Ilẹ̀ Ọba Ifẹ̀
| |||||||||||||||||||||||||||||||||||||||
Ilẹ̀ Ọba Ifẹ̀ ni ó jẹ́ ilẹ̀ Ọba àkọ́kọ́ ní inú ìtàn ìṣẹ̀dálẹ̀ Yorùbá.[2] Wọ́n dá a sílẹ̀ ní àsìkò 1000 sí 1420CE sí apá ìwọ̀-Oòrùn ilẹ̀ Adúláwọ̀ tí ó di Nàìjíríà lónìí. Ọdún yí ni ìwádí fi múlẹ̀ wípé wọ́n ṣẹ̀dá àwọn ẹ̀ṣọ́ àti àwòrán àtọwọ́dá kọ̀ọ̀kan tí ìtàn fi múlẹ̀. [3] Bí ó tilẹ̀ jẹ́ wípé èdè Yorùbá ni èdè abínibí ilẹ̀ náà síbẹ̀, wọ́n ní àwọn ẹ̀ka èdè mìíràn tí wọ́n ń sọ . Ilẹ̀ Ọba Ifẹ̀ di apèwáwò látàrí kárà-kátà pẹ̀lú àwọn àlejò oríṣiríṣi láti apá gúúsù ilẹ̀ Adúláwọ̀ tí olú ìlú rẹ̀ sì jẹ́ Ilé-Ifẹ̀. Ilẹ̀ Ọba yí jẹ́ ìkan lára àwọn ilẹ̀ Ọba tí ó wàyàmì lásìkò ọ̀rùndún kẹrìnlá (14 cent.) sẹ́yìn.
Ìtàn ìṣẹ̀dálẹ̀ rẹ̀
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Ohun tí a mọ̀ sí Ifẹ̀ lónìí bẹ̀rẹ̀ láti ibi àkójọ àwọn ilé, mọ̀lẹ́bí àti ìletò kéréje kéréje ṣáájú mìlẹ́níọ́mù BCE tí ó fi wá di ìlú ńlá tí ó di apèwáwò fún ọ̀pọ̀ ènìyàn lónìí, tí ọ̀pọ̀ àwọn ilé wọ̀nyí sì di ilé oyè àti àṣẹ ní fẹ̀ pẹ̀lú. Púpọ̀ àwọn ilé wọ̀nyí ni wọ́n ń fẹ́ láti darí ìṣàkóso ilẹ̀, ohun àlùmọ́nì àti ìjọba ilẹ̀ náà, èyí mú kí wọ́n ma kò ara wọn jọ ní ìbí-ò-jùbí; èyí tí ó sì fa ìjà láàrín wọn. Lásìkò yí, ikọ̀ àwọn ènìyàn kan tí Odùduwà tí ó léwájú wọn ni ó di adarí tí ó sì gbé ìjọba ilẹ̀ Ọba Ifẹ̀ kalẹ̀ ní nkan bí ọ̀rùndún Kẹwàá sí ìkọkànlá sẹẹ́yìn tí ilẹ̀ Ọba náà pẹ̀lú odi tí ó fẹ̀ tó 7 km (4.3 mi) tí fífẹ̀ rẹ̀ sì tó n 2.3 kilometres (1.4 mi) níye. Odi mímọ yìí ni ó dá fàá-kája sílẹ̀ láàrín ikọ̀ tí ó ń darí àti àwọn ọmọ ìlú tí àwọn náà kórajọ tí Ọbàtálá léwájú wọn. Lẹ́yìn ò rẹyìn, ikọ̀ Odùduwà ni ó padà borí nínú ìjà náà.[4] Lẹ́yìn iku Odùduwà àti Ọbàtálá ni wọ́n sọ àwọn méjèèjì di òrìṣà àkúnlẹ̀bọ tí wọ́n sì di ìkan pàtàkì lára ẹ̀sìn Yorùbá títí di òní. Gẹ́gẹ́ bí ìtàn àtẹnudẹ́nu ti wi, lẹ́yìn tí àwọn ọmọ oyè lọ́tún lósì ṣe àpérò ní agbègbè tí wọ́n ń pe ní Ìta-Ìlerò tí ó jẹ́ àdúgbò kan ní Ilé-Ifẹ̀ lẹ́yìn ìjà tí ó wáyé láàrín Odùduwà àti Ọbàtálá tí wọ́n sì pinu láti fọ́nká kí wọ́n lè dá ìletò tiwọn sílẹ̀ pẹ̀lú ìlérí wípé àwọn yóò ma kàn sí Ilé-Ifẹ̀, àwọn yóò sì ma pèsè ìrànwọ́ lásìkò ìpayà.[5]
Ilẹ̀ Ọba Ìbìní jẹ́ ìkan lára àwọn ilẹ̀ tí ó wà lábẹ́ àkóso Ifẹ̀ látàrí bí àwọn afọbajẹ ilẹ̀ Ìbìní ṣe pe Ọ̀rànmíyàn tí ó jẹ́ ọmọ Ọba ní Ile-Ifẹ̀ láti wá gba ìjọba kúrò lọ́wọ́ adarí wọn tẹ́lẹ̀ tí ń ṣe Ogiso kí ó sì gbé ìjọba tuntun tìrẹ kalẹ̀. Ìṣẹ̀lẹ̀ yí ni àwọn onímọ̀ sọ wípé ó wáyé láàrín ọdún 1200 sí 1250. Lábẹ́ ìṣàkóso Ọ̀rànmíyàn ni wọ́n ti yí orúkọ ilẹ̀ náà padà sí Ilẹ̀-Ìbínú kúrò ní orúkọ rẹ̀ tí ó ń jẹ́ tẹ́lẹ̀ Igodomigodo tí wọ́n sì ń ké kúrú pe ní Ìbíní.[6]
Àwọn ìtọ́kasí
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]- ↑ Kalilu, Razaq Olatunde Rom (1997). "Bearded Figure with Leather Sandals: Islam, Historical Cognition, and the Visual Arts of the Yorube". Africa: Rivista Trimestrale di Studi e Documentazione dell'Istituto Italiano per l'Africa e l'Oriente 52 (4): 579–591. JSTOR 40761227. https://www.jstor.org/stable/40761227.
- ↑ Akintoye, Stephen Adebanji (2010). A History of the Yoruba People. Amalion Publishing. ISBN 978-2359260052.
- ↑ akinwumi, ogundiran (2020). The Yoruba: A New History. Indiana University Press. p. 7. ISBN 9780253051509.
- ↑ Adepegba, Cornelius O. (1986). "The Descent from Oduduwa: Claims of Superiority among Some Yoruba Traditional Rulers and the Arts of Ancient Ife". The International Journal of African Historical Studies ([Trustees of Boston University, Boston University African Studies Center]) 19 (1): 77–92. ISSN 03617882. JSTOR 218696. http://www.jstor.org/stable/218696. Retrieved 2025-12-04.
- ↑ Ogundiran, Akinwumi (2020). The Yoruba: A New History. Indiana University Press. ISBN 9780253051509.
- ↑ Bondarenko, Dmitri (2003). "Advent of the Second (Oba) Dynasty: Another Assessment of a Benin History Key Point". History in Africa 30: 63–85. doi:10.1017/S0361541300003144. JSTOR 3172082. https://www.jstor.org/stable/3172082.
