Elizabeth Abimbola Awoliyi
| Chief Elizabeth Abimbola Awoliyi MBE, OFR | |
|---|---|
| Fáìlì:Elizabeth Abimbola Awoliyi.png Awoliyi in the 1940s-50s | |
| Ọjọ́ìbí | Elizabeth Abimbola Akerele 1910 Lagos, Nigeria |
| Aláìsí | 14 September 1971 (ọmọ ọdún 60–61) |
| Orílẹ̀-èdè | Nigerian |
| Ọmọ orílẹ̀-èdè | Nigeria |
| Iléẹ̀kọ́ gíga | |
| Iṣẹ́ | Physician |
| Gbajúmọ̀ fún |
|
| Olólùfẹ́ | S. O. Awoliyi |
| Àwọn ọmọ | 2 |
Olóyè Elizabeth Abimbola Awoliyi, MBE, OFR tí ó tún ń jẹ́ Akerele, ni eọ́n bí ní 1910 ni ó sì papòdà ní ọjọ́ kẹrìnlá oṣù kẹsàán , ọdún September 1971 ni ó jẹ́ obìnrin àkọ́kọ́ tí ó kọ́kọ́ jẹ́ oníṣègùn òyìnbó tí yóò ṣiṣẹ́ pẹ̀lú ìjọba ilẹ̀ Nàìjíríà.[1] Òun náà tún ni obìnrin akọ́kọ́ tí yóò kọ́kó gbàwé ẹ̀rí ṣiṣẹ́ gẹ́gẹ́ bí onímọ̀ nípa iṣẹ́ abẹ ní gbogbo apá ìwọ̀ Oòrùnilẹ̀ Adúláwọ̀ láti ìlú Dublin.[1][2] Elizabeth di obìrin kejì ní gbogbo ilẹ̀ Adúláwọ̀ tí yóò di onímọ̀ nípa ìṣègùn òyìbó ní ọdún 1938 tí ó sì gbàwé ẹ̀rí rẹ̀ lẹ́yìn arábìnrin Agnes Yewande Savage tí òun náà kẹ́kọ̀ọ́ gboyè jáde nílé ẹ̀kọ́ ìṣègùn ní ọdún 1929.[3] Elizabeth ni Ààrẹ kejì fún ẹgbẹ́ National Council of Women's Societies ní orílẹ̀-èdè Nàìjíríà láàrín ọdún 1964 títí ó fi kú ní ọdún 1971. [4]
Ìgbé ayé rẹ̀
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Bàbá rẹ̀ David Evaristo tí ó jẹ́ ọmọ Àgùdà tí ìyá rẹ̀ Rufina Akere bí Elizabeth Abimbola Awoliyi ní ìlú Èkó ní orílẹ̀-èdè Nàìjíríà. [1] Ó lọ sí ilé-ẹ̀kọ́ Alákọ̀ọ́bẹ̀rẹ̀ ti St. Mary's Catholic School, ní ilú Èkó kí ó tó lọ sí ilé-ẹ̀kọ́ Queen's College, Lagos.[5] Elizabeth gba ìwé ẹ̀rí ìṣègùn rẹ̀ ní ìlú Dublin ní ọdún 1938 láti ilé-ẹ̀kọ́ Trinity College Dublin, Cafreys College.[6][7][8] ó jáde nílé ẹ̀kọ́ Dublin pẹ̀lú ìwé ẹ̀rí tó wà ní ipò kínní first class honors, tí ó sì tún gba àmì ẹ̀yẹ èyí tó lọ́lá jùlọ nínú ìmọ̀ ẹ̀yà ara ènìyàn. Ó di ẹni àti obìnrin akọkọ́ rí yóò kọ́ gba ìwé ẹ̀rí licentiate of Royal Surgeon ní ìlú Dublin.[1][2] Ó jẹ́ ìkan lára àwọn ọmọ ẹgbẹ́ Royal College of Physicians ẹ̀ka ti (United Kingdom) àti Royal College of Obstetricians and Gynaecology pẹ̀lú ẹgbẹ́ iké-ẹ̀kọ́ Royal College of Paediatrics and Child Health.[1][2]
Lẹ́yìn tí Awoliyi padà sí orílẹ̀-èdè Nàìjíríà, ó di òṣìṣẹ́ ìjọba akọ́kọ́ tí yóò gbajúmọ̀ itọ́jú ẹ̀yà ara obìnrin nílé ìwòsàn ìjọba nílé ìwòsàn Massey Street Hospital ní ìlú Èkó. Ó padà di aṣàyẹ̀wò àgbà nílé ìwòsàn náà lári ọdún 1960 sí ọdún 1969. nílé Ìwòsàn náà.[2] Ní ọdún 1962, wọ́n fi Elizabeth ṣe adarí àgbà fún àwọn akọ́ṣẹ́mọṣẹ́ alátẹ̀wò nínú iṣẹ́ ìlera àwọn obìnrin ní Federal Ministry of Health.[2]
Ìwé àpilẹ̀kọ ọlọ́rọ̀ geere tí ọmọ rẹ̀ Túnjí Awólíyì kọ tí ó pè ní Return to Life, ni ó fi sọrí ìyá rẹ̀.[9] Wọ́n fi Awoliyi sínú ìwé kan tí wọ́n pè ní Nigerian Heroes and Heroines: and other issues in citizenship education, láti ọwọ́ Godwin Chukwuemeka Ezeh gẹ́gẹ́ bí ọ̀kan lára àwọn àkọni Obìnrin 20th century "Nigerian Heroine of the 20th Century".[10] Ilé ìwòsàn Dr. Abimbola Awoliyi Memorial Hospital wà ní erékùṣù Èkó, ní orílẹ̀-èdè Nàìjíríà.[11]
Awoliyi ní ilé adìyẹ tí ó tún fi gbin ọsàn sí tí ó tó saare méjìdínlọ́gbọ̀ ní Agege, ní ìlú Èkó, Ó tún di adarí fún ìlé ìta oògùn gbogbo gbò tí ó wà ní Èkó.[2]
NCWS
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Awoliyi ni ó dá ẹ̀ka National Council of Women's Societies (NCWS) sílẹ̀ tí ó sì jẹ́ Ààrẹ wọn. Bákan náà ni ó jẹ́ ìkan lára àwọn ìgbìmọ̀ ti àpapọ̀ àjọ náà. [12] Òun ni ó bèèrè fún olú ilé-ègbẹ́ náà tí ìjọba apapò fún wọn sí in Tafawa Balewa Square, òun ni ó sì jẹ́ dókítà fún òplọpọ̀ ìdílé tí ó wà níẹgbẹ́ náà. Arabìnrin Kofo Ademola ni ó gbapò náà lẹ́yìm rẹ̀ ní ọdún 1964. [12] .
Àwọn àjọ tí ó ti jẹ́ aṣáájú
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]- Ààrẹ àkọ́kọ́ fún Holy Cross Parish Women Council ní Holy Cross Cathedral in Lagos
- Motherless Babies Home Governing Council
- Business and Professional Women's Association (president)
- Child Care Voluntary Association (President)
- Lagos Colony Red Cross
- National Council of Women's Societies (Also became the first President of the Lagos branch)
Ìgbé ayé rẹ̀
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Elizabeth fẹ́ Dókítà S. O. Awoliyi, wọ́n sì jọ bí ọmọ méjì. Ọkùnrin kan obìnrin kan.[2] Ọkọ rẹ̀ kú ní ọdún 1965, nígbà rí Dr Elizabeth Abimbola Awoliyi fúnra rẹ̀ kú ní ọjọ́ kẹrìnlá oṣù kẹsàn ọdún 1971 ní ọmọ ọdún mọkànlélọ́gọ́ta .[2]
Awards and honours
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]- Member of the Order of the British Empire (MBE)
- Iya Abiye of Lagos
- Iyalaje of Oyo
- Nigerian National Honor – Officer of the Order of the Federal Republic (OFR).[2]
Ẹ tún wo èyí náà
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Àwọn itọ́kasí
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]- 1 2 3 4 5 Yinka Vidal (4 March 2015). How to Prevent the Spread of Ebola: Effective Strategies to Reduce Hospital Acquired Infections. Lara Publications Inc. pp. 7–. ISBN 978-0-9640818-8-8. https://books.google.com/books?id=9k4cBwAAQBAJ&pg=PA7.
- 1 2 3 4 5 6 7 8 9 Tabitha Admin (2015-03-12). "Celebrating African Women in Medicine". Tabitha Medical Center. Archived from the original on 2017-12-06. Retrieved 2015-07-02. Unknown parameter
|url-status=ignored (help) - ↑ "CAS Students to Lead Seminar On University's African Alumni, Pt. IV: Agnes Yewande Savage" (in en-US). CAS from the Edge. 2016-11-16. https://centreofafricanstudies.wordpress.com/2016/11/16/cas-students-to-lead-seminar-on-universitys-african-alumni-pt-iv-agnes-yewande-savage/.
- ↑ Ojewusi 1996, p. 283.
- ↑ Lagos Archdiocesan Council of Catholic Women Organisation (2000). Mobilising for Action. Dedun Educational Books, Indiana University. p. 47. ISBN 9789788013037. https://books.google.com/books?id=IMeKAAAAMAAJ&q=Elizabeth+Abimbola+Awoliyi+educated.
- ↑ Musliu Olaiya Anibaba (2003). A Lagosian of the 20th century: an autobiography. Tisons Limited. ISBN 9789783557116. https://books.google.com/books?id=Y9AuAQAAIAAJ&q=Elizabeth+Abimbola+Awoliyi+educated.
- ↑ Godwin Chukwuemeka Ezeh (2004). Nigerian heroes and heroines: and other issues in citizenship education. Mike Social Press, 2004. p. 97. https://books.google.com/books?id=3oAuAQAAIAAJ&q=Elizabeth+Abimbola+Awoliyi+born.
- ↑ Tabitha Admin (2015-03-12). "Celebrating African Women in Medicine". Tabitha Medical Center. Archived from the original on 2017-12-06. Retrieved 2015-07-02. Unknown parameter
|url-status=ignored (help) - ↑ Awoliyi, Tunji (2006-11-18). Return to Life - Tunji Awoliyi - Google Books. Nelson Publishers. ISBN 9789781261916. https://books.google.com/books?id=g8AVAAAAIAAJ&q=%22Abimbola+Awoliyi%22. Retrieved 2015-07-02.
- ↑ Ezeh, Godwin Chukwuemeka (2004). "Nigerian heroes and heroines: and other issues in citizenship education - Godwin Chukwuemeka Ezeh - Google Books". p. chapter 6. Archived from the original on 2016-05-06. Retrieved 2015-07-02. Unknown parameter
|url-status=ignored (help) - ↑ "Dr Abimbola Awoliyi Memorial Hospital in 183,Bamgbose Street, Lagos Island, Lagos, Nigeria | VConnect™". Vconnect.com. Archived from the original on 2015-07-03. Retrieved 2015-07-02. Unknown parameter
|url-status=ignored (help) - 1 2 Ojewusi 1996, p. 288.
External links
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]- Ojewusi, Sola (1996) (in en). Speaking for Nigerian women: (a history of the National Council of Women's Societies, Nigeria). Abuja: All State Pub. and Print. Co..
- Pages to import images to Wikidata
- Pages containing cite templates with deprecated parameters
- Pages with citations using unsupported parameters
- 1910 births
- 1971 deaths
- Nigerian gynaecologists
- Women gynaecologists
- Nigerian women medical doctors
- 20th-century Nigerian medical doctors
- Physicians from Lagos
- Alumni of Trinity College Dublin
- Queen's College, Lagos alumni
- People from colonial Nigeria
- Members of the Order of the British Empire
- Officers of the Order of the Niger
- History of women in Lagos
- 20th-century Nigerian women
- 20th-century women physicians