G. B. A. Koker
| Chief G. B. A Coker |
|---|

Oloye George Baptist Ayodola Coker (ọjọ́ kẹtàdínlọ́gbọ̀n oṣù kínní ọdún 1917 – ọjọ́ keje oṣù Kejì ọdún 1991) jẹ adajo Ilé-ejo gíga ti orílẹ-èdè Naijiria, ti o ṣíṣe láti ọdún 1964 titi di ọdún 1975. O jẹ Olùkọ̀wé ìwé méjì: Family Property Among The Yoruba, [1] ati jara ikẹkọ, freedom and Justice .
Òun ni Olori Eyo ti Àdìmú Orishá, ipò ti o ga julọ ninu Ọdun Eyo eégún nínú ètò ijẹ oye àwọn ọmọ Nàìjíríà , [2] atipe ní ọdún 2000 ọdún ẹyọ kàn wáyé láti fí ṣe ayẹyẹ ìgbésí ayé rẹ. Oun naa ni Baba Isale ti ilu Eko.
Ìpìlẹ
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Ọmọ bíbí ti idile Coker olokiki ni o jẹ , ìdílé ti o jẹ ọkan ninu àwọn ìdílé abiyì julọ ni Nàìjíríà wọn sí jẹ ẹni to ni ipa ninu ìṣòwò ati òṣèlú, olóyè Coker jẹ olori wọn ni ọpọlọpọ ọdun. Agbègbè to gbajúmò ni ilu Eko, Coker, ni orukọ idile rẹ. Awọn ọmọ ẹgbẹ miiran tún ní [3] FCO Coker ti o jẹ oniṣiro owo, Aare akọkọ ti (ICAN), Oluṣowo ilu Eko tẹlẹ ati akọwe si ijọba ipinlẹ Eko akọkọ. Oloye FBA Coker, OON, KJW; Oníṣègùn, alámọ̀ràn nípa oyún ati ìṣègùn obìnrin, ati alága, Victoria Island Consultancy ati iṣẹ ilè ìwòsàn. Iyaafin Oye Akintola-Williams (Mama MUSON), nọọsi alamọdaju ìlera ti o si di olutọju iṣẹ ọnà àti alailera àyíká pẹlú. Iyaafin Hilda Omolola Johnson SRN, SCM, Oludasile ati ìyá àfín ti Ile-iwosan Logemo; Oloye Henry Theodore Okeade Coker SAN, OON (ti a mọ si Oke) olófin ńlá tí ó gbé ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọ̀ràn kalẹ̀ nípa ilẹ̀ àti nípa ọkọ̀ ojú omi àti òfin ọkọ̀ ojú omi.
Igbesi aye
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Saro, Coker ti a bi ni Èkó gẹgẹbi ọmọ George Baptist Coker. [4] O jẹ ọmọ-ọmọ-ọmọ ti Daniel Coker, ẹrú ti o ni òmìnira ti o lọ si Sierra Leone ati pe o jẹ olùṣe pàtàkì nínú ẹ̀dá ti Ile-ijọsin Episcopal Methodist ti Afirika (AME) ni ọdún 1816, èyítí o di alákóso dúdú ti òmìnira akọkọ ni Amẹrika. Nígbà tí Coker dé sí Sierra Leone ní ọdún 1820, ó di míṣọ́nnárì àkọ́kọ́ ti Methodist láti orílẹ̀-èdè Ìwọ̀ Oòrùn kan. Níbẹ̀, Coker dá Ìjọ Methodist sílẹ̀ ní Ìwọ̀ Oòrùn Áfíríkà. [5]
[6] Bàbá rẹ̀ George Baptist Coker, jẹ́ alásè àti olùtajà, ó sì jẹ́ Asiwaju àkọ́kọ́ ti Èkó.
Oloye Coker ti kọ ẹkọ ni Olowogbowo Wesleyan Primary School, Eko lati ọdun 1924 si ọdún 1928 lẹhinna o lọ si ile-iwe giga Methodist Boys' High School, Eko lati ọdún 1929 si ọdún 1931, o pari ilé-ẹ̀kọ́ gíga rẹ gẹgẹbi ọkan nínú àwọn ọmọ ilé-ìwé ìpìlẹ ti Ile-ẹkọ giga Igbobi . Lẹ́yìn náà, ó ṣiṣẹ́ fúngbà díẹ̀ gẹ́gẹ́ bí òṣìṣẹ́ ìjọba àti lẹ́yìn náà gẹ́gẹ́ bí olùkọ́. Lẹhinna o tẹsiwaju si Ilu Lọndọnu lati gba oye ofin ati pe wọn pe si orí oye láti dajọ ni ọdún 1947. O gba Ph.D. Ofin ni ọdún 1955. Coker ni ilana ofin ti o ni owo ni ilu Eko ṣaaju ki o to yan si ijoko ti Ile-ẹjọ giga ti Eko ni ọdún 1958.
Ni ọdún 1962, lásìkò ìdààmú òṣèlú kan ni ẹkùn ìwọ̀-oòrùn orílẹ-èdè Nàìjíríà, Moses Majekodunmi, ẹni to jẹ alabojuto ẹkun naa, yan Coker lati jẹ alága ìgbìmọ̀ ìwádìí lóri ọrọ àwọn ilé-iṣẹ́ ti òfin kan. Àwọn kàn n wo ìgbìmò náà gẹgẹ bi ohùn èlò lati tako ẹgbẹ́ Awolowo ti egbe Action Group . [7] Ṣùgbọ́n, nínú ìròyìn ti o kẹhin ti iwadii naa, wọn rii pé Awolowo jẹbi pẹlú dídá àwọn owó agbègbè Action group lọnà, ṣugbọn o da Akintọla lare, eyiti o jẹ ki o rọrun fun ẹni ikẹhin lati tun pada sipo gẹgẹ bi Alakoso agbegbe naa. [8] [9] Eyi di mimọ si Igbimọ Iwadii Coker .
Igbimọ Iwadii Coker ti ṣe àtẹ̀jade ijabọ ìwọn mẹrin ti n ṣalaye awọn apọju ìṣàkóso ni agbègbè náà. O royin ìlòkulò àwọn owo ilu fun èrè ikọkọ ati ti ìṣèlú. Eyi kii ṣe ọran ni àwọn agbègbè méjì míìràn ti Ariwa ati Ìlà-orùn. Gomina ti Ipinle Ariwa Kashim Ibrahim ku si ipò tálákà, ati M.I Okpara, adarí agbègbè ilà orùn, pẹlu gbogbo àwọn ilé-iṣẹ́ ti o kọ ko le kọ ile kan fun ara rẹ; sugbon jakejado Niger, adarí ti ibùwọ̀ orun, Awo, ti jẹ ẹni tí o ti ni ọpọlọpọ mílíọ̀nù ni owo dọla tẹlẹ. Owo ti ijoba n ṣe fun iṣẹ akanṣe ni wọn ko si àwọn ile iṣẹ aladani bii àwọn oníròyìn (Tribune Newspapers), ohun ini gidi, ìṣàkóso ilè ìtura, ati àwọn ọrọ ajé míràn ti Olori ile Yoruba. [ <span title="accusations of wrongdoing really need to be sourced (August 2025)">Ti o nilo itọkasi</span> ]
Àwọn Komisona náà tun sọ síwájú sí wípé èròngbà Awolowo “ni lati fi owó náà kọ ilè obaluaye ti o le ni owó ni orílè-èdè Nàìjíríà ati lóde oke eyi ti yóò jẹ wípé òun nikàn ni yóò máa ṣàkóso rẹ̀ nipaṣẹ agbára owó ti o ti fi fún àwọn ènìyàn. Ni ọjọ kéjìlélógún oṣù kẹ̀sán, Ọdún 1962 – Wọ́n fi Awolọwọ sẹ́wọ̀n inú ilè nítorí ìwádìí tí ìgbìmọ̀ tó ń ṣèwádìí nípa rẹ̀ ṣe.
Coker di adájọ ni ile-ẹjọ to ga julọ ti Naijiria ni ọdún 1964. Ni Ilé-ẹjọ́ náà, Coker di olókìkí fun awọn idajọ rẹ nípa idaduro ti ipaniyan ti o wa ni isunmọtosi awọn idajọ. Awọn ẹjọ meji pàtàkì ti o da lóri iru ọ̀ran bẹẹ ni Vaswani v Savalakh ati Utilgas Nigerian And Overseas Gas Co. Ltd.v. Pan African Bank Ltd. [10]
Coker je ọmọ ijọ Methodist ni Tinubu, Eko.
Awọn itọkasi
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]- ↑ https://www.cambridge.org/core/journals/journal-of-african-law/article/abs/family-property-among-the-yoruba/A2611A3E4AF1507FC278F9E510CA3F14#access-block
- ↑ https://web.archive.org/web/20151208180254/http://www.methodistchurchtrinitytinubu.com/the_catedral.php
- ↑ https://guardian.ng/saturday-magazine/henry-theodore-okeade-coker-1929-2015/
- ↑ https://web.archive.org/web/20150926020401/http://lagosblog.net/h-t-oke-coker-buried/
- ↑ Exodus and Colonization: Charting the Journey in the Journals of Daniel Coker, a Descendant of Africa. https://www.jstor.org/stable/40027410.
- ↑ https://guardian.ng/saturday-magazine/henry-theodore-okeade-coker-1929-2015/#google_vignette
- ↑ https://en.wikipedia.org/wiki/G._B._A._Coker#cite_ref-7
- ↑ Falola, T., & Genova, A. (2009). Historical dictionary of Nigeria. Lanham, Md: Scarecrow Press. P.82 https://en.wikipedia.org/wiki/G._B._A._Coker#cite_ref-8
- ↑ https://oldnaija.com/2020/03/27/coker-commission-of-inquiry-why-awolowo-was-found-guilty-of-corruption-in-1962/
- ↑ Ogundere, J. D. (1994). The Nigerian judge and his court. Ibadan, University Press. P. 93 https://en.wikipedia.org/wiki/G._B._A._Coker#cite_ref-10