Jump to content

Ifon Osun

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́

Ifon Osun tabi Ifon Orolu jẹ́ ìlú ńlá kan ní Ìpínlẹ̀ Osun, Nàìjíríà.[1] Ifon je olu-ilu fun ìjọba ìbílẹ̀ Orolu. Ilu Ifon je didasile ni orundun mejila seyin nipase Oba Olaosa Aladikun Akogun Erujeje Adugbo nigba ti o ko awon eniyan re kuro ni Ile-Ife leyin ti Ifa soro. Oba Olaosa je omo akoko Obatala. Ifon ni awon ilu kereje ni abe, awon ilu kereje yi ni Osun-Eesa, Kajola, Idi-Iroko, Isangbe, Bashorun, Oloode, Alaiko, Ikimo, Oloso, Opapa, Odofin ati be be lo. Oba Ilu Ifon ni Oba Peter Oluwole Ipadeola Akinyooye III ti o gorioye ni Osu Keji, Odun 2024. Oba Oluwole ni Oba karundinlogoji ti o je ni Ifon. Olufon nikan ni o ni anfani lati wo ade ati bata re wo aafin Alaafin ti ilu Oyo. Ó ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn olóye àti àwọn agbo-ile. Awon agbo-ile nan ni Eesa, Afin, Laaropo, Eleesi, Sobaloju, Aaje, Alasape, Ooye, Asade, Ile Basorun, Ile Oba, àti bẹ́ẹ̀ bẹ́ẹ̀ lọ. Ilu Ifon jẹ́ ìjọba ńlá ti iran Obatala, ó ní nǹkan bí abúlé mẹ́rìnléláàádọ́rin tí ó yí ìlú náà ká. Ìlú náà ní Ọ́fíìsì Ìfìwéránṣẹ́ àti Ilé-ìkàwé ìjọba ìbílẹ̀. Ile ọlọ́ràá àti koríko tí ó dára jùlọ tí ó dára fún iṣẹ́ àgbẹ̀ àti igbó oko . Ó ní odò kan tí a ń pè ní Owala ní ààlà rẹ̀ pẹ̀lú ìlú Ilie. Ó ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ ohun mere mere fún ìfàmọ́ra awon arìnrìn-àjò. Ilu abinibi ni o je fun omo oba Adesola Adegboyega Akande ati awon bi Durotomi Amuda, Bashiru Akanfe Tijani, Professor Ademola Oladejo, Dr. Oyewo, Rufus Woleola Ojo, Chief James Layioye Ojo, Wale Ojo, Alhaji Sulaiman Bello Oyegbemi, Chief Bayo Zakariyah Bello Oyegbeyed, Oloye Joseph Oyegbemi, Oloye Joseph Ogbolu Oyegbemi, Oloye Joseph Oyegbemi, Oloye Bayo Zakariyah Bello Oyegbemi, Oloye Joseph Oyegbemi. Ona ti won fi un ya Olufon ti ilu Ifon ti o je oba alade ti ilu Ifon ni ki won bere lowo Obatala ati Orisha Olufon. Eyi yoo tẹsiwaju nipasẹ ifọwọsi ti o da lori ikede 1979 ti ijọba ibilẹ Orolu ati ijọba ipinlẹ Ọsun fi lede wipe ikede odun 1988 ti di ofo ati pe o ni aiṣedeede ninu nipase Adajọ Babatunji Olowofoyeku ti Ile-ẹjọ giga ti Ipinle Osun, Osogbo.

Ìjọba

Hon Abolade Nureni Adekunle ni alaga fun ìjọba ìbílẹ̀ Orolu lowolowo.[2]

  1. Aladeojebi, Gbade (2016-10-17). History of Yoruba Land. Partridge Africa. ISBN 978-1-4828-6248-5. https://books.google.com.ng/books?id=jbBODQAAQBAJ&dq=Ifon+Osun&pg=PT522&redir_esc=y. Retrieved 2026-01-01.
  2. "Political Leadership Platform". LeaderBox. Retrieved 2026-01-01.