Jump to content

Esa Oke

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́

Esa-Oke je ilu Yoruba ti o wa ni ijoba ibile Obokun ni ipinle Osun, ti o wa ni apa guusu ìwọ oòrùn orile-ede Naijiria. Ile Ijesa ni Esa OKe je, o si pa ala pelu awon ilu bi Oke-Imesi, Imesi-ile, Ijebu-Ijesa, Esa-Odo ati Efon-Alaaye.[1] Omiran Adebolu ti o je omo ebi Olofin ni Ile-Ife ni won gbagbo wipe o da ilu Esa-Oke sile leyin ti o kuro ni Ile-Ife ni 1184 A.D. Oye Oba ilu Esa-Oke ni Ọwámiran ti ilu Esa Oke.

Awon ara Esa-Oke je agbe ologbin ege, isu, agbado, iresi, cocoa, obi ati bee bee lo. Sibẹsibẹ, owo sise je nkan gbogi laarin awọn iṣẹ ti o wa ni ilu nan. Owo sise yi ni awon ara Esa-Oke un se kakakiri apa ìwọ̀ oòrùn ati ariwa orile-ede Naijiria.

Isakoso Ilu Esa-Oke wa lowo Oba ti a mon si "Owamiran ti ilu Esa Oke". Igbimo ariwa Ijesa ti o wa labe igbimo awon lobaloba ni ipinle Osun ni oun se isakoso lori oro lobaloba. Awon olori merin ni o wa labe Owamiran ti won si un jabo fun Owamiran ti ilu Esa Oke. Awon merin yi ni Oke Esa, Erinjiyan, Idofin ati Odo-Ese ti won si ni oruko oye ti a mon si Asaba, Osolo, Obafin ati Enurin.

Awon ile merin ni oun je Oba ni ilu Esa Oke. Awon merin yi ni:

  • Ile Afinbiokin (Iran Oba Isiaiah Adeniran, ti a tun mon si Ile-Otu)
  • Ile Beleyeke
  • Ile Gogodudu ti a tun mon si Ananye
  • Ile Aragadagbagun ti a mon si Yeye Owa (Iran Oba Adeyemi Adediran).

Awon Oba ti o je seyin ni:

  • Oba Adeyemi Adediran - Atipa Owaji II - 2004 titi di oni oloni
  • Oba Isaiah Ajayi Adeniran - Afinbiokin II- 1954 to 2004
  • Oba Fatolu - XXXXXXXXXX - 1948

Eto Eko ati Awujo Amayederun

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Ilu Esa-Oke ni ile eko imo-ero Osun State College of Technology(OSCOTECH) wa. Ile-ẹkọ sẹkọndiri ti ijoba meji lo wa ni ilu Esa-Oke, awon ile-ẹkọ Sẹkọndiri nan ni Esa-Oke Grammar School ati Saint Joseph's Catholic High School. Be si ni ile-iwe alakobere mejo lo wa ni ilu nan. Sibesibe, ni ode ni, idasile awon ile-iwe aladani ti o je sekondiri ati alakobere ti wopo ni ilu nan. Apeere ni Fayofunmi Model College, Elepolu Group of Schools ati Peace & Joy Group of Schools. Ilu Esa-Oke ni awon onan ti o da ti o si ja si awon ilu ti o yi ka.

Odun Egungun ati Ikedi ti won ma un se lododun je odun ti o larinrin. Odun nan je odun ti opolopo eniyan ti ma un jo orisirisi ijo ibile, ni pato ijo "Ege".

  • Oba Adeyemi Adediran: Owa Omiran ti ilu Esa-Oke
  • Chief Bola Ige: Gomina teleri ti ipinle Oyo ni igba kan ri ati Attorney General fun orile-ede Naijiria ati Minisita fun Idajo ni igba kan ri.
  • Joseph Omotoso Adeyemi-Bero[2]
  • Hon. Busayo Oluwole Oke: Omo egbe ile igbimo asofin ti o je asoju fun ijoba ibile Obokun/Oriade ti ipinle Osun.[3]
  • Prof. Timothy A. Adebayo: Igbakeji Oludari ile-eko giga Ladoke Akintola University ti o wa ni ilu Ogbomosho ni igba kan ri ati Oludari kerin ti ile-eko giga Ajayi Crowther University, Oyo.
  • Ayo Adediran
  • Dr. Olasiji Akanmu Olamiju: Oludasile ile-isoogun Akoi.
  • Prof. Oni Michael Abiodun: Olukoni Agba ni ile-iwe giga Babcock University, Remo, Ogun.
  • Dr. Festus Kehinde Ojo: Olukoni agba ni ile-iwe giga, Ladoke Akintola University of Technology (LAUTECH), Ogbomoso
  • Israel Adesanya[4]
  1. "Population and Demographics". CityFacts. Retrieved 2025-12-07.
  2. "First Military Gov of Lagos, Mobolaji Johnson, is Dead – THISDAYLIVE". THISDAYLIVE – Truth and Reason. 2019-10-30. Retrieved 2026-01-01.
  3. "ShineYourEye". ShineYourEye. Retrieved 2026-01-12.
  4. Kareem, Azeez (2024-08-23). "UFC star Adesanya visits Osun, to be honoured by kinsmen". The Guardian Nigeria News - Nigeria and World News. Retrieved 2026-01-01.