Jump to content

Idewu Ojulari

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́
Idewu Ojulari
Oba of Lagos
1829 - c1835
Osinlokun
Adele Ajosun
[[Royal house|]] Ado, Ologun Kutere, Osinlokun
Father Osinlokun
Born Lagos
Died c 1835
Lagos

Oba Idewu Ojulari (o kú ní ọdún 1835) o jẹ ọba gẹgẹbi ọba ìlú Eko (Oba of Lagos) láti ọdún 1829 titi dì ọdún 1834/5. Baba rẹ ni Oba Osinlokun tí àwọn ọmọ ìyà rẹ sí jẹ́ Kosoko (ẹniti o jẹ ọba láti ọdún 1845 si 1851) ati Opo Olu, olówó àti alágbára obìrin t'in ṣòwò ẹru. [1]

Ikú orò ti Idewu Ojulari

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Idewu Ojulari jẹ ọba lẹyìn ìgbà ti bàbá rẹ Osilokun kú ni ọdún 1829. Sugbon isejoba Idewu Ojulari ko gbajugbaja, nípa àṣẹ Oba ilu Benin ti awon ara ilu Eko ti bèrè si, Idewu Ojulari pa ara rẹ. Lakọsílẹ̀, ìlú Eko ti wa labẹ Benin suzerainty titi di akoko ijọba Oba Kosoko ti awọn ọmọ ogun ilẹ Gẹẹsi yọ kúrò ni ijọba ni ọdún 1851. Lẹhinna, Ọba Akitoye ati ẹni tí o tẹle, Oba Dosunmu, kọ lati san owo-ori lọdọdun fun Benin. [2] [3]

Gẹ́gẹ́ bí òpìtàn Kristin Mann ṣe sọ, ó ṣeé ṣe kó jẹ́ pé ìdààmú ètò ọrọ̀ ajé tó ṣẹlẹ̀ nínú òwò ẹrú lẹ́yìn ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọdún ìjọba Osinlokun ló fa àìlókìkí Idewu Ojulari. Iroyin fi to wa leti wípé awọn oloye Idewu fi aidunnu wọn han si Oba ti ilu Benin, to si fi Egun orí, ida, ati ọ̀rọ̀ àtẹ̀jiṣẹ́ pe “ àwọn ara ilu Eko ko ni da a mo gẹgẹ bi Oba won”. Idewu rí Egun orí náà gẹ́gẹ́ bí ìpè láti gbé májèlé jẹ àti idà gẹ́gẹ́ bí ìpè ogun. Idewu mu àṣàyàn májèlé ti o si pa ara rẹ. [4]

  1. Mann, Kristin (2007). Slavery and the Birth of an African City: Lagos, 1760-1900. Indiana University Press, 2007. p. 45. ISBN 9780253348845. https://archive.org/details/slaverybirthafri00mann.
  2. The Lagos Consulate, 1851-1861. https://en.wikipedia.org/wiki/Idewu_Ojulari#cite_ref-2
  3. Benin and the Europeans: 1485-1897. https://en.wikipedia.org/wiki/Idewu_Ojulari#cite_ref-3
  4. Slavery and the Birth of an African City: Lagos, 1760-1900. https://archive.org/details/slaverybirthafri00mann

Àdàkọ:Obas of Lagos