Jump to content

Jenifa's Diary

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́
Jenifa's Diary
Fáìlì:Jenifa's Diary.jpg
GenreSitcom
Created byFunke Akindele
Based onJenifa
Screenplay byFunke Akindele
Story byFunke Akindele
Directed byJJC Skillz
Tunde Olaoye
Starring
Music byTopage
Country of origin
  • Nigeria
Original language(s)English, Yoruba, Igbo, Hausa and Nigerian Pidgin
No. of seasons28
No. of episodes292
Production
Producer(s)Funke Akindele
Running time20 - 30 minutes
Production company(s)Scene One Productions
Funke Akindele Ayotunde Network (FAAN)
Release
Original networkAfrica Independent Television
Original releaseOṣù Kẹrin 15, 2015 (2015-04-15)

Jenifa's Diary Ó jẹ́ àkójọpọ̀ fíìmù lórí tẹlifíṣọ̀nù ní Nàìjíríà, tí Funke Akindele dá sílẹ̀. [1] Eto akojopo fiimu náà jẹ́ ara ìṣẹ̀dá Jenifa, tó dá lórí akọni kan tó jẹ́ aláìlòye àti eni to ni iwa tin panilerin tó si ní orúkọ kan náà. Jenifa's Diary Ó ní ìpín ẹ̀ẹ̀kẹjọdínlọgbọ̀n, tó sì ń lọ lọ́wọ́ nígbà náà ní ọdún 2017[2]

Jenifa Eto tẹlifísọ̀n náà sọ ìtàn ọmọbìnrin abúlé kan, Jenifa tí Funke Akindele se, tó fẹ́ jáde kúrò nínú ìgbé ayé rẹ̀ tó kún fún ìwà tí kò bójú mu. Nínú àìrẹ̀wẹ̀sì rẹ̀, ó fi abúlé rẹ̀ sílẹ̀ lọ sí Ìpínlẹ̀ Èkó láti lè kàwé dáradára. Toyosi, ọ̀rẹ́ rẹ̀ àtijọ́, kò ní àṣàyàn ju láti gbà á sílé lọ, bó tilẹ̀ jẹ́ pé kò kéde àbẹ̀wò rẹ̀.

Jenifa kò ṣe àṣeyọrí pẹ̀lú ẹ̀kọ́ rẹ̀, ṣùgbọ́n ó rí iṣẹ́ ní ilé onidirí Nikki'o ní Èkó, pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́ ọ̀rẹ́ rẹ̀ Kiki, ó sì di onídìrí tó lórúkọ gan-an.[3]

Ní ilé-ise ìdirí Nikki'o, ó pàdé onídìrí mìíràn, Segun (tí Folarin 'Falz' Falana), Ó di ẹni tó nífẹ̀ẹ́ rẹ̀. Jenifa kọ gbogbo ìrìnàjú rẹ̀ nítorí pé ó fẹ́ bá ẹni tó ga ju òun lọ ní ipò àti ẹ̀kọ́ ṣe ìbáṣepọ̀. Lẹ́yìn náà, Jenifa gbọ́ nípa ìgbìmọ̀ rẹ̀ láti lọ sí Orílẹ̀-èdè Amẹ́ríkà. Ó sọ fún un pé ó ti ń gbìyànjú láti sọ ìfẹ́ inú rẹ̀ fún un, àti láti ran òun lọ́wọ́ láti rìnrìn àjò lọ sí òkèèrè. Lẹ́yìn tí Segun ti lọ, iṣẹ́ ní ise ìdirí ni Nikki'o bẹ̀rẹ̀.

Ní ìpín àkọ́kọ́ ìgbà karùn-ún, Jenifa pàdé Marcus, oníṣòwò tó lówó. Marcus gbà á síṣẹ́ gẹ́gẹ́ bí alábòójútó nínú ilé idiri tuntun rẹ̀. Jenifa sọ fún Toyosi láti kọ lẹ́tà ìfìgbéṣẹ́ sílẹ̀ nítorí pé òun fẹ́ kúrò ní Nikki'O. Lọ́jọ́ kan, ìyàwó Marcus, Tiana, farahàn lójijì. Marcus kò sọ ìgbéyàwó rẹ̀ fún Jenifa rí. Nígbà tí Jenifa àti Adaku àti Benny tí wọ́n fi Nikki'O sílẹ̀ pẹ̀lú rẹ̀ láti lọ wá ibi tí ó dára kò gbà á lọ́rùn pẹ̀lú Tiana mọ́, wọ́n pinnu láti sá padà sí Nikki'O. Ohun tí Jenifa kò mọ̀ ni pé, Adaku àti Benny ti kọ lẹ́tà láti lọ fún ìgbà díẹ̀ dípò tí wọ́n ìbá ti kọ lẹ́tà ìfìgbéṣẹ́ sílẹ̀. Jenifa kò ní àṣàyàn kan mọ́ ju láti padà lọ sí Nikki'O láti bẹ Randy, alábòójútó láti gbà á síṣẹ́ padà. Ohun tó yà á lẹ́nu ni pé, wọ́n gbà á padà pẹ̀lú inú rere, pẹ̀lú ìròyìn pé wọ́n ti fọwọ́ sí àwọn ohun tó fẹ́, àti pé wọ́n ti fi owó iṣẹ́ rẹ̀ kún gẹ́gẹ́ bí ó ti béèrè. Dípò kí Toyosi kọ lẹ́tà ìfìgbéṣẹ́ sílẹ̀, ó kọ lẹ́tà fún ìgbéga owó iṣẹ́. Jenifa bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ rẹ̀ padà ní Nikki'O. Lọ́jọ́ kan, CEO Nikki'O pè ìpàdé kan, ó sì lé Jenifa, Adaku àti Benny kúrò lẹ́nu iṣẹ́ nítorí àìṣòótọ́ wọn. Ẹni tí ó jẹ́ òlùfẹ̀tọ́ tí ó tú àṣírí náà ni Pelumi, orògun Jenifa àti onídìrí ní Nikki'O.

Ìṣẹ̀dá míràn

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Ìṣẹ̀dá míràn tí a ń pè ní Aiyetoro Town ti won bẹ̀rẹ̀ ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ ní ọjọ́ kọkànlélógún oṣù kẹfà ọdún 2019. Ó ní ìpín kejìdínlógún, wọ́n sì ṣàgbéjáde rẹ̀ níbi kan ṣoṣoYoutube. Ó wà ní abúlé Jenifa, ìlú Aiyetoro tí wọ́n dá sílẹ̀ nínú ìtàn, èyí tí ó ṣẹ̀ṣẹ̀ di ìlú. Ó kópa pẹ̀lú Funke Akindele tí ó tún kó ipa rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí Jenifa, àti àwọn kan nínú àwọn òṣèré ẹgbẹ́ rẹ̀ láti Jenifa's Diary bii Tope Adebayo gẹ́gẹ́ bí Waheed (aburo Jenifa)" Tobi Makinde as Timini with Femi Branch, Deyemi Okanlawon, Nkechi Blessing, Ireti Osayemi, Funmi Awelewa, Ether Kalejaiye àti àwọn mìíràn tó darapọ̀ mọ́ àwọn òṣèré náà.

Wọ́n ṣe ìṣẹ̀dá tuntun kan tí wọ́n ń pè ní Jenifa on Lockdown bẹ̀rẹ̀ ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ ní ọjọ́ kẹtàlá oṣù karùn-ún ọdún 2021. Ó jẹ́ eré aláìdánùúrí, wọ́n sì ṣàgbéjáde rẹ̀ lórí YouTube. Ó tún wà ní ìlú Aiyetoro àti ní ibi ìṣọṣọ Jenifa. Funke Akindele kó ipa Jenifa nínú rẹ̀, pẹ̀lú Paschaline Alex Okoli, Tope Adebayo, Tobi Makinde tí wọ́n tún kópa wọn, pẹ̀lú Mustapha Sholagbade,Jumoke Odetola.,àti àwọn mìíràn tó darapọ̀ mọ́ àwọn òṣèré náà.

Àwọn ìtọ́kasí

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]