Jump to content

Gómìnà Ìpínlẹ̀ Èkó

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́
Gómìnà Ìpínlẹ̀ Èkó
Ọ̀pá Àṣẹ Ìpínlẹ̀ Èkó
Lọ́wọ́lọ́wọ́
Babajide Sanwo-Olu

since 29 Oṣù Kàrún 2019 (2019-05-29)
Ẹ̀ka Aṣekò-ó-tán ti Ìjọba Ìpínlẹ̀ Èkó
StyleỌlọ́lá (His Excellency)
Type
Member ofÌgbìmọ̀ Aṣekò-ó-tán ti Ìpínlẹ̀ Èkó
ResidenceLagos House
SeatIkeja
AppointerÌdìbò gbogboogbò tààrà tàbí nípasẹ̀ igbákejì gómìnà tí ó rọ́pò
Iye ìgbàỌdún mẹ́rin
ó ṣeé túnṣe lẹ́ẹ̀kan
Constituting instrumentÒfin Ìwé-àkóso Nàìjíríà
FormationOṣù Kàrún 27, 1967; ọdún 59 sẹ́yìn (1967-05-27)
First holderMobolaji Johnson
DeputyIgbákejì Gómìnà ti Ìpínlẹ̀ Èkó

Gómìnà Ìpínlẹ̀ Èkó ni olórí ìjọba ti Ìpínlẹ̀ ÈkóNàìjíríà.[1] Gómìnà ni ó ń darí ẹ̀ka aṣekò-ó-tán ti Ìjọba Ìpínlẹ̀ Èkó. Ipò yìí ń gbé ẹni tí ó wà níbẹ̀ sí ipò aṣáájú ìpínlẹ̀ pẹ̀lú àṣẹ lórí àwọn ọ̀rọ̀ ìpínlẹ̀. Wọ́n sábà máa ń pe Gómìnà ní ọmọ ilú àkọ́kọ́ (number one citizen) ti ìpínlẹ̀ náà.[2][3][4] Abala Kejì ti Òfin Ìwé-àkóso Nàìjíríà fi agbára aṣekò-ó-tán (executive power) ti ìpínlẹ̀ lé gómìnà lọ́wọ́, ó sì gbé e lé e lọ́wọ́ láti mú òfin ìpínlẹ̀ ṣẹ, pẹ̀lú ojúṣe láti yan àwọn aṣekò-ó-tán, aṣojú, olùṣe-òfin, àti àwọn òṣìṣẹ́ ilé-ẹjọ́ ti ìpínlẹ̀ lábẹ́ ìfọwọ́sí àwọn ọmọ Ilé-ìgbìmọ̀ Aṣòfin.[5]

Àwọn agbára àti ojúṣe

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Agbára àkọ́kọ́ tí Òfin Ìwé-àkóso fún gómìnà ni agbára láti kọ̀ (veto).[6] Abala Ìgbéwá (Presentment Clause) gba pé kí wọ́n gbé èyíkéyìí ìwé-òfin tí Ilé-ìgbìmọ̀ Aṣòfin Ìpínlẹ̀ Èkó bá fọwọ́sí wá síwájú gómìnà kí ó tó lè di òfin.[7] Nígbà tí wọ́n bá ti gbé ìwé-òfin náà wá, gómìnà ní àṣàyàn mẹ́ta:

  1. Kí ó fọwọ́sí ìwé-òfin náà; ìwé-òfin náà yóò wá di òfin.
  2. Kí ó kọ̀ ìwé-òfin náà (veto) kí ó sì dá a padà sí ilé-ìgbìmọ̀ aṣòfin ìpínlẹ̀ pẹ̀lú àlàyé ìdí tí ó fi kọ̀ ọ́; ìwé-òfin náà kò ní di òfin, àyàfi tí àwọn ọmọ ilé-ìgbìmọ̀ bá dìbò láti fagilé ìkọ̀sílẹ̀ gómìnà pẹ̀lú ìdá-mẹ́ta-méjì ìbò.[8]

Àwọn agbára Ìṣàkóso

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Gómìnà ni wọ́n fi ṣe olùtọ́jú kan ṣoṣo fún agbára aṣekò-ó-tán ti Ìpínlẹ̀ Èkó, àwọn agbára tí wọ́n gbé lé e lọ́wọ́ àti àwọn ojúṣe tí wọ́n fi fún un tóbi gan-an.[9] Gómìnà ni olórí ẹ̀ka aṣekò-ó-tán ti ìjọba ìpínlẹ̀, ó sì jẹ́ ojúṣe rẹ̀ lábẹ́ òfin láti "rí i dájú pé wọ́n fi òtítọ́ inú mú àwọn òfin ṣẹ." Gómìnà máa ń ṣe ọ̀pọ̀lọpọ̀ yíyàn sí ipò ẹ̀ka aṣekò-ó-tán: àwọn kọmíṣọ́nà àti àwọn òṣìṣẹ́ ìpínlẹ̀ mìíràn, gbogbo wọn ni gómìnà ń yàn pẹ̀lú ìfọwọ́sí ilé-ìgbìmọ̀ aṣòfin ìpínlẹ̀.[10] Agbára gómìnà láti yọ àwọn òṣìṣẹ́ aṣekò-ó-tán kúrò lẹ́nu iṣẹ́ ti pẹ́ tí ó jẹ́ ọ̀rọ̀ òṣèlú tí ó ń fa awuyewuye. Ní gbogboogbò, gómìnà le yọ àwọn òṣìṣẹ́ aṣekò-ó-tán kúrò ní ìfẹ́ inú rẹ̀. Síbẹ̀síbẹ̀, ilé-ìgbìmọ̀ aṣòfin le dín agbára gómìnà kù láti yọ àwọn kọmíṣọ́nà ti àwọn ilé-iṣẹ́ aládàáṣe àti àwọn òṣìṣẹ́ aṣekò-ó-tán kéékèèké kan kúrò nípasẹ̀ òfin. Gómìnà tún ní agbára láti darí púpọ̀ nínú ẹ̀ka aṣekò-ó-tán nípasẹ̀ àwọn àṣẹ aṣekò-ó-tán tí wọ́n fìdí múlẹ̀ nínú Òfin Ìpínlẹ̀ Èkó tàbí tí Òfin Ìwé-àkóso fún ní agbára.[11][12]

Àwọn agbára Ìdájọ́

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Gómìnà tún ní agbára láti yan Olórí Adájọ́ (Chief Judge) ti ìpínlẹ̀. Síbẹ̀síbẹ̀, àwọn yíyàn wọ̀nyí nílò ìfọwọ́sí Ilé-ìgbìmọ̀ Aṣòfin.[13] Rírí ìfọwọ́sí ilé-ìgbìmọ̀ le jẹ́ ìdènà ńlá fún àwọn gómìnà tí wọ́n fẹ́ láti darí ẹ̀ka ìdájọ́ ìpínlẹ̀ sí ọ̀nà èrò òṣèlú kan pàtó.[14] Àwọn gómìnà tún le fúnni ní ìdáríjì àti ìmúkúrò ẹ̀ṣẹ̀, bí ó ṣe máa ń sábà wáyé ní kété kí àkókò ìjọba gómìnà tó parí, èyí tí kì í ṣe pé kò ní fa awuyewuye.[15]

Olùrọ̀rùn Iṣẹ́ Òfin

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Abala Àìlẹ́tọ̀ọ́ ti Òfin Ìwé-àkóso kọ̀ fún gómìnà (àti gbogbo àwọn òṣìṣẹ́ aṣekò-ó-tán mìíràn) láti jẹ́ ọmọ ilé-ìgbìmọ̀ aṣòfin ìpínlẹ̀ ní àkókò kan náà. Nítorí náà, gómìnà kò le dá àbá òfin wọlé tààrà fún àyẹ̀wò ní ilé-ìgbìmọ̀ aṣòfin. Síbẹ̀síbẹ̀, gómìnà le kó ipa láti ẹ̀yìn láti ṣe àgbékalẹ̀ òfin, pàápàá tí ẹgbẹ́ òṣèlú gómìnà bá pọ̀ jù ní ilé-ìgbìmọ̀ (house of representative).[16] Fún àpẹẹrẹ, gómìnà tún àwọn òṣìṣẹ́ mìíràn ti ẹ̀ka aṣekò-ó-tán le kọ àbá òfin, kí wọ́n sì ní kí àwọn aṣojú gbé àbá wọ̀nyí wọlé sí ilé-ìgbìmọ̀. Gómìnà tún le ní ipa lórí ẹ̀ka aṣòfin nípasẹ̀ àwọn ìròyìn tí òfin pa láṣẹ pé kí ó máa fún ilé-ìgbìmọ̀ nígbà gbogbo.[11][17] Ní àfikún, gómìnà le gbìyànjú láti jẹ́ kí ilé-ìgbìmọ̀ aṣòfin ṣe àtúnṣe sí àbá òfin nípa dídún kòkò láti kọ̀ (veto) òfin náà tí wọn kò bá ṣe àwọn àtúnṣe tí ó béèrè fún.[18]

Ìdìbò tààrà láti ọwọ́ àwọn ènìyàn ni a fi ń yan Gómìnà nípasẹ̀ ẹgbẹ́ òṣèlú tí a forúkọsílẹ̀ fún àkókò ọdún mẹ́rin, òun sì jẹ́ ọ̀kan lára àwọn òṣìṣẹ́ ìpínlẹ̀ méjì péré tí a ń dìbò yàn, èkejì ni Igbákejì Gómìnà.[19] Orí kẹfà ti Òfin Ìwé-àkóso Nàìjíríà 1999 bí a ṣe tún un ṣe gbé àwọn ohun tí a nílò kalẹ̀ láti di ipò náà mú.[20][21] Gómìnà gbọ́dọ̀:

  • Jẹ́ ọmọ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà nípa ìbí.
  • Jẹ́ ẹni tí ó kéré jù ní ọmọ ọdún márùn-ún-le-lọ́gbọ̀n (35).
  • Jẹ́ ọmọ ẹgbẹ́ òṣèlú tí a forúkọsílẹ̀, kí ẹgbẹ́ òṣèlú náà sì dúró fún un.
  • Gbọ́dọ̀ ní ó kéré jù Ìwé-ẹ̀rí Ilé-ìwé ti Ìwọ̀-oòrùn Áfríkà (WAEC) tàbí èyí tí ó dọ́gba pẹ̀lú rẹ̀.

Àwọn gómìnà àtijọ́ àti ti lọ́wọ́lọ́wọ́

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Àwọn Ìtọ́kasí

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]
  1. "Governor Babatunde Raji Fashola". africa-confidential.com. Retrieved 17 April 2015.
  2. "Again, CACOL Petitions EFCC to Investigate Lagos State Government, Articles - THISDAY LIVE". thisdaylive.com. Archived from the original on 18 April 2015. Retrieved 17 April 2015. Unknown parameter |url-status= ignored (help)
  3. "Lagos State Government orders Jonathan's campaign posters removed - DailyPost Nigeria". DailyPost Nigeria. Retrieved 17 April 2015.
  4. "Lagos State Government Seizes September Salaries Of Doctors For The Second Month In A Row". Sahara Reporters. Retrieved 17 April 2015.
  5. "LG election and governors' veto power". Newswatch Times. Archived from the original on 17 April 2015. Retrieved 17 April 2015. Unknown parameter |url-status= ignored (help)
  6. Nwabueze, Benjamin Obi (1982). A Constitutional History of Nigeria. ISBN 9780905838793. https://books.google.com/books?id=B6jrE5CBhl0C&q=Governor+of+Lagos+with+Veto+power&pg=PA40. Retrieved 17 April 2015.
  7. "Nigeria". google.co.uk. 1982. Retrieved 17 April 2015.
  8. Coleman, James Smoot; Coleman, James Samuel (January 1958). Nigeria. ISBN 9780520020702. https://books.google.com/books?id=ZOgdDZlJqG8C&q=Governor+of+Lagos+with+Veto+power&pg=PA280. Retrieved 17 April 2015.
  9. "Lagos cabinet-Fashola's list tears ACN apart". Vanguard News. Retrieved 18 April 2015.
  10. "Lagos Cabinet: Fashola Submits 37 Names to Assembly, Articles - THISDAY LIVE". thisdaylive.com. Archived from the original on 16 April 2015. Retrieved 17 April 2015. Unknown parameter |url-status= ignored (help)
  11. 1 2 "Lagos Assembly Approves 499.105bn as 2013 Budget, Articles - THISDAY LIVE". thisdaylive.com. Archived from the original on 18 April 2015. Retrieved 17 April 2015. Unknown parameter |url-status= ignored (help)
  12. "Lagos SMS War: Fashola Sacks Commissioner". TheNigerianVoice. Retrieved 17 April 2015.
  13. "Fashola Swears in Four Judges, Charges them to Better the Judiciary, Articles - THISDAY LIVE". thisdaylive.com. Archived from the original on 18 April 2015. Retrieved 17 April 2015. Unknown parameter |url-status= ignored (help)
  14. "Fashola approves appointment of six new judges for lagos high court". The premiumtimes. Retrieved 18 April 2015.
  15. "Pardons and commutations in Nigeria". World Coalition Against the Death Penalty. Archived from the original on 18 April 2015. Retrieved 17 April 2015.
  16. "Attorney-General of Lagos State V Attorney-General of the Federation". nigeria-law.org. Archived from the original on 19 July 2014. Retrieved 17 April 2015. Unknown parameter |url-status= ignored (help)
  17. "LAGOS GOVERNOR SIGNS 2010 BUDGET". TheNigerianVoice. Retrieved 17 April 2015.
  18. Coleman, James S. "Nigeria". google.co.uk. Retrieved 17 April 2015.
  19. "Lagos State Governor-elect Thanks Residents, Party For Victory - Channels Television". Channels Television. Retrieved 17 April 2015.
  20. "Chapter Six of the 1999 Constitution of Nigeria: The Executive". waado.org. Archived from the original on 22 April 2015. Retrieved 17 April 2015. Unknown parameter |url-status= ignored (help)
  21. Leadership Newspaper (12 April 2015). "APC's Ambode Wins Lagos State Governorship Election". Nigerian News from Leadership News. Archived from the original on 15 April 2015. Retrieved 17 April 2015.

Àwọn ìjápọ̀ ìta

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Àdàkọ:Lagos Àdàkọ:LagosStatewideOfficials