Esther Soyannwo
Esther Oladunni Soyannwo (nee Ososami) fìgbà kan jẹ́ olùkọ́ àti olóṣèlú ilè Nàìíríà. Ní ọdún 1964 òun ni obìnrin àkọ́kọ́ tí wọ́n yàn sí Ilé Ìgbìmọ̀ Aṣòfin, àmọ́ kò ríbi gorí ipò náà.
Ìgbésí ayé rẹ̀
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Soyannwo gba ẹ̀kọ́ girama rẹ̀ ní CMS Girls School Lagos, ó sì ṣiṣẹ́ gẹ́gẹ́ bí olùkọ́. Gẹ́gẹ́ bí ìyá ọlọ́mọ mẹ́fà tó jẹ́, [1] ó wọ inú ètò ìṣèlú ní ọdún 1950, tí ó sì darapọ̀ mọ́ Action Group láti di ajàfẹ́tọ̀ọ́ àwọn ẹ̀ka obìnrin ti ẹgbẹ́ náà ni1953. Wọ́n yàn án sí Ijebu South district council,[2] lẹ́yìn náà ló di obìnrin kan ṣoṣo tó díje dupò nínú ìdìbò ti ọdún 1964.[3] Àbúrò rẹ̀ tó jẹ́ oníṣòwò ọlọ́lá kan ní ìlú Ìjẹ̀bú ló gbé gbogbo ohun tó rọ̀ mọ́ ìpolongo rẹ̀,[4] àbúrò rẹ̀ yìí fun ní £2,000.[2] Àwọn ẹgbẹ́ obìnrin ìlú Ìjẹ̀bú náà ṣe àtìlẹyìn fún ìpolongo yìí.[2] Ó jáwé olúborí, tí ó sì ṣẹ́gun olùdíjẹ rẹ̀, ìyẹn Sanya Onabamiro láti Nigerian National Democratic Party opponent pẹ̀lú ibò 18,232 sí to 2,149,[2] èyí sì mu kó jẹ́ ọ̀kan lára àwọn ọmọ ẹgbẹ́ Action Group láti jáwé olúborí ní Western Region.[1] Àmọ́, ìwà-ipá wọ inú ìdìbò náà, èyí tó mú kí àwọn ọmọ-ẹgbẹ́ rẹ̀ gbà á níyànjú láti mah gorí oyè náà nítorí ewu rẹ̀ máa ti pọ̀ jù fun.[2]
Àwọn ìtọ́kasí
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]- 1 2 STRIFE IN NIGERIA: PARTY HITS BACK; Loser in Vote See Threat to Political Existence The New York Times, 14 November 1965
- 1 2 3 4 5 "Nigerian Women Mobilized", Institute of International Studies, 1982, p263
- ↑ Flora Nwapa (1987) Women in Politics
- ↑ Catherine Coquery-Vidrovitch (2018) African Women: A Modern History p185