Gómìnà Ìpínlẹ̀ Èkó
| Gómìnà Ìpínlẹ̀ Èkó | |
|---|---|
Ọ̀pá Àṣẹ Ìpínlẹ̀ Èkó | |
| Ẹ̀ka Aṣekò-ó-tán ti Ìjọba Ìpínlẹ̀ Èkó | |
| Style | Ọlọ́lá (His Excellency) |
| Type | |
| Member of | Ìgbìmọ̀ Aṣekò-ó-tán ti Ìpínlẹ̀ Èkó |
| Residence | Lagos House |
| Seat | Ikeja |
| Appointer | Ìdìbò gbogboogbò tààrà tàbí nípasẹ̀ igbákejì gómìnà tí ó rọ́pò |
| Iye ìgbà | Ọdún mẹ́rin ó ṣeé túnṣe lẹ́ẹ̀kan |
| Constituting instrument | Òfin Ìwé-àkóso Nàìjíríà |
| Formation | Oṣù Kàrún 27, 1967 |
| First holder | Mobolaji Johnson |
| Deputy | Igbákejì Gómìnà ti Ìpínlẹ̀ Èkó |
Gómìnà Ìpínlẹ̀ Èkó ni olórí ìjọba ti Ìpínlẹ̀ Èkó ní Nàìjíríà.[1] Gómìnà ni ó ń darí ẹ̀ka aṣekò-ó-tán ti Ìjọba Ìpínlẹ̀ Èkó. Ipò yìí ń gbé ẹni tí ó wà níbẹ̀ sí ipò aṣáájú ìpínlẹ̀ pẹ̀lú àṣẹ lórí àwọn ọ̀rọ̀ ìpínlẹ̀. Wọ́n sábà máa ń pe Gómìnà ní ọmọ ilú àkọ́kọ́ (number one citizen) ti ìpínlẹ̀ náà.[2][3][4] Abala Kejì ti Òfin Ìwé-àkóso Nàìjíríà fi agbára aṣekò-ó-tán (executive power) ti ìpínlẹ̀ lé gómìnà lọ́wọ́, ó sì gbé e lé e lọ́wọ́ láti mú òfin ìpínlẹ̀ ṣẹ, pẹ̀lú ojúṣe láti yan àwọn aṣekò-ó-tán, aṣojú, olùṣe-òfin, àti àwọn òṣìṣẹ́ ilé-ẹjọ́ ti ìpínlẹ̀ lábẹ́ ìfọwọ́sí àwọn ọmọ Ilé-ìgbìmọ̀ Aṣòfin.[5]
Àwọn agbára àti ojúṣe
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Ipa nínú Òfin
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Agbára àkọ́kọ́ tí Òfin Ìwé-àkóso fún gómìnà ni agbára láti kọ̀ (veto).[6] Abala Ìgbéwá (Presentment Clause) gba pé kí wọ́n gbé èyíkéyìí ìwé-òfin tí Ilé-ìgbìmọ̀ Aṣòfin Ìpínlẹ̀ Èkó bá fọwọ́sí wá síwájú gómìnà kí ó tó lè di òfin.[7] Nígbà tí wọ́n bá ti gbé ìwé-òfin náà wá, gómìnà ní àṣàyàn mẹ́ta:
- Kí ó fọwọ́sí ìwé-òfin náà; ìwé-òfin náà yóò wá di òfin.
- Kí ó kọ̀ ìwé-òfin náà (veto) kí ó sì dá a padà sí ilé-ìgbìmọ̀ aṣòfin ìpínlẹ̀ pẹ̀lú àlàyé ìdí tí ó fi kọ̀ ọ́; ìwé-òfin náà kò ní di òfin, àyàfi tí àwọn ọmọ ilé-ìgbìmọ̀ bá dìbò láti fagilé ìkọ̀sílẹ̀ gómìnà pẹ̀lú ìdá-mẹ́ta-méjì ìbò.[8]
Àwọn agbára Ìṣàkóso
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Gómìnà ni wọ́n fi ṣe olùtọ́jú kan ṣoṣo fún agbára aṣekò-ó-tán ti Ìpínlẹ̀ Èkó, àwọn agbára tí wọ́n gbé lé e lọ́wọ́ àti àwọn ojúṣe tí wọ́n fi fún un tóbi gan-an.[9] Gómìnà ni olórí ẹ̀ka aṣekò-ó-tán ti ìjọba ìpínlẹ̀, ó sì jẹ́ ojúṣe rẹ̀ lábẹ́ òfin láti "rí i dájú pé wọ́n fi òtítọ́ inú mú àwọn òfin ṣẹ." Gómìnà máa ń ṣe ọ̀pọ̀lọpọ̀ yíyàn sí ipò ẹ̀ka aṣekò-ó-tán: àwọn kọmíṣọ́nà àti àwọn òṣìṣẹ́ ìpínlẹ̀ mìíràn, gbogbo wọn ni gómìnà ń yàn pẹ̀lú ìfọwọ́sí ilé-ìgbìmọ̀ aṣòfin ìpínlẹ̀.[10] Agbára gómìnà láti yọ àwọn òṣìṣẹ́ aṣekò-ó-tán kúrò lẹ́nu iṣẹ́ ti pẹ́ tí ó jẹ́ ọ̀rọ̀ òṣèlú tí ó ń fa awuyewuye. Ní gbogboogbò, gómìnà le yọ àwọn òṣìṣẹ́ aṣekò-ó-tán kúrò ní ìfẹ́ inú rẹ̀. Síbẹ̀síbẹ̀, ilé-ìgbìmọ̀ aṣòfin le dín agbára gómìnà kù láti yọ àwọn kọmíṣọ́nà ti àwọn ilé-iṣẹ́ aládàáṣe àti àwọn òṣìṣẹ́ aṣekò-ó-tán kéékèèké kan kúrò nípasẹ̀ òfin. Gómìnà tún ní agbára láti darí púpọ̀ nínú ẹ̀ka aṣekò-ó-tán nípasẹ̀ àwọn àṣẹ aṣekò-ó-tán tí wọ́n fìdí múlẹ̀ nínú Òfin Ìpínlẹ̀ Èkó tàbí tí Òfin Ìwé-àkóso fún ní agbára.[11][12]
Àwọn agbára Ìdájọ́
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Gómìnà tún ní agbára láti yan Olórí Adájọ́ (Chief Judge) ti ìpínlẹ̀. Síbẹ̀síbẹ̀, àwọn yíyàn wọ̀nyí nílò ìfọwọ́sí Ilé-ìgbìmọ̀ Aṣòfin.[13] Rírí ìfọwọ́sí ilé-ìgbìmọ̀ le jẹ́ ìdènà ńlá fún àwọn gómìnà tí wọ́n fẹ́ láti darí ẹ̀ka ìdájọ́ ìpínlẹ̀ sí ọ̀nà èrò òṣèlú kan pàtó.[14] Àwọn gómìnà tún le fúnni ní ìdáríjì àti ìmúkúrò ẹ̀ṣẹ̀, bí ó ṣe máa ń sábà wáyé ní kété kí àkókò ìjọba gómìnà tó parí, èyí tí kì í ṣe pé kò ní fa awuyewuye.[15]
Olùrọ̀rùn Iṣẹ́ Òfin
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Abala Àìlẹ́tọ̀ọ́ ti Òfin Ìwé-àkóso kọ̀ fún gómìnà (àti gbogbo àwọn òṣìṣẹ́ aṣekò-ó-tán mìíràn) láti jẹ́ ọmọ ilé-ìgbìmọ̀ aṣòfin ìpínlẹ̀ ní àkókò kan náà. Nítorí náà, gómìnà kò le dá àbá òfin wọlé tààrà fún àyẹ̀wò ní ilé-ìgbìmọ̀ aṣòfin. Síbẹ̀síbẹ̀, gómìnà le kó ipa láti ẹ̀yìn láti ṣe àgbékalẹ̀ òfin, pàápàá tí ẹgbẹ́ òṣèlú gómìnà bá pọ̀ jù ní ilé-ìgbìmọ̀ (house of representative).[16] Fún àpẹẹrẹ, gómìnà tún àwọn òṣìṣẹ́ mìíràn ti ẹ̀ka aṣekò-ó-tán le kọ àbá òfin, kí wọ́n sì ní kí àwọn aṣojú gbé àbá wọ̀nyí wọlé sí ilé-ìgbìmọ̀. Gómìnà tún le ní ipa lórí ẹ̀ka aṣòfin nípasẹ̀ àwọn ìròyìn tí òfin pa láṣẹ pé kí ó máa fún ilé-ìgbìmọ̀ nígbà gbogbo.[11][17] Ní àfikún, gómìnà le gbìyànjú láti jẹ́ kí ilé-ìgbìmọ̀ aṣòfin ṣe àtúnṣe sí àbá òfin nípa dídún kòkò láti kọ̀ (veto) òfin náà tí wọn kò bá ṣe àwọn àtúnṣe tí ó béèrè fún.[18]
Ìlànà yíyàn
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Yíyẹ sí ipò
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Ìdìbò tààrà láti ọwọ́ àwọn ènìyàn ni a fi ń yan Gómìnà nípasẹ̀ ẹgbẹ́ òṣèlú tí a forúkọsílẹ̀ fún àkókò ọdún mẹ́rin, òun sì jẹ́ ọ̀kan lára àwọn òṣìṣẹ́ ìpínlẹ̀ méjì péré tí a ń dìbò yàn, èkejì ni Igbákejì Gómìnà.[19] Orí kẹfà ti Òfin Ìwé-àkóso Nàìjíríà 1999 bí a ṣe tún un ṣe gbé àwọn ohun tí a nílò kalẹ̀ láti di ipò náà mú.[20][21] Gómìnà gbọ́dọ̀:
- Jẹ́ ọmọ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà nípa ìbí.
- Jẹ́ ẹni tí ó kéré jù ní ọmọ ọdún márùn-ún-le-lọ́gbọ̀n (35).
- Jẹ́ ọmọ ẹgbẹ́ òṣèlú tí a forúkọsílẹ̀, kí ẹgbẹ́ òṣèlú náà sì dúró fún un.
- Gbọ́dọ̀ ní ó kéré jù Ìwé-ẹ̀rí Ilé-ìwé ti Ìwọ̀-oòrùn Áfríkà (WAEC) tàbí èyí tí ó dọ́gba pẹ̀lú rẹ̀.
Àwọn gómìnà àtijọ́ àti ti lọ́wọ́lọ́wọ́
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Ẹ tún wo
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Àwọn Ìtọ́kasí
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]- ↑ "Governor Babatunde Raji Fashola". africa-confidential.com. Retrieved 17 April 2015.
- ↑ "Again, CACOL Petitions EFCC to Investigate Lagos State Government, Articles - THISDAY LIVE". thisdaylive.com. Archived from the original on 18 April 2015. Retrieved 17 April 2015. Unknown parameter
|url-status=ignored (help) - ↑ "Lagos State Government orders Jonathan's campaign posters removed - DailyPost Nigeria". DailyPost Nigeria. Retrieved 17 April 2015.
- ↑ "Lagos State Government Seizes September Salaries Of Doctors For The Second Month In A Row". Sahara Reporters. Retrieved 17 April 2015.
- ↑ "LG election and governors' veto power". Newswatch Times. Archived from the original on 17 April 2015. Retrieved 17 April 2015. Unknown parameter
|url-status=ignored (help) - ↑ Nwabueze, Benjamin Obi (1982). A Constitutional History of Nigeria. ISBN 9780905838793. https://books.google.com/books?id=B6jrE5CBhl0C&q=Governor+of+Lagos+with+Veto+power&pg=PA40. Retrieved 17 April 2015.
- ↑ "Nigeria". google.co.uk. 1982. Retrieved 17 April 2015.
- ↑ Coleman, James Smoot; Coleman, James Samuel (January 1958). Nigeria. ISBN 9780520020702. https://books.google.com/books?id=ZOgdDZlJqG8C&q=Governor+of+Lagos+with+Veto+power&pg=PA280. Retrieved 17 April 2015.
- ↑ "Lagos cabinet-Fashola's list tears ACN apart". Vanguard News. Retrieved 18 April 2015.
- ↑ "Lagos Cabinet: Fashola Submits 37 Names to Assembly, Articles - THISDAY LIVE". thisdaylive.com. Archived from the original on 16 April 2015. Retrieved 17 April 2015. Unknown parameter
|url-status=ignored (help) - 1 2 "Lagos Assembly Approves 499.105bn as 2013 Budget, Articles - THISDAY LIVE". thisdaylive.com. Archived from the original on 18 April 2015. Retrieved 17 April 2015. Unknown parameter
|url-status=ignored (help) - ↑ "Lagos SMS War: Fashola Sacks Commissioner". TheNigerianVoice. Retrieved 17 April 2015.
- ↑ "Fashola Swears in Four Judges, Charges them to Better the Judiciary, Articles - THISDAY LIVE". thisdaylive.com. Archived from the original on 18 April 2015. Retrieved 17 April 2015. Unknown parameter
|url-status=ignored (help) - ↑ "Fashola approves appointment of six new judges for lagos high court". The premiumtimes. Retrieved 18 April 2015.
- ↑ "Pardons and commutations in Nigeria". World Coalition Against the Death Penalty. Archived from the original on 18 April 2015. Retrieved 17 April 2015.
- ↑ "Attorney-General of Lagos State V Attorney-General of the Federation". nigeria-law.org. Archived from the original on 19 July 2014. Retrieved 17 April 2015. Unknown parameter
|url-status=ignored (help) - ↑ "LAGOS GOVERNOR SIGNS 2010 BUDGET". TheNigerianVoice. Retrieved 17 April 2015.
- ↑ Coleman, James S. "Nigeria". google.co.uk. Retrieved 17 April 2015.
- ↑ "Lagos State Governor-elect Thanks Residents, Party For Victory - Channels Television". Channels Television. Retrieved 17 April 2015.
- ↑ "Chapter Six of the 1999 Constitution of Nigeria: The Executive". waado.org. Archived from the original on 22 April 2015. Retrieved 17 April 2015. Unknown parameter
|url-status=ignored (help) - ↑ Leadership Newspaper (12 April 2015). "APC's Ambode Wins Lagos State Governorship Election". Nigerian News from Leadership News. Archived from the original on 15 April 2015. Retrieved 17 April 2015.
- "Nigerian Federal States". WorldStatesmen. Retrieved 2009-11-30.