Jump to content

Inumidun Akande

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́
Inumidun Akande
Adájọ́ Inumidun Akande
Olórí Adájọ́ ti Ìpínlẹ̀ Èkó
In office
8 Oṣù Kẹjọ 2009  10 Oṣù Kẹfà 2012
AsíwájúAugustine Alabi
Arọ́pòAyotunde Phillips
Àwọn àlàyé onítòhún
Ọjọ́ìbí10 Oṣù Kẹfà 1947 (1947-06-10) (ọmọ ọdún 78)

Inumidun Akande (tí wọ́n bí ní Ọjọ́ kẹwàá Oṣù Kẹfà 1947) jẹ́ amòfin ọmọ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà àti tẹ́lẹ̀rí Olórí Adájọ́ ti Ìpínlẹ̀ Èkó.[1][2]

Ìbẹ̀rẹ̀ ayé rẹ̀

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Ó lọ sí Holy Trinity Primary School ní Èbúté-Èrò, ìlú ńlá kan ní Ìpínlẹ̀ Èkó ní gúúsù-ìwọ̀-oòrùn Nàìjíríà kí ó tó tẹ̀síwájú lọ sí Ijebu Ode Grammar School, ní Ìpínlẹ̀ Ògùn, níbi tí ó ti gba Ìwé-ẹ̀rí Ilé-ìwé ti Ìwọ̀-oòrùn Áfríkà (West Africa School Certificate) ní 1966.[3] Ó gba oyè àkọ́kọ́ nínú ìmọ̀ Òfin láti Ilé-ẹ̀kọ́ Gíga Ifáfitì ti Èkó ní 1970. Ó jade ní Ilé-ẹ̀kọ́ Òfin Nàìjíríà ní 1971 wọ́n sì pè é sí ibi ìjókòó àwọn amòfin (Call to the bar) ní Ọjọ́ kẹrìndínlógún Oṣù Kẹfà 1971.[4]

Ó darapọ̀ mọ́ Ẹ̀ka Ìdájọ́ ti Ìpínlẹ̀ Èkó ní ìbẹ̀rẹ̀ àwọn ọdún 1970 ó sì ṣiṣẹ́ ní Ilé-iṣẹ́ Ìjọba tó ń rí sí Ìdájọ́ gẹ́gẹ́ bí Olùdarí Àkọsílẹ Òfin (Director of Legislative Drafting), kí wọ́n tó gbe lọ sí Ilé-ìgbìmọ̀ Aṣòfin Àpapọ̀, ní Èkó gẹ́gẹ́ bí Olùrànlọ́wọ́ Olórí Akọ̀wé Òfin ní 1983.[5] Wọ́n yàn án sí ipò adájọ́ ní Èkó ní Ọjọ́ kẹjọ Oṣù Kẹjọ 1989.[6] Wọ́n yàn án gẹ́gẹ́ bí Olórí Adájọ́ ti Ìpínlẹ̀ Èkó ní Ọjọ́ kẹjọ Oṣù Kẹsàn-án 2009, ọdún méjì lẹ́yìn tí Babatunde Fashola, Gómìnà Ìpínlẹ̀ Èkó bọ́ sí orí àléfà.[7] Inumidun fẹ̀yìntì lẹ́nu iṣẹ́ ní Ọjọ́ kẹwàá Oṣù Kẹfà 2012, ní ẹni ọdún márùn-ún-le-lọ́gọ́ta (65), ẹni tí ó sì rọ́pò rẹ̀ ni Ayotunde Phillips, Olórí Adájọ́ kẹrinlá ti Ìpínlẹ̀ Èkó.[8]

Àwọn Ìtọ́kasí

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]
  1. "Justice Inumidun Akande - P.M. NEWS Nigeria". pmnewsnigeria.com. Retrieved 26 April 2015.
  2. "Seven Nigerian Judges Targets Of EFCC Corruption Probe". Sahara Reporters. 11 November 2013. Retrieved 26 April 2015.
  3. "The Nation - 'She came, she saw, she conquered'". www.thenationonlineng.net. Archived from the original on 26 April 2015. Retrieved 6 June 2022. Unknown parameter |url-status= ignored (help)
  4. "Hon. Justice Inumidun Akande". nigeriannotables.com. Archived from the original on 26 April 2015. Retrieved 26 April 2015. Unknown parameter |url-status= ignored (help)
  5. Judicial Reporter. "New Chief Judge for Lagos". judicialreporter.org. Archived from the original on 26 April 2015. Retrieved 26 April 2015. Unknown parameter |url-status= ignored (help)
  6. Aka, Jubril Olabode (5 March 2012). Nigerian Women of Distinction, Honour and Exemplary Presidential Qualities. Trafford. ISBN 9781466915558. https://books.google.com/books?id=sZ1XAAAAQBAJ&q=Inumidun+Akande&pg=PT181. Retrieved 26 April 2015.
  7. "Akande bows out as Lagos Chief Judge". The Punch - Nigeria's Most Widely Read Newspaper. Archived from the original on 16 July 2012. Retrieved 26 April 2015. Unknown parameter |url-status= ignored (help)
  8. "Justice Akande retires as Chief Judge of Lagos State - www.channelstv.com". Channels Television. Retrieved 26 April 2015.