Elizabeth Olowu
Ọmọ-ọba Elizabeth Olowu jẹ́ oníṣẹ́ ọnà ọmọ ilẹ̀ Nàìjíríà àti ọmọbìnrin Oba Akenzua II, ẹni tí ó jẹ́ olórí àwọn ènìyàn Edo ní ibi tí a ń pè ní Benin City, Nàìjíríà báyìí. Olowu ń ṣiṣẹ́ pẹ̀lú idẹ, ohun èlò ìbílẹ̀ fún àwọn ènìyàn rẹ̀ (wo Benin Bronzes ), a sì mọ̀ ọ́n sí obìnrin àkọ́kọ́ tí ó ń ṣe idẹ ní Nàìjíríà. [ <span title="This claim needs references to reliable sources. (June 2022)">Ìtọ́kasí tí a nílò</span> ] Àwọn ère rẹ̀ ní òun ìṣàpẹẹrẹ àṣà àti ojú ìwòye òde òní àti ti àwọn ìwòye oníjàgbara obìnrin. [1] Ọmọbìnrin rẹ̀ ni ayàwòrán Peju Layiwola [2] tí ó jẹ́ Ọmọbìnrin Oba Akenzua II, Oba ti Benin tí ó jọba láti ọdún 1933 sí 1978.
Ìgbésí ayé àti ẹ̀kọ́ ìbẹ̀rẹ̀
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]A bí Ọmọ-ọba Elizabeth Olowu ní ọdún 1939 ní ìlú Benin, Ìpínlẹ̀ Edo ní apá Gúúsù Nàìjíríà. Bàbá rẹ̀ jẹ́ ọba pàtàkì ní ìjọba Benin, a sì mọ̀ ọ́n sí Ọba (Oba) Akenzua Kejì. Nígbà tí ó wà ní ọmọdé, Olowu ṣiṣẹ́ pẹ̀lú ìyá rẹ̀, ti ó ń kọ́ bí a ṣe ń gbẹ́ ère ati àwọn nǹkan tí ó ní í ṣe pẹ̀lú ìgbésí ayé nínú ààfin àti àṣà ìrúbọ. Bàbá rẹ̀ ṣe alátìléyìn fún nípa kiko ẹ̀kọ́ àti ìfẹ́ rẹ̀ si ère gbígbé, láìka àwọn ìgbàgbọ́ àgbáyé tí ó ń dí àwọn obìnrin lọ́wọ́ láti wọ ilé iṣẹ́ idẹ sí. [3] Olowu lọ sí ilé ìwé Holy Child College, Lagos, níbi tí ìfẹ́ iwe kíkà tí gbìnàyá nínú ọkàn re. Ó tẹ̀síwájú nínú ẹ̀kọ́ rẹ̀ ní Federal Emergency Science School níbi tí ó ti kẹ́kọ̀ọ́ nípa ìmọ̀ nípa ewéko, kemistri, àti ẹranko, èyí tí ó kọ́ ní ilé-ẹ̀kọ́ Anglican Girls' Grammar lẹ́yìn náà. Nígbà tí ó pé ọmọ ọdún méjìdínlógún, ó fẹ́ ọ̀rẹ́ rẹ̀ ní ilé-ẹ̀kọ́ gíga, Babatunde Olowu, ó sì bí ọmọ rẹ̀ àkọ́kọ́, Adedapo Tunde-Olowu ní ọdún 1965. Ní ọdún 1966, ó tẹ̀síwájú nínú ẹ̀kọ́ rẹ̀ nípa fíforúkọ sílẹ̀ ní Yunifásítì ti Nàìjíríà, ṣùgbọ́n ó ní láti fi ẹ̀kọ́ rẹ̀ sílẹ̀ nígbà tí Ogun Abẹ́lé Nàìjíríà bẹ̀rẹ̀ ní ọdún 1967 lẹ́yìn tí ó parí ọdún àkọ́kọ́ rẹ̀.
Ó tẹ̀síwájú nípa kíkóni nígbà kan rí, ó sì ń ṣètò àwọn ìfihàn iṣẹ́ ọ̀nà déédéé fún àwọn akẹ́kọ̀ọ́ obìnrin rẹ̀, lèyí tí ó fa àfiyèsí olùdarí Ẹ̀ka ti Creative Arts ti Yunifásítì Benin, ẹni tí ó pè é láti dara pọ̀ mọ́ ètò Fine Arts. Ní ọdún 1979, ó parí ẹ̀kọ́ Bachelor of Fine Arts, nígbà tí ó fi di ọdún 1981, ó ti bẹ̀rẹ̀ sí í ṣiṣẹ́ lórí ẹ̀kọ́ rẹ̀ lẹ́yìn-ẹ̀kọ́ gíga, èyí tí ó ní ìwé àkọ́lé rẹ̀ lórí “Ìwádìí nípa Ọ̀nà tí àwọn ará Benin gba ṣe iṣẹ́ Ide Cire Perdue .” Àṣeyọrí yìí mú kí ó jẹ́ obìnrin àkọ́kọ́ tí ó gba Master of Fine Arts ní yunifásítì àti obìnrin àkọ́kọ́ tí ó fi idẹ ṣe iṣé Ọ̀nà. [4] Ní ọdún 1985, ó gba Ẹ̀bùn Bendel State Award fún Ọ̀nà àti Àṣà, ẹgbẹ́ àwọn ọ̀dọ́mọbìnrin Catholic sì dá a mọ̀ lẹ́yìn náà fún àfikún rẹ̀ sí gbígbé ipò àwọn obìnrin ga ní orílẹ̀-èdè rẹ̀. Ó ń bá a lọ láti ṣiṣẹ́ ní Benin University níbi tí ó ti ń tọ́jú ilé iṣẹ́ idẹ tirẹ̀. [1]
Iṣẹ́ ọwọ́
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Gẹ́gẹ́ bí obìnrin oníṣé ọnà, ìfẹ́ pàtàkì tí Elizabeth Olowu ni láti “tu àwọn obìnrin sílẹ̀ kúrò nínú ìdè àwọn ọkùnrin, ìnilára àti èèwọ̀”. [1] Ní ọdún 1979, ó gbẹ́ ère ìgbésí ayé ọmọbìnrin kan tí ó jókòó sí orí tábìlì tí ojú rẹ sì tẹpẹlẹ mo ìwé kan tí òun ká. ère yìí jẹ́ ọ̀kan lára àwọn àkọ́kọ́ láti inú àṣà rẹ̀ tí ó ṣàfihàn obìnrin to dádúró. Ọdún 1983 tún jẹ́ ọdún pàtàkì nínú ìgbésí ayé rẹ̀. Ó ṣe àwárí, ní jíjinlẹ̀, àwọn kókó ọ̀rọ̀ agbára láti ojú ìwòye onírúurú ìmọ̀lára. Àwọn ère pàtàkì kan ninu ọdún yìí ní The Oba àti Christ Bearing the Sins of Humanity . Ere Oba na ṣe àfihàn baba rẹ̀, ẹni tí ó ṣe pàtàkì nínú ṣíṣe ìrànlọ́wọ́ fún iṣẹ́ rẹ̀ àti ẹ̀kọ́ rẹ̀. ère náà jẹ́ ti ara ẹni nípa gbígbé àmì ọwọ́ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí àwòrán aṣọ. Kristi Bearing the Sins of Humanity ga ju ẹsẹ̀ méje lọ ó sì fi àwòrán Kristi onígun mẹ́ta tí ó dúró lábẹ́ ìwúwo àgbélébùú hàn.
Àwọn ìtọ́kasí
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]- 1 2 3 LaDuke, Betty (1991). Africa through the Eyes of Women Artists. Africa World Press. Àṣìṣe ìtọ́kasí: Invalid
<ref>tag; name ":1" defined multiple times with different content - ↑ Empty citation (help)
- ↑ "Nigerian artists keep sculpture in the family" (in en-US). https://guardian.ng/art/nigerian-artists-keep-sculpture-in-the-family/.
- ↑ Empty citation (help)