Jump to content

Edward Lametek Adamu

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́
Edward Lametek Adamu
Deputy Governor of the Central Bank of Nigeria
In office
1 February 2018  13 September 2023
AsíwájúSuleiman Barau
Àwọn àlàyé onítòhún
Ọjọ́ìbí22 Oṣù Kẹfà 1959 (1959-06-22) (ọmọ ọdún 66)
Kaltungo, Gombe State, Nigeria
AráàlúNigeria
Ọmọorílẹ̀-èdèNigerian
Àwọn ọmọ4
Alma materAhmadu Bello University
Nigerian Institute of Quantity Surveyors
Institute of Credit Administration of Nigeria
Wharton Business School
INSEAD
Booth School of Business
IMD Switzerland
OccupationCentral Banker

Edward Lametek Adamu (tí a bí ní ọjọ́ kejìlélógún oṣù kẹfà ọdún 1959) jẹ́ onímọ̀ nípa iye owó ní Nàìjíríà, olùdámọ̀ràn ìṣòwò, àti onímọ̀ nípa ètò ìṣàkóso tó ṣiṣẹ́ gẹ́gẹ́ bí Igbákejì Gómìnà ti Bánkì àpapọ̀ Nàìjíríà(Central Bank of Nigeria) . Ààrẹ Muhammadu Buhari ló yàn án sí ipò náà ní ọjọ́ kìíní oṣù kejì ọdún 2018, láti rọ́pò Suleiman Barau, tó fẹ̀yìntì ní oṣù Kejìlá ọdún 2017. [1] Àwọn aṣòfin àpapọ̀ ti Nàìjíríà fọwọ́ sí i ní ọjọ́ kejìlélógún oṣù kẹta ọdún 2018. [2]

Lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀ kí wọ́n tó yàn án gẹ́gẹ́ bí Igbákejì Gómìnà náà, ó ti ṣiṣẹ́ gẹ́gẹ́ bí Olùdarí Àwọn Ohun Èlò Ènìyàn ní Bánkì àpapọ̀ orílè-èdè Nàìjíríà (Central Bank of Nigeria), láti ọdún 2016.[1] Adamu tún ti ṣiṣẹ́ gẹ́gẹ́ bí Alága ti Asset Management Company of Nigeria (AMCON). [3]

Ó jẹ́ igbákejì gómìnà lábẹ́ gómìnà tẹ́lẹ̀ Godwin Emefiele títí di ìgbà tí wọ́n dá a dúró. Ní ọjọ́ kẹẹ̀ẹ́dógún oṣù kẹsàn-án ọdún 2023, àwọn ìròyìn pàtàkì kan ní Nàìjíríà sọ pé gbogbo àwọn igbákejì gómìnà CBN ni wọ́n yọ kúrò ní ipò pẹ̀lú olórí wọn, Godwin Emefiele láti ọwọ́ Ààrẹ Bola Ahmed Tinubu.[4] [5][6]

Ìbẹ̀rẹ̀Ìgbésí ayé àti ẹ̀kọ́

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

A bí Adamu ní ọjọ́ kejìlélógún oṣù kẹfà ọdún 1959 ní Kaltungo, ìpínlẹ̀ Gombe, ní apá àríwá ìlà-oòrùn Nàìjíríà . Ó kẹ́kọ̀ọ́ ní Yunifásítì Ahmadu Bello, ní Zaria, ó sì parí ẹ̀kọ́ Bachelor of Science nínú Quantity Surveying . Ó tún ní ìwé ẹ̀rí iṣẹ́ ajé láti ilé-ẹ̀kọ́ gíga mìíràn, gẹ́gẹ́ bí Institute of Credit Administration of Nigeria, Wharton School, INSEAD, Booth School of Business àti IMD Switzerland . Ó tún jẹ́ ọ̀kan lára àwọn ọmọ ẹgbẹ́ Nigerian Institute of Quantity Surveyors . [7]

Wọ́n kọ́kọ́ gba Adamu síṣẹ́ ní Bánkì àpapọ̀ orílè-èdè Nàìjíríà (Central Bank of Nigeria CBN), ní ọdún 1992. Ní ọdún 2012, wọ́n yàn án gẹ́gẹ́ bí Olùdarí Ẹ̀ka Ìṣàkóso Ìlànà ní banki àpapọ̀. [7] [8] Láàárín àwọn ọdún tó kọjá, ó ṣiṣẹ́ ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ ipò àti ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹ̀ka ní CBN, gẹ́gẹ́ bí Ìṣàkóso Ìmọ̀, Ìṣàkóso Àkọsílẹ̀, Ìbáṣepọ̀ Strategic àti àgbọ́yé owó ọjà. Ó tún ṣiṣẹ́ gẹ́gẹ́ bí olórí Ẹ̀ka Ìṣètò àti Ìmúlò Àwọn Iṣẹ́ Àkànṣe.[7]

Ní ọdún 2016, wọ́n yan Adamu gẹ́gẹ́ bí Olùdarí Àjọ Àwọn Ènìyàn ní CBN, ipò tí ó dìmú kí wọ́n tó yàn án gẹ́gẹ́ bí Igbákejì Gómìnà CBN. [7][8]

Ní ọjọ́ kẹsàn-án oṣù Kejìlá, ọdún 2019, Ààrẹ Muhammadu Buhari yan Adamu gẹ́gẹ́ bí Alága Ilé- iṣẹ́ Ìṣàkóso Àdáni ti Nàìjíríà (AMCON), ipò tí ó gbà lọ́wọ́ Muiz Banire .[3]

Ní ọjọ́ kẹtàlá oṣù kẹsàn-án ọdún 2023, Ààrẹ Bola Tinubu fòpin sí yíyàn Adamu pẹ̀lú àwọn olùdarí CBN lẹ́yìn yíyàn ẹgbẹ́ olùdarí tuntun pátápátá fún Báńkì náà. [9] [10]

Ìgbésí ayé ara ẹni

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Adamu ti ṣe ìgbéyàwó, ó sì ní ọmọ mẹ́rin (ọmọkùnrin méjì àti ọmọbìnrin méjì). [7]

Àwọn ìtọ́kasí

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Àwọn ìjápọ̀ òde

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]