Ibironke Akinsete
Ibironke Akinsete | |
|---|---|
| Born | 1938 (age 87–88) |
| Citizenship | Nigerian |
| Title | Professoor |
| Academic background | |
| Alma mater | Aberdeen University |
| Academic work | |
| Discipline | Haematology |
Ibironke Akinsete (tí a bí ní ọdún 1938) jẹ́ ọ̀jọ̀gbọ́n ọmọ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà nínú ìmọ̀ nípa ẹ̀jẹ̀ àti ìfàjẹ̀sí ẹ̀jẹ̀ àti olùgbèjà fún ìlera àwọn obìnrin. [1] [2] Ó yan ìmọ̀ nípa ẹ̀jẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ipa ọ̀nà iṣẹ́ rẹ̀ nítorí pé ẹ̀jẹ̀ àti bí a ṣe ń ṣe ara ènìyàn ló wù ú. [3]
Ìtàn ìgbésí ayé
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Ibironke Akinsete gba oyè ìṣègùn rẹ̀ láti Aberdeen University, Scotland. Ó tún gba àwọn ìwé ẹ̀rí mìíràn tó yẹ lórí ẹ̀kọ́ nípa ẹ̀jẹ̀ láti Aberdeen University.
Akinsete ṣiṣẹ́ ní Yunifásítì ti Èkó, níbi tí ó ti ṣiṣẹ́ gẹ́gẹ́ bí Olùdámọ̀ràn sí Ẹ̀ka Ìtọ́jú Ẹ̀jẹ̀, ní Kọ́lẹ́ẹ̀jì Ìṣègùn. Ó ṣiṣẹ́ gẹ́gẹ́ bí Alága ti Iṣẹ́ Ìfàjẹ̀sí Ẹ̀jẹ̀ ti Ìpínlẹ̀ Èkó. Ó tún jẹ́ olùtọ́jú fún Ìdènà Àrùn AIDS ní Nàìjíríà àti olùtọ́jú ìgbésí ayé ti awùjọ fún awọn Obìnrin àti arùn AIDS ní Áfíríkà, Nàìjíríà (SWAAN), Ọ̀jọ̀gbọ́n Akinsete ni Alága àkọ́kọ́ ti Ìgbìmọ̀ Ìgbésẹ̀ ti Orílẹ̀-èdè lórí AIDS-NACA.
Wọ́n yan Akinsete gẹ́gẹ́ bí ọmọ ẹgbẹ́ ti Ilé-ẹ̀kọ́ ìmọ̀ sáyẹ́ǹsì ti Nàìjíríà ní ọdún 2006. [4] Ní ọdún 2017, wọ́n fún un ní ẹ̀bùn Achievement Awards ní Nigerian Healthcare Excellence Award (NHEA) fún ìfaradà rẹ̀ sí iṣẹ́ rere àti ìtọ́jú tó dára. [5]
Àwọn ìtọ́kasí
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]- ↑ "Bot Verification". nigeriahealthcareawards.com.ng. Archived from the original on 2024-04-24. Retrieved 2025-08-11.
- ↑ "Nigeria: HIV-Aids Prevalence Is Stabilising in Nation - Professor Akinsete".
- ↑ joseph (2010-04-10). "A Woman must be able to manage and co-ordinate her family and work life - Prof. Ibironkae Akinsete". Vanguard News (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). Retrieved 2025-08-11.
- ↑ "Fellows of the Academy". The Nigerian Academy of Science. Archived from the original on 2024-03-02. Retrieved 2025-09-02.
- ↑ "Bot Verification". nigeriahealthcareawards.com.ng. Archived from the original on 2024-07-13. Retrieved 2025-08-12.