archived from the original on May 26, 2024. Retrieved May 26, 2024.
- 1 2 3 Odunsi, Wale (April 3, 2017). "Ondo Governor, Akeredolu makes new appointments". Daily Post. https://dailypost.ng/2017/04/03/ondo-governor-akeredolu-makes-new-appointments/.
- ↑ Dayo Johnson Akure (May 28, 2022). "2023: Ondo Former Information Commissioner, Ojogo clinches Rep ticket in Ondo". Vanguard. https://www.vanguardngr.com/2022/05/2023-ondo-former-information-commissioner-ojogo-clinches-rep-ticket-in-ondo/.