Jump to content

Emmanuel Nwobosi

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́

Emmanuel Nwobosi jẹ́ olórí ọmọ ogun Naijiria o sì jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn tí wọn kópa nínú ifipa gba ijọba ti wọn sẹ́lorí eleyii ti o wáyé ni ọjọ kẹẹdogun oṣù kínní ọdún 1966, eleyii ti o le ijoba Sir Alhaji Abubakar Tafawa Balewa kuro ni orí ìṣèjọba. O jagun ninu Ogun Biafra tako àwọn ọmọ ológun Nàìjíríà gẹgẹ bi Kononeli nigba Ogun Abele Naijiria to wáyé lẹyìn ti wọn fipá gbàjọ́bá ni osu kinni ati ìfòjọba wọn lọ́jọ́ kọkàndínlọ́gbàn oṣù keje ọdún 1966. [1]

Ìbẹ̀rẹ̀ Ìgbésí ayé ati iṣẹ

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Nwobosi wa lati Obosi, Arewa Idemili ti Ìpínlẹ̀ Anambra. Òun ni olórí fún gbogbo àwọn oṣiṣẹ fún Chukwuemeka Odumegwu Ojukwu, olórí ọlọtẹ̀ Biafra nígbà Ogun Abẹle Nàìjíríà. [2] Ni ìgbà ti ogun tán, Nwobosi tẹle Ojukwu lọsí ààyè aimọ̀n ni Ivory Coast .

Nwobosi lo sáájú ifipa gba ijọba naa nílùú Ibadan ni Iwọ oorun lẹhinna o sí padà pejọ si ilu Eko pẹlu Emmanuel Ifeajuna, ọkan ninu awọn olori akọkọ ti putsch. [3] Nwobosi mu àwọn apanirun naa lo si ile Oloye Remilekun Fani-Kayode ati Oloye Samuel Ladoke Akintola . [4] O mu ẹni àkọkọ, sugbon nigba ti won de ile Akintola, o koju ija sí, ija ibon si bẹ́sile. Ibọn síi mu Oloye Akintọla, Oloye Ilẹ Iwọ-Oorun nígbà ti wọn ṣe paṣipaaro ibọn yẹn. [5] Lẹyìn ti ifipagbàjọba naa kuna ti àwọn agbofinro naa si ti ko àwọn ọlọtẹ nipasẹ General JTU Ironsi, Nwobosi wa ni atimọle ninu ẹwọn Kirikiri, lẹhinna wọn gbe lọ si Enugu, lẹhinna lọ si ẹwọn Owerri. [6]

Nwobosi ku ni ọdún 2020 ni ẹni ọdun mejilélọ́gọrin. [7] [8]

  1. https://punchng.com/obiano-mourns-ojukwus-chief-of-staff-nwobosi/
  2. https://www.channelstv.com/2020/11/24/colonel-who-participated-in-1966-coup-dies-at-81/
  3. https://thesun.ng/insecurity-dont-push-nigeria-to-war-col-nwobosi/
  4. "Ẹda pamosi". Archived from the original on 2025-12-12. Retrieved 2025-09-09.
  5. https://opinion.premiumtimesng.com/2016/01/26/a-night-of-darkness-and-the-law-of-karma-by-femi-fani-kayode/
  6. https://www.bbc.com/igbo/afirika-55074814
  7. https://dailypost.ng/2020/11/24/col-emmanuel-nwobosi-is-dead/
  8. https://independent.ng/my-father-died-thinking-about-unity-of-ndigbo-nwobosi/