Joe Ajaero
Joe Ajaero
Joe Ajaero (tí a bí ní ọjọ́ 17 oṣù Kejìlá ọdún 1964) jẹ́ akọ̀ròyìn ilẹ̀ Nàìjíríà àti a oníṣòwò kátàkárà, Nigerian journalist and trade ẹni tí ó jẹ́ Ààrẹ àwọn òṣìṣẹ́ lọ́wọ́lọ́wọ́ Nigerian Labour Congress. Ó tẹ̀lé Ayuba Wabba ẹni tí ó lo sáà méjì láti ọdún 2015 sí ọdún 2023.
Ìgbésí ayé ìbẹ̀rẹ̀ pẹ̀pẹ̀ àti ẹ̀kọ́ life
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]A bí Joe Ajaero ní ọjọ́ 17 oṣù Kejìlá ọdún 1964, ní Emekuku, Owerri North, Imo State. Ó gba ìwé ẹ̀rí onípò kìíní rẹ̀ nínú ẹ̀kọ́ ní University of Nigeria, Nsukka ní ọdún 1990 àti onípò kejì post graduate diploma nínú Akọ̀ròyìn(Journalism) ní Times Journalism Institute ní ọdún 1994. Ní ọdún 1998, ó gba ìwé ẹ̀rí onípò kejì nínú Industrial and Labour Relations ní ilé ẹ̀kọ́ gíga University of Lagos Ó tún gba ìwé ẹ̀rí ti ìmọ̀ òfin ní Baze University, Abuja ní ọdún 2023. Ní ọdún 2003, ó gba sabuké nínú Advance Tariff Structuring and Subsidy Design Option ní International Professional Practice Partnership, Cape Town, South Africa. Ó tún gba àwọn ìwé ẹ̀rí mìíràn ní St George's Business School, Cambridge University; Harvard Business School; East and South African Management Institute (2011); International Training Centre of the International Labour Organization, Turin-Italy (2009).
Iṣẹ́
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Joe Ajaero jẹ́ olùsewádìí ní One Mechanised Infantry Division Nigerian Army, Kaduna, láàárín ọdún 1990 sí 1991 fún ìsìnrú rẹ̀ NYSC. Ó ṣiṣẹ́ gẹ́gẹ́ bí oníròyìn àti olóòtú ìròyìn ní Vanguard láàárín ọdún 1992 sí 2001 síwájú kí ó tó darapọ̀ mọ́ National Union of Electricity Employees (NUEE) gẹ́gẹ́ bí olórí Head of Training/Information láàárín ọdún 2001 sí ọdún 2005. Ní oṣù kẹsàn-án ọdún 2024, Nigerian State Security Department fi òfin mú Joe Ajaero, lẹ́yìn tí ó tako ìjọba ilẹ̀ Nàìjíríà fún fífi owó kún epo rọ̀bì.