Esin Yoruba
| Ìṣẹ̀ṣe | |
|---|---|
| Ìsọ̀rí | Áfíríkà |
| Ìwé Mímọ́ | Odù Ifá |
| Ẹ̀kọ́ ẹ̀sìn | Diffused monotheism |
| Agbègbè | Káríayé[1] |
| Èdè | Yorùbá |
| Ìpínlẹ̀ | Ilẹ̀ Yorùbá |
| Ìbẹ̀rẹ̀ | 500–300 B.C.E[2] Ilé-Ifẹ̀, Àárín gbùngbùn Ilẹ̀ Yorùbá |
| Iye àwọn ẹlẹ́sìn | fojú bù. àràádọ́ta ọ̀kẹ́ (several millions)[3] ▲ (referred to as Oníṣẹ̀ṣe) |
| Apá kan nínú ẹ̀sìn Yorùbá |
| Ẹ̀sìn Yorùbá |
|---|
| Àwọn Ọlọ́run àti Òrìṣà |
| Ìgbàgbọ́ |
| Àṣà àti Ìṣe |
| Àwọn Ẹ̀yà tàbí Ìyàtọ̀ |
|
| Àwọn ibi mímọ́ |
| Àwọn akíkanjú ìtàn |
Ẹ̀sìn Yorùbá (Ìṣẹ̀ṣe ìʃɛ̀ʃē), Òrìṣà Ìwọ̀-oòrùn Áfíríkà (Òrìṣà òɾìʃà), tàbí Ìṣẹ̀ṣe (Ìṣẹ̀ṣe), jẹ́ àkópọ̀ àwọn èrò àti àṣà ẹ̀sìn tẹ̀mí ti ìbílẹ̀ àwọn Yorùbá.[4] Orísun rẹ̀ wà ní agbègbè tí a mọ̀ dunjú sí Ilẹ̀ Yorùbá (Ilẹ̀ Káàárọ̀-Oòjíire), èyí tó kápọ̀ púpọ̀ nínú àwọn ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́, Ògùn, Ọ̀ṣun, Òǹdó, Èkìtì, Kwara, Èkó àti apá kan Kogi ní gúúsù-ìwọ̀-oòrùn Nàìjíríà tòde-òní; àwọn Ìpínlẹ̀ Collines, Oueme, Plateau ní Gúúsù Benin; àti àwọn apá ibi tí ó sún mọ́ ọn ní Àárín gbùngbùn Togo. Ó ti di ẹ̀sìn / ìgbàgbọ́ ìbílẹ̀ Áfíríkà tí ó tóbi jùlọ lágbàáyé pẹ̀lú àràádọ́ta ọ̀kẹ́ àwọn ẹlẹ́sìn yìí káríayé.[5]
Ó jọ ẹ̀sìn Vodun tí àwọn ẹ̀yà Fon àti Ewe tó wà ní ìwọ̀-oòrùn rẹ̀ ń ṣe, àti pẹ̀lú ẹ̀sìn àwọn Edo ní ìlà-oòrùn rẹ̀. Ẹ̀sìn Yorùbá ni ìpìlẹ̀ fún oríṣiríṣi ẹ̀sìn ní Ayé Tuntun (New World), pàápàá jùlọ Santería, Umbanda, Trinidad Orisha, àti Candomblé.[6] Àwọn ìgbàgbọ́ ẹ̀sìn Yorùbá jẹ́ apá kan Ìtàn, èyí tó jẹ́ àkópọ̀ àwọn orin, ìtàn, àlọ́, àti àwọn èrò àṣà mìíràn tó ṣẹ̀dá àwùjọ Yorùbá.[6][7]
Ọ̀rọ̀ tàbí Orúkọ
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Orúkọ tí àwọn Yorùbá ń pe ẹ̀sìn ìbílẹ̀ wọn ni Ìṣẹ̀ṣe, èyí tó tún tọ́ka sí àwọn àṣà àti ìsìn tó yí àṣà Yorùbá ká. Ọ̀rọ̀ yìí wá láti inú àkópọ̀ ọ̀rọ̀ méjì, Ìṣẹ̀ (tó túmọ̀ sí "orísun/gbòǹgbò"), àti ìṣe (tó túmọ̀ sí "àṣà/ohun tí a ń ṣe") tí wọ́n para pọ̀ láti túmọ̀ sí "Àṣà àtìbá" tàbí "Àṣà ìwáṣẹ̀" nítorí pé púpọ̀ nínú àwọn ìsìn, ìgbàgbọ́, àṣà, àti àkíyèsí àwọn Yorùbá wá láti inú ìjọsìn ẹ̀sìn fún Olódùmarè àti fífún àwọn Òrìṣà ní ọ̀wọ̀.
Ìgbàgbọ́
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Gẹ́gẹ́ bí Kola Abimbola ṣe sọ, àwọn Yorùbá ti mú ìmọ̀ ìṣẹ̀dá àgbáyé (cosmology) tó fẹsẹ̀múlẹ̀ dàgbà.[6] Ọ̀jọ̀gbọ́n ọmọ Nàìjíríà fún Ẹ̀sìn ìbílẹ̀ Áfíríkà, Jacob K. Olupona, ṣe àkópọ̀ pé kókó pàtàkì fún ẹ̀sìn Yorùbá, tí gbogbo ẹ̀dá alààyè sì ní, ni a mọ̀ sí "Àṣẹ", èyí tí í ṣe "ọ̀rọ̀ agbára tí ó gbọ́dọ̀ ṣẹ," "agbára ìyè" àti "agbára" tó "ń darí gbogbo ìṣípòpadà àti ìgbésẹ̀ nínú àgbáyé".[8][9][10] Gbogbo èrò àti ìṣe olúkúlùkù ènìyàn tàbí ẹ̀dá nínú Ayé máa ń ní ìbáṣepọ̀ pẹ̀lú agbára Ọ̀gá-ògo, gbogbo àwọn ohun alààyè mìíràn, títí kan Ayé fúnra rẹ̀, bẹ́ẹ̀ náà ni pẹ̀lú Ọ̀run, níbi tí àwọn òrìṣà, ẹ̀mí àti àwọn òkú-ọ̀run wà.[11][9][10] A lè ṣàpèjúwe ẹ̀sìn Yorùbá gẹ́gẹ́ bí ìgbàgbọ́ nínú Ọlọ́run kan tó tàn kálẹ̀ (diffused monotheism), pẹ̀lú Agbára Ẹlẹ́dàá tí ó ga jùlọ ṣùgbọ́n tí ó wà ní òkèèrè, tó gba gbogbo àgbáyé sínú.[10]
Àtúnwá (Reincarnation)
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]
Àwọn Yorùbá gbàgbọ́ nínú Àtúnwá, wíwá sáyé ẹ̀ẹ̀kejì (reincarnation) láàrin ìdílé. Àwọn orúkọ bíi Babátúndé (baba tún padà dé), Yétúndé (Ìyá tún padà wá), Babátúnjí (Baba tún jíǹde), àti Sótúndé (Ọlọ́gbọ́n tún padà dé) gbogbo wọn jẹ́ ẹ̀rí tó fìdí rẹ̀ múlẹ̀ nípa èrò Ifá lórí àtúnwá nínú ẹbí.[12] Ṣùgbọ́n, kò sí ẹ̀rí tó dájú pé baba-ńlá tàbí ẹ̀gbọ́n baba ẹni yóò "padà wá" nínú ìbí ọmọdé gangan.
Nígbàkígbà tí àkókò bá tó fún ẹ̀mí láti padà wá sí Ayé (tí a tún mọ̀ sí Ọjà) nípasẹ̀ ìlóyún ẹ̀dá tuntun nínú ẹ̀jẹ̀ ìdílé náà, ọ̀kan nínú àwọn ẹ̀mí tó para pọ̀ di ènìyàn yóò padà wá, nígbà tí èkejì yóò dúró ní Ìkọ̀lé Ọ̀run. Ẹ̀mí tó padà wá ń ṣe bẹ́ẹ̀ ní ọ̀nà Ẹlẹ́dàá Orí (Guardian Ori). Ẹlẹ́dàá Orí ẹni, tí ó wà ní àárín agbárí, kò dúró fún ẹ̀mí àti agbára ìbátan ẹ̀jẹ̀ ẹni ti tẹ́lẹ̀ nìkan, ṣùgbọ́n fún àkójọpọ̀ ọgbọ́n tí ó ti kó jọ nínú àwọn ìgbésíayé rẹ̀ púpọ̀.[13] Kò yẹ kí a gbé èyí dọ́ti Orí tẹ̀mí ẹni, èyí tó gbé kádàrá ẹni, ṣùgbọ́n dípò bẹ́ẹ̀ ó tọ́ka sí pípada wá sí Ọjà fún Orí ẹ̀jẹ̀ ẹni nípasẹ̀ ìgbésíayé àti àwọn ìrírí tuntun rẹ̀. Baba-ńlá tàbí Ìyá-ńlá àkọ́kọ́ (Primary Ancestor) yìí máa ń di "atọ́nà" fún onítọ̀hún jálẹ̀ ìgbésíayé rẹ̀—tí ó bá mọ̀ nípa rẹ̀ tí ó sì ń bá agbára yẹn ṣiṣẹ́. Ní òpin ìgbésíayé yẹn, wọ́n á padà sínú ẹ̀mí wọn kan náà, wọ́n á sì di ẹyọ kan, wọ́n á gba ìmọ̀ àfikún tí wọ́n ti rí gbà látara ìrírí ẹni náà gẹ́gẹ́ bí "ẹ̀san".[12]
Ipò Ẹ̀yà Akọ-tàbí-Abo Nínú Ẹ̀sìn Yorùbá
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Àwọn ipò ẹ̀yà-akọ-tàbí-abo jẹ́ kókó pàtàkì nínú ẹ̀sìn Yorùbá, níbi tí àwọn obìnrin ti wà ní ipò ńlá gẹ́gẹ́ bí ìyálòrìṣà àti olùtọ́jú ìmọ̀ mímọ́.[14] Àwọn ipò wọ̀nyí ṣe pàtàkì fún títọ́jú àwọn àṣà ẹ̀sìn wọ́n sì ń nípa lórí bí agbára tẹ̀mí ṣe ń yí padà nínú àwùjọ.[15] Àwọn àṣà Yorùbá gba ìwà obìnrin wọlé gẹ́gẹ́ bí apá pàtàkì fún ìrírí tẹ̀mí.[16] Àwọn obìnrin máa ń kópa gidigidi nínú àwọn àṣà ẹ̀sìn àti ìjọsìn, èyí tó ń mú ipa àti ìtóbi wọn pọ̀ sí i nínú ètò ẹ̀mí.[17]
Onímọ̀ nípa ẹ̀dá-ènìyàn Robert Voeks ṣàpèjúwe ẹ̀sìn Yorùbá gẹ́gẹ́ bí ẹ̀sìn tó gba àwọn ohun àdáyébá gbọ́ pé wọ́n ní ẹ̀mí (animistic), ó tẹnumọ́ ọn pé ó "fẹsẹ̀múlẹ̀ ṣinṣin sínú ibì kan".[18]
Olúkúlùkù ẹni tó ń gbé lórí ilẹ̀ ayé máa ń gbìyànjú láti dé ìpé pé pérépéré àti láti rí kádàrá wọn ní Ọ̀run-Rere (ibùgbé tẹ̀mí fún àwọn tó ṣe rere àti ohun tó wúlò).
Orí-inú ẹni gbọ́dọ̀ dàgbà kí ó lè bára mu pẹ̀lú "Ìpọ̀nrí" (Orí Ọ̀run ẹni).[8]
Ìwà pẹ̀lẹ́, kíkẹ́kọ̀ọ́ àti pípàròwà Ifá, àti ìfọkànsìn tòótọ́ ti tó láti sọ orí-inú ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn dọ̀tun.[11][8] Wọ́n gbàgbọ́ pé àwọn ènìyàn tó ní ìwọ̀ntúnwọ̀nsì lè lo ọ̀nà ìbáṣepọ̀ tó rọrùn jùlọ láàrin Orí wọn àti Alágbára jùlọ Olú-Ọ̀run: èyí ni Àwúre (ẹ̀bẹ̀ tàbí àdúrà) fún àtìlẹ́yìn àtọ̀runwá.
Nínú èrò ìgbàgbọ́ Yorùbá, Olódùmarè ló ní àṣẹ lórí ohun gbogbo tó wà. Nítorí náà, wọ́n jẹ́ Ọ̀gá-ògo.[11]
Ìwé Mímọ́
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Àwọn ìwé mímọ́ Yorùbá ni a ń pè ní Odù Ifá, èyí tó jẹ́ àkójọpọ̀ àwọn ọ̀rọ̀ àsọtẹ́lẹ̀ mímọ́ tí wọ́n ń sọ lẹ́nu láti ìran dé ìran láàrin àwọn Babaláwo.[19] Ní ìṣẹ̀dálẹ̀, wọ́n pín in sí ìsọ̀rí mẹ́rìndínlọ́gọ́ta-lé-nígba (256), tàbí Odù, èyí tí a tún pín sí ẹsẹ. Ó ní í ṣe pẹ́kípẹ́kí pẹ̀lú ètò ìdáfá ti ẹ̀sìn Yorùbá, Ifá. Àwọn ẹsẹ Ifá yìí ní àwọn òwe, ìtàn, àti àwọn ọ̀rọ̀ tó kàn mọ́ gbogbo apá ìgbésíayé. Odù Ifá ni ìpìlẹ̀ ìmọ̀ tẹ̀mí Yorùbá, ó sì ti nípa lórí àwọn àwùjọ tẹ̀mí ní Amẹ́ríkà, gẹ́gẹ́ bíi Santería. Ifá ń tọ́ka sí òrìṣà Ọ̀rúnmìlà, ẹni tí wọ́n mọ̀ mọ́ ọgbọ́n, òye, àti ìdáfá.[19]
Ní ọdún 2005, UNESCO sọ àṣà Odù Ifá di ọ̀kan lára Àwọn Iṣẹ́-Ọnà Ọ̀rọ̀-ẹnu àti Ogún Àìlèfojúrí ti Ẹ̀dá-ènìyàn (Masterpieces of the Oral and Intangible Heritage of Humanity) káríayé.[19]
Ìmọ̀ Ìṣẹ̀dá Àgbáyé (Cosmology)
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Olódùmarè
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Olódùmarè jẹ́ ẹni tí a gbàgbọ́ pé Ó jẹ́ Ẹlẹ́dàá Gíga Jùlọ àti orísun gbogbo ìṣẹ̀dá nínú ìgbàgbọ́ Yorùbá. Ohun gbogbo tó wà—Òrìṣà, ènìyàn, ẹranko, ẹ̀dá, àti àwọn agbára tẹ̀mí—wá láti ọ̀dọ̀ Olódùmarè. Gẹ́gẹ́ bí ayàwòrán àtọ̀runwá fún àgbáyé, Olódùmarè ni ó ní àṣẹ tí ó ga jùlọ, òun sì ni olùfúnni ní àṣẹ, agbára mímọ́ tí ń ṣètọ́jú tí ó sì ń fi agbára fún gbogbo ìyè.[20]
Olódùmarè ni "ipò ìwà-láàyè" tó ṣe pàtàkì jùlọ.[21] "Wọ́n" ni olúwa gbogbo orí, nítorí pé lásìkò ìṣẹ̀dá ènìyàn, Olódùmarè fún ẹ̀dá-ènìyàn ní "èmí" (èémí ìyè). Nínú èyí, Olódùmarè ga jùlọ.[21] Bóyá ọ̀kan nínú àwọn ìsapá ẹ̀dá-ènìyàn tó ṣe pàtàkì jùlọ tí wọ́n gbé ga nínú Odù Ifá ni ìlékè láti mú "Ìwà" ẹni sunwọ̀n sí i. Nípa báyìí, àwọn ẹ̀kọ́ náà kọjá ẹ̀kọ́ ẹ̀sìn lásán, ó ń gba ènìyàn níyànjú pé ó tún gbọ́dọ̀ mú kí àwùjọ, ìbáṣepọ̀, àti òye rẹ̀ sunwọ̀n sí i; gbogbo Odù ti korpus Ifá mímọ́ ní apá kan tó ń sọ nípa ìwúlò "Ìwà". Kókó nínú èyí ni kókó-ọ̀rọ̀ ìwà òdodo, yálà ti ẹnìkan tàbí ti àkójọpọ̀.[22]
Ìṣẹ̀dá
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Àwọn ẹlẹ́sìn Yorùbá gba Olódùmarè gẹ́gẹ́ bí agbára pàtàkì fún ìṣẹ̀dá.[23]
Gẹ́gẹ́ bí ọ̀kan nínú àwọn ìtàn Yorùbá nípa ìṣẹ̀dá, ní ìpele kan nínú ètò náà, wọ́n rán "òtítọ́" jáde láti fìdí rẹ̀ múlẹ̀ bóyá àwọn ayé tí wọ́n ṣẹ̀ṣẹ̀ dá dára láti gbé. Ayé tí a wà yìí wà lára wọn, wọ́n bẹ̀ ẹ́ wò ṣùgbọ́n wọ́n rí i pé ó tutù jù fún ìgbé-ayé tó gbámúṣé.[24]
Lẹ́yìn àkókò kan, wọ́n rán ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn òrìṣà tí Ọbàtálá lékè wọn wá láti ran ayé lọ́wọ́ láti mú ilẹ̀ rẹ̀ le. Nínú ọ̀kan lára àwọn ìbẹ̀wò wọn sí ilẹ̀ ayé, òrìṣà ńlá Ọbàtálá gbé ìgbésẹ̀ pẹ̀lú ìkarahun kan (mollusc) tó gbé irúfẹ́ erùpẹ̀ kan pamọ́, àwọn ẹranko abìyẹ (winged beasts), àti nǹkan kan tó dà bí aṣọ. Wọ́n da àwọn nǹkan yìí sórí ohun tí ó padà di ebè ńlá lójú omi, lẹ́yìn náà ni àwọn ẹranko abìyẹ náà bẹ̀rẹ̀ sí í fọ́n erùpẹ̀ náà ká títí tí ó fi dàpọ̀ di ilẹ̀ gbígbẹ ńlá; onírúurú kòtò tí wọ́n dá padà di àwọn òkè àti àfonífojì.[25]
Ọbàtálá bẹ́ sórí ilẹ̀ gíga yẹn ó sì sọ ibẹ̀ ní Ifẹ̀. Ilẹ̀ náà tutù, àwọn ewéko sì bẹ̀rẹ̀ sí í hù dádá. Pẹ̀lú ẹ̀kúnwọ́ erùpẹ̀, ó bẹ̀rẹ̀ sí í mọ àwọn ère ẹ̀dá-ènìyàn (figurines). Ní báyìí, bí èyí ṣe ń lọ lórí ilẹ̀ Ayé, Olódùmarè kó àwọn gáàsì (gases) jọ láti àwọn ibi tó jìnnà rẹ́rẹ́ ní òfuurufú ó sì dá ìbúgbàù kan tó yí padà di ìṣù iná (fireball). Ó tì í wá sí Ifẹ̀, níbi tó ti sọ púpọ̀ nínú ilẹ̀ náà di gbígbẹ tó sì tún ń yan àwọn ère ẹ̀dá-ènìyàn náà níná. Ní àkókò yìí ni Olódùmarè fẹ́ "èémí ìyè" jáde láti fẹ́ kọjá lórí ilẹ̀ náà, àwọn ère náà sì bẹ̀rẹ̀ sí í yípadà díẹ̀díẹ̀ di "alààyè" gẹ́gẹ́ bí àwọn ènìyàn àkọ́kọ́ ní Ifẹ̀.[25]
Nítorí èyí, àwọn ènìyàn tún máa ń pe Ifẹ̀ ní "Ifẹ̀ Ọ̀ọ̀dáyé" – "ibi tí ayé ti bẹ̀rẹ̀".[21][26]
Irúnmọlẹ̀
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Àwọn Irúnmọlẹ̀ jẹ́ àwọn ẹ̀dá àkọ́kọ́ tí Ọlọ́run rán wá láti parí àwọn iṣẹ́ tí a yàn fún wọn, wọ́n sábà máa ń ṣiṣẹ́ gẹ́gẹ́ bí alárinà láàrin Òde Ọ̀run àti Ilé Ayé.[27] Nítorí náà, a lè ṣàpèjúwe àwọn Irúnmọlẹ̀ gẹ́gẹ́ bí àwọn òrìṣà tí ipò wọn ga jùlọ; níbi tí a ti gba irúfẹ́ àwọn òrìṣà bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ bí àwọn òrìṣà pàtàkì. Àwọn Irúnmọlẹ̀ tàbí Ìmọlẹ̀ ni àwọn òrìṣà ìpìlẹ̀ àkọ́kọ́. Ní àkópọ̀, gbogbo Ìmọlẹ̀ jẹ́ Òrìṣà, ṣùgbọ́n kì í ṣe gbogbo Òrìṣà ni Ìmọlẹ̀.
Òkú
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Nínú ẹ̀sìn àti àṣà Yorùbá, Òkú jẹ́ ìmọ̀ tó díjú tó sì ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ apá tó gba onírúurú ẹ̀ka ikú, ìgbésíayé lẹ́yìn ikú, àti ìbáṣepọ̀ láàrin àwọn alààyè àti àwọn òkú. Wọ́n sábà máa ń túmọ̀ Òkú sí "the dead," ṣùgbọ́n ó gbé ìtumọ̀ tó jìn gan-an tó kọjá kíkalẹ̀ (iku) lásán.[28] Òkú ń tọ́ka sí ìyípadà ènìyàn láti inú ayé àwọn alààyè sí ayé àwọn òkú àti ìrìn-àjò tó kàn fún ẹni tí ó sùn láti lọ sí ìkọ̀lé ọ̀run.
Òkú jẹ́ apá kan ìgbésíayé ẹ̀dá, ikú sì jẹ́ ìyípadà sí ìpele tuntun ti ìwàláàyè dípò kí wọ́n kà á sí òpin patapata.[29] Àwọn Yorùbá gbàgbọ́ pé àwọn òkú ń báa nìṣó láti kópa nínú ìgbésíayé àwọn ọmọ wọn lẹ́yìn àti pé wọ́n lè nípa lórí àwọn alààyè ní onírúurú ọ̀nà.[30] Nípa bẹ́ẹ̀, Òkú tún ní í ṣe pẹ̀lú èrò "ará ọ̀run," èyí tó ń tọ́ka sí àyè ẹ̀mí tàbí ayé àwọn òkú.[31] Àwọn Yorùbá gbàgbọ́ pé àwọn òkú ń gbé nínú ayé tẹ̀mí yìí, níbi tí wọ́n ti ń gbé tí wọ́n sì ń bára wọn sọ̀rọ̀ títí kan àwọn alààyè.
Jù bẹ́ẹ̀ lọ, àfihàn Òkú lórí ilẹ̀ ayé ni Egúngún, èyí tó gbé ẹ̀mí àwọn baba-ńlá wọ̀ tí wọ́n sì sábà máa ń lò láti bá àwọn òkú sọ̀rọ̀ àti láti bọlá fún ìrántí wọn.[32] Egúngún ni àwòrán àrífojúkò àṣà Òkú lórí ilẹ̀ ayé, èyí tó pọkànpọ̀ sọ́rọ̀ fífún àwọn baba-ńlá ní ọlá àti ọ̀wọ̀.[33] Egúngún ní àwọn agbára tẹ̀mí láti bá àwọn baba-ńlá sọ̀rọ̀, pẹ̀lú àṣà Òkú ti wíwá ìbùkún àti ìdáàbòbò látọ̀dọ̀ àwọn òkú tàbí baba-ńlá.
Síbẹ̀síbẹ̀, ó yẹ kí a mọ̀ pé àṣà Egúngún kì í ṣe àfihàn Òkú nìkan, ṣùgbọ́n wọ́n ní àwọn àbùdá àti pàtàkì wọn tó dá yàtọ̀, èyí tó sinmi lórí ibi tí wọ́n ti ń yọ. Egúngún lè ní àwọn ètò, ayẹyẹ, àti àṣà tirẹ̀ tó yàtọ̀ sí ti Òkú, bótilẹ̀jẹ́pé àwọn méjèèjì bára wọn tan tímọ́tímọ́.[34] Nítorí náà, àwọn Yorùbá lè pe Egúngún ní "Òkú ará ọ̀run," tó túmọ̀ sí "Òkú ti inú ọ̀run" tàbí "Òkú àwọn ẹ̀mí." Orúkọ yìí ń tọ́ka sí ìbáṣepọ̀ tímọ́tímọ́ láàrin Egúngún àti àṣà Òkú, ó sì ṣe àfihàn ipa Egúngún gẹ́gẹ́ bí àfihàn àwọn baba-ńlá àti ibùgbé ẹ̀mí.
Àkójọpọ̀ Òrìṣà àti Ajogun
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]
Àwọn Òrìṣà, (Òrìṣà) jẹ́ àwọn ẹ̀dá tó ní agbára láti ṣàfihàn díẹ̀ nínú àwọn ohun tó ṣẹlẹ̀ látọ̀dọ̀ Olódùmarè. Ìtumọ̀ Òrìṣà Yorùbá lóòrèkóòrè (wọ́n sábà máa ń túmọ̀ rẹ̀ sí "orí àkànṣe/tí a yàn") ni pé wọ́n jẹ́ alárinà láàrin ẹ̀dá ènìyàn àti ẹ̀dá ẹ̀mí/àtọ̀runwá. Wọ́n ti túmọ̀ ọ̀rọ̀ yìí sí "Deities", "Divinities" tàbí "Gods" (Àwọn Òrìṣà/Ọlọ́run).[35] Wọ́n ń bọ̀wọ̀ fún àwọn Òrìṣà fún wíwà ní ìdarí lórí àwọn nǹkan kan gangan nínú ìṣẹ̀dá. Nítorí náà ni wọ́n tún fi ń pè wọ́n ní Ìmọlẹ̀ nígbà mìíràn. Lára wọn, àwọn kan wà tó jọ àwọn akikanjú ìtàn àtijọ́ àti/tàbí ọlọ́gbọ́n jù bí wọ́n ṣe jọ òrìṣà àkọ́bẹ̀rẹ̀ lọ.[27] A lè pe àwọn wọ̀nyí ní òrìṣà ìbílẹ̀ (dema deities). Bótilẹ̀jẹ́pé wọ́n sábà máa ń lo ọ̀rọ̀ náà Òrìṣà fún àwọn ẹ̀ka ẹ̀dá ẹ̀mí méjèèjì, èyí àkọ́kọ́ ló yẹ gan-an.[27]
Ní ọwọ́ kejì ẹ̀wẹ̀, a lè ṣàpèjúwe àwọn Ajogun gẹ́gẹ́ bí agbára búburú, olùparun tàbí agbára ìkà nínú ayé. Wọ́n wà ní ipele agbára kan náà pẹ̀lú Òrìṣà ṣùgbọ́n wọ́n ta kò wọ́n wọ́n sì ń bá Orí ẹni jà. Wọ́n ń dúró fún apá kejì nínú ìgbésíayé Yorùbá tó ń jẹ́ Ire, tó túmọ̀ sí oore tàbí kíkó ara pọ̀ pẹ̀lú kádàrá ẹni, tàbí Ibi, tó sábà máa ń túmọ̀ sí ibi tàbí wíwà níyàtọ̀ sí kádàrá ẹni.[36] Tí a bá fọ́ ọ̀rọ̀ náà Ajogun sí wẹ́wẹ́, ó wá láti ara ọ̀rọ̀; A + Jẹ + Ogun, tó túmọ̀ gbàà sí; "Ẹni tí ó ń jẹ/tí ó ń gbé orí ìyọnu/ogun". Wọ́n sábà máa ń pe Ajogun ní "àwọn jagunjagun" tó ń bá ẹ̀dá-ènìyàn jagun. Nínú wọn, àwọn Ajogun pàtàkì mẹ́jọ wà tí 'Ikú' jẹ́ aṣáájú wọn.[37]
Àwọn Yorùbá ti ṣe àkójọpọ̀ ńlá fún àwọn òrìṣà, kọ̀ọ̀kan wọn ti fẹsẹ̀múlẹ̀ nínú ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ ìlànà àti àṣà wọn. Ọ̀pọ̀ nínú àwọn wọ̀nyí ti dé ipò ti kárí-Yorùbá tí wọ́n sì mọ̀ wọ́n kárí gbogbo ilẹ̀ Yorùbá, kódà ó ti kọjá Ilẹ̀ Yorùbá wọ inú àwọn àṣà àti ìgbàgbọ́ àwọn aládùúgbò wọn, bótilẹ̀jẹ́pé wọ́n lè ní ìsopọ̀ tó lágbára tàbí tímọ́tímọ́ mọ́ àwọn àdúgbò, iṣẹ́ tàbí ẹ̀ka-ilẹ̀ kan jákèjádò ilẹ̀ Yorùbá.[38] Wọ́n sọ pé ẹgbẹẹgbẹ̀rún wọn ló wà; nínú èyí tí Irúnmọlẹ̀ jẹ́ irínwó-ó-lé-kan (401) ní àpapọ̀; Igba Ọ̀tún (200 fún ọwọ́ ọ̀tún), Igba Òsì (200 fún ọwọ́ òsì) àti ọ̀kan dín-dín (tí wọ́n fi ń ṣàpẹẹrẹ pé ènìyàn kò mọ iye wọn gangan).
Àpèjúwe àti Ìṣesí Àwọn Òrìṣà Pàtàkì
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]| Òrìṣà | Àwọn orúkọ mìíràn | Àpèjúwe àti ìṣesí (Description and attributes) | Àwòrán | Ibùgbé Ayé & ojúbo rẹ̀[39][40] |
|---|---|---|---|---|
| Orí | Orí jẹ́ Òrìṣà àkọ́kọ́ nínú ilé àti aláàbò tí gbogbo ènìyàn ń bọ ní Ilẹ̀ Yorùbá, gẹ́gẹ́ bí olùtọ́jú kádàrá. Nítorí náà, wọ́n ń bọ Orí kí ènìyàn lè ní kádàrá rere. Nígbà tí ènìyàn bá ní ìwà tó dára, yóò ní ìṣọ̀kan pẹ̀lú Orí tàbí ẹ̀mí rẹ̀. Àwòrán tí ó dúró fún Orí ni wọ́n sọ pé ó jẹ́ owó ẹyọ mọ́kànlélógójì (41) tí a tò pọ̀ bí adé, èyí tí wọ́n sábà máa ń tọ́jú sínú àpótí ńlá kan tí a ń pè ní Ilé Orí tí a fi ohun kan náà ṣe, tí ó sì tóbi tó bí ẹni tó fẹ́ ẹ ṣe lágbára láti fẹ́ ẹ tó.[41][42] | _______ | ||
| Ọ̀rúnmìlà | Àgbọnìrègún Ẹlẹ́rìí Ìpín Ẹ̀là Àjànà Òkìtìbìrí |
Àlùfáà-àgbà fún Yorùbá, ọlọ́gbọ́n àti olùtọ́jú ọ̀rọ̀ Ifá, orísun ìmọ̀ tí wọ́n gbàgbọ́ pé ó ń ṣe àkóso ìmọ̀ nípa ẹ̀dá ènìyàn, mímọ́, àwọn oògùn àrùn àti àbùkù. Àwọn Babaláwo jẹ́ ọmọ ẹ̀yìn, àlùfáà, àti aṣíwájú Ọ̀rúnmìlà. Ìmọ́lẹ̀ Ifá fúnrarẹ̀ ni a ń pè ní Ẹ̀là. Àwọn Babaláwo àti Ìyánífá máa ń pe ìmọ́lẹ̀ Ẹ̀là nígbà tí wọ́n bá ń ké pe ọ̀kùnkùn Ọ̀rúnmìlà. Ọ̀pọ̀lọpọ̀ gba Ọ̀rúnmìlà gẹ́gẹ́ bí ọ̀kan náà tàbí aṣojú Ẹ̀là, wọ́n sì sábà máa ń fọ́ orúkọ rẹ̀ sí (Ọ̀run mí Ẹ̀là) tó túmọ̀ sí; Ọ̀run tàn ìmọ́lẹ̀. Nítorí náà, Ifá, Ọ̀rúnmìlà àti Ẹ̀là, gbogbo rẹ̀ jẹ́ apá kan ìmọ́lẹ̀ àtọ̀runwá tó ń ṣí àwọn nǹkan tó farasin payá - yálà nínú ìgbà àtijọ́, ìgbà yìí tàbí ọjọ́ ọ̀la.[43] | Adó Èkìtì. (Ibùgbé) ________ Ilé Ifẹ̀. (Orísun) | |
| Èṣù (Ẹlẹ́gbáa) | Láróyè Bàrà Láàlú Ògiri Òkò Ọ̀dàrà Látọ́pa |
Wọ́n sábà máa ń ṣì í túmọ̀ sí "Èṣù" (The Devil) tàbí "Ẹlẹ́mìí Búburú", ṣùgbọ́n Èṣù kì í ṣe ìkankan nínú wọn tòótọ́. Wọ́n pè é ní "Aláwàdà/Ẹlẹ́tàn" (The Trickster), ó ń pín jamba fún àwọn tí kò bá rọni lọ́rùn tàbí tí kò rúbọ tàbí àwọn tí wọ́n pè ní ọmọ-ọwọ́ nínú ẹ̀mí. Wọ́n tún gba òun gẹ́gẹ́ bí "òjíṣẹ́ àtọ̀runwá", olùgbéèrò àkọ́kọ́ láàrin àwọn agbára búburú àti rere nínú ara, àti olùfipá-mú "òfin ìwà-láàyè" ṣẹ. Wọ́n sọ pé ó ń rànwọ́ láti fún agbára tí ó wá láti inú oògùn ewébe àti àwọn irúfẹ́ ìmọ̀-ẹ̀rọ ẹ̀mí mìíràn.
Èṣù ni Òrìṣà fún oríre, jamba àti ohun àìròtẹ́lẹ̀. Nítorí pé òun ni agbẹnusọ Ọlọ́run, ó sì mọ oríṣiríṣi èdè, Èṣù ni ó gbé ẹrù iṣẹ́ kíkó ìhìn àti ẹbọ lọ láti ọ̀dọ̀ ẹ̀dá-ènìyàn sí Ọlọ́run lókè. Ó tún gbajúmọ̀ fún agbára nínú ìbáṣepọ̀ (phallic powers) àti ìgboyà, wọ́n sọ pé Èṣù máa ń sápamọ́ sẹ́nu ọ̀nà, lópópó-ònà àti ní ìkóríta, níbi tí ó ti ń sọ oríre tàbí àgbákò di ara ìgbésíayé ẹ̀dá-ènìyàn. A mọ̀ ọ́ pẹ̀lú onírúurú orúkọ, títí kan Ẹlẹ́gbára.[44] |
Kétu, Benin.[38] (Ibùgbé) _______ Ìjẹ̀lú, Èkìtì. (Ibùgbé) | |
| Òrìṣà Oko | Àjàngele | Òrìṣà fún iṣẹ́ àgbẹ̀, pápá gbangba àti abúlé. Wọ́n mọ̀ ọ́ gẹ́gẹ́ bí ajagun sí iṣẹ́ aje, ọdẹ tó sin ajá tó sì tún ní fèrè - wọ́n yìn ín fún ìdàgbàsókè àwọn ohun eèlò iṣẹ́-àgbẹ̀. Ó jẹ mọ́ ayẹyẹ ìkórè iṣu tuntun lọ́dọọdún. Oyin ni òjíṣẹ́ rẹ̀, tí a bá sì pèsè Ẹ̀gúsí (melon) nínú èso Bara (tàkìtì) ni ẹbọ tó fẹ́ràn jùlọ.[45] Òrìṣà Oko ni wọ́n máa ń ṣàpẹẹrẹ pẹ̀lú ọ̀pá gígùn tó ní okùn Bàbà (copper) tí wọ́n wé mọ́ ẹnu rẹ̀ (Ọ̀pá Òrìṣà Oko) àti fèrè eyín erin. Ẹfun (White chalk) àti ìlẹ̀kẹ̀ ẹyọ (ilarere) ni àwọn awo ọkùnrin rẹ̀ máa ń lò.[46][47] | Ifẹ̀, Ọ̀ṣun. (Ibùgbé, Orísun) _______ | |
| Ògún | Lákáayé Aládá Méjì Ọṣìn Ìmọlẹ̀ Alágbẹ̀dẹ |
Òrìṣà irin, ogun, ìṣẹ́gun àti iṣẹ́ fífọ́-irin. Gbogbo àwọn tó ń ṣiṣẹ́ pẹ̀lú irin àti ìmọ̀-ẹ̀rọ ló ń bọ ọ́.[46][49] | Ilé Ifẹ̀, Ọ̀ṣun. (Orísun) _______ Ìrè, Èkìtì. (Ibùgbé) | |
| Bàyànni | Dàda Àjàká Báyọ̀ni |
Bàyànni tàbí Dàda-Àjàká jẹ́ arakùnrin Ṣàngó àti ọmọkùnrin Ọ̀rànmíyàn mìíràn. Ó jẹ́ Aláàfin Ọ̀yọ́ ṣáájú Ṣàngó, ó sì tún jẹ ẹ́ lẹ́yìn rẹ̀. Ó jẹ́ Òrìṣà ìbí, fún àwọn ọ̀dọ́ àti àwọn ọmọdé tí wọ́n ní irun orí tó ta kókó-kókó (Dàda) wọ́n sì sábà máa ń sopọ̀ mọ́ ọrọ̀ àti aásìkí. Gẹ́gẹ́ bí àwọn ìtàn kan, Dàda Àjàká jẹ́ arakùnrin fún Ṣàngó nítòótọ́, nígbà tí Bàyànni jẹ́ obìnrin àti arábìnrin.[50] Ṣùgbọ́n agbára àwọn ènìyàn méjèèjì yìí ti parapọ̀ di púpọ̀. Ó ní ìsopọ̀ pẹ́kípẹ́kí pẹ̀lú agbègbè Yewa/Ẹ̀gbádò, àmì rẹ̀ jẹ́ adé owó ẹyọ pẹ̀lú àwọn okùn kẹ́kẹ́kẹ́ pẹ̀lú orí rẹ̀ tó yọ ṣónṣó (Ṣónṣó Orí) tí wọ́n ń pè ní Adé Bàyànni.[51] | Ọ̀yọ́ Ilé. (Ibùgbé, Orísun) | |
| Yemọja | Àwòyó Olódò Mọjẹlẹ́wù Yemaja |
Ìyá fún Odò Ògùn tó ń ṣàn láti àwọn ìpínlẹ̀ òkè ti Ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́ (Òkè Ògùn), kọjá ní Ìpínlẹ̀ Ògùn àti ìlú Abẹ́òkúta, kí ó tó ṣàn sínú ọ̀sà Èkó (Ọ̀sà); àwọn odò kéékèèkéé àti omi rẹ̀ ni wọ́n yàsọ́tọ̀ fún Ìyẹmọjá kárí Ilẹ̀ Yorùbá; Ìyá tẹ̀mí fún Ṣàngó. Gẹ́gẹ́ bí àwọn Olórìṣà ṣe sọ, òun ni omi tó ń ṣọ́ oyún nínú abiyamo (amniotic fluid), àti ọmú tó ń fọ́mọ lọ́mú. Wọ́n gba òun gẹ́gẹ́ bí agbára ààbò fún obìnrin. Orúkọ rẹ̀ wá látara àwọn ọ̀rọ̀ náà; Yèyé-Ọmọ-Ẹja - Tó túmọ̀ sí; Ìyá àwọn ọmọ ẹja, èyí tó jẹ́ àkàwé fún àwọn odò omi tó ní ẹja nínú títí kan adágún àti òkun.[52] | Ilé Ifẹ̀, Ìpínlẹ̀ Ọ̀ṣun. (Orísun) _______ Ṣakí, Ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́. (Ibùgbé) | |
| Ọ̀ṣun | Yèyé Ládékojú Ẹ̀wùjí |
Ìyàwó kejì fún Ṣàngó, wọ́n sọ pé ó rọ̀ wọ inú odò ní Òṣogbo. Àwọn àlùfáà Yorùbá fún un ní ẹ̀bùn ìwà púpọ̀, ẹwà àti ojú-aáyan, ó ń ṣàpẹẹrẹ ẹ̀mí wíwá ìyédáńtọ́ àti ìṣípòpadà fún àwọn ènìyàn rẹ̀. Wọ́n pọ̀ ọ́ mọ́ ọ̀pọ̀lọpọ̀ agbára, pẹ̀lú agbára láti fi omi tútù woni sàn, ríranlọ́wọ́ fún ọmọ-bíbí, àti ìkápá lórí ìwà-obìnrin. Àwọn obìnrin ń bẹ̀ ẹ́ fún ọmọ-bíbí àti ìtura àwọn àrùn obìnrin. Àwọn ìtàn Yorùbá sọ pé ó fẹ́ràn àwọn ọmọdé, wọ́n sì máa ń wá ìrànlọ́wọ́ rẹ̀ tí ọmọ-ọwọ́ bá ń ṣàìsàn. Ọ̀ṣun tún gbajúmọ̀ fún ìfẹ́ tó ní sí oyin, àti pé ọ̀ni (crocodiles) ni oníṣẹ́ rẹ̀. Àwọn nǹkan tó bá Ọ̀ṣun pọ̀ ṣọ̀kàn ni; Abẹ̀bẹ̀ idẹ, Àjà idẹ (brass bells), Ìdè, Àdá idẹ, Ìkótí idẹ (brass hair pins), Ìkóódẹ (red parrot feathers) àti Òòyà idẹ.[53][54] | Ìgèdè, Èkìtì. (Ibùgbé, Orísun) _______ Ìjùmú, Kogi. (Orísun) _______ Òṣogbo, Ọ̀ṣun. (Igbo Mímọ́) | |
| Ṣàngó | Jákúta Ọba Kòso |
Òrìṣà fún àrá àti mànàmáná.[55] Wọ́n so mọ́ agbára ọkùnrin, iná, mànàmáná, òkúta, àwọn jagunjagun Ọ̀yọ́, àti òòfà. Wọ́n sọ pé ó ní agbára láti yí àwọn nǹkan lásán padà sí ohun tó mọ́ tó sì níyebíye. Òun ni Ọba Ọ̀yọ́ ní àsìkò kan nínú ìtàn rẹ̀. Ó gba orúkọ-ìnagijẹ rẹ̀ "Ọba Kòso" (The king does not hang) látara ìtàn àìkú rẹ̀. Ṣàngó ni Òrìṣà edùn-àrá, tí wọ́n sọ pé ó ṣàkóso ilẹ̀-ọba Ọ̀yọ́ àtijọ́. Wọ́n tún mọ̀ ọ́ sí Jákúta àti Ọba Kòso.[56][57] Àwọn ìyàwó rẹ̀ ni Ọya, Ọ̀ṣun àti Ọbà.[55] | Ọ̀yọ́ Ilé. (Ibùgbé) _______ Kòso, Kwara. (Ojúbo) | |
| Erinlẹ̀ | Ẹyinlẹ̀ | Ọdẹ ńlá, apẹja àti Òrìṣà omi, kò ní ìyàwó ó sì gbé ní etí Odò Erinlẹ̀. Wọ́n tún mọ̀ ọ́ fún aṣàwòtán ńlá. Àwọn ìtàn kan fi í joyè ìṣẹ̀dá àṣà kíkọ Ìjálá, ewi-ẹnu ìbílẹ̀ pẹ̀lú ọhùn ìmú (nasal twang) èyí tí àwọn ọdẹ máa ń kọ jù (tí wọ́n sì máa ń pọ̀ mọ́ Ògún) nítorí ìdánìkanwà rẹ̀.[58] Wọ́n máa ń ṣàpẹẹrẹ rẹ̀ pẹ̀lú àwọn òkúta dúdú dídán láti inú Odò Erinlẹ̀, odò kékeré kan tó ń ṣàn sínú Odò Ọ̀ṣun nítòsí Ẹdẹ, èyí tí wọ́n fi sínú ìkòkò amọ̀ tó kún fún omi. Àwọn nǹkan rẹ̀ jẹ́ ọ̀pá irin tó ní orí tàbí ẹ̀ka tó gbé ẹyẹ lórí.[59] | Àjàgbúṣì. _______ Ìlọbùú, Ọ̀ṣun. (Gbùngbùn)[38] | |
| Ọya | Ìyásàán Àràká Òrìrí |
Ìyàwó kẹta fún ẹni tí ó ti fìgbà kan jẹ́ Ọba Ọ̀yọ́ tí ń jẹ́ Ṣàngó, ó mọ̀ pé òun náà ní ìbínú gbigbona tó jọ ti Ṣàngó wọ́n sì sọ pé ó rọ̀ wọ inú Odò Ọya (River Niger). Ó jẹ́ òrìṣà afẹ́fẹ́ líle, ìjì, aláàbò ilẹ̀-òkú, ìjì-líle àti ìyípadà. Ó ní agbára láti yí padà láàrin àwòrán ènìyàn àti ẹranko ó sì ní ìsopọ̀ pẹ́kípẹ́kí pẹ̀lú ẹfọ̀n (African buffalo). Wọ́n tún pè é ní Ìyá àwọn Mẹ́sàn-án (Ìyá-èsán) nítorí ẹ̀ka mẹ́sàn-án odò náà. Nítorí agbára ara rẹ̀ àti ìwà rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí òrìṣà jagunjagun-obìnrin, wọ́n sábà máa ń ṣàpèjúwe rẹ̀ ní wíwà pẹ̀lú ọkọ rẹ̀ Ṣàngó. Òun ni Òrìṣà àtúnbí.[60] | Ìrá, Oyun, Kwara. (Ibùgbé) _______ Okọ̀rọ̀, Àjàṣẹ́, Benin. (Tẹ́ḿpìlì Ìyá Abẹsan)[61] | |
| Òsanyìn | Àrọ̀nì | Òsanyìn jẹ́ ọlọ́run ewébe tí ó lágbára jùlọ pẹ̀lú àṣẹ lórí gbogbo àwọn tó bá ewéko àti idán lò.[38] Wọ́n ṣàpẹẹrẹ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ẹlẹ́yọ-ojú, ọlọ́wọ́-kan, àti ẹlẹ́sẹ̀-kínní, ó jẹ́ Òrìṣà ewébe, ohun-ọ̀gbìn, idán, oògùn àti ìwòsàn. Wọ́n sábà máa ń ṣàpèjúwe Òsanyìn gẹ́gẹ́ bí Òrìṣà to máa ń gba àwòrán àrùn tí wọ́n ń pè é láti wòsàn tàbí ṣe òògùn rẹ̀. Ó tún ṣojú fún agbára-méjì àti ìwọ̀ntúnwọ̀nsì ẹ̀dá àti ọ̀nà-méjì agbára ewébe; 'Ohun tí ó lè mú ọ láradá tún lè ṣe ọ́ léṣè tí a bá lò ó ní ọ̀nà tí kò tọ́ tàbí tí a ṣi lò.' Ohun rẹ̀ ni Ọ̀pá Òsanyìn. Ọ̀pá yìí jẹ́ ohun ìyíká àwọn ẹyẹ kékeré àti igi kan láàrin tó gbé ẹyẹ ńlá kan sókè ju àwọn kékeré lọ.[62] | Ìsaba, Ìkọ̀lé, Ìpínlẹ̀ Èkìtì. (Ibùgbé, Orísun). | |
| Ọbalúayé | Ṣọ̀pọ̀ná Babalú Ayé Ọmọlú Olóde Sapata |
Itumọ̀ rẹ̀ ni "Ọba ayé" àti òrìṣà tí gbogbo ayé bẹ̀rù púpọ̀, wọ́n tún mọ̀ ọ́ sí Ṣọ̀pọ̀ná, Ọmọlú tàbí Sapata, Òrìṣà tí ó ni àrùn àti àìsàn. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ó ní agbára láti fi Ṣọ̀pọ̀ná (smallpox), Ẹ̀tẹ̀, Ikọ́-ẹ̀gbẹ (Tuberculosis) àti àwọn àrùn tí ń ràn kálẹ̀ jẹni-níyà, wọ́n tún so ó mọ́ mímú àradá bá àwọn tí ń ṣàìsàn rẹ̀. Ní ìbẹ̀rẹ̀ ọ̀rúndún ogún (1917), Ìjọba Amúnisìn ilẹ̀ Gẹ̀ẹ́sì ní Nàìjíríà fi òfin de Ọbalúayé nítorí pé wọ́n rò pé àwọn olùfọkànsìn rẹ̀ ń mọ̀ọ́mọ̀ tan Ṣọ̀pọ̀ná kálẹ̀. Àwọn òǹkọ̀wé lẹ́yìn náà kò fara mọ́ àwọn èrò / àbá ti tẹ́lẹ̀ wọ̀nyí.
Àwọn awo Ṣọ̀pọ̀ná máa ń dènà títànkálẹ̀ àwọn àrùn tí ń ràn kálẹ̀ nípa jíjẹ́ ẹni tó ń rí sí yíyọ àwọn òkú àti ohun-ìní àwọn tó kú nítorí rẹ̀ kúrò. Àwọn awo Ṣọ̀pọ̀ná dàbí ẹni pé wọ́n mọ̀ nípa ààbò àti ewu kòkòrò àrùn náà, wọ́n sì sábà máa ń fọ́ àwọn ènìyàn lábẹ́rẹ́ fún àrùn náà pẹ̀lú gbígbẹ́ awọ-ara.[63] |
||
| Yewá | Yeruwa Ìyáwá Ìyẹwá |
Òrìṣà fún Odò Yewa tí a so mọ́ ibojì, ìmọ́lẹ̀, ẹwà, àlá àti idán. Ó ń gbé nínú ibojì pẹ̀lú Ọbà àti Ọya. Ó ń mú ẹ̀mí tọ arábìnrin rẹ̀ Ọya wá èyí tó túmọ̀ sí pé òun ni olùbẹ̀rẹ̀ fún gbogbo ìyípadà tó bá ń ṣẹlẹ̀. Ọ̀rọ̀ tàbí ariwo kò jẹ́ ohun gbigba ní tòsí àwọn ibi ìjọsìn rẹ̀. Ìtàn (pataki) tún wà nípa bí òrìṣà yìí ṣe lo ọgbọ́n láti tan Ikú fúnra rẹ̀. Bákan náà, wọn kò gbọdọ̀ bọ Yewá ní tòsí Ṣàngó gẹ́gẹ́ bí àwọn ìtàn (pataki) ti sọ pé ó ṣe ìwà-ipá ìbálòpọ̀ sí i. Yewá tún wà fún kíkẹ́ ẹ̀dá-ènìyàn pẹ̀lú àlá àti ìrònú.[64] Orúkọ rẹ̀ 'Ìyẹ́ wá' tàbí 'Ìyá wá' túmọ̀ sí 'Ìyá Wa.[38] | Ado-Odo, Ìpínlẹ̀ Ògùn. (Ìsopọ̀) | |
| Ọbàtálá | Òrìṣàlá Òṣàlúfọ́n Òṣàgìrìyàn Olúwa Ayé Oṣẹ̀rẹ̀màgbó |
A tún mọ̀ ọ́ sí Òrìṣà-ńlá/Òòṣàlá, tó túmọ̀ sí "Òrìṣà ńlá," àti Òrìṣà Funfun. A tún mọ̀ ọ́ sí Baba-Ọ̀run (Skyfather). Wọ́n sábà máa ń fi í wé mímọ́ (purity), a sì máa ń ṣàpẹẹrẹ rẹ̀ pẹ̀lú "Alá," tàbí aṣọ funfun, àti "Ẹfun," (white chalk). Ọ̀pọ̀lọpọ̀ nǹkan tí wọ́n fi ń dá Ọbàtálá mọ̀ sábà máa ń jẹ́ funfun tàbí báláú. Wọ́n kà á sí Ẹlẹ́dàá Ayé àti ẹni tó ń mọ àwòrán ẹ̀dá-ènìyàn pẹ̀lú amọ̀. A tún mọ̀ ọ́ gẹ́gẹ́ bí aláàbò fún àwọn tó ní àbùkù-ara. Ìyàwó rẹ̀ tó fẹ́ràn jùlọ ni Yemòwó (Yèyé Mowò). Ní ibùgbé rẹ̀ ní Ifọ́n, a mọ̀ ọ́ sí orúkọ Òṣàlúfọ́n, nígbà tí ó ń jẹ́ Òṣàgìyán/Òṣàgìrìyàn ní Èjìgbò, èyí jẹ́ aṣojú Ọbàtálá méjì tó gbajúmọ̀. Ẹbọ rẹ̀ ni Ìgbín ilẹ̀ Áfíríkà.[65][66] | Òde Ìrànjé (Ìdẹ̀ta), Ifẹ̀. (Orísun, Ibùgbé) _______ Ifọ́n, Ọ̀ṣun. (Ìsopọ̀) _______ Èjìgbò, Ọ̀ṣun. (Ìsopọ̀) | |
| Aganjù | Aganjùṣọlá | Pẹ̀lú ìtumọ̀ rẹ̀, "òkùnkùn aginjù," Aganjù ní ìbátan tímọ́tímọ́ pẹ̀lú Ṣàngó a sì kà á sí Òrìṣà aginjù, aṣálẹ̀, òkè iná (volcanoes), àti ihà. Ní ìpilẹ̀ṣẹ̀, ó jẹ́ ọba ilẹ̀-ọba Ọ̀yọ́ (Ẹ wo; Aláàfin Aganjù ṣọlá) kí ó tó sọ di òrìṣà lẹ́yìn ikú rẹ̀. Òun ni aláàbò fún ìrìn-àjò jíjìn, wọ́n sọ pé ó máa ń rìn pẹ̀lú idà ní àwọn ìrìn-kèsekèse bí ẹni pé ó ń bẹ lórí ohun-ìdènà, a sì mọ̀ ọ́ pé ó ń jà nípa yíyọ iná, ní ìyàtọ̀ sí Ṣàngó tí ó ń jà pẹ̀lú mànàmáná nígbà tí ó ń ju ẹdùn àrá. Ohun rẹ̀ ni àáké-olóyú-méjì (double axe) tó jọ ti Ṣàngó ṣùgbọ́n tí ó ní ọ̀pá gígùn jùlọ.[67] | Ọ̀yọ́ Ilé. (Ibùgbé) | |
| Ọ̀ṣọ́ọ̀sì | Ọ̀ṣọ́wùsì Ọdẹ Mẹ́ta |
Òun ni Òrìṣà ìrìn-àjò-akíkanjú, iṣẹ́ ọdẹ àti igbó, ó sì tún jẹ́ aláàbò míràn fún àwọn ọdẹ. Òun ni ògbóǹtarìgì tafàtafà (Wọ́n pè é ní 'tafàtafà àwọn Òrìṣà') wọ́n sì máa ń ṣàpèjúwe rẹ̀ ní gbogbo ìgbà pé ó di ọrun àti ọfà pẹ̀lú àpò (Apó). Agbára rẹ̀ máa ń farahàn nínú ìyára àti isọ́yẹ ọfà rẹ̀ pẹ̀lú ìgbéraga rẹ̀ nínú ìyára ọpọlọ àti ara rẹ̀. Ohun rẹ̀ jẹ́ ọrun ọfà idẹ (Ọrún) pẹ̀lú okùn owó-ẹyọ tí ó ṣọ̀ láti ara rẹ̀, àti ìkòkò irin kéékèèkéé tí ó kún fún àwọn ọfà kékeré (Ọfà)[68] | Ìdó. | |
| Olókun | Malòkun Ṣẹ̀níadé |
Agbára ìwáṣẹ̀ kan tí ó ti wà ní ìbẹ̀rẹ̀ ìṣẹ̀dá, Olókun, tó túmọ̀ sí "Olóhun òkun" jẹ́ ẹni tí a tún mọ̀ sí Ìmọlẹ̀ Òkun. Olókun ti wà láti ìbẹ̀rẹ̀ ìṣẹ̀dá gẹ́gẹ́ bí Òrìṣà abẹ̀yà-méjì tó ń ṣàkóso ìbú òkun àti gbogbo omi orí ilẹ̀ kí Ọbàtálá tó wá dá ilẹ̀ gbígbẹ. Àwọn ni òbí fún Òrìṣà Ajé àti Ọlọ́sà wọ́n sì ṣàpẹẹrẹ ọrọ̀, ìwòsàn, àti gbígbòòrò òkun.[69][70][71] | Ilé Ifẹ̀, Ọ̀ṣun. (Orísun, Ibùgbé) | |
| Ajé | Ṣàlùgá Ògúgúlùso |
Kí a má ṣe gbé èyí dọ́ti Ìyàmi Àjẹ́, wọ́n tún ń pè é ní Ajé Ṣàlùgá. Ajé ni àpẹẹrẹ àti òrìṣà ọrọ̀ àti àṣeyọrí nínú ọrọ̀-ajé. Ó tún jẹ́ aláàbò fún àwọn oníṣòwò, oníṣẹ́-ajé, àti àwọn ọjà. Ọ̀rọ̀ Yorùbá fún ọjọ́ ajé (Monday), wọ́n ń pè é ní Ajé nítorí pé ó sábà máa ń jẹ́ ọjọ́ àkọ́kọ́ nínú ọ̀sẹ̀ tí àwọn ọjà máa ń ṣí.[72] | ||
| Odùduwà | Ọlọ́fin Àdìmúlà Ọṣìn Ọ̀rà Ọlọ́fin Ayé |
A gba Odùduwà gẹ́gẹ́ bí olùdásílẹ̀ àwọn Yorùbá àti Ọba Ifẹ̀ àkọ́kọ́, a tún so ó mọ́ òrìṣà ìṣẹ̀dá abẹ̀yà-méjì kan. Ọ̀pọ̀lọpọ̀ Yorùbá, àti pàápàá jùlọ àwọn ọba wọn, polongo pé a tẹ̀ wá láti ara Odùduwà. Òun ni baba tàbí baba-ńlá fún Ọ̀rànmíyàn, Ṣàngó, Àjàká, Ọbàlùfọ̀n, àti àwọn Ọba Ifẹ̀ mìíràn. Wọ́n tún kà á sí baba-ńlá fún àwọn Ọba Ilẹ̀-Ọba Benin. Ó jẹ́ Òrìṣà ilẹ̀ ayé àti olùdásílẹ̀ ẹgbẹ́ Ògbóni èyí tó bẹ̀rẹ̀ láti ìlú mímọ́ Ifẹ̀ tí wọ́n sì gbé ojúṣe títọ́jú ètò àwùjọ lé wọn lọ́wọ́.[73][74] | Òkè Ọ̀rà. (Orísun, Ibùgbé) _______ Ilé Ifẹ̀. (Ibùgbé) | |
| Ọbà | Ibú | Ìyàwó àkọ́kọ́ àti ẹni-àgbà fún Ṣàngó, òun ni Òrìṣà fún Odò Ọbà, òun tún ni Òrìṣà ìdílé, agbára, ìrìn, àti ìṣàn àkókò àti ìyè. Wọ́n mọ̀ ọ́ jùlọ fún bí àwọn ìyàwó Ṣàngó tókù ṣe tàn án láti rẹ́ etí rẹ̀ kí ó sì fi jẹ́ ọkọ rẹ̀ Ṣàngó.[13] Gẹ́gẹ́ bí apá kan nínú àwọn obìnrin mẹ́ta tó sún mọ́ Ṣàngó, wọ́n fi wé kurukuru tí ń wá pẹ̀lú gbogbo ìjì-líle.[38] |
Ipa rẹ̀
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Ẹ̀sìn àwọn ọmọ Áfíríkà lókè-òkun
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Gẹ́gẹ́ bí Ọ̀jọ̀gbọ́n Adams Abdullahi Suberu ti sọ, àwọn Yorùbá jẹ́ ọlọ́gbọ́n-ìlú ti wọ́n tàn káàkiri gbogbo àgbáyé láìní ìrírí ti tẹ́lẹ̀;[75] fífẹ̀ àṣà wọn yá dá lórí ìṣíípòpadà—ìṣíípòpadà tó ṣẹṣẹ ṣẹlẹ̀ nípa ti òwò-ẹrú lókè-òkun, àti pẹ̀lú rírí àwọn Yorùbá ilẹ̀ Nàìjíríà àti Benin ṣí kúrò lọ sí orílẹ̀-èdè Amẹ́ríkà, UK, Brazil, àti àwọn orílẹ̀-èdè mìíràn ní ayé àti Yúróòpù. Lásìkò ṣáájú ìmúnisìn (pre-colonial period), ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn Yorùbá ni wọ́n mú lẹ́rú tí wọ́n sì tà sínú òwò-ẹrú wọ́n sì gbé wọn lọ sí Argentina, Brazil, Cuba, Colombia, Dominican Republic, Puerto Rico, Trinidad and Tobago, St. Vincent & The Grenadines, Uruguay, Venezuela, àti àwọn apá mìíràn. Wọ́n gbé ìgbàgbọ́ ẹ̀sìn wọn dání. Èrò yìí papọ̀ sínú ohun tí ó wá di apá pàtàkì nínú "New World lineages" èyí tí ó jẹ́ oríṣiríṣi àwọn ẹ̀sìn Áfíríkà tòde òní tó ṣẹ̀ wá láti ara Yorùbá:[75][76][77]
- Candomblé (Brazil, Argentina, Uruguay)
- Santería (Cuba, Puerto Rico, Dominican Republic)
- Trinidad Orisha (Trinidad and Tobago)
- Venezuelan spiritism (Venezuela)
- Spiritual Baptist (St. Vincent & The Grenadines)
- Umbanda (Brazil, Argentina, Uruguay)
Ní ọdún 1989, wọ́n gbàgbọ́ pé àwọn tó lé ní àádọ́rin mílíọ̀nù (70 million) kárí Áfíríkà àti New World ló ń kópa nínú ẹ̀sìn Yorùbá ní onírúurú ọ̀nà.[78]
Ìgbàgbọ́ Vodun, èyí tó ṣẹ̀wá látàrí ẹ̀yà mìíràn (àwọn ènìyàn tó ń sọ èdè Gbe ní Benin, Togo, àti Ghana tòde-òní), ní àwọn kókó tó ní ipa lórí àwọn ọmọ Áfíríkà lókè-òkun nínú àwọn orílẹ̀-èdè bíi Haiti àti Cuba, bẹ́ẹ̀ náà ni ní New Orleans, Louisiana nínú Amẹ́ríkà.[79]
Ní Gúúsù Amẹ́ríkà, ẹ̀sìn Yorùbá ti wà nínú ìmúkòópọ̀ ẹ̀sìn tí ó lágbára pẹ̀lú ẹ̀sìn Kìrìstẹ́nì, ẹ̀sìn ìbílẹ̀, àti Spiritism láti ìgbà àwọn àlejò Áfíríkà àkọ́kọ́. Ní Brazil, ẹ̀sìn Umbanda wáyé látara ìbáṣepọ̀ tó gbòòrò nínú àwọn ìgbàgbọ́ tí Gúúsù Amẹ́ríkà pèsè. Àwọn ẹlẹ́sìn Umbanda sábà máa ń ka ara wọn sí ẹlẹ́sìn-ọlọ́run-kan (Monotheistic), ṣùgbọ́n wọ́n ń bọlá fún àwọn ẹni mímọ́ Kátólíìkì àti Òrìṣà gẹ́gẹ́ bí àfihàn látọ̀dọ̀ Ọlọ́run tàbí gẹ́gẹ́ bí òrìṣà aláàbò. Ìjọsìn Umbanda tún fàyè gba àwọn ohun inú àṣà àwọn ọmọ ìbílẹ̀ Gúúsù Amẹ́ríkà bíi lílo Tábà fún ayẹyẹ àti ìbáraẹnisọ̀rọ̀ pẹ̀lú àwọn ẹ̀mí jagunjagun Ìńdíà tó ti kú (Caboclo).[80]
Nínú fídíò àkọsílẹ̀ ti ọdún 1949 Fiestas de Santiago Apóstol en Loíza Aldea, onímọ̀ nípa ẹ̀dá-ènìyàn Ricardo Alegría ṣe àkíyèsí irúfẹ́ àṣà yìí ní Loíza, Puerto Rico, ó sọ pé ìsopọ̀ tó wà láàrin àwọn ènìyàn aláwọ̀ dúdú ní agbègbè náà àti ẹni mímọ́ Kátólíìkì Santiago Apóstol lè jẹyọ látara bí wọ́n ṣe ń ṣàpèjúwe rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí jagunjagun; kókó kan tó jọ díẹ̀ nínú àwọn àpèjúwe Ṣàngó àti Aganjù.[81] Èrò yìí ṣàbá pé wọ́n lo ìjọra yìí láti ọwọ́ àwọn ènìyàn gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà bòókẹ́lẹ́ láti bọlá fún òrìṣà baba-ńlá wọn.[81]
Ní ìbẹ̀rẹ̀ ọ̀rúndún kọkànlélógún (21st century), àwọn aṣíwájó Nàìjíríà tún ti mú ẹ̀sìn Yorùbá lọ sí Brazil.[82]
Japan
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Koshikawa Yoshiaki, ọ̀jọ̀gbọ́n fún lítíréṣọ̀ ní Meiji University, ló di ọmọ orílẹ̀-èdè Japan àkọ́kọ́ tí wọ́n dá kọ láti di Babaláwo ní ọdún 2013.[83]
Àwọn Ìtọ́kasí
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Àlàyé Ìsàlẹ̀-ìwé
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]- ↑ "Celebrating Isese: Unraveling the Rich Tapestry of Yoruba Heritage and Spirituality PART 1".
- ↑ "Yoruba Religion: History, Beliefs & Facts".
- ↑ "Performing Religious Worship: Discussion around Isese and other religious practice among the Yoruba of West Africa".
- ↑ Ogundiran, A. (2024, October 23). Yorùbá Indigenous Religion. Oxford Research Encyclopedia of African History. Retrieved 19 Jan. 2026, from https://oxfordre.com/africanhistory/view/10.1093/acrefore/9780190277734.001.0001/acrefore-9780190277734-e-1556.
- ↑ Ogundiran, Akinwumi (15 January 2025). "Nigeria’s Ọ̀ṣun Òṣogbo festival celebrates the power of a Yoruba goddess". The Conversation. Retrieved 6 February 2025.
- 1 2 3 Abimbola, Kola (2005). Yoruba Culture: A Philosophical Account (Paperback ed.). Iroko Academics Publishers. ISBN 1-905388-00-4.
- ↑ Oyeyemi Oyekan. (2024, May 01). Yorùbá Traditional Religion. Database of Religious History, Vancouver, BC: University of British Columbia. Retrieved June 27, 2024, from https://doi.org/10.5281/zenodo.12574758
- 1 2 3 Ọlabimtan, Afọlabi (1973). Àyànmọ. Lagos, Nigeria: Macmillan. OCLC 33249752.
- 1 2 Yancy, George (2021-02-14). "Opinion | Death Has Many Names" (in en-US). The New York Times. ISSN 0362-4331. https://www.nytimes.com/2021/02/14/opinion/Yoruba-religion-death.html.
- 1 2 3 Olupona, Jacob K. (1993-01-01). "The Study of Yoruba Religious Tradition in Historical Perspective" (in en). Numen 40 (3): 240–273. doi:10.1163/156852793X00176. ISSN 1568-5276. https://brill.com/view/journals/nu/40/3/article-p240_2.xml.
- 1 2 3 Ọlabimtan, Afọlabi (1991). Yoruba Religion and Medicine in Ibadan. Translated by George E. Simpson. Ibadan University Press. ISBN 978-121-068-0. OCLC 33249752.
- 1 2 Omobola, Odejobi. "Influence of Yoruba Culture in Christian Religious Worship". International J. Soc. Sci. & Education 4: 586.
- 1 2 Bascom, William (2017). "Yoruba Concepts of the Soul". Men and Cultures. pp. 401–410. doi:10.9783/9781512819526-065. ISBN 978-1-5128-1952-6.
- ↑ Olajubu, Oyeronke (2004). "Seeing through a Woman's Eye: Yoruba Religious Tradition and Gender Relations". Journal of Feminist Studies in Religion 20 (1): 41–60. ISSN 8755-4178. https://www.jstor.org/stable/25002489.
- ↑ Olajubu, Oyeronke (2003). Women in the Yoruba Religious Sphere. State University of New York Press. ISBN 978-0-7914-8611-5. https://doi.org/10.1353/book4731.
- ↑ Olajubu, Oyeronke (2004). "Seeing through a Woman's Eye: Yoruba Religious Tradition and Gender Relations". Journal of Feminist Studies in Religion 20 (1): 41–60. ISSN 8755-4178. https://www.jstor.org/stable/25002489.
- ↑ Oládémọ, Oyèrónké (2022-07-15). Women in Yoruba Religions. New York University Press. ISBN 978-1-4798-1402-2. https://doi.org/10.18574/nyu/9781479814022.001.0001.
- ↑ Voeks 1997, p. 160.
- 1 2 3 "What Is Ifa?". THE IFA INSTITUTE (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). Archived from the original on 5 August 2025. Retrieved 2024-09-30.
- ↑ Awo, Ifagbemi (2024) (in English). The Yoruba Spiritual Training Manual (First ed.). United States: Michael Perez. pp. 24-25. ISBN 979-8990901810. https://www.google.com/books/edition/The_Yoruba_Spiritual_Training_Manual_The/_5o3EQAAQBAJ?hl=en&gbpv=1.
- 1 2 3 Bolaji Idowu (1982). Olódùmarè: God in Yorùbá Belief. Ikeja, Nigeria: Longman. ISBN 0-582-60803-1.
- ↑ Ifaloju (February 2011). "Odù-Ifá Iwòrì Méjì; Ifá speaks on Righteousness". Ifa Speaks... S.S. Popoola, Ifa Dida, Library, INC. Retrieved 8 April 2012.
- ↑ Opoku, Kofi Asare (1993), "African traditional religion: An enduring heritage", Religious Plurality in Africa, DE GRUYTER, ISBN 978-3-11-085007-9, doi:10.1515/9783110850079.67
- ↑ Halliday, William D. (2018-09-08). ""Half-Earth: Our Planet's Fight for Life" by Edward O. Wilson, 2017. [book review]". The Canadian Field-Naturalist 132 (1): 78. doi:10.22621/cfn.v132i1.2129. ISSN 0008-3550.
- 1 2 "Yoruba Creation". Yoruba. Oxford University Press. 1994. ISBN 978-0-19-510275-8. http://www.oxfordreference.com/abstract/10.1093/acref/9780195102758.001.0001/acref-9780195102758-e-319?rskey=hcxXT3&result=309. Retrieved 2010-04-30.
- ↑ Leeming & Leeming 2009 – entry "Yoruba Creation". Yoruba. Oxford University Press. 1994. ISBN 978-0-19-510275-8. http://www.oxfordreference.com/abstract/10.1093/acref/9780195102758.001.0001/acref-9780195102758-e-319?rskey=hcxXT3&result=309. Retrieved 2010-04-30.
- 1 2 3 J. Olumide Lucas, The Religion of the Yorubas, Athelia Henrietta PR, 1996. ISBN 0-9638787-8-6
- ↑ Oripeloye, Henri; Omigbule, Morufu Bukola (2019). "The Yoruba of Nigeria and the ontology of death and burial.". Death Across Cultures: Death and Dying in Non-Western Cultures: 193-205.
- ↑ Awe, Solomon Kolawole (2019). "Existentialist Concerns in Africa: The Yorùbá Perspectives of Death and Suicide.". Language, Literature and Culture 2.2: 41-48.
- ↑ Oripeloye, Henri; Omigbule, Morufu Bukola (2019). "The Yoruba of Nigeria and the ontology of death and burial.". Death Across Cultures: Death and Dying in Non-Western Cultures: 193-205.
- ↑ Famule, Olawole Francis (2005). Art and Spirituality: The Ijumu Northeastern-Yoruba Egúngún.. The University of Arizona. p. 64.
- ↑ Lawal, Babatunde (2001). "Aworan: representing the self and its metaphysical other in Yoruba art.". The Art Bulletin 83.3: 498-526.
- ↑ Adepegba, C.O. (1984). . Yoruba Egungun: Its association with ancestors and the typology of Yoruba masquerades by its costume. Ibadan, Nigeria: University of Ibadan.
- ↑ Famule, Olawole Francis (2005). Art and Spirituality: The Ijumu Northeastern-Yoruba Egúngún.. The University of Arizona. p. 64.
- ↑ The Concept of God: The People of Yoruba Archived 11 July 2020 at the Wayback Machine. for the acceptability of the translation
- ↑ Awo, Ifagbemi (2024) (in English). The Yoruba Spiritual Training Manual (First ed.). United States: Michael Perez. pp. 24-25. ISBN 979-8990901810. https://www.google.com/books/edition/The_Yoruba_Spiritual_Training_Manual_The/_5o3EQAAQBAJ?hl=en&gbpv=1.
- ↑ Ogunnaike, Oludamini (26 October 2020) (in en). Deep Knowledge: Ways of Knowing in Sufism and Ifa, Two West African Intellectual Traditions. Penn State Press. ISBN 978-0-271-08763-4. https://books.google.com/books?id=FJ6YEAAAQBAJ&dq=ajogun&pg=PA212. Retrieved 22 September 2024.
- 1 2 3 4 5 6 7 McKenzie 2023.
- ↑ Alabi, Adetayo (19 August 2021) (in en). Oral Forms of Nigerian Autobiography and Life Stories. Routledge. ISBN 978-1-000-42886-5. https://books.google.com/books?id=Rlw1EAAAQBAJ&dq=esu+ijelu&pg=PT46. Retrieved 27 July 2023.
- ↑ Origunwa, Obafemi (20 May 2015) (in en). Fundamentals of Òrìsà Lifestyle. Lulu.com. p. 127. ISBN 978-1-329-15169-7. https://books.google.com/books?id=MSzRCQAAQBAJ&dq=osun+ijumu&pg=PA127. Retrieved 27 July 2023.
- ↑ Gbadegesin, Segun (1991). African philosophy: Traditional Yoruba philosophy and contemporary African realities. New York: Peter Lang. pp. 27–59.
- ↑ Camara, Louis (1996). Le choix de l'Ori: conte. Saint-Louis, Senegal: Xamal.
- ↑ Kumari, Ayele (23 June 2020) (in en). Isese Spirituality Workbook. Ayele Kumari. p. 61. https://books.google.com/books?id=7pPsDwAAQBAJ&dq=orunmila+okiribiti&pg=PA61. Retrieved 22 September 2023.
- ↑ Courlander, Harold (March 1973). Tales of Yoruba Gods and Heroes. Crown Pub. ISBN 978-0517500637. https://archive.org/details/talesofyorubagod00cour.
- ↑ Olupona, Jacob Kẹhinde; Rey, Terry (2008) (in en). Òrìşà Devotion as World Religion: The Globalization of Yorùbá Religious Culture. Univ of Wisconsin Press. ISBN 978-0-299-22464-6. https://books.google.com/books?id=QlW3ZMxrCKMC&dq=ajangele&pg=PA114. Retrieved 27 September 2024.
- 1 2 Adeoye, C. L. (1989). Ìgbàgbọ́ àti ẹ̀sìn Yorùbá. Ibadan, Nigeria: Evans Bros. Nigeria Publishers. pp. 270–279. ISBN 9781675098.
- ↑ Prandi, Reginaldo (2017). Aimó: Uma viagem pelo mundo dos orixás. Editora Seguinte. p. 200. ISBN 978-8543809670.
- ↑ Olupona, Jacob Kẹhinde; Rey, Terry (2008) (in en). Òrìşà Devotion as World Religion: The Globalization of Yorùbá Religious Culture. Univ of Wisconsin Press. p. 115. ISBN 978-0-299-22464-6. https://books.google.com/books?id=QlW3ZMxrCKMC&dq=Obatala+iranje&pg=PA115. Retrieved 20 September 2023.
- ↑ Barnes, Sandra (1997). Africa's Ogun: Old World and New. Bloomington, Indiana: Indiana University Press. ISBN 0253-332516.
- ↑ PhD, Patricia Monaghan (1 April 2014) (in en). Encyclopedia of Goddesses and Heroines. New World Library. p. 6. ISBN 978-1-60868-218-8. https://books.google.com/books?id=Cj5OAwAAQBAJ&dq=bayanni+orisha&pg=PA6. Retrieved 14 October 2023.
- ↑ "X77.903 Ade Bayanni (cowrie crown) | Fowler Museum at UCLA". Fowler museum at UCLA. Retrieved 14 October 2023.
- ↑ M. Smith, Omari Tunkara. "Manipulating the Sacred, Yoruba Art, Ritual and Resistance in Brazilian Candomble" (PDF). iu.edu. Archived from the original (PDF) on 28 July 2023. Retrieved 28 July 2023. Unknown parameter
|url-status=ignored (help) - ↑ Monaghan, Monaghan (2014). Encyclopedia of Goddesses and Heroines. New World Library. p. 15. ISBN 9781608682188.
- ↑ Murrell, Nathaniel Samuel (2009). Afro-Caribbean Religions: An Introduction to Their Historical, Cultural, and Sacred Traditions. Temple University Press. ISBN 9781439901755. https://books.google.com/books?id=9h5KDRfZ-JgC&pg=PA35.
- 1 2 Simpson, George Eaton (December 1962). "The Shango Cult in Nigeria and in Trinidad". American Anthropologist 64 (6): 1205. doi:10.1525/aa.1962.64.6.02a00050. JSTOR 667846. https://www.jstor.org/stable/667846. Retrieved 17 June 2024.
- ↑ Ojebodé, Ayokúnmi O. (2023). "Eulogizing the Big Man: Murals as Royal Art in Ọ̀yó Aláàfin Palace". Delos 38 (1): 1–119.
- ↑ Thieme, Darius L. (1969). A descriptive catalogue of Yoruba musical instruments. The Catholic University of America.
- ↑ Barnes, Sandra T. (22 June 1997) (in en). Africa's Ogun: Old World and New. Indiana University Press. p. 148. ISBN 978-0-253-11381-8. https://books.google.com/books?id=5UwAAQAAQBAJ&dq=erinle+ajagbusi&pg=PA148. Retrieved 27 July 2023.
- ↑ Drewal, Henry John; Pemberton, John; Abiodun, Rowland; Wardwell, Allen (1989). Yoruba: nine centuries of African art and thought. Center for African Art. ISBN 978-0-8109-1794-1. https://www.amherst.edu/system/files/media/1627/Reduced%2520Yoruba_9_Centuries_Chap_6_part_2.pdf.
- ↑ Washington, Teresa N. (2014). The architects of existence: Aje in Yoruba cosmology, ontology, and orature.. Oya's Tornado.
- ↑ Verger, Pierre (1970). "Notes sur le culte des Orisa et Vodun à Bahia: la Baie de tous les saints au Brésil et à l'ancienne Côte des esclaves en Afrique" (in Èdè Faransé). IFAN. Retrieved 22 August 2023.
- ↑ Adeoye, C. L. (1989) (in Yoruba). Ìgbàgbọ́ àti ẹ̀sìn Yorùba. Ibadan: Evans Bros. Nigeria Publishers. pp. 214–219. ISBN 9781675098.
- ↑ Parrinder, Geoffrey (17 September 2014) (in en). West African Religion: A Study of the Beliefs and Practices of Akan, Ewe, Yoruba, Ibo, and Kindred Peoples. Wipf and Stock Publishers. p. 44. ISBN 978-1-4982-0492-7. https://books.google.com/books?id=UAOQBAAAQBAJ&dq=shopona+four+principal+deities+with+his+own+sacred+day&pg=PA41. Retrieved 24 September 2024.
- ↑ Curto, José C., ed (2005). "R. Yewa". Africa and the Americas: Interconnections during the Slave Trade. Africa World Press.
- ↑ Probst, Peter (2011). Osogbo and the Art of Heritage. Bloomington: Indiana University Press. p. 17. ISBN 978-0-253-22295-4.
- ↑ Lynch, Patricia Ann (2004). African mythology A to Z. Mythology A to Z (1st ed.). New York: Facts on file. pp. 84-85. ISBN 978-0-8160-4892-2.
- ↑ Pinn, Anthony (2000). "Orisha Worship in the United States". Down by the Riverside: Readings in African American religion. New York University Press. pp. 243–255.
- ↑ Thompson, Robert Farris (26 May 2010) (in en). Flash of the Spirit: African & Afro-American Art & Philosophy. Knopf Doubleday Publishing Group. p. 57. ISBN 978-0-307-87433-7. https://books.google.com/books?id=DzOIY4iHSjAC&dq=osanyin&pg=PA42. Retrieved 18 September 2023.
- ↑ Harvey, Marcus (2015). "Engaging the Orisa: An Exploration of the Yoruba Concepts of Ibeji and Olokun as Theoretical Principles in Black Theology". Black Theology 6 (1): 61–82. doi:10.1558/blth2008v6i1.61. ISSN 1476-9948.
- ↑ Adeoye, C. L. (1989) (in yo). Ìgbàgbọ́ àti ẹ̀sìn Yorùba. Ibadan: Evans Bros. Nigeria Publishers. pp. 227–236. ISBN 9781675098.
- ↑ Clark, Mary Ann (2007). Santería : correcting the myths and uncovering the realities of a growing religion. Westport, Conn.: Praeger Publishers. pp. 62. ISBN 978-0-275-99079-4.
- ↑ Verger, Pierre Fatumbi (1985). Orixás. Salvador, Bahia, Brazil: Corrupio.
- ↑ Nwanyanwu, O. J.; Opajobi, Bola; Olayinka, Sola (1997) (in en). Education for Socio-economic & Political Development in Nigeria. Visual Resources. p. 159. ISBN 978-978-34467-0-0. https://books.google.com/books?id=99tCAQAAIAAJ&q=oke+ora+ife. Retrieved 1 May 2024.
- ↑ Law, R. C. C. (1973). "The Heritage of Oduduwa: Traditional History and Political Propaganda among the Yoruba". The Journal of African History 14 (2): 207–222. doi:10.1017/S0021853700012524. ISSN 0021-8537. JSTOR 180445.
- 1 2 Akintoye, Prof S. A. (2010). A history of the Yoruba people. Amalion Publishing. ISBN 978-2-35926-005-2. Àdàkọ:ASIN.
- ↑ Brown (Ph.D.), David H. (2003). Santería Enthroned: Innovation in an Afro-Cuban Religion. University of Chicago Press. ISBN 0-226-07610-5.
- ↑ Karade, Baba Ifa (1994). The Handbook of Yoruba Religious Concepts. York Beach, New York: Weiser Books. ISBN 0-87728-789-9.
- ↑ Mark, Joshua J. "Orisha". World History Encyclopedia (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). Retrieved 2022-12-11.
- ↑ Fandrich, Ina J. (2007). "Yorùbá Influences on Haitian Vodou and New Orleans Voodoo". Journal of Black Studies 37 (5 (May)): 775–791. doi:10.1177/0021934705280410. JSTOR 40034365.
- ↑ Engler, Steven (2012). "Umbanda and Africa.". Nova Religio: The Journal of Alternative and Emergent Religions 15 (4): 13–35. doi:10.1525/nr.2012.15.4.13.
- 1 2 Hernández 2002, pp. 125
- ↑ Schmidt 2014, p. 139.
- ↑ "Faculty Database - Koshikawa Yoshiaki".[Ìjápọ̀ tí kò ṣiṣẹ́ mọ́]
Ìwé Àkàkún (Bibliography)
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]- Hernández, Carmen Dolores (2002) (in es). Ricardo Alegría: Una Vida. Centro de Estudios Avanzados del Caribe, Fundación Puertorriqueña de las Humanidades, Instituto de Cultura Puertorriqueña, Academia Puertorriqueña de Historia. ISBN 1563282100.
- Schmidt, Bettina E. (2014). "Spirit Possession in Brazil: The Perception of the (Possessed) Body". Anthropos 109 (1): 135–147. doi:10.5771/0257-9774-2014-1-135. JSTOR 43861689. https://repository.uwtsd.ac.uk/id/eprint/1763/1/43861689%20Anthropos_Spirit%20Possession.pdf.
- Voeks, Robert A. (1997). Sacred Leaves of Candomblé: African Magic, Medicine, and Religion in Brazil. Austin, TX: University of Texas Press. ISBN 9780292787315.
- McKenzie, Peter (14 August 2023) (in en). Hail Orisha!: A Phenomenology of a West African Religion in the Mid-Nineteenth Century. BRILL. p. 28. ISBN 978-90-04-66468-5. https://www.google.ca/books/edition/Hail_Orisha/ntv7EAAAQBAJ?hl=en&gbpv=1&dq=orisha+yewa&pg=PA28&printsec=frontcover.
Kà Sí i
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]- Fayemi Fatunde Fakayode, "Iwure, Efficacious Prayer to Olodumare, the Supreme Force" ISBN 978-978-915-402-9
- Chief S. Solagbade Popoola & Fakunle Oyesanya, Ikunle Abiyamo: The ASE of Motherhood 2007. ISBN 978-0-9810013-0-2
- Chief S. Solagbade Popoola Library, INC Ifa Dida Volume One (EjiOgbe - Orangun Meji)ISBN 978-0-9810013-1-9
- Chief S. Solagbade Popoola Library, INC ISBN 978-1-926538-24-2
- The Way of the Orisha by Philip John Neimark: Publisher HarperOne; 1st edition (28 May 1993) ISBN 978-0-06-250557-6
- Olódùmarè : God in Yoruba Belief by Bolaji Idowu, Ikeja : Longman Nigeria (1982) ISBN 0-582-60803-1
- Dr. Jonathan Olumide Lucas, "The Religion of the Yorubas", Lagos 1948, C. M. S. Bookshop.
- Leeming, David Adams; Leeming, Margaret Adams (2009). A Dictionary of Creation Myths (Oxford Reference Online ed.). Oxford University Press.
- Morales, Ed (2003). The Latin Beat. Da Capo Press. ISBN 0-306-81018-2. https://archive.org/details/latinbeatrhythms00mora_0., pg. 177
- Miguel A. De La Torre, Santería: The Beliefs and Rituals of a Growing Religion in America, 2004, ISBN 0-8028-4973-3.
- Miguel R. Bances – Baba Eshu Onare, Àdàkọ:Usurped. Los 16 Meyis y sus Omoluos u Odus o Signos de Ifa.
- Ológundúdú, Dayọ̀ (2008). The cradle of Yoruba culture. foreword by Akinṣọla Akiwọwọ (Rev. ed.). Institute of Yoráubâa Culture - Center for Spoken Words. ISBN 978-0-615-22063-5.
Àwọn Ìjápọ̀ Ìta
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]| Wikimedia Commons ní àwọn amóunmáwòrán bíbátan mọ́: Esin Yoruba |
- Yoruban cosmology and mythology
- Ifa Studies Podcast hosted by Awoyinfa Ifaloju on iTunes
- Yoruba Movies & Films Archived 26 February 2023 at the Wayback Machine. Yoruba Theatre is the origin of Nigeria's Nollywood, the equivalent of America's Hollywood.
- Articles containing Old Norse-language text
- Articles containing Yorùbá-language text
- Pages containing cite templates with deprecated parameters
- CS1 Èdè Gẹ̀ẹ́sì-language sources (en)
- Webarchive template wayback links
- Pages with citations using unsupported parameters
- CS1 Èdè Faransé-language sources (fr)
- All articles with dead external links
- Articles with dead external links from April 2026
- Articles with invalid date parameter in template
- Articles with permanently dead external links
- Ẹ̀sìn ní Áfíríkà
- Ẹ̀sìn ìbílẹ̀ Áfíríkà
- Àṣà Yorùbá
- Ẹ̀sìn Yorùbá