Jump to content

Elegua

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́

 

Elegua ( Yorùbá : Èṣù-Ẹlẹ́gbára àti Ẹlẹ́gbá, Ẹlẹ́gbára ni ilu North America, ni Cuba, wọ́n m má npe ni Eleggua ; tabi Eleguá ni Latin America àti ní àwọn agbègbè Caribbean Islands nibi ti won nti sọ Spanish ) ó jẹ́ Orisha, ìkòríta nínú esin Ifa-Orisha, àwọn Santería, Winti, Umbanda, àti Quimblé . [1] [2]

Elegua, tí a tuń mon gẹ́gẹ́bi Èṣù-Ẹlẹ́gbára àti Ẹlẹ́gbá nínú ẹ̀sìn Yọrùbá. A tún mọ̀ ń sì Eṣu . Ẹlẹ́gbára túmọ̀ sí “olórí agbára” ní èdè Yorùbá . [1] [2]

Ní Àríwá Amẹ́ríkà, Elegbara (tí a tún ń pè ní Elegba) jẹ́ Orisa tí ó wá láti inú ẹ̀sìn Yorùbá ti Ìwọ̀ Oòrùn Áfíríkà, tí a mọ̀ sí òrìsà oríta, ìránṣẹ́ Eledua, àti ẹni tí ó lágbára, tí ó sì tún ní ìwà àrékérekè. [3] Ọ̀rọ̀ náà túmọ̀ sí "ẹni tí ó ní okun, àti agbára . [1] Elegbara je ìsopọ̀ pàtàkì láàrín ènìyàn àti àwọn Orisas (àwọn òrìṣà) àti Olodumare. Gbogbo àwọn ìrúbọ àti àdúrà gbọ́dọ̀ gba àṣẹ àti ìfọwọ́sí lọdọ rẹ, aisebe àdúrà àti ẹbọ kò ní fin. Òun ni "olùní ọ̀nà" àti ìlẹ̀kùn nínú ìgbésí ayé, leyi tí ó ń ṣàpẹẹrẹ àyànmọ́, ìgbéga, àti àwọn àkúnlèyàn ènìyàn. Ó lè ṣí tàbí ti ọ̀nà sí ọrọ̀, ó sì ní ìbáṣepọ̀ pẹ̀lú àwọn ibi tí ìgbésí ayé ẹnìyan lè yípadà kíákíá, bí ọjà àti oríta. Nígbà tí a sábà máa ń ṣàpèjúwe rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí òrìṣà oníwà ìkà àti oníwà méjì, ó fi ìṣọ̀kan ìgbésí ayé hàn, ó ń mú àwọn ìpèníjà àti àǹfààní wá. [3] Ó ń ṣiṣẹ́ gẹ́gẹ́ bí "ọlọ́pàá," ó ń fi òfin àwùjọ àti ìsìn múlẹ̀, ó sì ń mú àwọn tí ń gbé ní ìlòdì sí iwá rere. Nínú àṣà Àríwá Amẹ́ríkà àti Caribbean, níbi tí wọ́n ti máa ń da àwọn àṣà Áfíríkà pọ̀ mọ́ ẹ̀sìn Kristẹni nítorí Òwò Ẹrú Trans-Atlantic, wọ́n máa ń so Elegbara pọ̀ mọ́ àwọn ènìyàn mímọ́ Kátólíìkì láti pa ìjọsìn àwọn baba ńlá wa mọ́n. Wọ́n sábà máa ń dá a mọ̀ pẹ̀lú Ọmọ Mímọ́ ti Atocha, Saint Anthony ti Padua, tàbí Ańgẹ́lì Máíkẹ́lì. [3]

A mọ̀ Eleguá (tí a tún mọ̀ sí Legba) ní Orílẹ̀-èdè Dominican Republic, Haiti, Colombia, Cuba, Puerto Rico, àti Mexico gẹ́gẹ́ bí orisha àti “onílé” àti ẹni tí ọní ipa caminos. A

Ìtàn kan wà ní Santería níbi tí Olodumare ti fún Eleguá ní kọ́kọ́rọ́ sí ìgbà àtijọ́, ìsinsìnyí, àti ọjọ́ iwájú; nítorí èyí, a sábà máa ń ṣe àpèjúwe Eleguá tí ó ní kọ́kọ́rọ́ kan. A lè gbé àwòrán Eleguá sí ilé lẹ́yìn ẹnu ọ̀nà. A sábà máa ń fi símẹ́ǹtì àti ìkarawun Òwò eyo ṣe àwọn àwòrán wọ̀nyí, nígbà míìrán a máa ń wà nínú àwo amọ̀. [2]

Ninu esin Afro-Brazil Elegbara ni Exu . [2]

  • Bàbá Lẹ́gba

Àwọn ìtọ́kasí

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]
  1. 1 2 3 Adeoye, C.L. (1989) (in Yoruba). Ìgbàgbọ́ àti ẹ̀sìn Yorùba. Ibadan: Evans Bros. Nigeria Publishers. p. 123. ISBN 9781675098.
  2. 1 2 3 4 Lopes, Nei (2004). Enciclopédia brasileira da diáspora africana. São Paulo, SP: Selo Negro Edições. p. 252. ISBN 9788587478214.
  3. 1 2 3 Falola, Toyin (2013). Èṣù Yoruba God, Power, And The Imaginative Frontiers. Carolina Academic Press. pp. 16–54. ISBN 9781611632224.

Àwọn ìtọ́kasí Ìta

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]