Jump to content

Emmanuel Daraloye

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́

Emmanuel Daraloye

Emmanuel Daraloye (tí a bí ní ọjọ́ 30 oṣù kejìlá ọdún 1994) jẹ́ akọrin oníròyìn Nàìjíríàa. Àwọn iṣẹ́ rẹ̀ ti farahàn nínú NotJustOk, TheCable, The Lagos Review, Vanguard, The Guardian, ModernGhana, Legit.ng, and Nigerian Tribune.

Ìgbésí ayé ìbẹ̀rẹ̀ pẹ̀pẹ̀

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Bàbá rẹ̀ jẹ́ olùsírò owó kékeré kan, tí ìyá rẹ̀ sì jẹ́ oníṣòwò káràkátà, A bí Emmanuel Daraloye ní ọjọ́ 30 oṣù kejìlá ọdún 1994 ní Ipele, Ìpínlẹ̀ Ondo ṣùgbọ́n tí a tọ́ ọ dàgbà ní Akure níbi tí ó ti padà lọ ní ọdún 2003. Daraloye lo díẹ̀ lára ìgbà èwe rẹ̀ láàárín Ipele àti Akure pẹ̀lú àwọn òbí, òbí òbí àti alágbàtọ́ rẹ̀. Daraloye ka ilé ẹ̀kọ́ alákọ̀ọ́bẹ̀rẹ̀ rẹ̀ fún ìgbà díẹ̀ ní ilé ẹ̀kọ́ St. Stephen Anglican Primary School lẹ́yìn náà ni ó lọ sí King and Queen Nursery and Primary School, Oke Aro, Àkúrẹ́ níbi tí ó ti parí ilé-ẹ̀kọ́ alákọ̀ọ́bẹ̀rẹ̀ rẹ̀. Daraloye ká ilé-ẹ̀kọ́ sẹ́kọ́ńdírí rẹ̀ ní St. Dominic's High School, Àkúrẹ́ ó sì parí ní ilé-ẹ̀kọ́ olùkọ́ni àgbà Adeyemi College of Education pẹ̀lú ìwé ẹ̀rí nínú ìmọ̀ Èdè Gẹ̀ẹ́sì ní ọdún 2023

Gẹ́gẹ́ bí akẹ́kọ̀ọ́ tuntun ní ilé-ẹ̀kọ́ olùkọ́ni àgbà ní Adeyemi College of Education, Daraloye pẹ̀lú akẹgbẹ́ rẹ̀ Ayomide Oguntimehin ṣe ìdásílẹ̀ ìwé ìròyìn orí ayélujára Arbico Parrot, ìwé ìròyìn ayélujára ti akẹ́kọ̀ọ́.

Láti ọdún 2015 sí 2019, Daraloye ṣiṣẹ́ gẹ́gẹ́ bí akàròyìn, olóòtú ètò, àti àwòkọ́se orí afẹ́fẹ́ ní Arbico FM, Ace Campus, EKI 100.9 Fm, Ondo Town àti King Sunny Ade owned Music & Culture 106.5 Fm, Ondo Town

Láti ọdún 2022, Daraloye ti ṣiṣẹ́ gẹ́gẹ́ bí lámèyítọ́ àgbà orin ní Afrocritik àti ṣíṣe àtúnyẹ̀wò ní AfroReview, ìwé ìròyìn tí ó dá sílẹ̀ ní oṣù kìíní ọdún 2022.