Jump to content

Israel Oludotun Ransome-Kuti

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́
Israel Oludotun Ransome-Kuti
Reverend Israel àti olóyè Funmilayo lẹ́gbẹ́ rẹ, Dolu wà lẹyìn àti Fela ní ilẹlẹ ni wájú, Beko ni ọmọ ti wọn gbè dání, Olikoye lo wà ni apá ọtún
Ọjọ́ìbí(1891-04-30)30 Oṣù Kẹrin 1891
Abeokuta, ipinlẹ Ogun, Nàìjíríà
Aláìsí6 April 1955(1955-04-06) (ọmọ ọdún 63)
Abeokuta, Nàìjíríà
Orílẹ̀-èdèNigerian
Iléẹ̀kọ́ gígaFourah Bay College
CMS Grammar School, Lagos
Iṣẹ́
Ìgbà iṣẹ́19161954
Olólùfẹ́Àdàkọ:Ìyàwó rẹ
Àwọn ọmọ
Parent(s)Josiah Ransome-Kuti Amy Bertha Arinola Ransome-Kuti (Née Olubi)
Notes
Israel Oludotun Ransome-Kuti Ní ààrẹ akọ́kọ́ Nigeria Union of Teachers[1]

Israel Oludotun Ransome-Kuti (ọgbọ̀njọ́ oṣù kẹrin ọdún 1891 ọjọ kẹfà oṣù kẹrin ọdún 1955) [2] jẹ olùkọ ọmọ Nàìjíríà. [3]

A bí Israeli ni ọgbọ̀njọ́ oṣù Kẹrin ọdún 1891 ni Abeokuta, Ipinle Ogun si ìdílé Josiah Ransome-Kuti ati Bertha Anny Olubi. O pari ẹkọ alákọ́bẹ̀rẹ̀ àti gíràmà ní Lagos Grammar School àti Abeokuta Grammar School ki o to lo si Fourah Bay College, Freetown níbi ti o ti parí eko gboyè. [4]

Nígbàtí o jáde ní Fourah Bay College, Israel padà sí Nàìjíríà ní ọdún 1916 láti bẹrẹ iṣẹ rẹ àkọ́kọ́ gẹgẹbi olùkọ kílásì ni Abéòkúta Grammar School títí di ọdún 1918 nígbàtí o fi ìlú rẹ̀ sílẹ̀. [5] Wọ́n yàn án gẹ́gẹ́ bí ọ̀gá àgbà ilé ẹ̀kọ́ Gírámà Ìjẹ̀bú Ode fún ọdún mẹ́tàlá, ó sì tẹ̀ síwájú láti dá ẹgbẹ́ ọ̀gá àgbà ilé ẹ̀kọ́ Ìjẹ̀bú sílẹ̀ lọ́dún 1926. [ <span title="This claim needs references to reliable sources. (April 2022)">Ti o nilo itọkasi</span> ]

Ni ọdún 1931, wọn yán Israel gẹgẹbi Ààrẹ Alàkóso ti Nigeria Union of Teachers ti wọn ṣẹṣẹ dasilẹ, [6] ipò ti o wà titi dì ìgbà ti o fẹhinti ni ọdún 1954. Gbọ̀ngán Kuti , ọkàn nínú àwọn gbọngàn ibùgbé ní Fasiti ìlú Ibadan ti wọn ṣii ni ọdún 1954, ni orukọ rẹ láti bu olá fún. [7]

Ìgbésí ayé ara ẹni

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Ransome-Kuti ní bàbá olórin Fẹla Kuti, àti Oníṣègùn Olikoye Ransome-Kuti ati Beko Ransome-Kuti . O je bàbá bàbá olórin Seun Kuti .

Ní ọjọ kẹfà oṣù kẹrin ọdún 1955 ni Israel ku lóri àisàn tó jẹmọ́ jẹjẹrẹ kàn ní ilè rẹ tó wà ní Abeokuta, ìpínlẹ̀ Ogun. [8]

Àwọn ìtọ́kasí

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]